< Salmos 6 >
1 Salmo de Davi para o regente, com instrumentos de cordas, uma harpa de oito cordas: SENHOR, não me repreendas na tua ira; e não me castigues em teu furor.
Fún adarí orin. Fún ohun èlò orin olókùn. Gẹ́gẹ́ bí ti ṣeminiti. Saamu ti Dafidi. Olúwa, má ṣe bá mi wí nínú ìbínú rẹ kí ìwọ má ṣe nà mí nínú gbígbóná ìrunú rẹ.
2 Tem misericórdia de mim, SENHOR; porque eu [estou] enfraquecido; cura-me, SENHOR, porque meus ossos estão afligidos.
Ṣàánú fún mi, Olúwa, nítorí èmi ń kú lọ; Olúwa, wò mí sán, nítorí egungun mi wà nínú ìnira.
3 Até minha alma está muito aflita; e tu, SENHOR, até quando?
Ọkàn mi wà nínú ìrora. Yóò ti pẹ́ tó, Olúwa, yóò ti pẹ́ tó?
4 Volta, SENHOR; livra minha alma; salva-me por tua bondade.
Yípadà, Olúwa, kí o sì gbà mí; gbà mí là nípa ìfẹ́ rẹ tí kì í ṣákì í.
5 Porque na morte não há lembrança de ti; no Xeol quem te louvará? (Sheol )
Ẹnikẹ́ni kò ni rántí rẹ nígbà tí ó bá kú. Ta ni yóò yìn ọ́ láti inú isà òkú? (Sheol )
6 Já estou cansado do meu gemido; toda a noite eu inundo a minha cama; com minhas lágrimas molho meu leito.
Agara ìkérora mi dá mi tán. Gbogbo òru ni mo wẹ ibùsùn mi pẹ̀lú ẹkún, mo sì fi omi rin ibùsùn mi pẹ̀lú omijé.
7 Meus olhos estão desolados de mágoa, [e] têm se envelhecido por causa de todos os meus adversários.
Ojú mi di aláìlera pẹ̀lú ìbànújẹ́; wọ́n kùnà nítorí gbogbo ọ̀tá mi.
8 Sai para longe de mim, todos vós praticantes de maldade; porque o SENHOR já ouviu a voz do meu choro.
Kúrò lọ́dọ̀ mi, gbogbo ẹ̀yin tí ń ṣe iṣẹ́ ibi, nítorí Olúwa ti gbọ́ igbe mi.
9 O SENHOR tem ouvido a minha súplica; o SENHOR aceitará a minha oração.
Olúwa ti gbọ́ ẹkún mi fún àánú; Olúwa ti gba àdúrà mi.
10 Todos os meus inimigos se envergonharão e ficarão muito perturbados; voltarão para trás, [e] repentinamente se envergonharão.
Gbogbo àwọn ọ̀tá mi lójú yóò tì, wọn yóò sì dààmú; wọn yóò sì yípadà nínú ìtìjú àìròtẹ́lẹ̀.