< Salmos 47 >

1 Salmo para o regente, dos filhos de Coré: Vós todos os povos, batei palmas; clamai a Deus com voz de alegria.
Fún adarí orin. Ti àwọn ọmọ Kora. Saamu. Ẹ pàtẹ́wọ́, gbogbo ẹ̀yin ènìyàn ẹ hó sí Ọlọ́run pẹ̀lú orin ayọ̀ tó rinlẹ̀.
2 Porque o SENHOR Altíssimo [é] temível, o grande Rei sobre toda a terra.
Báwo ni Olúwa Ọ̀gá-ògo ti ní ẹ̀rù tó ọba ńlá lórí gbogbo ayé.
3 Ele subjugará aos povos debaixo de nós, e as nações debaixo de nossos pés.
Ṣe ìkápá àwọn orílẹ̀-èdè lábẹ́ wa àwọn ènìyàn lábẹ́ ẹsẹ̀ wa
4 Ele escolhe para nós nossa herança, a glória de Jacó, a quem ele amou. (Selá)
Ó mú ilẹ̀ ìní wa fún wa, ọlá Jakọbu, ẹni tí ó fẹ́ wa.
5 Deus sobe com gritos de alegria; o SENHOR, com voz de trombeta.
Ọlọ́run tó gòkè lọ tí òun tayọ̀, Olúwa ti òun ti ariwo ìpè.
6 Cantai louvores a Deus, cantai; cantai louvores ao nosso Rei, cantai.
Ẹ kọrin ìyìn sí Ọlọ́run, ẹ kọrin ìyìn. Ẹ kọrin ìyìn sí ọba wa, ẹ kọrin ìyìn!
7 Porque Deus é o Rei de toda a terra; cantai louvores com entendimento.
Nítorí Ọlọ́run ni ọba gbogbo ayé, ẹ kọrin ìyìn pẹ̀lú Saamu!
8 Deus reina sobre as nações; Deus se senta sobre o trono de sua santidade.
Ọlọ́run jẹ ọba lórí gbogbo kèfèrí; Ọlọ́run jókòó lórí ìtẹ́ ìwà mímọ́ rẹ̀.
9 Os chefes dos povos se juntaram ao povo do Deus de Abraão, porque os escudos da terra pertencem a Deus, [e] ele é muito exaltado.
Àwọn aládé ayé kó ara wọn jọ gẹ́gẹ́ bí ènìyàn Ọlọ́run Abrahamu nítorí asà ayé ti Ọlọ́run ni, òun ni ó ga jùlọ.

< Salmos 47 >