< Salmos 139 >

1 Salmo de Davi, para o regente: SENHOR, tu me examinas e me conheces.
Fún adarí orin. Ti Dafidi. Saamu. Olúwa, ìwọ tí wádìí mi, ìwọ sì ti mọ̀ mí.
2 Tu sabes o meu sentar e o meu caminhar; de longe entendes meus pensamentos.
Ìwọ mọ̀ ìjókòó mi àti ìdìde mi, ìwọ mọ̀ èrò mi ní ọ̀nà jíjìn réré.
3 Tu cercas o meu andar e meu deitar; conheces desde antes os meus caminhos.
Ìwọ yí ipa ọ̀nà mi ká àti ìdùbúlẹ̀ mi, gbogbo ọ̀nà mi sì di mí mọ̀ fún ọ.
4 Mesmo não havendo [ainda] palavra [alguma] em minha língua, eis, SENHOR, que já sabes tudo.
Nítorí tí kò sí ọ̀rọ̀ kan ní ahọ́n mi, kíyèsi i, Olúwa, ìwọ mọ̀ ọ́n pátápátá.
5 Tu me envolves por detrás e pela frente, e pões tua mão sobre mim.
Ìwọ sé mi mọ́ lẹ́yìn àti níwájú, ìwọ sì fi ọwọ́ rẹ lé mi.
6 [Teu] conhecimento é maravilhoso demais para mim, tão alto que não posso [alcançá] -lo.
Irú ìmọ̀ yìí jẹ ohun ìyanu fún mi jù; ó ga, èmi kò le mọ̀ ọ́n.
7 Para onde eu escaparia de teu Espírito? E para onde fugiria de tua presença?
Níbo ní èmi yóò gbé lọ kúrò ni ọwọ́ ẹ̀mí rẹ? Tàbí níbo ni èmi yóò sáré kúrò níwájú rẹ?
8 Se eu subisse até os céus, lá tu [estás]; se eu fizer meu leito no Xeol, eis que tu [também ali estás]. (Sheol h7585)
Bí èmi bá gòkè lọ sí ọ̀run, ìwọ wà níbẹ̀; bí èmí ba sì tẹ́ ẹní mi ní ipò òkú, kíyèsi i, ìwọ wà níbẹ̀ pẹ̀lú. (Sheol h7585)
9 Se eu tomasse as asas do amanhecer, e morasse nas extremidades do mar,
Èmi ìbá mú ìyẹ́ apá òwúrọ̀, kí èmi sì lọ jókòó ní ìhà òpin Òkun,
10 Até ali tua mão me guiaria, e tua mão direita me seguraria.
àní, níbẹ̀ náà ni ọwọ́ rẹ̀ yóò fà mí ọwọ́ ọ̀tún rẹ yóò sì dì mímú.
11 Se eu dissesse: Certamente as trevas me encobrirão; e a luz ao redor de mim [será como] a noite.
Bí mo bá wí pé, “Ǹjẹ́ kí òkùnkùn kí ó bò mí mọ́lẹ̀; kí ìmọ́lẹ̀ kí ó di òru yí mi ká.”
12 Porém nem mesmo as trevas [me] esconderão de ti; ao invés disso, [pois] a noite é tão clara quanto o dia, [e aos teus olhos] as trevas são como a luz.
Nítòótọ́ òkùnkùn kì í ṣú lọ́dọ̀ rẹ; ṣùgbọ́n òru tan ìmọ́lẹ̀ bí ọ̀sán; àti òkùnkùn àti ọ̀sán, méjèèjì bákan náà ní fún ọ.
13 Porque tu és dono do meu ser, e me cobriste no ventre da minha mãe.
Nítorí ìwọ ni ó dá ọkàn mi; ìwọ ni ó bò mí mọ́lẹ̀ nínú ìyá mi.
14 Eu te louvarei porque de um [jeito] assombroso e maravilhoso eu fui feito; maravilhosas [são] tuas obras; e minha alma sabe muito bem.
Èmi yóò yìn ọ, nítorí tẹ̀rù tẹ̀rù àti tìyanu tìyanu ní a dá mi; ìyanu ní iṣẹ́ rẹ; èyí nì ni ọkàn mi sì mọ̀ dájúdájú.
15 Meus ossos não estavam escondidos de ti quando eu fui feito em oculto, e formado como tramas de tecido nas profundezas da terra.
Ẹ̀dá ara mi kò pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ rẹ, nígbà tí a dá mi ní ìkọ̀kọ̀. Tí a sì ń ṣiṣẹ́ ní àràbarà ní ìhà ìsàlẹ̀ ilẹ̀ ayé,
16 Teus olhos viram meu corpo [ainda] sem forma, e tudo estava escrito em teu livro; [até] os dias estavam determinados quando nenhum deles [ainda] havia.
ojú rẹ ti rí ohun ara mi nígbà tí a kò tí ì ṣe mí pé, àti nínú ìwé rẹ ni a ti kọ ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn sí, ní ọjọ́ tí a dá wọn, nígbà tí wọn kò tilẹ̀ tí ì sí.
17 Como são preciosos para mim os teus pensamentos, Deus! Como é grande a quantidade deles!
Ọlọ́run, èrò inú rẹ tí ṣe iyebíye tó fún mi, iye wọn ti pọ̀ tó!
18 Se eu os contasse, seriam muito mais [numerosos] que a areia; [quando] acordo, ainda estou contigo.
Èmi ìbá kà wọ́n, wọ́n ju iyanrìn lọ ní iye: nígbà tí mo bá jí, èmi yóò wà lọ́dọ̀ rẹ síbẹ̀.
19 Ah, Deus, tomara que mates ao perverso! E vós, homens sanguinários, afastai-vos de mim;
Ọlọ́run ìbá jẹ́ pa àwọn ènìyàn búburú nítòótọ́; nítorí náà kúrò lọ́dọ̀ mi ẹ̀yin ọkùnrin ẹlẹ́jẹ̀.
20 Porque eles falam de ti com maldade, [e] teus inimigos [se] exaltam em vão.
Ẹni tí ń fi inú búburú sọ̀rọ̀ sí ọ, àwọn ọ̀tá rẹ ń pe orúkọ rẹ ní asán!
21 Por acaso, SENHOR, eu não odiaria aos que te odeiam? E não detestaria os que se levantam contra ti?
Olúwa, ǹjẹ́ èmi kò kórìíra àwọn tó kórìíra rẹ? Ǹjẹ́ inú mi kò a sì bàjẹ́ sí àwọn tí ó dìde sí ọ?
22 Eu os odeio com ódio completo; eu os considero como inimigos.
Èmi kórìíra wọn ní àkótán; èmi kà wọ́n sí ọ̀tá mi.
23 Examina-me, Deus, e conhece meu coração; prova-me, e conhece meus pensamentos.
Ọlọ́run, wádìí mi, kí o sì mọ ọkàn mí; dán mi wò, kí o sì mọ ìrò inú mi.
24 E vê se em mim [há algum] mau caminho; e guia-me pelo caminho eterno.
Kí ó sì wò ó bí ipa ọ̀nà búburú kan bá wà nínú mi kí ó sì fi ẹsẹ̀ mi lé ọ̀nà àìnípẹ̀kun.

< Salmos 139 >