< Salmos 119 >
1 [Álefe]: Bem-aventurados são os puros em [seus] caminhos, os que andam na lei do SENHOR.
Ìbùkún ni fún àwọn ẹni tí ọ̀nà wọn wà láìlẹ́ṣẹ̀, ẹni tí í rìn ní ìbámu pẹ̀lú òfin Olúwa.
2 Bem-aventurados são os que guardam os testemunhos dele, [e] o buscam com todo o coração;
Ìbùkún ni fún àwọn ẹni tí ń pa òfin rẹ̀ mọ́ tí wọn sì ń wá a pẹ̀lú gbogbo ọkàn wọn.
3 E não praticam perversidade, [mas] andam nos caminhos dele.
Wọn kò ṣe ohun tí kò dára; wọ́n rìn ní ọ̀nà rẹ̀.
4 Tu mandaste que teus mandamentos fossem cuidadosamente obedecidos.
Ìwọ ti la ìlànà rẹ̀ sílẹ̀ kí a sì pa wọ́n mọ́ gidigidi.
5 Ah! Como gostaria que meus caminhos fossem dirigidos a guardar teus estatutos!
Ọ̀nà mi ìbá dúró ṣinṣin láti máa pa òfin rẹ̀ mọ́!
6 Então não me envergonharia, quando eu observasse todos os teus mandamentos.
Nígbà náà, ojú kò ní tì mí nígbà tí mo bá ń kíyèsi àṣẹ rẹ̀ gbogbo.
7 Louvarei a ti com um coração correto, enquanto aprendo os juízos de tua justiça.
Èmi yóò yìn ọ́ pẹ̀lú ọkàn ìdúró ṣinṣin bí èmi bá ti kọ́ òfin òdodo rẹ̀.
8 Eu guardarei teus estatutos; não me abandones por completo.
Èmi yóò gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ̀, má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀ pátápátá.
9 [Bete]: Com que um rapaz purificará o seu caminho? Sendo obediente conforme a tua palavra.
Báwo ni àwọn ọ̀dọ́ yóò ti ṣe pa ọ̀nà rẹ̀ mọ́? Láti máa gbé ní ìbámu sí ọ̀rọ̀ rẹ.
10 Eu te busco como todo o meu coração; não me deixes desviar de teus mandamentos.
Èmi wá ọ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi má ṣe jẹ́ kí èmi yapa kúrò nínú àṣẹ rẹ.
11 Guardei a tua palavra em meu coração, para eu não pecar contra ti.
Èmi ti pa ọ̀rọ̀ rẹ mọ́ ní ọkàn mi kí èmi má ba à ṣẹ̀ sí ọ.
12 Bendito [és] tu, SENHOR; ensina-me os teus estatutos.
Ìyìn ni fún Olúwa; kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
13 Com meus lábios contei todos os juízos de tua boca.
Pẹ̀lú ètè mi èmi tún ṣírò gbogbo òfin tí ó wá láti ẹnu rẹ.
14 Eu me alegro mais com o caminho de teus estatutos, do que com todas as riquezas.
Èmi ń yọ̀ ní ọ̀nà ẹ̀rí rẹ, bí ènìyàn ṣe ń yọ̀ nínú ọláńlá.
15 Meditarei em teus mandamentos, e darei atenção aos teus caminhos.
Èmi ń ṣe àṣàrò nínú ìlànà rẹ èmi sì kíyèsi ọ̀nà rẹ.
16 Terei prazer em teus estatutos; não me esquecerei de tua palavra.
Inú mi dùn sí àṣẹ rẹ; èmi kì yóò gbàgbé ọ̀nà rẹ.
17 [Guímel]: Trata bem o teu servo, [para] que eu viva, e obedeça tua palavra.
Ṣe rere sí ìránṣẹ́ rẹ, èmi yóò sì wà láààyè; èmi yóò ṣe ìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ rẹ.
18 Abre meus olhos, para que eu veja as maravilhas de tua lei.
La ojú mi kí èmi lè ríran rí ohun ìyanu tí ó wà nínú òfin rẹ.
19 Eu sou peregrino na terra, não escondas de mim os teus mandamentos.
Àlejò ní èmi jẹ́ láyé, má ṣe pa àṣẹ rẹ mọ́ fún mi.
20 Minha alma está despedaçada de tanto desejar os teus juízos em todo tempo.
Ọkàn mi pòruurù pẹ̀lú ìfojúsọ́nà nítorí òfin rẹ nígbà gbogbo.
21 Tu repreendes aos malditos arrogantes, que se desviam de teus mandamentos.
Ìwọ fi àwọn agbéraga bú, àwọn tí a fi gégùn ún tí ó ṣìnà kúrò nínú àṣẹ rẹ.
22 Tira-me de minha humilhação e desprezo, pois eu guardei teus testemunhos.
Mú ẹ̀gàn àti àbùkù kúrò lára mi, nítorí èmi pa òfin rẹ mọ́.
23 Até mesmo os príncipes se sentaram, e falaram contra mim; porém o teu servo estava meditando em teus estatutos.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn alákòóso kójọpọ̀, wọ́n ń sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ sí mi, ṣùgbọ́n ìránṣẹ́ rẹ ń ṣe àṣàrò nínú àṣẹ rẹ.
24 Pois teus testemunhos são meus prazeres [e] meus conselheiros.
Òfin rẹ ni dídùn inú mi; àwọn ní olùbádámọ̀ràn mi.
25 [Dálete]: Minha alma está grudada ao pó; vivifica-me conforme tua palavra.
Ọkàn mí lẹ̀ mọ́ erùpẹ̀; ìwọ sọ mí di ààyè gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
26 Eu [te] contei os meus caminhos, e tu me respondeste; ensina-me conforme teus estatutos.
Èmi tún ọ̀nà mi ṣírò ìwọ sì dá mi lóhùn; kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
27 Faze-me entender o caminho de teus preceitos, para eu falar de tuas maravilhas.
Jẹ́ kí n mọ ẹ̀kọ́ ìlànà rẹ: nígbà náà ni èmi yóò ṣe àṣàrò iṣẹ́ ìyanu rẹ.
28 Minha alma se derrama de tristeza; levanta-me conforme tua palavra.
Ọkàn mi ń ṣe àárẹ̀ pẹ̀lú ìbànújẹ́; fi agbára fún mi gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
29 Desvia de mim o caminho de falsidade; e sê piedoso dando-me tua lei.
Pa mí mọ́ kúrò nínú ọ̀nà ẹ̀tàn fún mi ní oore-ọ̀fẹ́ nípa òfin rẹ.
30 Eu escolhi o caminho da fidelidade; e pus [diante de mim] os teus juízos.
Èmi ti yan ọ̀nà òtítọ́ èmi ti gbé ọkàn mi lé òfin rẹ.
31 Estou apegado a teus testemunhos; ó SENHOR, não me envergonhes.
Èmi yára di òfin rẹ mú. Olúwa má ṣe jẹ́ kí ojú kí ó tì mí.
32 Correrei pelo caminho de teus mandamentos, porque tu alargaste o meu coração.
Èmi sáré ní ipa ọ̀nà àṣẹ rẹ, nítorí ìwọ, ti tú ọkàn mi sílẹ̀.
33 [Hê]: Ensina-me, SENHOR, o caminho de teus estatutos, e eu o guardarei até o fim.
Kọ́ mi, Olúwa, láti tẹ̀lé àṣẹ rẹ; nígbà náà ni èmi yóò pa wọ́n mọ́ dé òpin.
34 Dá-me entendimento, e eu guardarei a tua lei, e a obedecerei de todo [o meu] coração.
Fún mi ní òye, èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́ èmi yóò sì máa kíyèsi i pẹ̀lú ọkàn mi.
35 Faze-me andar na trilha de teus mandamentos, porque nela tenho prazer.
Fi ipa ọ̀nà àṣẹ rẹ hàn mí, nítorí nínú rẹ̀ ni èmi rí inú dídùn.
36 Inclina meu coração a teus testemunhos, e não à ganância.
Yí ọkàn mi padà sí òfin rẹ kí ó má ṣe sí ojúkòkòrò mọ́.
37 Desvia meus olhos para que não olhem para coisas inúteis; vivifica-me pelo teu caminho.
Yí ojú mi padà kúrò láti máa wo ohun asán: pa ọ̀nà mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
38 Confirma tua promessa a teu servo, que tem temor a ti.
Mú ìlérí rẹ sẹ sí ìránṣẹ́ rẹ, nítorí òfin rẹ dára.
39 Desvia de mim a humilhação que eu tenho medo, pois teus juízos são bons.
Yí ẹ̀gàn mi padà tí mo bẹ̀rù nítorí tí ìdájọ́ rẹ dára.
40 Eis que amo os teus mandamentos; vivifica-me por tua justiça.
Kíyèsi i, ọkàn mi ti fà sí ẹ̀kọ́ rẹ! Pa ayé mi mọ́ nínú òdodo rẹ.
41 [Vau]: E venham sobre mim tuas bondades, SENHOR; [e também] a tua salvação, segundo tua promessa.
Jẹ́ kí ìfẹ́ rẹ tí kì í kùnà wá bá mi, Olúwa, ìgbàlà rẹ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
42 Para que eu tenha resposta ao que me insulta; pois eu confio em tua palavra.
Nígbà náà ni èmi yóò dá ẹni tí ń sọ̀rọ̀ ẹ̀gàn sí mi lóhùn, nítorí èmi gbẹ́kẹ̀lé ọ̀rọ̀ rẹ.
43 E nunca tires de minha boca a palavra da verdade, pois eu espero em teus juízos.
Má ṣe gba ọ̀rọ̀ òtítọ́ láti ẹnu mi nítorí èmi ti gbé ìrètí mi sínú àṣẹ rẹ.
44 Assim obedecerei a tua lei continuamente, para todo o sempre.
Èmi yóò máa gbọ́rọ̀ sí òfin rẹ nígbà gbogbo láé àti láéláé.
45 E andarei [livremente] por longas distâncias, pois busquei teus preceitos.
Èmi yóò máa rìn káàkiri ní òmìnira, nítorí èmi ti kígbe ẹ̀kọ́ rẹ jáde.
46 Também falarei de teus testemunhos perante reis, e não me envergonharei.
Èmi yóò sọ̀rọ̀ òfin rẹ níwájú àwọn ọba ojú kì yóò sì tì mí,
47 E terei prazer em teus mandamentos, que eu amo.
nítorí èmi ní inú dídùn nínú àṣẹ rẹ nítorí èmi ní ìfẹ́ wọn.
48 E levantarei as minhas mãos a teus mandamentos, que eu amo; e meditarei em teus estatutos.
Èmi gbé ọwọ́ mi sókè nítorí àṣẹ rẹ, èyí tí èmi fẹ́ràn, èmi sì ń ṣe àṣàrò òfin rẹ̀.
49 [Záin]: Lembra-te da palavra [dada] a teu servo, à qual mantenho esperança.
Rántí ọ̀rọ̀ rẹ sí ìránṣẹ́ rẹ, nítorí ìwọ ti fún mi ní ìrètí.
50 Isto é meu consolo na minha aflição, porque tua promessa me vivifica.
Ìtùnú mi nínú ìpọ́njú mi ni èyí: ìpinnu rẹ pa ayé mi mọ́.
51 Os arrogantes têm zombado de mim demasiadamente; [porém] não me desviei de tua lei.
Àwọn agbéraga fi mí ṣe ẹlẹ́yà láì dádúró, ṣùgbọ́n èmi kò padà nínú òfin rẹ.
52 Eu me lembrei de teus juízos muito antigos, SENHOR; e [assim] me consolei.
Èmi rántí àwọn òfin rẹ ìgbàanì, Olúwa, èmi sì rí ìtùnú nínú wọn.
53 Eu me enchi de ira por causa dos perversos, que abandonam tua lei.
Ìbínú dì mímú ṣinṣin nítorí àwọn ẹni búburú, tí wọ́n ti kọ òfin rẹ sílẹ̀.
54 Teus estatutos foram meus cânticos no lugar de minhas peregrinações.
Òfin rẹ ni ọ̀rọ̀ ìpìlẹ̀ orin mi níbikíbi tí èmi ń gbé.
55 De noite tenho me lembrado de teu nome, SENHOR; e tenho guardado tua lei.
Ní òru èmi rántí orúkọ rẹ, Olúwa, èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́
56 Isto eu tenho feito, porque guardo teus mandamentos.
nítorí tí mo gba ẹ̀kọ́ rẹ gbọ́.
57 [Hete]: O SENHOR é minha porção; eu disse que guardaria tuas palavras.
Ìwọ ni ìpín mi, Olúwa: èmi ti pinnu láti tẹríba sí ọ̀rọ̀ rẹ.
58 Busquei a tua face com todo o [meu] coração; tem piedade de mim segundo tua palavra.
Èmi ti wá ojú rẹ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi: fún mi ní oore-ọ̀fẹ́ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
59 Eu dei atenção a meus caminhos, e dirigi meus pés a teus testemunhos.
Èmi ti kíyèsi ọ̀nà mi èmi sì ti gbé ìgbésẹ̀ mi sí òfin rẹ.
60 Eu me apressei, e não demorei a guardar os teus mandamentos.
Èmi yóò yára, ń kò ni lọ́ra láti gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ.
61 Bandos de perversos me roubaram; [porém] não me esqueci de tua lei.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ẹni búburú dì mí pẹ̀lú okùn, èmi kò ní gbàgbé òfin rẹ.
62 No meio da noite eu me levanto para te louvar, por causa dos juízos de tua justiça.
Ní àárín ọ̀gànjọ́ òru èmi dìde láti fi ọpẹ́ fún ọ nítorí òfin òdodo rẹ.
63 Sou companheiro de todos os que te temem, e dos que guardam os teus mandamentos.
Èmi jẹ́ ọ̀rẹ́ sí gbogbo àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ, sí gbogbo àwọn tí ń tẹ̀lé ẹ̀kọ́ rẹ.
64 A terra está cheia de tua bondade, SENHOR; ensina-me os teus estatutos.
Ayé kún fún ìfẹ́ rẹ, Olúwa, kọ́ mi ní òfin rẹ.
65 [Tete]: Tu fizeste bem a teu servo, SENHOR, conforme tua palavra.
Ṣe rere sí ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ, Olúwa.
66 Ensina-me bom senso e conhecimento, pois tenho crido em teus mandamentos.
Kọ́ mi ní ìmọ̀ àti ìdájọ́ rere, nítorí mo gbàgbọ́ nínú àṣẹ rẹ.
67 Antes de ter sido afligido, eu andava errado; mas agora guardo tua palavra.
Kí a tó pọ́n mi lójú èmi ti ṣìnà, ṣùgbọ́n ni ìsinsin yìí èmi gbọ́rọ̀ sí ọ̀rọ̀ rẹ.
68 Tu és bom, e fazes o bem; ensina-me os teus estatutos.
Ìwọ dára, ohun tí ìwọ sì ń ṣe rere ni; kọ́ mi ní ìlànà rẹ.
69 Os arrogantes forjaram mentiras contra mim; [mas] eu com todo o [meu] coração guardo os teus mandamentos.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn agbéraga ti gbìmọ̀ èké sí mí, èmi pa ẹ̀kọ́ rẹ mọ́ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi.
70 O coração deles se incha como gordura; [mas] eu tenho prazer em tua lei.
Ọkàn wọn yigbì kò sì ní àánú, ṣùgbọ́n èmi ní inú dídùn nínú òfin rẹ.
71 Foi bom pra mim ter sido afligido, para assim eu aprender os teus estatutos.
Ó dára fún mi kí a pọ́n mi lójú nítorí kí èmi lè kọ́ òfin rẹ.
72 Melhor para mim é a lei de tua boca, do que milhares de [peças] de ouro ou prata.
Òfin tí ó jáde láti ẹnu rẹ ju iyebíye sí mi lọ ó ju ẹgbẹ̀rún ẹyọ fàdákà àti wúrà lọ.
73 [Iode]: Tuas mãos me fizeram e me formaram; faze-me ter entendimento, para que eu aprenda teus mandamentos.
Ọwọ́ rẹ ni ó dá mi tí ó sì mọ mí; fún mi ní òye láti kọ́ àṣẹ rẹ.
74 Os que te temem olham para mim e se alegram, porque eu mantive esperança em tua palavra.
Jẹ́ kí gbogbo àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ máa yọ̀ nígbà tí wọ́n bá rí mi, nítorí èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
75 Eu sei, SENHOR, que teus juízos são justos; e que tu me afligiste [por] tua fidelidade.
Èmi mọ, Olúwa, nítorí òfin rẹ òdodo ni, àti ní òtítọ́ ni ìwọ pọ́n mi lójú.
76 Seja agora tua bondade para me consolar, segundo a promessa [que fizeste] a teu servo.
Kí ìfẹ́ rẹ tí kì í kùnà jẹ́ ìtùnú mi, gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ sí ìránṣẹ́ rẹ.
77 Venham tuas misericórdias sobre mim, para que eu viva; pois tua lei é o meu prazer.
Jẹ́ kí àánú rẹ kí ó tọ̀ mí wá, kí èmi kí ó lè yè, nítorí òfin rẹ jẹ́ ìdùnnú mi.
78 Sejam envergonhados os arrogantes, porque eles me prejudicaram com mentiras; [porém] eu medito em teus mandamentos.
Kí ojú kí ó ti àwọn agbéraga nítorí wọn pa mí lára láìnídìí ṣùgbọ́n èmi yóò máa ṣe àṣàrò nínú ẹ̀kọ́ rẹ.
79 Virem-se a mim os que te temem e conhecem os teus testemunhos.
Kí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ yí padà sí mi, àwọn tí ó ní òye òfin rẹ.
80 Seja meu coração correto em teus estatutos, para eu não ser envergonhado.
Jẹ́ kí ọkàn mi wà láìlẹ́bi sí òfin rẹ, kí ojú kí ó má ṣe tì mí.
81 [Cafe]: Minha alma desfalece por tua salvação; em tua palavra mantenho esperança.
Ọkàn mi ń fojú ṣọ́nà nítorí ìgbàlà rẹ, ṣùgbọ́n èmi ti fi ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
82 Meus olhos desfaleceram por tua promessa, enquanto eu dizia: Quando tu me consolarás?
Ojú mi kùnà, pẹ̀lú wíwo ìpinnu rẹ; èmi wí pé, “Nígbà wo ni ìwọ yóò tù mí nínú?”
83 Porque fiquei como um odre na fumaça, [porém] não me esqueci teus testemunhos.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi dàbí awọ-wáìnì lójú èéfín, èmi kò gbàgbé ìlànà rẹ.
84 Quantos serão os dias de teu servo? Quando farás julgamento aos meus perseguidores?
Báwo ni ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò ṣe dúró pẹ́ tó? Nígbà wo ni ìwọ yóò bá àwọn tí ń ṣe inúnibíni sí mi wí?
85 Os arrogantes me cavaram covas, aqueles que não são conforme a tua lei.
Àwọn agbéraga wa ihò ìṣubú fún mi, tí ó lòdì sí òfin rẹ.
86 Todos os teus mandamentos são verdade; com mentiras me perseguem; ajuda-me.
Gbogbo àṣẹ rẹ yẹ ní ìgbẹ́kẹ̀lé; ràn mí lọ́wọ́, nítorí ènìyàn ń ṣe inúnibíni sí mi láìnídìí.
87 Estou quase que destruído por completo sobre a terra; porém eu não deixei teus mandamentos.
Wọ́n fẹ́rẹ pa mí rẹ́ kúrò nínú ayé, ṣùgbọ́n èmi kò kọ ẹ̀kọ́ rẹ.
88 Vivifica-me conforme tua bondade, então guardarei o testemunho de tua boca.
Pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ, èmi yóò sì gba ẹ̀rí ẹnu rẹ̀ gbọ́.
89 [Lâmede]: Para sempre, SENHOR, tua palavra permanece nos céus.
Ọ̀rọ̀ rẹ, Olúwa, títí láé ni; ó dúró ṣinṣin ní ọ̀run.
90 Tua fidelidade [dura] de geração em geração; tu firmaste a terra, e [assim] ela permanece.
Òtítọ́ rẹ̀ ń lọ dé gbogbo ìran dé ìran; ìwọ ti dá ayé, ó sì dúró ṣinṣin.
91 Elas continuam por tuas ordens até hoje, porque todos são teus servos.
Òfin rẹ dúró di òní nítorí ohun gbogbo ń sìn ọ́.
92 Se a tua lei não fosse meu prazer, eu já teria perecido em minha aflição.
Bí òfin rẹ̀ kò bá jẹ́ dídùn inú mi, èmi ìbá ti ṣègbé nínú ìpọ́njú mi.
93 Nunca esquecerei de teus mandamentos, porque tu me vivificaste por eles.
Èmi kì yóò gbàgbé ẹ̀kọ́ rẹ láé, nítorí nípa wọn ni ìwọ ti pa ayé mi mọ́.
94 Eu sou teu, salva-me, porque busquei teus preceitos.
Gbà mí, nítorí èmi jẹ́ tìrẹ èmi ti wá ẹ̀kọ́ rẹ.
95 Os perversos me esperaram, para me destruírem; [porém] eu dou atenção a teus testemunhos.
Àwọn ẹni búburú dúró láti pa mí run, ṣùgbọ́n èmi yóò kíyèsi ẹ̀rí rẹ.
96 A toda perfeição eu vi fim; [mas] teu mandamento é extremamente grande.
Sí ohun pípé gbogbo èmi ti rí òpin; ṣùgbọ́n àṣẹ rẹ aláìlópin ni.
97 [Mem]: Ah, como eu amo a tua lei! O dia todo eu medito nela.
Báwo ni èmi ti fẹ́ òfin rẹ tó! Èmi ń ṣe àṣàrò nínú rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ pípẹ́ wá.
98 Ela me faz mais sábio do que meus inimigos [por meio de] teus mandamentos, porque ela está sempre comigo.
Àṣẹ rẹ mú mi gbọ́n ju àwọn ọ̀tá mi lọ, nítorí wọ́n wà pẹ̀lú mi láé.
99 Sou mais inteligente que todos os meus instrutores, porque medito em teus testemunhos.
Èmi ní iyè inú ju gbogbo olùkọ́ mi lọ, nítorí èmi ń ṣe àṣàrò nínú òfin rẹ.
100 Sou mais prudente que os anciãos, porque guardei teus mandamentos.
Èmi ni òye ju àwọn àgbà lọ, nítorí mo gba ẹ̀kọ́ rẹ.
101 Afastei meus pés de todo mau caminho, para guardar tua palavra.
Èmi ti pa ẹsẹ̀ mi mọ́ nínú gbogbo ọ̀nà ibi nítorí kí èmi lè gba ọ̀rọ̀ rẹ.
102 Não me desviei de teus juízos, porque tu me ensinaste.
Èmi kò yà kúrò nínú òfin rẹ, nítorí ìwọ fúnra rẹ̀ ni ó kọ́ mi.
103 Como são doces tuas palavras ao meu paladar! Mais que o mel em minha boca.
Báwo ni ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣe dùn mọ́ mi lẹ́nu tó, ó dùn ju oyin lọ ní ẹnu mi!
104 Obtenho conhecimento por meio de teus preceitos; por isso odeio todo caminho de mentira.
Èmi rí òye gbà nínú ẹ̀kọ́ rẹ; nítorí náà èmi kórìíra gbogbo ọ̀nà tí kò tọ́.
105 [Nun]: Tua palavra é lâmpada para meus pés e luz para meu caminho.
Ọ̀rọ̀ rẹ ni fìtílà sí ẹsẹ̀ mi àti ìmọ́lẹ̀ sí ipa ọ̀nà mi.
106 Eu jurei, e [assim] cumprirei, de guardar os juízos de tua justiça.
Èmi ti ṣe ìbúra èmi sì ti tẹnumọ́ ọn wí pé èmi yóò máa tẹ̀lé òfin òdodo rẹ.
107 Eu estou muito aflito, SENHOR; vivifica-me conforme a tua palavra.
A pọ́n mi lójú gidigidi; Olúwa, sọ mi di ààyè, gẹ́gẹ́ bi ọ̀rọ̀ rẹ
108 Agrada-te das ofertas voluntárias de minha boca, SENHOR; e ensina-me teus juízos.
Olúwa, gba ìyìn àtinúwá ẹnu mi, kí o sì kọ́ mi ní òfin rẹ̀.
109 Continuamente arrisco minha alma, porém não me esqueço de tua lei.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ayé mi wà ni ọwọ́ mi nígbà gbogbo, èmi kò ní gbàgbé òfin rẹ.
110 Os perversos me armaram um laço de armadilha, mas não me desviei de teus mandamentos.
Àwọn ẹni búburú ti dẹ okùn sílẹ̀ fún mi, ṣùgbọ́n èmi kò ṣìnà kúrò nínú ẹ̀kọ́ rẹ.
111 Tomei teus testemunhos por herança para sempre, pois eles são a alegria de meu coração.
Òfin rẹ ni ogún mi láéláé; àwọn ni ayọ̀ ọkàn mi.
112 Inclinei meu coração para praticar os teus testemunhos para todo o sempre.
Ọkàn mi ti lé pípa òfin rẹ mọ́ láé dé òpin.
113 [Sâmeque]: Odeio os inconstantes, mas amo a tua lei.
Èmi kórìíra àwọn ọlọ́kàn méjì, ṣùgbọ́n èmi fẹ́ òfin rẹ.
114 Tu és meu refúgio e meu escudo; eu espero em tua palavra.
Ìwọ ni ààbò mi àti asà mi; èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
115 Afastai-vos de mim, malfeitores, para que eu guarde os mandamentos de meu Deus.
Ẹ kúrò lọ́dọ̀ mi, ẹ̀yin olùṣe búburú, kí èmi lè pa àṣẹ Ọlọ́run mi mọ́!
116 Sustenta-me conforme a tua promessa, para que eu viva; e não me faças ser humilhado em minha esperança.
Gbé mi sókè gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ, kí èmi kí ó lè yè Má sì jẹ́ kí ojú ìrètí mi kí ó tì mí.
117 Segura-me, e estarei protegido; então continuamente pensarei em teus estatutos.
Gbé mi sókè, èmí yóò sì wa láìléwu; nígbà gbogbo ni èmi yóò máa júbà òfin rẹ.
118 Tu atropelas a todos que se desviam de teus estatutos; pois o engano deles é mentira.
Ìwọ kọ gbogbo àwọn tí ó ṣìnà kúrò nínú òfin rẹ, nítorí ẹ̀tàn wọn asán ni.
119 Tu tiras a todos os perversos da terra como [se fossem] lixo; por isso eu amo teus testemunhos.
Gbogbo àwọn ẹni búburú ní ayé ni ìwọ yọ kúrò bí i ìdàrọ́; nítorí náà, èmi fẹ́ òfin rẹ̀.
120 Meu corpo se arrepia de medo de ti; e temo os teus juízos.
Ara mi wárìrì ní ìbẹ̀rù nítorí rẹ̀: èmi dúró ní ìbẹ̀rù òfin rẹ.
121 [Áin]: Eu fiz juízo e justiça; não me abandones com os meus opressores.
Èmi ti ṣe ohun tí i ṣe òdodo àti ẹ̀tọ́: má ṣe fi mí sílẹ̀ fún àwọn tó ń ni mí lára.
122 Sê tu a garantia do bem de teu servo; não me deixes ser oprimido pelos arrogantes.
Mú kí àlàáfíà ìránṣẹ́ rẹ dájú: má ṣe jẹ́ kí àwọn agbéraga ni mi lára.
123 Meus olhos desfaleceram [de esperar] por tua salvação, e pela palavra de tua justiça.
Ojú mi kùnà, fún wíwo ìgbàlà rẹ, fún wíwo ìpinnu òdodo rẹ.
124 Age para com teu servo segundo tua bondade, e ensina-me teus estatutos.
Ṣe pẹ̀lú ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí dídúró ṣinṣin ìfẹ́ rẹ kí o sì kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
125 Eu sou teu servo. Dá-me entendimento; então conhecerei teus testemunhos.
Èmi ni ìránṣẹ́ rẹ; ẹ fún mi ní òye kí èmi lè ní òye òfin rẹ
126 É tempo do SENHOR agir, porque estão violando tua lei.
Ó tó àsìkò fún ọ láti ṣe iṣẹ́, Olúwa; nítorí òfin rẹ ti fọ́.
127 Por isso eu amo teus mandamentos mais que o ouro, o mais fino ouro.
Nítorí èmi fẹ́ràn àṣẹ rẹ ju wúrà, àní ju wúrà dídára lọ,
128 Por isso considero corretos todos os [teus] mandamentos quanto a tudo, e odeio todo caminho de falsidade.
nítorí èmi kíyèsi gbogbo ẹ̀kọ́ òtítọ́ rẹ̀, èmi kórìíra gbogbo ipa ọ̀nà búburú.
129 [Pê]: Maravilhosos são teus testemunhos, por isso minha alma os guarda.
Òfin rẹ̀ ìyanu ni: nítorí náà èmi gbà wọ́n gbọ́.
130 A entrada de tuas palavras dá luz, dando entendimento aos simples.
Ìṣípayá ọ̀rọ̀ rẹ̀ mú ìmọ́lẹ̀ wá; ó fi òye fún àwọn òpè.
131 Abri minha boca, e respirei; porque desejei teus mandamentos.
Èmi ya ẹnu mi mo sì mí hẹlẹ, nítorí èmi fojú ṣọ́nà sí àṣẹ rẹ.
132 Olha-me, e tem piedade de mim; conforme [teu] costume para com os que amam o teu nome.
Yí padà sí mi kí o sì ṣàánú fún mi, bí ìwọ ṣe máa ń ṣe nígbà gbogbo sí àwọn tí ó fẹ́ràn orúkọ rẹ.
133 Firma meus passos em tua palavra, e que nenhuma perversidade me domine.
Fi ìṣísẹ̀ mi múlẹ̀ nínú ọ̀rọ̀ rẹ, má ṣe jẹ́ kí ẹ̀ṣẹ̀ borí mi.
134 Resgata-me da opressão dos homens; então guardarei teus mandamentos.
Rà mí padà lọ́wọ́ aninilára ènìyàn, kí èmi lè gbọ́ ẹ̀kọ́ rẹ.
135 Brilha teu rosto sobre teu servo, e ensina-me teus estatutos.
Jẹ́ kí ojú rẹ kí ó tàn sí ìránṣẹ́ rẹ lára kí ó sì kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
136 Ribeiros d'água descem de meus olhos, porque eles não guardam tua lei.
Omijé sàn jáde ní ojú mi, nítorí wọn kò gba pé òfin rẹ̀ jẹ́ òtítọ́.
137 [Tsadê]: Tu és justo, SENHOR; e corretos são teus juízos.
Olódodo ni ìwọ Olúwa ìdájọ́ rẹ sì dúró ṣinṣin.
138 Tu ensinaste teus testemunhos justos e muito fiéis.
Òfin ti ìwọ gbé kalẹ̀ jẹ́ òdodo: wọ́n yẹ ni ìgbẹ́kẹ̀lé.
139 Meu zelo me consumiu, porque meus adversários se esqueceram de tuas palavras.
Ìtara mi ti pa mí run, nítorí àwọn ọ̀tá mi fi ojú fo ọ̀rọ̀ rẹ dá.
140 Refinada é a tua palavra, e teu servo a ama.
Wọ́n ti dán ìpinnu rẹ wò pátápátá ìránṣẹ́ rẹ sì fẹ́ràn wọ́n.
141 Eu sou pequeno e desprezado; [porém] não me esqueço de teus mandamentos.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi jẹ́ onírẹ̀lẹ̀ àti ẹni ẹ̀gàn èmi kò ni gbàgbé ẹ̀kọ́ rẹ.
142 Tua justiça é justa para sempre, e tua lei é verdade.
Òdodo rẹ wà títí láé òtítọ́ ni òfin rẹ̀.
143 Aperto e angústia me encontraram; [ainda assim] teus mandamentos são meus prazeres.
Ìyọnu àti ìpọ́njú wá sórí mi, ṣùgbọ́n àṣẹ rẹ ni inú dídùn mi.
144 A justiça de teus testemunhos [dura] para sempre; dá-me entendimento, e então viverei.
Òfin rẹ jẹ́ òtítọ́ láé; fún mi ní òye kí èmi lè yè.
145 [Cofe]: Clamei com todo o [meu] coração; responde-me, SENHOR; guardarei teus estatutos.
Èmi kígbe pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi: dá mi lóhùn Olúwa, èmi yóò sì gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ.
146 Clamei a ti; salva-me, e então guardarei os teus testemunhos.
Èmi kígbe pè ọ́; gbà mí èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́.
147 Eu me antecedi ao amanhecer, e gritei; [e] mantive esperança em tua palavra.
Èmi dìde ṣáájú àfẹ̀mọ́júmọ́ èmi ké fún ìrànlọ́wọ́; èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
148 Meus olhos antecederam as vigílias da noite, para meditar em tua palavra.
Ojú mi ṣáájú ìṣọ́ òru, nítorí kí èmi lè ṣe àṣàrò nínú ọ̀rọ̀ rẹ.
149 Ouve minha voz, segundo tua bondade, SENHOR; vivifica-me conforme teu juízo.
Gbọ́ ohùn mi ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú ìfẹ́ rẹ: pa ayé mi mọ́, Olúwa, gẹ́gẹ́ bí òfin rẹ.
150 Aproximam-se [de mim] os que praticam maldade; eles estão longe de tua lei.
Àwọn tí ń gbìmọ̀ ìlànà búburú wà ní tòsí, ṣùgbọ́n wọ́n jìnnà sí òfin rẹ.
151 [Porém] tu, SENHOR, estás perto [de mim]; e todos os teus mandamentos são verdade.
Síbẹ̀ ìwọ wà ní tòsí, Olúwa, àti gbogbo àṣẹ rẹ jẹ́ òtítọ́.
152 Desde antigamente eu soube de teus testemunhos, que tu os fundaste para sempre.
Láti ọjọ́ pípẹ́ wá èmi ti kọ́ nínú òfin rẹ tí ìwọ ti fi ìdí wọn múlẹ̀ láéláé.
153 [Rexe]: Olha a minha aflição, e livra-me [dela]; pois não me esqueci de tua lei.
Wo ìpọ́njú mi kí o sì gbà mí, nítorí èmi kò gbàgbé òfin rẹ.
154 Defende minha causa, e resgata-me; vivifica-me conforme tua palavra.
Gba ẹjọ́ mi rò kí o sì rà mí padà; pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
155 A salvação está longe dos perversos, porque eles não buscam teus estatutos.
Ìgbàlà jìnnà sí àwọn ẹni búburú nítorí wọn kò wá àṣẹ rẹ.
156 Muitas são tuas misericórdias, SENHOR; vivifica-me conforme teus juízos.
Ìyọ́nú rẹ̀ tóbi, Olúwa; pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí òfin rẹ.
157 Muitos são meus perseguidores e meus adversários; [porém] eu não me desvio de teus testemunhos.
Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn ọ̀tá tí wọ́n ń ṣe inúnibíni sí mi, ṣùgbọ́n èmi kò tí ì yípadà kúrò nínú òfin rẹ.
158 Eu vi aos enganadores e os detestei, porque eles não guardam tua palavra.
Èmi wo àwọn ẹlẹ́tàn, inú mi sì bàjẹ́ nítorí wọn kò gba ọ̀rọ̀ rẹ gbọ́.
159 Vê, SENHOR, que eu amo teus mandamentos; vivifica-me conforme a tua bondade.
Wo bí èmi ṣe fẹ́ràn ẹ̀kọ́ rẹ; pa ayé mi mọ́, Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ.
160 O princípio de tua palavra é fiel, e o juízo de tua justiça [dura] para sempre.
Òtítọ́ ni gbogbo ọ̀rọ̀ rẹ; gbogbo òfin òdodo rẹ láéláé ni.
161 [Xin]: Príncipes me perseguiram sem causa, mas meu coração temeu a tua palavra.
Àwọn alákòóso ṣe inúnibíni sí mi láìnídìí, ṣùgbọ́n ọkàn mi wárìrì sí ọ̀rọ̀ rẹ.
162 Eu me alegro em tua palavra, tal como alguém que encontra um grande tesouro.
Èmi yọ̀ nínú ìpinnu rẹ bí ẹni tí ó rí ìkógun púpọ̀.
163 Odeio e abomino a falsidade; [mas] amo a tua lei.
Èmi kórìíra mo sì kọ èké ṣíṣe ṣùgbọ́n mo fẹ́ràn òfin rẹ.
164 Louvo a ti sete vezes ao dia, por causa dos juízos de tua justiça.
Èmi yìn ọ́ ní ìgbà méje lójúmọ́ nítorí òfin òdodo rẹ.
165 Muita paz têm aqueles que amam a tua lei; e para eles não há tropeço.
Àlàáfíà púpọ̀ wà fún àwọn tí ó ní ìfẹ́ sí òfin rẹ, kò sì ṣí ohun tí ó lè mú wọn kọsẹ̀.
166 Espero por tua salvação, SENHOR; e pratico teus mandamentos.
Èmi yóò dúró de ìgbàlà rẹ, Olúwa, èmi yóò sì tẹ̀lé àṣẹ rẹ.
167 Minha alma guarda teus testemunhos, e eu os amo muito.
Èmi gba òfin rẹ gbọ́, nítorí mo fẹ́ràn wọn púpọ̀púpọ̀.
168 Eu guardo teus preceitos e teus testemunhos, porque todos os meus caminhos estão diante de ti.
Èmi ṣe ìgbọ́ràn sí ẹ̀kọ́ rẹ àti òfin rẹ, nítorí ìwọ mọ gbogbo ọ̀nà mi.
169 [Tau]: Chegue meu clamor perante teu rosto, SENHOR; dá-me entendimento conforme tua palavra.
Jẹ́ kí igbe mi wá sí iwájú rẹ, Olúwa; fún mi ní òye gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
170 Venha minha súplica diante de ti; livra-me conforme tua promessa.
Jẹ́ kí ẹ̀bẹ̀ mi wá sí iwájú rẹ; gbà mí gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
171 Meus lábios falarão muitos louvores, pois tu me ensinas teus estatutos.
Ètè mi yóò sọ ìyìn jáde, nítorí ìwọ kọ́ mi ní ìlànà rẹ.
172 Minha língua falará de tua palavra, porque todos os teus mandamentos são justiça.
Jẹ́ kí ahọ́n mi kọ orin ọ̀rọ̀ rẹ, nítorí gbogbo àṣẹ rẹ jẹ́ òdodo.
173 Que tua mão me socorra, porque escolhi [seguir] teus preceitos.
Jẹ́ kí ọwọ́ rẹ ṣetán láti ràn mí lọ́wọ́, nítorí èmi ti yan ẹ̀kọ́ rẹ.
174 Desejo tua salvação, SENHOR; e tua lei é o meu prazer.
Èmi wo ọ̀nà fún ìgbàlà rẹ, Olúwa, àti òfin rẹ jẹ́ dídùn inú mi.
175 Que minha alma viva e louve a ti; e que teus juízos me socorram.
Jẹ́ kí èmi wà láààyè ki èmi lè yìn ọ́, kí o sì jẹ́ kí òfin rẹ mú mi dúró.
176 Tenho andado sem rumo, como uma ovelha perdida; busca a teu servo, pois eu não me esqueci de teus mandamentos.
Èmí ti ṣìnà bí àgùntàn tí ó sọnù. Wá ìránṣẹ́ rẹ, nítorí èmi kò gbàgbé àṣẹ rẹ.