< Salmos 118 >
1 Agradecei ao SENHOR, porque ele é bom; pois sua bondade [dura] para sempre.
Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó dára; àánú rẹ̀ dúró láéláé.
2 Diga agora Israel, que sua bondade [dura] para sempre.
Jẹ́ kí Israẹli wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé”.
3 Diga agora casa de Arão, que sua bondade [dura] para sempre.
Jẹ́ kí ilé Aaroni wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé”.
4 Digam agora os que temem ao SENHOR, que sua bondade [dura] para sempre.
Jẹ́ kí àwọn tí ó bẹ̀rù Olúwa wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé.”
5 Na angústia clamei ao SENHOR; [e] o SENHOR me respondeu, e [me pôs] num lugar amplo.
Nínú ìrora mi, mo sọkún sí Olúwa, ó sì dá mi lóhùn nípa pé ó tú mi sílẹ̀.
6 O SENHOR está comigo, não temerei; o que poderá me fazer o homem?
Olúwa ń bẹ fún èmi; èmi kì yóò bẹ̀rù. Kí ni ènìyàn lè ṣe sí mi?
7 O SENHOR está comigo entre os que ajudam; por isso verei [o fim] daqueles que me odeiam.
Olúwa ń bẹ fún mi; òun ni olùrànlọ́wọ́ mi. Nítorí náà ni èmi ó ṣe rí ìṣẹ́gun mi lórí àwọn tí ó kórìíra mi.
8 Melhor é buscar refúgio no SENHOR do que confiar no homem.
Ó dára láti máa gbẹ́kẹ̀lé Olúwa ju àti gbẹ́kẹ̀lé ènìyàn lọ.
9 Melhor é buscar refúgio no SENHOR do que confiar em príncipes.
Ó dára láti máa gbẹ́kẹ̀lé Olúwa ju à ti gbẹ́kẹ̀lé àwọn ọmọ-aládé lọ.
10 Todas as nações me cercaram; [mas foi] no nome do SENHOR que eu as despedacei.
Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè yí mi káàkiri, ṣùgbọ́n ní orúkọ Olúwa èmi gé wọn kúrò.
11 Cercaram-me, cercaram-me mesmo; [mas foi] no nome do SENHOR que eu as despedacei.
Wọ́n yí mi káàkiri ní gbogbo ẹ̀gbẹ́, ṣùgbọ́n ní orúkọ Olúwa èmi gé wọn dànù.
12 Cercaram-me como abelhas, mas se apagaram como fogo de espinhos; [porque] foi no nome do SENHOR que eu as despedacei.
Wọ́n gbá yìn ìn yí mi ká bí oyin, ṣùgbọ́n wọ́n kú kíákíá bí iná ẹ̀gún; ní orúkọ Olúwa èmi ké wọn dànù.
13 Com força me empurraste para que eu caísse; mas o SENHOR me ajudou.
Ìwọ tì mí gidigidi kí n lè ṣubú, ṣùgbọ́n Olúwa ràn mí lọ́wọ́.
14 O SENHOR é minha força e [minha] canção, porque ele tem sido minha salvação.
Olúwa ni agbára àti orin mi; ó sì di ìgbàlà mi.
15 Nas tendas dos justos há voz de alegria e salvação; a mão direita do SENHOR faz proezas.
Ohùn ayọ̀ àti ìgbàlà ń bẹ nínú àgọ́ àwọn olódodo: “Ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ń ṣe ohun agbára!
16 A mão direita do SENHOR se levanta; a mão direita do SENHOR faz proezas.
Ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ní a gbéga; ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ń ṣe ohun agbára!”
17 Eu não morrerei, mas viverei; e contarei as obras do SENHOR.
Èmi kì yóò kú, ṣùgbọ́n èmi yóò yè, èmi yóò pòkìkí ohun tí Olúwa ṣe.
18 É verdade que o SENHOR me castigou, porém ele não me entregou à morte.
Olúwa bá mi wí gidigidi, ṣùgbọ́n òun kò fi mí lé ikú lọ́wọ́.
19 Abri para mim as portas da justiça; entrarei por elas [e] louvarei ao SENHOR.
Ṣí ìlẹ̀kùn ẹnu-ọ̀nà òdodo fún mi: èmi yóò bá ibẹ̀ wọlé, èmi yóò sì fi ọpẹ́ fún Olúwa.
20 Esta é a porta do SENHOR, pela qual os justos entrarão.
Èyí ni ìlẹ̀kùn Olúwa ibẹ̀ ni àwọn olódodo yóò bá wọlé.
21 Eu te louvarei porque tu me respondeste e me salvaste.
Èmi yóò fi ọpẹ́ fún ọ, nítorí ó dá mi lóhùn; ìwọ sì di ìgbàlà mi.
22 A pedra que os construtores rejeitaram se tornou cabeça de esquina.
Òkúta tí àwọn ọ̀mọ̀lé kọ̀sílẹ̀, ni ó di pàtàkì igun ilé;
23 Pelo SENHOR isto foi feito, [e] é maravilhoso aos nossos olhos.
Olúwa ti ṣe èyí, ó ṣe ìyanu ní ojú wa.
24 Este é o dia em que o SENHOR agiu; alegremos e enchamos de alegria nele.
Èyí ni ọjọ́ tí Olúwa dá: ẹ jẹ́ kí ayọ̀ kí inú wa sì máa dùn nínú rẹ̀.
25 Ah, SENHOR, salva-nos! Ah, SENHOR, faze [-nos] prosperar!
Olúwa, gbà wá; Olúwa, fún wa ní àlàáfíà.
26 Bendito aquele que vem no nome do SENHOR; nós vos bendizemos desde a casa do SENHOR.
Ìbùkún ni ẹni tí ń bọ̀ wá ní orúkọ Olúwa. Àwa ti fi ìbùkún fún ọ láti ilé Olúwa wá.
27 O SENHOR é o [verdadeiro] Deus, que nos deu luz; atai os [sacrifícios] da festa, para [levá-los] aos chifres do altar.
Olúwa ni Ọlọ́run, ó ti mú ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ tàn sí wa lára pẹ̀lú ẹ̀ka igi ní ọwọ́, ó dára pọ̀ mọ́ ọ̀pọ̀ ènìyàn tí ń wọ́ nínú ayọ̀ ẹ fi okùn di ẹbọ náà mọ́ ìwo pẹpẹ.
28 Tu és meu Deus, por isso eu te louvarei. Eu te exaltarei, meu Deus.
Ìwọ ni Ọlọ́run mi, èmi yóò máa fi ọpẹ́ fún ọ; ìwọ ni Ọlọ́run mi, èmi yóò gbé ọ ga.
29 Agradecei ao SENHOR, porque ele é bom; pois sua bondade [dura] para sempre.
Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó ṣeun; nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.