< Salmos 116 >
1 Amo o SENHOR, porque ele escuta minha voz [e] minhas súplicas.
Èmi fẹ́ràn Olúwa, nítorí ó gbọ́ ohùn mi; ó gbọ́ ẹkún mi fún àánú.
2 Porque ele tem inclinado a mim seus ouvidos; por isso eu clamarei a ele em [todos] os meus dias.
Nítorí ó yí etí rẹ̀ padà sí mi, èmi yóò máa pè é ni wọ́n ìgbà tí mo wà láààyè.
3 Cordas da morte me cercaram, e angústias do Xeol me afrontaram; encontrei opressão e aflição. (Sheol )
Okùn ikú yí mi ká, ìrora isà òkú wá sórí mi; ìyọnu àti ìbànújẹ́ borí mi. (Sheol )
4 Mas clamei ao nome do SENHOR, [dizendo]: Ah SENHOR, livra minha alma!
Nígbà náà ni mo ké pe orúkọ Olúwa: “Olúwa, èmi bẹ̀ ọ́, gba ọkàn mi!”
5 O SENHOR é piedoso e justo; e nosso Deus é misericordioso.
Olúwa ní oore-ọ̀fẹ́, ó sì ní òdodo; Ọlọ́run wa kún fún àánú.
6 O SENHOR protege os simples; eu estava com graves problemas, mas ele me livrou.
Olúwa pa àwọn ọlọ́kàn fífúyẹ́ mọ́ nígbà tí mo wà nínú àìní ńlá, ó gbà mí.
7 Minha alma, volta ao teu descanso, pois o SENHOR tem te tratado bem.
Padà, ìwọ ọkàn mi, sí ibi ìsinmi rẹ, nítorí Olúwa ṣe dáradára sí ọ.
8 Porque tu, [SENHOR], livraste minha alma da morte, meus olhos das lágrimas, e meu pé do tropeço.
Nítorí ìwọ, Olúwa, ti gba ọkàn mi kúrò lọ́wọ́ ikú, ojú mi kúrò lọ́wọ́ omijé, àti ẹsẹ̀ mi kúrò lọ́wọ́ ìṣubú,
9 Andarei diante do SENHOR na terra dos viventes.
nítorí èmi yóò máa rìn níwájú Olúwa ní ilẹ̀ alààyè.
10 Eu cri, por isso falei; estive muito aflito.
Èmi gbàgbọ́; nítorí náà mo wí pé, “èmi rí ìpọ́njú púpọ̀”.
11 Eu dizia em minha pressa: Todo homem é mentiroso.
Àti nínú ìdààmú mi mo wí pé, “Èké ni gbogbo ènìyàn”.
12 O que pagarei ao SENHOR por todos os benefícios dele para mim?
Kí ni èmi yóò san fún Olúwa nítorí gbogbo rere rẹ̀ sí mi?
13 Tomarei o copo da salvação, [e] chamarei o nome do SENHOR.
Èmi yóò gbé ago ìgbàlà sókè èmi yóò sì máa ké pe orúkọ Olúwa.
14 Certamente pagarei meus votos ao SENHOR, na presença de todo o seu povo.
Èmi yóò mú ìlérí mi ṣẹ sí Olúwa ní ojú àwọn ènìyàn rẹ̀.
15 Preciosa é aos olhos do SENHOR a morte de seus santos.
Iyebíye ní ojú Olúwa àti ikú àwọn ẹni mímọ́ rẹ̀.
16 Ah SENHOR, verdadeiramente eu sou teu servo; sou teu servo, filho de tua serva; tu me soltaste das correntes que me prendiam.
Olúwa, nítòótọ́ ìránṣẹ́ rẹ ni mo jẹ́; èmi ni ìránṣẹ́ rẹ, ọmọ ìránṣẹ́bìnrin rẹ; ó ti tú mi sílẹ̀ nínú ìdè mi.
17 Sacrificarei a ti sacrifício de agradecimento, e chamarei o nome do SENHOR.
Èmi yóò rú ẹbọ ọpẹ́ sí ọ èmi yóò sì ké pe orúkọ Olúwa.
18 Certamente pagarei meus votos ao SENHOR, na presença de todo o seu povo;
Èmi yóò mú ìlérí mi sẹ sí Olúwa ní ojú gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀,
19 Nos pátios da casa do SENHOR, em meio de ti, ó Jerusalém. Aleluia!
nínú àgbàlá ilé Olúwa ní àárín rẹ̀, ìwọ Jerusalẹmu. Ẹ yin Olúwa.