< Salmos 102 >

1 Oração do aflito, quando ele se viu desfalecido, e derramou sua súplica diante do SENHOR: Ó SENHOR, ouve minha oração; e que meu clamor chegue a ti.
Àdúrà olùpọ́njú tí àárẹ̀ mú, tí ó sí ọkàn rẹ̀ payá níwájú Olúwa. Gbọ́ àdúrà mi, Olúwa, jẹ́ kí igbe ẹ̀bẹ̀ mi kí ó wá sí ọ̀dọ̀ rẹ.
2 Não escondas de mim o teu rosto no dia da minha angústia; inclina a mim teu ouvidos; no dia em que eu clamar, apressa-te para me responder.
Má ṣe pa ojú rẹ mọ́ kúrò lọ́dọ̀ mi ní ọjọ́ tí èmi wà nínú ìpọ́njú. Dẹ etí rẹ sí mi; nígbà tí mo bá pè, dá mi lóhùn kíákíá.
3 Porque os meus dias têm se desfeito como fumaça; e meus ossos se têm se queimado como [n] um forno.
Nítorí tí ọjọ́ mi run bí èéfín; egungun mi sì jóná bí ààrò.
4 Meu coração, tal como a erva, está tão ferido e seco, que me esqueci de comer meu pão.
Àyà mi lù, ó sì rọ bí i koríko; mo gbàgbé láti jẹ oúnjẹ mi.
5 Por causa da voz do meu gemido, meus ossos têm se grudado à minha carne.
Nítorí ohùn ìkérora mi, egungun mi lẹ̀ mọ́ ẹran-ara mi.
6 Estou semelhante a uma ave no deserto, estou como uma coruja num lugar desabitado.
Èmi dàbí ẹyẹ igún ní ijù: èmi dàbí òwìwí ibi ahoro.
7 Fico alerta e estou como um pardal solitário sobre o telhado.
Èmi dìde; èmi dàbí ẹyẹ lórí ilé.
8 Os meus inimigos me insultam o dia todo; os que me odeiam juram [maldições] contra mim.
Ní ọjọ́ gbogbo, àwọn ọ̀tá ológoṣẹ́ mi ń gàn mí; àwọn tí ń ṣe ìkanra sí mi ń fi orúkọ mi bú.
9 Porque estou comendo cinza como [se fosse] pão, e misturo minha bebida com lágrimas,
Èmi jẹ eérú gẹ́gẹ́ bí oúnjẹ mi, èmi sì da ohun mímu mi pọ̀ pẹ̀lú omijé.
10 Por causa de tua irritação e tua ira; porque tu me levantaste e me derrubaste.
Nítorí ìbínú ríru rẹ, nítorí ìwọ ti gbé mi sókè, ìwọ sì gbé mi ṣánlẹ̀.
11 Meus dias [têm sido] como a sombra, que declina; e eu estou secando como a erva.
Ọjọ́ mi dàbí òjìji àṣálẹ́ èmi sì rọ bí koríko.
12 Porém tu, SENHOR, permaneces para sempre; e tua lembrança [continua] geração após geração.
Ṣùgbọ́n ìwọ, Olúwa, ni yóò dúró láéláé; ìrántí rẹ láti ìran dé ìran.
13 Tu te levantarás, e terás piedade de Sião; porque chegou o tempo determinado para se apiedar dela.
Ìwọ ó dìde ìwọ ó sì ṣàánú fún Sioni, nítorí ìgbà àti ṣe ojúrere sí i; àkókò náà ti dé.
14 Pois os teus servos se agradam de suas pedras, e sentem compaixão do pó de suas [ruínas].
Nítorí tí àwọn òkúta jẹ́ inú dídùn sí àwọn ìránṣẹ́ rẹ; wọ́n sì káàánú erùpẹ̀ rẹ.
15 Então as nações temerão o nome do SENHOR; e todos os reis da terra [temerão] a tua glória;
Àwọn kèfèrí yóò bẹ̀rù orúkọ Olúwa, gbogbo ọba ayé yóò máa bẹ̀rù ògo rẹ.
16 Quando o SENHOR edificar a Sião, [e] aparecer em sua glória;
Torí tí Olúwa yóò gbé Sioni ró, yóò farahàn nínú ògo rẹ̀.
17 E der atenção à oração do desamparado, e não desprezar sua oração.
Yóò dáhùn àdúrà àwọn aláìní; kì yóò sì gan ẹ̀bẹ̀ wọn.
18 Isto será escrito para a geração futura; e o povo que for criado louvará ao SENHOR;
Jẹ́ kí a kọ èyí fún ìran tí ń bọ̀, àwọn ènìyàn tí a kò tí ì dá yóò yin Olúwa:
19 Porque ele olhará desde o alto de seu santuário; o SENHOR olhará desde os céus para a terra,
“Olúwa wo ilẹ̀ láti òkè mímọ́ rẹ̀ wá láti ọ̀run wá ni ó bojú wo ayé,
20 Para ouvir o gemido dos prisioneiros; para soltar aos sentenciados à morte.
láti gbọ́ ìrora ará túbú, láti tú àwọn tí a yàn sí ikú sílẹ̀.”
21 Para eles anunciarem o nome do SENHOR em Sião, e seu louvor em Jerusalém.
Kí a lè sọ orúkọ Olúwa ní Sioni àti ìyìn rẹ̀ ní Jerusalẹmu.
22 Quando os povos se reunirem, e os reinos, para servirem ao SENHOR.
Ní ìgbà tí a kó àwọn ènìyàn àti ìjọba pọ̀ láti máa sìn Olúwa.
23 Ele abateu minha força no caminho; abreviou os meus dias.
Ní ipa ọ̀nà mi, ó rẹ agbára mi sílẹ̀, ó gé ọjọ́ mi kúrú.
24 Eu dizia: Meu Deus, não me leves no meio dos meus dias; teus anos são [eternos], geração após geração.
Èmi sì wí pé: “Ọlọ́run mi, má ṣe mú mi kúrò ní agbede-méjì ọjọ́ mi; ọdún rẹ̀ ń lọ láti ìran dé ìran.
25 Desde muito antes fundaste a terra; e os céus são obra de tuas mãos.
Ní ìbẹ̀rẹ̀ ní ìwọ fi ìpìlẹ̀ ayé sọlẹ̀, ọ̀run sì jẹ́ iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.
26 Eles se destruirão, porém tu permanecerás; e todos eles como vestimentas se envelhecerão; como roupas tu os mudarás, e serão mudados.
Wọn yóò ṣègbé, wọn yóò parun, ṣùgbọ́n ìwọ yóò wà; gbogbo wọn ni yóò gbó bí aṣọ. Bí ẹ̀wù ni ìwọ yóò pààrọ̀ wọn wọn yóò sì di àpatì.
27 Porém tu és o mesmo; e teus anos nunca se acabarão.
Ṣùgbọ́n ìwọ wà digbí síbẹ̀, ọdún rẹ kò sì ní òpin.
28 Os filhos de teus servos habitarão [seguros], e a semente deles será firmada perante ti.
Àwọn ọmọ ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò dúró ní iwájú rẹ pẹ́; a ó sì fi ẹsẹ̀ irú-ọmọ wọn sọlẹ̀ ní iwájú rẹ.”

< Salmos 102 >