< Provérbios 9 >
1 A verdadeira sabedoria edificou sua casa; ela lavrou suas sete colunas.
Ọgbọ́n ti kọ́ ilé rẹ̀, ó ti gbẹ́ òpó o rẹ̀ méjèèjì,
2 Ela sacrificou seu sacrifício, misturou seu vinho, e preparou sua mesa.
ó ti fi ilé pọn tí, ó ti fọ̀nà rokà. Ó sì ti ṣètò o tábìlì oúnjẹ rẹ̀
3 Mandou suas servas, [e] está convidando desde os pontos mais altos da cidade, dizendo:
ó ti rán àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ jáde, ó sì ń pè, láti ibi tí ó ga jù láàrín ìlú.
4 Qualquer um que for ingênuo, venha aqui. Aos que têm falta de entendimento, ela diz:
“Jẹ́ kí gbogbo àwọn aláìgbọ́n wọ ibí wá!” Ó ń wí fún àwọn tí kò lọ́gbọ́n pé,
5 Vinde, comei do meu pão; e bebei do vinho que misturei.
“Wá, ẹ wá jẹ́ oúnjẹ mi sì mu wáìnì tí mo ti pò.
6 Abandonai a tolice; e vivei; e andai pelo caminho da prudência.
Fi ìwà àìmọ̀kan rẹ sílẹ̀ ìwọ yóò sì yè; rìn ní ọ̀nà òye.
7 Aquele que repreende ao zombador, toma desonra para si mesmo; e o que tenta corrigir ao perverso acaba sendo manchado.
“Ẹnikẹ́ni tí ó bá bá ẹlẹ́gàn wí, kọ lẹ́tà sí àbùkù ẹnikẹ́ni tí ó bá bá ẹni búburú wí kọ lẹ́tà sí èébú.
8 Não repreendas ao zombador, para que ele não te odeie; repreende ao sábio, e ele te amará.
Má ṣe bá ẹlẹ́gàn wí, àìṣe bẹ́ẹ̀ yóò kórìíra rẹ. Bá ọlọ́gbọ́n wí yóò sì fẹ́ràn rẹ;
9 Ensina ao sábio, e ele será mais sábio ainda; instrui ao justo, e ele aumentará seu conhecimento.
kọ́ ọlọ́gbọ́n ènìyàn lẹ́kọ̀ọ́, yóò sì gbọ́n sí i kọ́ olódodo ènìyàn lẹ́kọ̀ọ́, yóò sì fi kún ìmọ̀ rẹ̀.
10 O temor ao SENHOR é o princípio da sabedoria; e o conhecimento dos santos [é] a prudência.
“Ìbẹ̀rù Olúwa ni ìbẹ̀rẹ̀ ọgbọ́n, ìmọ̀ nípa Ẹni Mímọ́ ni òye.
11 Porque por mim teus dias serão multiplicados; e anos de vida a ti serão aumentados.
Nítorí nípasẹ̀ mi ọjọ́ rẹ yóò gùn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún yóò sì kún ọjọ́ ayé rẹ.
12 Se fores sábio, serás sábio para ti; e se fores zombador, somente tu aguentarás.
Bí ìwọ bá gbọ́n, ọgbọ́n rẹ yóò fún ọ ní èrè: bí ìwọ bá jẹ́ ẹlẹ́gàn, ìwọ nìkan ni yóò jìyà.”
13 A mulher louca é causadora de tumultos; [ela é] tola, e não sabe coisa alguma.
Òmùgọ̀ obìnrin jẹ́ aláriwo; ó jẹ́ aláìlẹ́kọ̀ọ́ àti aláìní ìmọ̀.
14 E se senta à porta de sua casa, sobre uma cadeira, nos lugares altos da cidade;
Ó jókòó ní ẹnu-ọ̀nà ilé rẹ̀ lórí ìjókòó níbi tí ó ga jù láàrín ìlú,
15 Para chamar aos que passam pelo caminho, e passam por suas veredas, [dizendo]:
ó ń pe àwọn tí ó ń kọjá lọ, tí wọn ń lọ tààrà ní ọ̀nà wọn.
16 Qualquer um que for ingênuo, venha aqui! E aos que tem falta de entendimento, ela diz:
“Jẹ́ kí gbogbo ẹni tí ó jẹ́ aláìlóye súnmọ́ bí!” Ni ó wí fún ẹni tí òye kù díẹ̀ ká à tó fún.
17 As águas roubadas são doces; e o pão escondido é agradável.
“Omi tí a jí mu dùn oúnjẹ tí a jẹ ní ìkọ̀kọ̀ a máa ládùn!”
18 Porém não sabem que ali estão os mortos; seus convidados estão nas profundezas do Xeol. (Sheol )
Ṣùgbọ́n wọn ò funra pé àwọn òkú wà níbẹ̀, pé àwọn àlejò rẹ̀ wà ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀ isà òkú. (Sheol )