< Josué 15 >

1 E foi a sorte da tribo dos filhos de Judá, por suas famílias, junto ao termo de Edom, do deserto de Zim ao sul, ao lado do sul.
Ìpín fún ẹ̀yà Juda, ní agbo ilé agbo ilé, títí dé agbègbè Edomu, títí dé aginjù Sini ní òpin ìhà gúúsù.
2 E seu termo da parte do sul foi desde a costa do mar Salgado, desde a baía que está voltada ao sul;
Ààlà wọn ní ìhà gúúsù bẹ̀rẹ̀ láti etí òpin ìhà gúúsù Òkun Iyọ̀,
3 E saía até o sul à subida de Acrabim, passando até Zim; e subindo pelo sul até Cades-Barneia, passava a Hebrom, e subindo por Adar dava volta a Carca;
ó sì gba gúúsù Akrabbimu lọ, títí dé Sini àti sí iwájú ìhà gúúsù Kadeṣi-Barnea. Nígbà náà ó sì tún kọjá Hesroni lọ sí Adari, ó sì tún yípo yíká lọ sí Karka.
4 De ali passava a Azmom, e saía ao ribeiro do Egito; e sai este termo ao ocidente. Este pois vos será o termo do sul.
Ó tún kọjá lọ sí Asmoni, ó sì papọ̀ mọ́ Wadi ti Ejibiti, ó parí sí Òkun. Èyí ni ààlà wọn ní ìhà gúúsù.
5 O termo do oriente é o mar Salgado até o fim do Jordão. E o termo da parte do norte, desde a baía do mar, desde o fim do Jordão:
Ààlà wọn ní ìhà ìlà-oòrùn ní Òkun Iyọ̀ títí dé ẹnu Jordani. Ààlà àríwá bẹ̀rẹ̀ láti etí òkun ní ẹnu Jordani,
6 E sobe este termo por Bete-Hogla, e passa do norte a Bete-Arabá, e daqui sobe este termo à pedra de Boã, filho de Rúben.
ààlà náà sì tún dé Beti-Hogla, ó sì lọ sí ìhà àríwá Beti-Araba. Ààlà náà sì tún dé ibi Òkúta Bohani ti ọmọ Reubeni.
7 E torna a subir este termo a Debir desde o vale de Acor: e ao norte olha sobre Gilgal, que está diante da subida de Adumim, a qual está ao sul do ribeiro: e passa este termo às águas de En-Semes, e sai à fonte de Rogel:
Ààlà náà gòkè lọ títí dé Debiri láti àfonífojì Akori, ó sì yípadà sí àríwá Gilgali, èyí tí ń bẹ ní iwájú òkè Adummimu, tí ń bẹ ní ìhà gúúsù odò náà. Ó sì tẹ̀síwájú sí apá omi En-Ṣemeṣi, ó sì jáde sí En-Rogeli.
8 E sobe este termo pelo vale do filho de Hinom ao lado dos jebuseus ao sul: esta é Jerusalém. Logo sobe este termo pelo cume do monte que está diante do vale de Hinom até o ocidente, o qual está ao fim do vale dos gigantes ao norte;
Ààlà náà sì tún gòkè lọ sí àfonífojì Beni-Hinnomu ní ìhà gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ gúúsù ti Jebusi (tí í ṣe Jerusalẹmu). Ó sì gòkè lọ sí orí òkè tí ó wà lórí àfonífojì Hinnomu tí ń bẹ ní ìpẹ̀kun àfonífojì Refaimu ní ìhà àríwá.
9 E rodeia este termo desde o cume do monte até a fonte das águas de Neftoa, e sai às cidades do monte de Efrom, rodeando logo o mesmo termo a Baalá, a qual é Quriate-Jearim.
Ààlà náà sì lọ láti orí òkè lọ sí ìsun omi Nefitoa, ó sì jáde sí ìlú òkè Efroni, ó sì lọ sí apá ìsàlẹ̀ Baalahi (tí í ṣe, Kiriati-Jearimu).
10 Depois torna este termo desde Baalá até o ocidente ao monte de Seir: e passa ao lado do monte de Jearim até o norte, esta é Quesalom, e desce a Bete-Semes, e passa a Timna.
Ààlà tí ó yípo láti Baalahi lọ sí ìhà ìwọ̀-oòrùn sí òkè Seiri, ó sì lọ sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ àríwá òkè Jearimu (tí í ṣe, Kesaloni), ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí Beti-Ṣemeṣi, ó sì kọjá lọ sí Timna.
11 Sai logo este termo ao lado de Ecrom até o norte; e rodeia o mesmo termo a Sicrom, e passa pelo monte de Baalá, e sai a Jabneel: e sai este termo ao mar.
Ààlà náà sì lọ sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ àríwá òkè Ekroni, ó sì yípadà lọ sí Ṣikkeroni, ó sì yípadà lọ sí òkè Baalahi, ó sì dé Jabneeli, ààlà náà sì parí sí Òkun.
12 O termo do ocidente é o mar grande. Este, pois, é o termo dos filhos de Judá em derredor, por suas famílias.
Ààlà ìwọ̀-oòrùn sì jẹ́ agbègbè Òkun Ńlá. Ìwọ̀nyí ni ààlà àyíká ènìyàn Juda ní agbo ilé wọn.
13 Mas a Calebe, filho de Jefoné, deu parte entre os filhos de Judá, conforme o mandamento do SENHOR a Josué: isto é, a Quiriate-Arba, do pai de Anaque, que é Hebrom.
Gẹ́gẹ́ bí àṣẹ tí Olúwa pa fún Joṣua, ó fi ìpín fún Kalebu ọmọ Jefunne, ìpín ní Juda—Kiriati-Arba, tí í ṣe Hebroni. (Arba sì ní baba ńlá Anaki.)
14 E Calebe expulsou dali três filhos de Anaque, a Sesai, Aimã, e Talmai, filhos de Anaque.
Kalebu sì lé àwọn ọmọ Anaki mẹ́ta jáde láti Hebroni; Ṣeṣai, Ahimani, àti Talmai, ìran Anaki.
15 De aqui subiu aos que moravam em Debir: e o nome de Debir era antes Quiriate-Sefer.
Ó sì wọ́de ogun láti ibẹ̀ lọ bá àwọn ènìyàn tí ń gbé ní Debiri (tí à ń pè ní Kiriati-Seferi nígbà kan rí).
16 E disse Calebe: Ao que ferir a Quiriate-Sefer, e a tomar, eu lhe darei a minha filha Acsa por mulher.
Kalebu sì wí pé, “Èmi yóò fi ọmọbìnrin mi Aksa fún ọkùnrin tí ó bá kọlu Kiriati-Seferi, tí ó sì gbà á ní ìgbéyàwó.”
17 E tomou-a Otniel, filho de Quenaz, irmão de Calebe; e ele lhe deu por mulher a sua filha Acsa.
Otnieli ọmọ Kenasi, arákùnrin Kalebu, sì gbà á, báyìí ni Kalebu sì fi ọmọbìnrin rẹ̀ Aksa fún un ní ìyàwó.
18 E aconteceu que quando a levava, ele a persuadiu que pedisse a seu pai terras para lavrar. Ela então desceu do asno. E Calebe lhe disse: Que tens?
Ní ọjọ́ kan, nígbà tí Aksa lọ sí ọ̀dọ̀ Otnieli, ó rọ̀ ọ́ kí ó béèrè ilẹ̀ oko lọ́wọ́ baba rẹ̀. Nígbà náà ni Aksa sọ̀kalẹ̀ ní orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀, Kalebu sì béèrè pé, “Kí ni kí èmi ṣe fún ọ?”
19 E ela respondeu: Dá-me bênção; pois me deste terra de secura, dá-me também fontes de águas. Ele então lhe deu as fontes de acima, e as de abaixo.
Ó sì dáhùn pé, “Mo ń fẹ́ kí o ṣe ojúrere kan fún mi, nígbà ti o ti fún mi ní ilẹ̀ ní gúúsù, fún mi ní ìsun omi náà pẹ̀lú.” Kalebu sì fún un ní ìsun òkè àti ìsun ìsàlẹ̀.
20 Esta, pois é a herança das tribos dos filhos de Judá por suas famílias.
Èyí ni ilẹ̀ ìní ẹ̀yà àwọn ọmọ Juda gẹ́gẹ́ bi ìdílé wọn.
21 E foram as cidades do termo da tribo dos filhos de Judá até o termo de Edom ao sul: Cabzeel, e Éder, e Jagur,
Ìlú ìpẹ̀kun gúúsù ti ẹ̀yà Juda ní gúúsù ní ààlà Edomu nìwọ̀nyí: Kabṣeeli, Ederi, Jaguri,
22 E Quiná, e Dimona, e Adada,
Kina, Dimona, Adada,
23 E Quedes, e Hazor, e Itnã,
Kedeṣi, Hasori, Itina,
24 Zife, e Telém, Bealote,
Sifi, Telemu, Bealoti,
25 E Hazor-Hadata, e Queriote-Hezrom, que é Hazor,
Hasori Hadatta, Kerioti Hesroni (tí í ṣe Hasori),
26 Amã, e Sema, e Moladá,
Amamu, Ṣema, Molada,
27 E Hazar-Gada, e Hesmom, e Bete-Pelete,
Hasari Gada, Heṣmoni, Beti-Peleti,
28 E Hazar-Sual, Berseba, e Biziotiá,
Hasari-Ṣuali, Beerṣeba, Bisiotia,
29 Baalá, e Iim, e Azém,
Baalahi, Limu, Esemu,
30 E Eltolade, e Quesil, e Hormá,
Eltoladi, Kesili, Horma,
31 E Ziclague, e Madmana, Sansana,
Siklagi, Madmana, Sansanna,
32 E Lebaote, Silim, e Aim, e Rimom; em todas vinte e nove cidades com suas aldeias.
Leboati, Ṣilhimu, Aini àti Rimoni, àpapọ̀ ìlú mọ́kàndínlọ́gbọ̀n àti àwọn ìletò wọn.
33 Nas planícies, Estaol, e Zorá, e Asná,
Ní ìhà ìwọ̀-oòrùn ẹsẹ̀ òkè: Eṣtaoli, Sora, Aṣna,
34 E Zanoa, e En-Ganim, Tapua, e Enã,
Sanoa, Eni-Gannimu, Tapua, Enamu,
35 Jeremote, e Adulão, Socó, e Azeca,
Jarmatu, Adullamu, Soko, Aseka,
36 E Saaraim, e Aditaim, e Gederá, e Gederotaim; catorze cidades com suas aldeias.
Ṣaaraimu, Adittaimu àti Gedera (tàbí Gederotaimu). Ìlú mẹ́rìnlá àti àwọn ìletò wọn.
37 Zenã, e Hadasa, e Migdal-Gade,
Senani, Hadaṣa, Migdali Gadi,
38 E Dileã, e Mispá, e Jocteel,
Dileani, Mispa, Jokteeli,
39 Laquis, e Bozcate, e Eglom,
Lakiṣi, Boskati, Egloni,
40 E Cabom, e Laamás, e Quitilis,
Kabboni, Lamasi, Kitlisi,
41 E Gederote, Bete-Dagom, e Naamá, e Maquedá; dezesseis cidades com suas aldeias.
Gederoti, Beti-Dagoni, Naama àti Makkeda, ìlú mẹ́rìndínlógún àti ìletò wọn.
42 Libna, e Eter, e Asã,
Libina, Eteri, Aṣani,
43 E Iftá, e Asná, e Nezibe,
Hifita, Aṣna, Nesibu,
44 E Queila, e Aczibe, e Maressa; nove cidades com suas aldeias.
Keila, Aksibu àti Meraṣa: ìlú mẹ́sàn-án àti àwọn ìletò wọn.
45 Ecrom com suas vilas e suas aldeias:
Ekroni, pẹ̀lú ibùgbé àti àwọn ìletò rẹ̀ tó yí i ká,
46 Desde Ecrom até o mar, todas as que estão à costa de Asdode com suas aldeias.
ìwọ̀-oòrùn Ekroni, gbogbo èyí tí ń bẹ nítòsí Aṣdodu, pẹ̀lú àwọn ìletò wọn,
47 Asdode com suas vilas e suas aldeias: Gaza com suas vilas e suas aldeias até o rio do Egito, e o grande mar com seus termos.
Aṣdodu, agbègbè ìlú rẹ̀ àti ìletò; àti Gasa, ìlú rẹ̀ àti ìletò, títí ó fi dé odò Ejibiti àti agbègbè Òkun Ńlá.
48 E nas montanhas, Samir, e Jatir, e Sucote,
Ní ilẹ̀ òkè náà: Ṣamiri, Jattiri, Soko,
49 E Dana, e Quiriate-Saná, que é Debir,
Dannah, Kiriati-Sannnah (tí í ṣe Debiri),
50 E Anabe, e Estemo, e Anim,
Anabu, Eṣitemo, Animu,
51 E Gósen, e Holom, e Gilo; onze cidades com suas aldeias.
Goṣeni, Holoni àti Giloni, ìlú mọ́kànlá àti ìletò wọn.
52 Arabe, e Dumá, e Esã,
Arabu, Duma, Eṣani,
53 E Janim, e Bete-Tapua, e Afeca,
Janimu, Beti-Tapua, Afeka,
54 E Hunta, e Quiriate-Arba, que é Hebrom, e Zior; nove cidades com suas aldeias.
Hamuta, Kiriati-Arba (tí í ṣe, Hebroni) àti Ṣiori: ìlú mẹ́sàn-án àti àwọn ìletò rẹ̀
55 Maom, Carmelo, e Zife, e Jutá,
Maoni, Karmeli, Sifi, Jutta,
56 E Jezreel, Jocdeão, e Zanoa,
Jesreeli, Jokdeamu, Sanoa,
57 Caim, Gibeá, e Timna; dez cidades com suas aldeias.
Kaini, Gibeah àti Timna: ìlú mẹ́wàá àti àwọn ìletò wọn.
58 Halul, e Bete-Zur, e Gedor,
Halhuli, Beti-Suri, Gedori,
59 E Maarate, e Bete-Anote, e Eltecom; seis cidades com suas aldeias.
Maarati, Beti-Anoti àti Eltekoni: ìlú mẹ́fà àti àwọn ìletò wọn.
60 Quriate-Baal, que é Quriate-Jearim, e Rabá; duas cidades com suas aldeias.
Kiriati-Baali (tí í ṣe, Kiriati-Jearimu) àti Rabba ìlú méjì àti ìletò wọn.
61 No deserto, Bete-Arabá, Midim, e Secacá,
Ní aginjù: Beti-Araba, Middini, Sekaka,
62 E Nibsã, e a cidade do sal, e En-Gedi; seis cidades com suas aldeias.
Nibṣani, Ìlú Iyọ̀ àti En-Gedi: ìlú mẹ́fà àti ìletò wọn.
63 Mas aos jebuseus que habitavam em Jerusalém, os filhos de Judá não os puderam desarraigar; antes restaram os jebuseus em Jerusalém com os filhos de Judá, até hoje.
Juda kò lè lé àwọn ọmọ Jebusi jáde, tí wọ́n ń gbé ní Jerusalẹmu. Àwọn ará Jebusi sì ń gbé pẹ̀lú àwọn ènìyàn Juda títí dí òní.

< Josué 15 >