< 8 >

1 Então Bildade, o suíta, respondeu, dizendo:
Ìgbà náà ni Bilidadi, ará Ṣuhi, sì dáhùn wí pé,
2 Até quando falarás tais coisas, e as palavras de tua boca serão como um vento impetuoso?
“Ìwọ yóò ti máa sọ nǹkan wọ̀nyí pẹ́ tó? Tí ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ yóò sì máa bí ẹ̀fúùfù ńlá?
3 Por acaso Deus perverteria o direito, ou o Todo-Poderoso perverteria a justiça?
Ọlọ́run a ha máa yí ìdájọ́ po bí? Tàbí Olódùmarè a máa gbé ẹ̀bi fún aláre?
4 Se teus filhos pecaram contra ele, ele também os entregou ao castigo por sua transgressão.
Nígbà tí àwọn ọmọ rẹ̀ ṣẹ̀ sí i, ó sì gbá wọn kúrò nítorí ìrékọjá wọn.
5 Se tu buscares a Deus com empenho, e pedires misericórdia ao Todo-Poderoso;
Bí ìwọ bá sì ké pe Ọlọ́run ní àkókò, tí ìwọ sì gbàdúrà ẹ̀bẹ̀ sí Olódùmarè.
6 Se fores puro e correto, certamente logo ele se levantará em teu favor, e restaurará a morada de tua justiça.
Ìwọ ìbá jẹ́ mímọ, kí ó sì dúró ṣinṣin: ǹjẹ́ nítòótọ́ nísinsin yìí òun yóò tají fún ọ, òun a sì sọ ibùjókòó òdodo rẹ di púpọ̀.
7 Ainda que teu princípio seja pequeno, o teu fim será muito grandioso.
Ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ ìbá tilẹ̀ kéré si í, bẹ́ẹ̀ ìgbẹ̀yìn rẹ ìbá pọ̀ sí i gidigidi.
8 Pois pergunta agora à geração passada, e considera o que seus pais descobriram.
“Èmi bẹ̀ ọ́ ǹjẹ́, béèrè lọ́wọ́ àwọn ará ìgbà nì kí o sì kíyèsi ìwádìí àwọn baba wọn.
9 Pois nós somos de ontem e nada sabemos, pois nossos dias sobre a terra são como a sombra.
Nítorí pé ọmọ-àná ni àwa, a kò sì mọ nǹkan, nítorí pé òjìji ni ọjọ́ wa ni ayé.
10 Por acaso eles não te ensinarão, e te dirão, e falarão palavras de seu coração?
Àwọn kì yóò wa kọ ọ́, wọn kì yóò sì sọ fún ọ? Wọn kì yóò sì sọ̀rọ̀ láti inú òye wọn jáde wá?
11 Pode o papiro crescer sem lodo? Ou pode o junco ficar maior sem água?
Papirusi ha lè dàgbà láìní ẹrẹ̀ tàbí eèsún ha lè dàgbà láìlómi?
12 Estando ele ainda verde, sem ter sido cortado, ainda assim se seca antes de toda erva.
Nígbà tí ó wà ní tútù, tí a kò ké e lulẹ̀, ó rọ dànù, ewéko gbogbo mìíràn hù dípò rẹ̀.
13 Assim são os caminhos de todos os que esquecem de Deus; e a esperança do corrupto perecerá;
Bẹ́ẹ̀ ni ipa ọ̀nà gbogbo àwọn tí ó gbàgbé Ọlọ́run, bẹ́ẹ̀ ni ìrètí àwọn àgàbàgebè yóò di òfo.
14 Sua esperança será frustrada, e sua confiança será como a teia de aranha.
Àbá ẹni tí a ó kèé kúrò, àti ìgbẹ́kẹ̀lé ẹni tí ó dàbí ilé aláǹtakùn.
15 Ele se apoiará em sua casa, mas ela não ficará firme; ele se apegará a ela, mas ela não ficará de pé.
Yóò fi ara ti ilé rẹ̀, ṣùgbọ́n kì yóò lè dúró, yóò fi di ara rẹ̀ mú ṣinṣin ṣùgbọ́n kì yóò lè dúró pẹ́.
16 Ele está bem regado diante do sol, e seus ramos brotam por cima de sua horta;
Ó tutù bí irúgbìn tí a bomirin níwájú oòrùn, ẹ̀ka rẹ̀ sì yọ jáde nínú ọgbà rẹ̀.
17 Suas raízes se entrelaçam junto à fonte, olhando para o pedregal.
Gbòǹgbò rẹ̀ ta yí ebè ká, ó sì wó ibi òkúta wọ̀n-ọn-nì.
18 Se lhe arrancarem de seu lugar, este o negará, [dizendo]: Nunca te vi.
Bí ó bá sì pa á run kúrò ní ipò rẹ̀, nígbà náà ni ipò náà yóò sọ, ‘Èmi kò ri ọ rí!’
19 Eis que este é o prazer de seu caminho; e do solo outros brotarão.
Kíyèsi i, ayé rẹ̀ gbẹ dànù àti láti inú ilẹ̀ ní irúgbìn òmíràn yóò hù jáde wá.
20 Eis que Deus não rejeita ao íntegro, nem segura pela mão aos malfeitores.
“Kíyèsi i, Ọlọ́run kì yóò ta ẹni òtítọ́ nù, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò ran oníwà búburú lọ́wọ́
21 Ainda ele encherá tua boca de riso, e teus lábios de júbilo.
títí yóò fi fi ẹ̀rín kún ọ ní ẹnu, àti ètè rẹ pẹ̀lú ìhó ayọ̀,
22 Os que te odeiam se vestirão de vergonha, e nunca mais haverá tenda de perversos.
ìtìjú ní a o fi bo àwọn tí ó kórìíra rẹ̀, àti ibùjókòó ènìyàn búburú kì yóò sí mọ́.”

< 8 >