< Salmos 148 >

1 Louvai ao Senhor. louvai ao Senhor desde os céus, louvai-o nas alturas.
Ẹ fi ìyìn fún Olúwa. Ẹ fi ìyìn fún Olúwa láti ọ̀run wá, ẹ fi ìyìn fún un níbi gíga.
2 Louvai-o, todos os seus anjos; louvai-o todos os seus exércitos.
Ẹ fi ìyìn fún un, gbogbo ẹ̀yin angẹli rẹ̀, ẹ fi ìyìn fún un, gbogbo ẹ̀yin ọmọ-ogun rẹ̀.
3 Louvai-o, sol e lua; louvai-o, todas as estrelas luzentes.
Ẹ fi ìyìn fún un, oòrùn àti òṣùpá. Ẹ fi ìyìn fún un, gbogbo ẹ̀yin ìràwọ̀ ìmọ́lẹ̀.
4 Louvai-o, céus dos céus, e as águas que estão sobre os céus.
Ẹ fi ìyìn fún un, ẹ̀yin ọ̀run àti àwọn ọ̀run gíga àti ẹ̀yin omi tí ń bẹ ní òkè ọ̀run.
5 Louvem o nome do Senhor, pois mandou, e logo foram criados.
Ẹ jẹ́ kí wọn kí ó yin orúkọ Olúwa nítorí ó pàṣẹ a sì dá wọn
6 E os confirmou para sempre, e lhes deu uma lei que não ultrapassarão.
Ó fi ìdí wọn múlẹ̀ láé àti láéláé ó sì ti ṣe ìlànà kan tí kì yóò já.
7 Louvai ao Senhor desde a terra: vós, baleias, e todos os abismos,
Ẹ yin Olúwa láti ilẹ̀ ayé wá ẹ̀yin ẹ̀dá inú òkun títóbi àti ẹ̀yin ibú òkun,
8 Fogo e saraiva, neve e vapores, e vento tempestuoso que executa a sua palavra:
mọ̀nàmọ́ná àti òjò yìnyín ìdí omi àti àwọn ìkùùkuu, ìjì líle tí ń mú ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣẹ,
9 Montes e todos os outeiros, árvores frutiferas e todos os cedros:
òkè ńlá àti gbogbo òkè kéékèèké, igi eléso àti gbogbo igi kedari,
10 As feras e todos os gados, réptis e aves voadoras:
àwọn ẹranko ńlá àti ẹran ọ̀sìn gbogbo ohun afàyàfà àti àwọn ẹyẹ abìyẹ́,
11 Reis da terra e todos os povos, príncipes e todos os juízes da terra:
àwọn ọba ayé àti ènìyàn ayé gbogbo àwọn ọmọ-aládé àti gbogbo àwọn onídàájọ́ ayé,
12 Mancebos e donzelas, velhos e crianças,
ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin àwọn arúgbó àti àwọn ọmọdé.
13 Louvem o nome do Senhor, pois só o seu nome é exaltado: a sua glória está sobre a terra e o céu.
Ẹ jẹ́ kí wọn kí ó yin orúkọ Olúwa nítorí orúkọ rẹ̀ nìkan ni ó ní ọlá ògo rẹ̀ kọjá ayé àti ọ̀run
14 Ele também exalta o poder do seu povo, o louvor de todos os seus santos, dos filhos de Israel, um povo que lhe é chegado. louvai ao Senhor.
Ó sì gbé ìwo kan sókè fún àwọn ènìyàn rẹ̀, ìyìn fún gbogbo ènìyàn mímọ́ rẹ̀ àní fún àwọn ọmọ Israẹli, àwọn ènìyàn tí ó súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ̀. Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.

< Salmos 148 >