< Salmos 132 >

1 Lembra-te, Senhor, de David, e de todas as suas aflições.
Orin fún ìgòkè. Olúwa, rántí Dafidi nínú gbogbo ìpọ́njú rẹ̀.
2 Como jurou ao Senhor, e fez votos ao poderoso de Jacob, dizendo:
Ẹni tí ó ti búra fún Olúwa, tí ó sì ṣe ìlérí fún alágbára Jakọbu pé.
3 Certamente que não entrarei na tenda de minha casa, nem subirei ao leito da minha cama.
Nítòótọ́, èmi kì yóò wọ inú àgọ́ ilé mi lọ, bẹ́ẹ̀ èmi kì yóò gun orí àkéte mi.
4 Não darei sono aos meus olhos, nem adormecimento às minhas pestanas,
Èmi kì yóò fi oorun fún ojú mi, tàbí òògbé fún ìpéǹpéjú mi,
5 Enquanto não achar lugar para o Senhor, uma morada para o Poderoso de Jacob.
títí èmi ó fi rí ibi fún Olúwa, ibùjókòó fún alágbára Jakọbu.
6 Eis que ouvimos falar dela em Ephrata, e a achamos no campo do bosque.
Kíyèsi i, àwa gbúròó rẹ̀ ni Efrata: àwa rí i nínú oko ẹgàn náà.
7 Entraremos nos seus tabernáculos: prostrar-nos-emos ante o escabelo de seus pés.
Àwa ó lọ sínú àgọ́ rẹ̀: àwa ó máa sìn níbi àpótí ìtìsẹ̀ rẹ̀
8 Levanta-te, Senhor, no teu repouso, tu e a arca da tua força.
Olúwa, dìde sí ibi ìsinmi rẹ: ìwọ, àti àpótí agbára rẹ.
9 Vistam-se os teus sacerdotes de justiça, e alegrem-se os teus santos.
Kí a fi òdodo wọ àwọn àlùfáà rẹ: kí àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ kí ó máa hó fún ayọ̀.
10 Por amor de David, teu servo, não faças virar o rosto do teu ungido.
Nítorí tí Dafidi ìránṣẹ́ rẹ̀, má ṣe yí ojú ẹni òróró rẹ padà.
11 O Senhor jurou na verdade a David: não se apartará dela: Do fruto do teu ventre porei sobre o teu trono.
Olúwa ti búra nítòótọ́ fún Dafidi, Òun kì yóò yípadà kúrò nínú rẹ̀, nínú irú-ọmọ inú rẹ ni èmi ó gbé kalẹ̀ sí orí ìtẹ́ rẹ.
12 Se os teus filhos guardarem o meu concerto, e os meus testemunhos, que eu lhes hei de ensinar, também os seus filhos se assentarão perpetuamente no teu trono.
Bí àwọn ọmọ rẹ̀ yóò bá pa májẹ̀mú mi mọ́ àti ẹ̀rí mi tí èmi yóò kọ́ wọn, àwọn ọmọ wọn pẹ̀lú yóò jókòó lórí ìtẹ́ rẹ láéláé.
13 Porque o Senhor elegeu a Sião; desejou-a para a sua habitação, dizendo:
Nítorí tí Olúwa ti yan Sioni: ó ti fẹ́ ẹ fún ibùjókòó rẹ̀.
14 Este é o meu repouso para sempre: aqui habitarei, pois o desejei.
Èyí ni ibi ìsinmi mi láéláé: níhìn-ín ni èmi yóò máa gbé: nítorí tí mo fẹ́ ẹ.
15 Abençoarei abundantemente o seu mantimento; fartarei de pão os seus necessitados.
Èmi yóò bùkún oúnjẹ rẹ̀ púpọ̀púpọ̀: èmi yóò fi oúnjẹ tẹ́ àwọn tálákà rẹ̀ lọ́rùn.
16 Vestirei os seus sacerdotes de salvação, e os seus santos saltarão de prazer.
Èmi yóò sì fi ìgbàlà wọ àwọn àlùfáà rẹ̀: àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀ yóò máa hó fún ayọ̀.
17 Ali farei brotar a força de David: preparei uma lâmpada para o meu ungido.
Níbẹ̀ ni èmi yóò gbé mú ìwo Dafidi yọ̀, èmi ti ṣe ìlànà fìtílà kan fún ẹni òróró mi.
18 Vestirei os seus inimigos de confusão; mas sobre ele florescerá a sua coroa.
Àwọn ọ̀tá rẹ̀ ni èmi yóò fi ìtìjú wọ̀: ṣùgbọ́n lára òun tìkára rẹ̀ ni adé yóò máa gbilẹ̀.

< Salmos 132 >