< Lamentações de Jeremias 5 >

1 Lembra-te, Senhor, do que nos tem sucedido: considera, e olha o nosso opróbrio.
Rántí, Olúwa, ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí wa; wò ó, kí o sì rí ìtìjú wa.
2 A nossa herdade passou a estranhos, e as nossas casas a forasteiros.
Àwọn ohun ìní wa ti di ti àlejò, ilé wa ti di ti àjèjì.
3 órfãos somos sem pai, nossas mães são como viúvas.
Àwa ti di aláìní òbí àti aláìní baba, àwọn ìyá wa ti di opó.
4 A nossa água por dinheiro a bebemos, por preço vem a nossa lenha.
A gbọdọ̀ ra omi tí à ń mu; igi wa di títà fún wa.
5 Padecemos perseguição sobre os nossos pescoços: estamos cançados, e nós não temos descanço.
Àwọn tí ó ń lé wa súnmọ́ wa; àárẹ̀ mú wa àwa kò sì rí ìsinmi.
6 Aos egípcios estendemos as mãos, e aos siros, para nos fartarem de pão.
Àwa jọ̀wọ́ ara wa fún Ejibiti àti Asiria láti rí oúnjẹ tó tó jẹ.
7 Nossos pais pecaram, e já não são: nós levamos as suas maldades.
Àwọn baba wa ti ṣẹ̀, wọn kò sì ṣí mọ́, àwa sì ń ru ìjìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
8 Servos dominam sobre nós; ninguém há que nos arranque da sua mão.
Àwọn ẹrú ń jẹ ọba lórí wa, kò sì ṣí ẹni tí yóò gbà wá lọ́wọ́ wọn.
9 Com perigo de nossas vidas trazemos o nosso pão, por causa da espada do deserto.
Àwa ń rí oúnjẹ wa nínú ewu ẹ̀mí wa nítorí idà tí ó wà ní aginjù.
10 Nossa pele se enegreceu como um forno, por causa do ardor da fome.
Ẹran-ara wa gbóná bí ààrò, ebi sì yó wa bí àárẹ̀.
11 Forçaram as mulheres em Sião, as virgens nas cidades de Judá.
Wọ́n ti fipá bá àwọn obìnrin wa lòpọ̀ ní Sioni, àti àwọn wúńdíá ti o wa ní ìlú Juda.
12 Os príncipes foram enforcados pelas mãos; as faces dos velhos não foram reverenciadas.
Àwọn ọmọ ọbakùnrin ti di síso sókè ní ọwọ́ wọn; kò sí ìbọ̀wọ̀ fún àgbàgbà mọ́.
13 Aos mancebos tomaram para moer, e os moços tropeçaram debaixo da lenha.
Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wa ru òkúta; àwọn ọmọkùnrin sì ń ṣàárẹ̀ lábẹ́ ẹrù igi.
14 Os velhos cessaram de se assentarem à porta, os mancebos de sua canção.
Àwọn àgbàgbà ti lọ kúrò ní ẹnu-bodè ìlú; àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin sì dákẹ́ orin wọn.
15 Cessou o gozo de nosso coração, converteu-se em lamentação a nossa dança.
Ayọ̀ ti ṣáko ní ọkàn wa; ọ̀fọ̀ sì ti dúró bí ijó fún wa.
16 Já caiu a coroa da nossa cabeça; ai agora de nós, porque pecamos.
Adé ti ṣí kúrò ní orí wa ègbé ni fún wa, nítorí a ti ṣẹ̀.
17 Portanto desmaiou o nosso coração, por isto se escureceram os nossos olhos.
Nítorí èyí, àárẹ̀ mú ọkàn wa, nítorí èyí, ojú wa sì ṣú.
18 Pelo monte de Sião, que está assolado, as raposas andam por ele.
Fún òkè Sioni tí ó ti di ahoro lórí rẹ̀ àwọn kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ sì ń rìn kiri.
19 Tu, Senhor, permaneces eternamente, e o teu trono de geração em geração.
Ìwọ, Olúwa, jẹ ọba títí láé; ìjọba rẹ dúró láti ìran kan dé ìran mìíràn.
20 Porque te esquecerias de nós para sempre? porque nos desampararias tanto tempo?
Kí ló dé tí o ń gbàgbé wa ní gbogbo ìgbà? Kí ló dé tí o fi kọ̀ wá sílẹ̀ fún ọjọ́ pípẹ́?
21 Converte-nos, Senhor, a ti, e nos converteremos: renova os nossos dias como de antes.
Mú wa padà sí ọ̀dọ̀ rẹ, Olúwa, kí àwa kí ó le padà; mú ọjọ́ wa di tuntun bí ìgbàanì,
22 Porque nos rejeitarias totalmente? te enfurecerias contra nós em tão grande maneira?
àyàfi tí o bá ti kọ̀ wá sílẹ̀ pátápátá tí ìbínú rẹ sí wa sì kọjá ìwọ̀n.

< Lamentações de Jeremias 5 >