< Lamentações de Jeremias 3 >
1 Eu sou aquele homem que viu a aflição pela vara do seu furor.
Èmi ni ọkùnrin tí ó rí ìpọ́njú pẹ̀lú ọ̀pá ìbínú rẹ.
2 A mim me guiou e levou às trevas e não à luz.
Ó ti lé mi jáde ó sì mú mi rìn nínú òkùnkùn ju ti ìmọ́lẹ̀.
3 Deveras se tornou contra mim e virou a sua mão todo o dia.
Nítòótọ́, ó ti yí ọwọ́ rẹ̀ padà sí mi síwájú àti síwájú sí i ní gbogbo ọjọ́.
4 Fez envelhecer a minha carne e a minha pele, quebrantou os meus ossos.
Ó jẹ́ kí àwọ̀ mi àti ẹran-ara mi gbó ó sì tún ṣẹ́ egungun mi.
5 Edificou contra mim, e me cercou de fel e trabalho.
Ó ti fi mí sí ìgbèkùn, ó sì ti yí mi ká pẹ̀lú ìkorò àti làálàá.
6 Assentou-me em lugares tenebrosos, como os que estavam mortos há muito.
Ó mú mi gbé nínú òkùnkùn, bí ti àwọn tó ti kú fún ìgbà pípẹ́.
7 Cercou-me de sebe, e não posso sair: agravou os meus grilhões.
Ó ti tì mí mọ́ ilé, nítorí náà n kò le è sálọ; ó ti fi ẹ̀wọ̀n mú mi mọ́lẹ̀.
8 Ainda quando clamo e grito, ele exclui a minha oração.
Pàápàá nígbà tí mo ké fún ìrànlọ́wọ́, ó kọ àdúrà mi.
9 Cercou de sebe os meus caminhos com pedras lavradas, divertiu as minhas veredas.
Ó fi ògiri òkúta dí ọ̀nà mi; ó sì mú ọ̀nà mi wọ́.
10 Fez-se-me como urso de emboscada, um leão em esconderijos.
Bí i beari tí ó dùbúlẹ̀, bí i kìnnìún tí ó sá pamọ́.
11 Desviou os meus caminhos, e fêz-me em pedaços; deixou-me assolado.
Ó wọ́ mi kúrò ní ọ̀nà, ó tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ ó fi mi sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́.
12 Armou o seu arco, e me pôs como alvo à flecha.
Ó fa ọfà rẹ̀ yọ ó sì fi mí ṣe ohun ìtafàsí.
13 Faz entrar nos meus rins as flechas da sua aljava.
Ó fa ọkàn mí ya pẹ̀lú ọfà nínú àkọ̀ rẹ̀.
14 Fui feito um objeto de escarneio a todo o meu povo, de canção sua todo o dia.
Mo di ẹni yẹ̀yẹ́ láàrín àwọn ènìyàn mi; wọn yẹ̀yẹ́ mi pẹ̀lú orin ní gbogbo ọjọ́.
15 Fartou-me de amarguras, embriagou-me de absinto.
Ó ti kún mi pẹ̀lú ewé kíkorò àti ìdààmú bí omi.
16 Quebrou com pedrinhas de areia os meus dentes; abaixou-me na cinza.
Ó ti fi òkúta kán eyín mi; ó ti tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ nínú eruku.
17 E afastaste da paz a minha alma; esqueci-me do bem.
Mo ti jìnnà sí àlàáfíà; mo ti gbàgbé ohun tí àṣeyege ń ṣe.
18 Então disse eu: Já pereceu a minha força, como também a minha esperança no Senhor.
Nítorí náà mo wí pé, “Ògo mi ti lọ àti ìrètí mi nínú Olúwa.”
19 Lembra-te da minha aflição e do meu pranto, do absinto e do fel.
Mo ṣe ìrántí ìpọ́njú àti ìdààmú mi, ìkorò àti ìbànújẹ́.
20 Minha alma certamente disto se lembra, e se abate em mim.
Mo ṣèrántí wọn, ọkàn mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
21 Disto me recordarei no meu coração; por isso esperarei.
Síbẹ̀, èyí ni mo ní ní ọkàn àti nítorí náà ní mo nírètí.
22 As misericórdias do Senhor são a causa de não sermos consumidos; porque as suas misericórdias não tem fim.
Nítorí ìfẹ́ Olúwa tí ó lágbára ni àwa kò fi ṣègbé, nítorí ti àánú rẹ kì í kùnà.
23 Novas são cada manhã; grande é a tua fidelidade.
Wọ́n jẹ́ ọ̀tún ní àárọ̀; títóbi ni òdodo rẹ̀.
24 A minha porção é o Senhor, diz a minha alma; portanto esperarei nele.
Mo wí fún ara mi, ìpín mi ni Olúwa; nítorí náà èmi yóò dúró dè ọ́.
25 Bom é o Senhor para os que se atêm a ele, para a alma que o busca.
Dídára ni Olúwa fún àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ̀, sí àwọn tí ó ń wá a.
26 Bom é esperar, e aguardar em silêncio a salvação do Senhor.
Ó dára kí a ní sùúrù fún ìgbàlà Olúwa.
27 Bom é para o homem levar o jugo na sua mocidade.
Ó dára fún ènìyàn láti gbé àjàgà nígbà tí ó wà ní èwe.
28 Assentar-se-á solitário, e ficará em silêncio; porquanto Deus o pôs sobre ele.
Jẹ́ kí ó jókòó ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́, nítorí Olúwa ti fi fún un.
29 Ponha a sua boca no pó, dizendo: Porventura haverá esperança.
Jẹ́ kí ó bo ojú rẹ̀ sínú eruku— ìrètí sì lè wà.
30 Dê a sua face ao que o fere; farte-se de afronta.
Jẹ́ kí ó fi ẹ̀rẹ̀kẹ́ fún àwọn tí yóò gbá a, sì jẹ́ kí ó wà ní ìdójútì.
31 Porque o Senhor não rejeitará para sempre.
Ènìyàn kò di ìtanù lọ́dọ̀ Olúwa títí láé.
32 Antes, se entristeceu a alguém, compadecer-se-á dele, segundo a grandeza das suas misericórdias.
Lóòtítọ́ ó mú ìbànújẹ́ wá, yóò fi àánú hàn, nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ̀.
33 Porque não aflige nem entristece aos filhos dos homens do seu coração.
Nítorí kò mọ̀ ọ́n mọ̀ mú ìpọ́njú wá tàbí ìrora wá fún ọmọ ènìyàn.
34 Para atropelar debaixo dos seus pés a todos os presos da terra.
Láti tẹ mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀ gbogbo àwọn ẹlẹ́wọ̀n ní ilẹ̀ náà.
35 Para perverter o direito do homem perante a face do altíssimo.
Láti ṣẹ́ ọmọ ènìyàn fún ẹ̀tọ́ rẹ̀ níwájú Ọ̀gá-ògo jùlọ,
36 Para subverter ao homem no seu pleito; porventura não o veria o Senhor?
láti yí ìdájọ́ ènìyàn padà, ǹjẹ́ Olúwa kò rí ohun bẹ́ẹ̀.
37 Quem é aquele que diz, e assim acontece, quando o Senhor o não mande?
Ta ni yóò sọ̀rọ̀ tí yóò rí bẹ́ẹ̀ tí Olúwa kò bá fi àṣẹ sí i.
38 Porventura da boca do altíssimo não sai o mal e o bem?
Ǹjẹ́ kì í ṣe láti ẹnu Ọ̀gá-ògo jùlọ ni rere àti búburú tí ń wá?
39 De que se queixa logo o homem vivente? queixe-se cada um dos seus pecados.
Kí ló dé tí ẹ̀dá alààyè ṣe ń kùn nígbà tí ó bá ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀?
40 Esquadrinhemos os nossos caminhos, e investiguemo-los, e voltemos para o Senhor.
Ẹ jẹ́ kí a yẹ ọ̀nà wa, kí a sì dán an wò, kí a sì tọ Olúwa lọ.
41 Levantemos os nossos corações com as mãos a Deus nos céus, dizendo:
Ẹ jẹ́ kí a gbé ọkàn àti ọwọ́ wa sókè sí Ọlọ́run ní ọ̀run, kí a wí pé,
42 Nós prevaricamos, e fomos rebeldes; por isso tu não perdoaste.
“Àwa ti ṣẹ̀ a sì ti ṣọ̀tẹ̀ ìwọ kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá.
43 Cobriste-nos da tua ira, e nos perseguiste; mataste, não perdoaste.
“Ìwọ fi ìbínú bo ara rẹ ìwọ sì ń lépa wa; ìwọ ń parun láìsí àánú.
44 Cobriste-te de nuvens, para que não passe a nossa oração.
Ìwọ ti fi àwọsánmọ̀ bo ara rẹ pé kí àdúrà wa má ba à dé ọ̀dọ̀ rẹ.
45 Por cisco e rejeitamento nos puseste no meio dos povos.
Ó ti sọ wá di èérí àti ààtàn láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
46 Todos os nossos inimigos abriram contra nós a sua boca.
“Gbogbo àwọn ọ̀tá wa ti la ẹnu wọn gbòòrò sí wa.
47 Temor e cova vieram sobre nós, assolação e quebrantamento.
Àwa ti jìyà àti ìparun, nínú ìbẹ̀rù àti ewu.”
48 Correntes de águas derramou o meu olho pelo quebrantamento da filha do meu povo.
Omijé ń sàn ní ojú mi bí odò nítorí a pa àwọn ènìyàn mi run.
49 O meu olho manou, e não cessa, porquanto não há descanço,
Ojú mi kò dá fún omijé, láì sinmi,
50 Até que atente e veja o Senhor desde os céus.
títí ìgbà tí Olúwa yóò síjú wolẹ̀ láti òkè ọ̀run tí yóò sì rí i.
51 O meu olho move a minha alma, por causa de todas as filhas da minha cidade.
Ohun tí mo rí mú ìbẹ̀rù wá ọkàn mi nítorí gbogbo àwọn obìnrin ìlú mi.
52 Como ave me caçaram os que são meus inimigos sem causa.
Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí dẹ mí bí ẹyẹ.
53 Arrancaram a minha vida na masmorra, e lançaram pedras sobre mim.
Wọ́n gbìyànjú láti mú òpin dé bá ayé mi nínú ihò wọ́n sì ju òkúta lù mí.
54 Derramaram-se as águas sobre a minha cabeça; eu disse: Estou cortado.
Orí mi kún fún omi, mo sì rò pé ìgbẹ̀yìn dé.
55 Invoquei o teu nome, Senhor, desde a mais profunda cova.
Mo pe orúkọ rẹ, Olúwa, láti ọ̀gbun ìsàlẹ̀ ihò.
56 Ouviste a minha voz; não escondas o teu ouvido ao meu suspiro, ao meu clamor.
Ìwọ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi, “Má ṣe di etí rẹ sí igbe ẹ̀bẹ̀ mi fún ìtura.”
57 Tu te chegaste no dia em que te invoquei; disseste: Não temas.
O wá tòsí nígbà tí mo ké pè ọ́, o sì wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù.”
58 Pleiteaste, Senhor, os pleitos da minha alma, remiste a minha vida.
Olúwa, ìwọ gba ẹjọ́ mi rò, o ra ẹ̀mí mi padà.
59 Viste, Senhor, a injustiça que me fizeram; julga a minha causa.
O ti rí i, Olúwa, búburú tí a ṣe sí mi. Gba ẹjọ́ mi ró!
60 Viste toda a sua vingança, todos os seus pensamentos contra mim.
Ìwọ ti rí ọ̀gbun ẹ̀san wọn, gbogbo ìmọ̀ wọn sí mi.
61 Ouviste o seu opróbrio, Senhor, todos os seus pensamentos contra mim,
Olúwa ìwọ ti gbọ́ ẹ̀gàn wọn àti ìmọ̀ búburú wọn sí mi,
62 Os ditos dos que se levantam contra mim e as suas imaginações contra mim todo o dia.
ohun tí àwọn ọ̀tá mi ń sọ sí mi ní gbogbo ọjọ́.
63 Observa-os a eles ao assentarem-se e ao levantarem-se; eu sou a sua canção.
Wò wọ́n! Ní jíjòkòó tàbí ní dídìde, wọ́n ń ṣẹlẹ́yà mi nínú orin wọn.
64 Rende-lhes recompensa, Senhor, conforme a obra das suas mãos.
Olúwa san wọ́n lẹ́san ohun tí ó tọ́ sí wọn fún ohun tí ọwọ́ wọn ti ṣe.
65 Dá-lhes ancia de coração, maldição tua sobre eles.
Fi ìbòjú bò wọ́n ní ọkàn, kí o sì fi wọ́n ré.
66 Na tua ira persegue-os, e desfa-los de debaixo dos céus do Senhor.
Ni wọ́n lára kí o sì pa wọ́n run pẹ̀lú ìbínú, lábẹ́ ọ̀run Olúwa.