< 1 Crônicas 24 >

1 E quanto aos filhos de Aarão, estes foram as suas divisões: os filhos de Aarão foram Nadab, e Abihu, e Eleazar e Ithamar.
Àwọn wọ̀nyí sì ni pínpín àwọn ọmọ Aaroni. Àwọn ọmọ Aaroni ni Nadabu, Abihu, Eleasari àti Itamari.
2 E morreram Nadab e Abihu antes de seu pai, e não tiveram filhos: e Eleazar e Ithamar administravam o sacerdócio.
Ṣùgbọ́n Nadabu àti Abihu kú kí ó tó di wí pé baba wọn kú, wọn kò sì ní àwọn ọmọ; bẹ́ẹ̀ ni Eleasari àti Itamari sì ṣe gẹ́gẹ́ bí àlùfáà.
3 E David os repartiu, como também a Zadok, dos filhos de Eleazar, e Ahimelech, dos filhos de Ithamar, segundo o seu ofício no seu ministério.
Pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ Sadoku ọmọ Eleasari àti Ahimeleki ọmọ Itamari, Dafidi sì yà wọ́n nípa nínú ìpín fún ìyàsọ́tọ̀ àwọn iṣẹ́ ìsìn wọn.
4 E achou-se que eram muitos mais os filhos de Eleazar entre os chefes de famílias do que os filhos de Ithamar, quando os repartiram: dos filhos de Eleazar dezeseis chefes das casas dos pais, mas dos filhos de Ithamar, segundo as casas de seus pais, oito.
A rí ọ̀pọ̀ àwọn olórí lára àwọn ọmọ Eleasari ju lára àwọn ọmọ Itamari lọ, wọ́n sì pín wọn lẹ́sẹ lẹ́sẹ: mẹ́rìndínlógún olórí láti ìdílé ọmọ Eleasari ìran wọn àti olórí méjọ ìdílé láti ara àwọn ọmọ Itamari.
5 E os repartiram por sortes, uns com os outros; porque houve maiorais do santuário e maiorais da casa de Deus, assim dentre os filhos de Eleazar, como dentre os filhos de Ithamar.
Wọ́n sì pín wọn láìṣègbè nípa yíya ìpín, nítorí àwọn olórí ibi mímọ́ àti àwọn olórí ilé Ọlọ́run wà láàrín àwọn ọmọ méjèèjì Eleasari àti Itamari.
6 E os registou Semaias, filho de Nathanael, o escrivão dentre os levitas, perante o rei, e os príncipes, e Zadok, o sacerdote, e Ahimelech, filho de Abiathar, e os chefes dos pais entre os sacerdotes, e entre os levitas: uma dentre as casas dos pais se tomou para Eleazar, e se tomou outra para Ithamar.
Ṣemaiah ọmọ Netaneli, akọ̀wé ọ̀kan lára àwọn ọmọ Lefi sì kọ orúkọ wọn níwájú ọba àti àwọn ìjòyè: Sadoku àlùfáà, Ahimeleki ọmọ Abiatari àti olórí ìdílé àwọn àlùfáà tí a mú láti ọ̀dọ̀ Eleasari àti ọ̀kan láti ọ̀dọ̀ Itamari.
7 E saiu a primeira sorte a Jojarib, a segunda a Jedaias,
Ìpín èkínní jáde sí Jehoiaribu, èkejì sí Jedaiah,
8 A terceira a Harim, a quarta a Seorim,
ẹlẹ́ẹ̀kẹta sì ni Harimu, ẹ̀kẹrin sì ní Seorimu,
9 A quinta a Malchias, a sexta a Mihamin.
ẹ̀karùnún sì ni Malkiah, ẹlẹ́ẹ̀kẹfà sì ni Mijamini,
10 A sétima a Hakkos, a oitava a Abias,
èkeje sì ni Hakosi, ẹlẹ́ẹ̀kẹjọ sí ni Abijah,
11 A nona a Jesua, a décima a Sechanias,
ẹ̀kẹsànán sì ni Jeṣua, ẹ̀kẹwàá sì ni Ṣekaniah,
12 A undécima a Eliasib, a duodécima a Jakim,
ẹ̀kọkànlá sì ni Eliaṣibu, ẹlẹ́ẹ̀kẹjìlá sì ni Jakimu,
13 A décima terceira a Huppa, a décima quarta a Jesebeab,
ẹ̀kẹtàlá sì ni Hupa, ẹlẹ́ẹ̀kẹrìnlá sì ni Jeṣebeabu,
14 A décima quinta a Bilga, a décima sexta a Immer,
ẹ̀kẹdógún sì ni Bilgah, ẹ̀kẹrìndínlógún sì ni Immeri,
15 A décima sétima a Hezir, a décima oitava a Happises,
ẹ̀kẹtàdínlógún sì ni Hesiri, èkejìdínlógún sì ni Hafisesi,
16 A décima nona a Petahias, a vigésima a Jehezkel,
ẹ̀kọkàndínlógún sì ni Petahiah, ogún sì ni Jeheskeli,
17 A vigésima primeira a Jachin, a vigésima segunda a Gamul,
ẹ̀kọkànlélógún sì ni Jakini, ẹ̀kẹrìnlélógún sì ni Gamuli,
18 A vigésima terceira a Delaias, a vigésima quarta a Maazias.
ẹ̀kẹtàlélógún sì ni Delaiah, ẹ̀kẹrìnlélógún sì ni Maasiah.
19 O ofício destes no seu ministério era entrar na casa do Senhor, segundo lhes fôra ordenado por Aarão seu pai, como o Senhor Deus de Israel lhe tinha ordenado.
Àwọn wọ̀nyí ni a yàn fún iṣẹ́ ìsìn nígbà tí wọ́n wọ ilé Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ìlànà àti àṣẹ tí a ti fi fún wọn láti ọwọ́ baba ńlá wọn Aaroni gẹ́gẹ́ bí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, tí pàṣẹ fun un.
20 E do resto dos filhos de Levi: dos filhos de Amram, Subael: dos filhos de Subael, Jehdias.
Ìyókù àwọn ọmọ Lefi. Láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Amramu: Ṣubaeli láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Ṣubaeli; Jehdeiah.
21 Quanto a Rehabias: dos filhos de Rehabias Issias era chefe;
Àti gẹ́gẹ́ bí Rehabiah, láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Rehabiah, Iṣiah sì ni alákọ́kọ́.
22 Dos isharitas, Selomoth; dos filhos de Selomoth, Jahoth;
Láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Isari: Ṣelomiti; láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Ṣelomoti: Jahati.
23 E dos filhos de Hebron, Jerias o primeiro, Amarias o segundo, Jahaziel o terceiro, Jekamam o quarto;
Àwọn ọmọ Hebroni: Jeriah alákọ́kọ́, Amariah ẹlẹ́ẹ̀kejì, Jahasieli ẹlẹ́ẹ̀kẹta àti Jekameamu ẹlẹ́ẹ̀kẹrin.
24 Dos filhos de Uziel, Micha; dos filhos de Micha, Samir;
Àwọn ọmọ Usieli: Mika; nínú àwọn ọmọ Mika: Ṣamiri.
25 O irmão de Micha, Issias; dos filhos de Issias, Zacarias;
Àwọn arákùnrin Mika: Iṣi; nínú àwọn ọmọ Iṣiah: Sekariah.
26 Os filhos de Merari, Maheli e Musi; dos filhos de Jaazias, Beno;
Àwọn ọmọ Merari: Mahili àti Muṣi. Àwọn ọmọ Jaasiah: Beno.
27 Os filhos de Merari de Jaazias, Beno, e Soham, e Zaccur, e Hibri;
Àwọn ọmọ Merari. Láti Jaasiah: Beno, Ṣohamu, Sakkuri àti Ibri.
28 De Maheli, Eleazar: e este não teve filhos.
Láti Mahili: Eleasari, ẹni tí kò ni àwọn ọmọ.
29 Quanto a Kis: dos filhos de Kis, Jerahmeel;
Láti Kiṣi. Àwọn ọmọ Kiṣi: Jerahmeeli.
30 E os filhos, de Musi, Maheli, e Eder, e Jerimoth; estes foram os filhos dos levitas, segundo as suas casas paternas.
Àti àwọn ọmọ Muṣi: Mahili, Ederi àti Jerimoti. Èyí ni àwọn ọmọ Lefi, gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn.
31 E também eles lançaram sortes igualmente com seus irmãos, os filhos de Aarão, perante o rei David, e Zadok, e Ahimelech, e os chefes dos pais entre os sacerdotes e entre os levitas: o chefe da casa dos pais e bem assim seu irmão menor.
Wọ́n sì ṣé kèké gẹ́gẹ́ bí àwọn arákùnrin wọn àwọn ọmọ Aaroni ṣe ṣẹ́, níwájú ọba Dafidi àti Sadoku, Ahimeleki, àti olórí ìdílé àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi. Àwọn ìdílé àgbàgbà arákùnrin wọ́n sì ṣe bẹ́ẹ̀ lórí àwọn arákùnrin wọn kéékèèké.

< 1 Crônicas 24 >