< Jó 38 >
1 Depois d'isto o Senhor respondeu a Job d'um redemoinho, e disse:
Nígbà náà ní Olúwa dá Jobu lóhùn láti inú ìjì àjàyíká wá, ó sì wí pé,
2 Quem é este que escurece o conselho com palavras sem conhecimento?
“Ta ni èyí tí ń fi ọ̀rọ̀ àìlóye láti fi ṣókùnkùn bo ìmọ̀ mi?
3 Agora cinge os teus lombos, como homem; e perguntar-te-hei, e tu me ensina.
Di ẹ̀gbẹ́ ara rẹ ní àmùrè bí ọkùnrin nísinsin yìí, nítorí pé èmi yóò béèrè lọ́wọ́ rẹ kí o sì dá mi lóhùn.
4 Onde estavas tu, quando eu fundava a terra? faze-m'o saber, se tens intelligencia.
“Níbo ni ìwọ wà nígbà tí mo fi ìpìlẹ̀ ayé sọlẹ̀? Wí bí ìwọ bá mòye.
5 Quem lhe poz as medidas? se tu o sabes; ou quem estendeu sobre ella o cordel?
Ta ni ó fi ìwọ̀n rẹ lélẹ̀, dájú bí ìwọ bá mọ̀ ọ́n? Tàbí ta ni ó ta okùn wíwọ̀n sórí rẹ?
6 Sobre que estão fundadas as suas bases? ou quem assentou a sua pedra da esquina,
Lórí ibo ni a gbé kan ìpìlẹ̀ rẹ̀ mọ́, tàbí ta ni ó fi òkúta igun rẹ̀ lélẹ̀,
7 Quando as estrellas da alva juntas alegremente cantavam, e todos os filhos de Deus jubilavam?
nígbà náà àwọn ìràwọ̀ òwúrọ̀ jùmọ̀ kọrin pọ̀, tí gbogbo àwọn ọmọ Ọlọ́run hó ìhó ayọ̀?
8 Ou quem encerrou o mar com portas, quando trasbordou e saiu da madre;
“Tàbí ta ni ó fi ìlẹ̀kùn sé omi òkun mọ́, nígbà tí ó ya padà bí ẹni pé ó ti inú jáde wá.
9 Quando eu puz as nuvens por sua vestidura, e a escuridão por envolvedouro?
Nígbà tí mo fi àwọsánmọ̀ ṣe aṣọ rẹ̀, tí mo sì fi òkùnkùn biribiri ṣe ọ̀já ìgbà inú rẹ̀.
10 Quando passei sobre elle o meu decreto, e lhe puz portas e ferrolhos;
Nígbà tí mo ti pàṣẹ ìpinnu mi fún un, tí mo sì ṣe bèbè àti ìlẹ̀kùn.
11 E disse: Até aqui virás, e não mais adiante, e aqui se quebrarão as tuas ondas empolladas?
Tí mo sì wí pé níhìn-ín ni ìwọ ó dé, kí o má sì rékọjá, níhìn-ín sì ni ìgbéraga rẹ yóò gbé dúró mọ?
12 Ou desde os teus dias déste ordem á madrugada? ou mostraste á alva o seu logar;
“Ìwọ pàṣẹ fún òwúrọ̀ láti ìgbà ọjọ́ rẹ̀ wá, ìwọ sì mú ìlà-oòrùn mọ ipò rẹ̀,
13 Para que pegasse dos fins da terra, e os impios fossem sacudidos d'ella;
í ó lè di òpin ilẹ̀ ayé mú, ki a lè gbọ́n àwọn ènìyàn búburú kúrò nínú rẹ̀?
14 E se transformasse como o barro, sob o sello, e se pozessem como vestidos;
Kí ó yí padà bí amọ̀ fún èdìdì amọ̀, kí gbogbo rẹ̀ kí ó sì fi ara rẹ̀ hàn bí ẹni pé nínú aṣọ ìgúnwà.
15 E dos impios se desvie a sua luz, e o braço altivo se quebrante;
A sì fa ìmọ́lẹ̀ wọn sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ ènìyàn búburú, apá gíga ni a sì ṣẹ́.
16 Ou entraste tu até ás origens do mar? ou passeaste no mais profundo do abysmo?
“Ìwọ ha wọ inú ìsun òkun lọ rí bí? Ìwọ sì rìn lórí ìsàlẹ̀ ibú ńlá?
17 Ou descobriram-se-te as portas da morte? ou viste as portas da sombra da morte?
A ha ṣílẹ̀kùn ikú sílẹ̀ fún ọ rí bí, ìwọ sì rí ìlẹ̀kùn òjìji òkú?
18 Ou com o teu entendimento chegaste ás larguras da terra? faze-m'o saber, se sabes tudo isto.
Ìwọ mòye ìbú ayé bí? Sọ bí ìwọ bá mọ gbogbo èyí.
19 Onde está o caminho para onde mora a luz? e, quanto ás trevas, onde está o seu logar;
“Ọ̀nà wo ni ìmọ́lẹ̀ ń gbé? Bí ó ṣe ti òkùnkùn, níbo ni ipò rẹ̀,
20 Para que as tragas aos seus limites, e para que saibas as veredas da sua casa?
tí ìwọ í fi mú un lọ sí ibi àlá rẹ̀, tí ìwọ ó sì le mọ ipa ọ̀nà lọ sínú ilé rẹ̀?
21 Acaso tu o sabes, porque já então eras nascido, e por ser grande o numero dos teus dias?
Ìwọ mọ èyí, nítorí nígbà náà ni a bí ọ? Iye ọjọ́ rẹ sì pọ̀.
22 Ou entraste tu até aos thesouros da neve? e viste os thesouros da saraiva,
“Ìwọ ha wọ inú ìṣúra ìdì òjò lọ rí bí, ìwọ sì rí ilé ìṣúra yìnyín rí,
23 Que eu retenho até do tempo da angustia, até ao dia da peleja e da guerra?
tí mo ti fi pamọ́ de ìgbà ìyọnu, dé ọjọ́ ogun àti ìjà?
24 Onde está o caminho em que se reparte a luz, e se espalha o vento oriental sobre a terra?
Ọ̀nà wo ni ó lọ sí ibi tí ìmọ́lẹ̀ fi ń la, tí afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn ń tàn káàkiri lórí ilẹ̀ ayé?
25 Quem abriu para a inundação um leito, e um caminho para os relampagos dos trovões;
Ta ni ó la ipadò fún ẹ̀kún omi, àti ọ̀nà fún mọ̀nàmọ́ná àrá,
26 Para chover sobre a terra, onde não ha ninguem, e no deserto, em que não ha gente;
láti mú u rọ̀jò sórí ayé níbi tí ènìyàn kò sí, ní aginjù níbi tí ènìyàn kò sí;
27 Para fartar a terra deserta e assolada, e para fazer crescer os renovos da herva?
láti mú ilẹ̀ tútù, ijù àti aláìro láti mú àṣẹ̀ṣẹ̀yọ ewéko rú jáde?
28 A chuva porventura tem pae? ou quem géra as gottas do orvalho,
Òjò ha ní baba bí? Tàbí ta ni o bí ìkún ìṣe ìrì?
29 De cujo ventre procede o gelo? e quem gera a geada do céu?
Láti inú ta ni ìdì omi ti jáde wá? Ta ni ó bí ìrì dídì ọ̀run?
30 Como debaixo de pedra as aguas se escondem: e a superficie do abysmo se coalha.
Nígbà tí omi di líle bí òkúta, nígbà tí ojú ibú ńlá sì dìpọ̀.
31 Ou poderás tu ajuntar as delicias das sete estrellas, ou soltar os atilhos do Orion?
“Ìwọ ha le fi ọ̀já de àwọn ìràwọ̀ Pleiadesi dáradára? Tàbí ìwọ le tún di ìràwọ̀ Orioni?
32 Ou produzir as constellações a seu tempo? e guiar a Ursa com seus filhos?
Ìwọ le mú àwọn àmì méjìlá ìràwọ̀ Masaroti jáde wá nígbà àkókò wọn? Tàbí ìwọ le ṣe amọ̀nà Beari pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀?
33 Sabes tu as ordenanças dos céus? ou podes dispor do dominio d'elles sobre a terra?
Ǹjẹ́ ìwọ mọ ìlànà ọ̀run? Ìwọ le fi ìjọba Ọlọ́run lélẹ̀ lórí ayé?
34 Ou podes levantar a tua voz até ás nuvens, para que a abundancia das aguas te cubra?
“Ìwọ le gbé ohùn rẹ sókè dé àwọsánmọ̀ kí ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi kí ó lè bò ọ́?
35 Ou enviarás aos raios para que saiam, e te digam: Eis-nos aqui?
Ìwọ le rán mọ̀nàmọ́ná kí wọn kí ó le lọ, ní ọ̀nà wọn kí wọn kí ó sì wí fún wọn pé, ‘Àwa nìyí’?
36 Quem poz a sabedoria nas entranhas? ou quem deu ao sentido o entendimento?
Ta ni ó fi ọgbọ́n pamọ́ sí odò ikùn tàbí tí ó fi òye sínú àyà?
37 Quem numerará as nuvens pela sabedoria? ou os odres dos céus, quem os abaixará,
Ta ni ó fi ọgbọ́n ka iye àwọsánmọ̀? Ta ni ó sì mú ìgò ọ̀run dà jáde,
38 Quando se funde o pó n'uma massa, e se apegam os torrões uns aos outros?
nígbà tí erùpẹ̀ di líle, àti ògúlùtu dìpọ̀?
39 Porventura caçarás tu preza para a leôa? ou fartaras a fome dos filhos dos leões,
“Ìwọ ha dẹ ọdẹ fún abo kìnnìún bí? Ìwọ ó sì tẹ ebi ẹgbọrọ kìnnìún lọ́rùn,
40 Quando se agacham nos covis, e estão á espreita nas covas?
nígbà tí wọ́n bá mọ́lẹ̀ nínú ihò tí wọ́n sì ba ní ibùba de ohun ọdẹ?
41 Quem prepara aos corvos o seu alimento, quando os seus pintainhos gritam a Deus e andam vagueando, por não terem de comer?
Ta ni ó ń pèsè ohun jíjẹ fún ẹyẹ ìwò, nígbà tí àwọn ọmọ rẹ ń ké pe Ọlọ́run, tí wọ́n sì máa ń fò kiri nítorí àìní ohun jíjẹ?