< 1 Crônicas 2 >
1 Estes são os filhos de Israel: Ruben, Simeão, Levi, Judah, Issacar e Zebulon;
Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Israẹli. Reubeni, Simeoni, Lefi, Juda, Isakari, Sebuluni,
2 Dan, José e Benjamin, Naphtali, Gad e Aser.
Dani, Josẹfu, Benjamini; Naftali, Gadi: àti Aṣeri.
3 Os filhos de Judah foram Er, e Onan, e Sela: estes tres lhe nasceram da filha de Sua, a cananea: e Er, o primogenito de Judah, foi mau aos olhos do Senhor, pelo que o matou.
Àwọn ọmọ Juda: Eri, Onani àti Ṣela, àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta wọ̀nyí ni wọ́n bí fún un láti ọ̀dọ̀ arábìnrin Kenaani, ọmọbìnrin Ṣua. Eri àkọ́bí Juda, ó sì burú ní ojú Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa sì pa á.
4 Porém Tamar, sua nora, lhe pariu a Perez e a Serah: todos os filhos de Judah foram cinco.
Tamari, aya ọmọbìnrin Juda, ó sì bí Peresi àti Sera sì ní ọmọ márùn-ún ní àpapọ̀.
5 Os filhos de Perez foram Hezron e Hamul.
Àwọn ọmọ Peresi: Hesroni àti Hamulu.
6 E os filhos de Serah: Zimri, e Ethan, e Heman, e Calcol, e Dara: cinco ao todo.
Àwọn ọmọ Sera: Simri, Etani, Hemani, Kalkoli àti Dara, gbogbo wọn jẹ́ márùn-ún.
7 E os filhos de Carmi foram Acar, o perturbador de Israel, que peccou no anathema.
Àwọn ọmọ Karmi: Akani, ẹni tí ó mú ìyọnu wá sórí Israẹli nípa ẹ̀ṣẹ̀ ìfibú lórí mímú ohun ìyàsọ́tọ̀.
8 E os filhos de Ethan foram Azarias.
Àwọn ọmọ Etani: Asariah.
9 E os filhos de Hezron, que lhe nasceram, foram Jerahmeel, e Ram, e Chelubai.
Àwọn ọmọ tí a bí fún Hesroni ni: Jerahmeeli, Ramu àti Kalebu.
10 E Ram gerou a Amminadab, e Amminadab gerou a Nahasson, principe dos filhos de Judah.
Ramu sì ni baba Amminadabu, àti Amminadabu baba Nahiṣoni olórí àwọn ènìyàn Juda.
11 E Nahasson gerou a Salma, e Salma gerou a Booz.
Nahiṣoni sì ni baba Salmoni, Salmoni ni baba Boasi,
12 E Booz gerou a Obed, e Obed gerou a Jessé.
Boasi baba Obedi àti Obedi baba Jese.
13 E Jessé gerou a Eliah, seu primogenito, e Abinadab, o segundo, e Simea, o terceiro,
Jese sì ni baba Eliabu àkọ́bí rẹ̀; ọmọ ẹlẹ́ẹ̀kejì sì ni Abinadabu, ẹlẹ́ẹ̀kẹta ni Ṣimea,
14 Nathanael, o quarto, Radda, o quinto,
ẹlẹ́ẹ̀kẹrin Netaneli, ẹlẹ́ẹ̀karùnún Raddai,
15 Osem, o sexto, David, o setimo.
ẹlẹ́ẹ̀kẹfà Osemu àti ẹlẹ́ẹ̀keje Dafidi.
16 E foram suas irmãs Zeruia e Abigail: e foram os filhos de Zeruia: Abisai, e Joab, e Asael, tres.
Àwọn arábìnrin wọn ni Seruiah àti Abigaili. Àwọn ọmọ mẹ́ta Seruiah ni Abiṣai, Joabu àti Asaheli.
17 E Abigail pariu a Amasa: e o pae de Amasa foi Jether, o ishmaelita.
Abigaili ni ìyá Amasa, ẹni tí baba rẹ̀ sì jẹ́ Jeteri ará Iṣmaeli.
18 E Caleb, filho de Hezron, gerou filhos de Azuba, sua mulher, e de Jerioth: e os filhos d'esta foram estes: Jeser, e Sobab, e Ardon.
Kalebu ọmọ Hesroni ní ọmọ láti ọ̀dọ̀ ìyàwó rẹ̀ Asuba (láti ọ̀dọ̀ Jerioti). Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ rẹ̀: Jeṣeri, Ṣobabu àti Ardoni.
19 E morreu Azuba; e Caleb tomou para si a Ephrath, a qual lhe pariu a Hur.
Nígbà tí Asuba sì kú, Kalebu sì fẹ́ Efrata ní aya, ẹni tí ó bí Huri fún un.
20 E Hur gerou a Uri, e Uri gerou a Besaleel.
Huri ni baba Uri, Uri sì jẹ́ baba Besaleli.
21 Então Hezron entrou á filha de Machir, pae de Gilead, e, sendo elle de sessenta annos, a tomou: e ella lhe pariu a Segub.
Nígbà tí ó yá, Hesroni sì dùbúlẹ̀ pẹ̀lú ọmọbìnrin Makiri baba Gileadi (ó sì ti fẹ́ ní aya láti ìgbà tí ó ti wà ní ẹni ọgọ́ta ọdún) ó sì bí Segubu.
22 E Segub gerou a Jair: e este tinha vinte e tres cidades na terra de Gilead.
Segubu sì jẹ́ baba Jairi, ẹni tí ó jẹ́ olùdarí ìlú mẹ́tàlélógún ní ilẹ̀ Gileadi.
23 E Gesur e Aram tomaram d'elles as aldeias de Jair, e Kenath, e seus logares, sessenta cidades: todos estes foram filhos de Machir, pae de Gilead.
(Ṣùgbọ́n Geṣuri àti Aramu sì fi agbára gba Hafoti-Jairi, àti Kenati pẹ̀lú gbogbo agbègbè rẹ̀ tí wọn tẹ̀dó sí jẹ́ ọgọ́ta ìlú.) Gbogbo wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Makiri baba Gileadi.
24 E, depois da morte de Hezron, em Caleb de Ephrata, Abia, mulher de Hezron, lhe pariu a Ashur, pae de Tekoa.
Lẹ́yìn tí Hesroni sì kú ni Kalebu Efrata, Abijah ìyàwó rẹ̀ ti Hesroni sì bí Aṣihuri baba Tekoa fún un.
25 E os filhos de Jerahmeel, primogenito de Hezron, foram Ram, o primogenito, e Buna, e Oren, e Osem, e Ahija.
Ọmọ Jerahmeeli àkọ́bí Hesroni: Ramu ọmọ àkọ́bí rẹ̀ Buna, Oreni, Osemu àti Ahijah.
26 Teve tambem Jerahmeel ainda outra mulher cujo nome era Atara: esta foi a mãe de Onam.
Jerahmeeli ní ìyàwó mìíràn, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Atara; ó sì jẹ́ ìyá fún Onamu.
27 E foram os filhos de Ram, primogenito de Jerahmeel: Maas, e Jamin, e Eker.
Àwọn ọmọ Ramu àkọ́bí Jerahmeeli: Maasi, Jamini àti Ekeri.
28 E foram os filhos de Onam: Sammai e Judah; e os filhos de Sammai: Nadab e Abisur.
Àwọn ọmọ Onamu: Ṣammai àti Jada. Àwọn ọmọ Ṣammai: Nadabu àti Abiṣuri.
29 E era o nome da mulher de Abisur Abiail, que lhe pariu a Ahban e a Molid.
Orúkọ ìyàwó Abiṣuri ni Abihaili ẹni tí ó bí Ahbani àti Molidi.
30 E foram os filhos de Nadab Seled e Appaim: e Seled morreu sem filhos.
Àwọn ọmọ Nadabu Seledi àti Appaimu. Seledi sì kú láìsí ọmọ.
31 E os filhos d'Appaim foram Ishi; e os filhos de Ishi: Sesan. E os filhos de Sesan: Ahlai.
Àwọn ọmọ Appaimu: Iṣi, ẹni tí ó jẹ́ baba fún Ṣeṣani. Ṣeṣani sì jẹ́ baba fún Ahlai.
32 E os filhos de Jada, irmão de Sammai, foram Jether e Jonathan: e Jether morreu sem filhos.
Àwọn ọmọ Jada, arákùnrin Ṣammai: Jeteri àti Jonatani. Jeteri sì kú láìní ọmọ.
33 E os filhos de Jonathan foram Peleth e Zaza: estes foram os filhos de Jerahmeel.
Àwọn ọmọ Jonatani: Peleti àti Sasa. Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Jerahmeeli.
34 E Sesan não teve filhos, mas filhas: e tinha Sesan um servo egypcio, cujo nome era Jarha.
Ṣeṣani kò sì ní ọmọkùnrin àwọn ọmọbìnrin nìkan ni ó ní. Ó sì ní ìránṣẹ́ ará Ejibiti tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Jariha.
35 Deu pois Sesan sua filha por mulher a Jarha, seu servo: e lhe pariu a Attai.
Ṣeṣani sì fi ọmọ obìnrin rẹ̀ ní aya fún ìránṣẹ́ rẹ̀ Jariha, ó sì bí ọmọ fún tí orúkọ rẹ̀ jẹ́ Attai.
36 E Attai gerou a Nathan, e Nathan gerou a Zabad.
Attai sì jẹ́ baba fún Natani, Natani sì jẹ́ baba fún Sabadi,
37 E Zabad gerou a Eflal, e Eflal gerou a Obed.
Sabadi ni baba Eflali, Eflali jẹ́ baba Obedi,
38 E Obed gerou a Jehu, e Jehu gerou a Azarias.
Obedi sì ni baba Jehu, Jehu ni baba Asariah,
39 E Azarias gerou a Heles, e Heles gerou a Eleasa.
Asariah sì ni baba Helesi, Helesi ni baba Eleasa,
40 E Eleasa gerou a Sismai, e Sismai gerou a Sallum.
Eleasa ni baba Sismai, Sismai ni baba Ṣallumu,
41 E Sallum gerou a Jekamias, e Jekamias gerou a Elisama.
Ṣallumu sì ni baba Jekamiah, Jekamiah sì ni baba Eliṣama.
42 E foram os filhos de Caleb, irmão de Jerahmeel, Mesa, seu primogenito (este foi o pae de Ziph), e os filhos de Maresa, pae de Hebron.
Àwọn ọmọ Kalebu arákùnrin Jerahmeeli: Meṣa àkọ́bí rẹ̀, ẹni tí ó jẹ́ baba fún Sifi, àti àwọn ọmọ rẹ̀ Meraṣa, ẹni tí ó jẹ́ baba fún Hebroni.
43 E foram os filhos de Hebron: Korah, e Tappuah, e Rekem, e Sema.
Àwọn ọmọ Hebroni: Kora, Tapua, Rekemu, àti Ṣema.
44 E Sema gerou a Raham, pae de Jorkeam: e Rekem gerou a Sammai.
Ṣema ni baba Rahamu, Rahamu sì jẹ́ baba fún Jorkeamu. Rekemu sì ni baba Ṣammai.
45 E foi o filho de Sammai Maon: e Maon foi pae de Bethzur.
Àwọn ọmọ Ṣammai ni Maoni, Maoni sì ni baba Beti-Suri.
46 E Epha, a concubina de Caleb, pariu a Haran, e a Mosa, e a Gazez: e Haran gerou a Gazez.
Efani obìnrin Kalebu sì ni ìyá Harani, Mosa àti Gasesi, Harani sì ni baba Gasesi.
47 E foram os filhos de Johdai: Regem, e Jotham, e Gesan, e Pelet, e Epha, e Saaph.
Àwọn ọmọ Jahdai: Regemu, Jotamu, Geṣani, Peleti, Efani àti Ṣaafu.
48 De Maaca, concubina, gerou Caleb a Seber e a Tirhana.
Maaka obìnrin Kalebu sì ni ìyá Seberi àti Tirhana.
49 E a mulher de Saaph, pae de Madmanna, pariu a Seva, pae de Machbena e pae de Gibea: e foi a filha de Caleb Acsa.
Ó sì bí Ṣaafu baba Madmana, Ṣefa baba Makbena àti baba Gibeah, ọmọbìnrin Kalebu sì ni Aksa.
50 Estes foram os filhos de Caleb, filho de Hur, o primogenito de Ephrata: Sobal, pae de Kiriath-jearim,
Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Kalebu. Àwọn ọmọ Huri, àkọ́bí Efrata: Ṣobali baba Kiriati-Jearimu.
51 Salma, pae dos bethlehemitas, Hareph, pae de Beth-gader.
Salma baba Bẹtilẹhẹmu àti Harefu baba Beti-Gaderi.
52 E foram os filhos de Sobal, pae de Kiriath-jearim: Haroe e metade dos menuhitas.
Àwọn ọmọ Ṣobali baba Kiriati-Jearimu ni: Haroe, ìdajì àwọn ará Manaheti.
53 E as familias de Kiriath-jearim foram os jethreos, e os putheos, e os sumatheos, e os misraeos: d'estes sairam os zoratheos, e os esthaoleos.
Àti ìdílé Kiriati-Jearimu: àti àwọn ara Itri, àti àwọn ará Puti, àti àwọn ará Ṣumati àti àwọn ará Miṣraiti: láti ọ̀dọ̀ wọn ni àwọn ọmọ ará Sorati àti àwọn ará Eṣtaoli ti wá.
54 Os filhos de Salma foram Beth-lehem e os nethophatitas, Atroth, e Beth-joab, e metade dos manahthitas, e os zoritas.
Àwọn ọmọ Salma: Bẹtilẹhẹmu, àti àwọn ará Netofa, Atrotu Beti-Joabu, ìdajì àwọn ará Manahati, àti ará Sori,
55 E as familias dos escribas que habitavam em Jabez foram os thirathitas, os simathitas, e os sucathitas: estes são os kineos, que vieram de Hammath, pae da casa de Rechab.
àti àwọn ìdílé àwọn akọ̀wé, ẹni tí ń gbé ní Jabesi: àti àwọn ọmọ Tirati àti àwọn ará Ṣimeati àti àwọn ará Sukati. Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ará Keni, ẹni tí ó wá láti ọ̀dọ̀ Hamati, baba ilé Rekabu.