< Zachariasza 8 >

1 Potem doszło [do mnie] słowo PANA zastępów mówiące:
Ọ̀rọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun si tún tọ́ mí wá.
2 Tak mówi PAN zastępów: Byłem zazdrosny o Syjon w wielkiej gorliwości, byłem zazdrosny w wielkim gniewie.
Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Owú ńlá ńlá ni mo jẹ fún Sioni, pẹ̀lú ìbínú ńlá ńlá ni mo fi jowú fún un.”
3 Tak mówi PAN: Wróciłem na Syjon i zamieszkam w Jerozolimie; a Jerozolima będzie nazwana Miastem Wiernym, a góra PANA zastępów – Górą Świętą.
Báyìí ni Olúwa wí, “Mo yípadà sí Sioni èmi ó sì gbé àárín Jerusalẹmu. Nígbà náà ni a ó sì pé Jerusalẹmu ni ìlú ńlá òtítọ́; àti òkè ńlá Olúwa àwọn ọmọ-ogun, ni a ó pè ní òkè ńlá mímọ́.”
4 Tak mówi PAN zastępów: Jeszcze siadać będą starcy i staruszki na ulicach Jerozolimy, każdy z nich z laską w ręku z powodu podeszłego wieku.
Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Arúgbó ọkùnrin, àti arúgbó obìnrin, yóò gbé ìgboro Jerusalẹmu, àti olúkúlùkù pẹ̀lú ọ̀pá ni ọwọ́ rẹ̀ fún ogbó.
5 I ulice miasta będą pełne bawiących się na nich chłopców i dziewcząt.
Ìgboro ìlú yóò sì kún fún ọmọdékùnrin, àti ọmọdébìnrin, tí ń ṣiré ní ìta wọn.”
6 Tak mówi PAN zastępów: Jeśli w tych dniach wyda się to niemożliwe w oczach resztki tego ludu, czy będzie to też niemożliwe w moich oczach? – mówi PAN zastępów.
Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Bí ó bá ṣe ìyanu ní ojú ìyókù àwọn ènìyàn yìí ni ọjọ́ wọ̀nyí, ǹjẹ́ ó ha lè jẹ́ ìyanu ni ojú mi bí?” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
7 Tak mówi PAN zastępów: Oto wybawię swój lud z ziemi wschodniej i z ziemi zachodniej.
Báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Kíyèsi i, èmi ó gba àwọn ènìyàn mi kúrò ni ilẹ̀ ìlà-oòrùn, àti kúrò ni ilẹ̀ ìwọ̀-oòrùn.
8 Sprowadzę go i zamieszka w Jerozolimie, i będzie moim ludem, a ja będę jego Bogiem, w prawdzie i sprawiedliwości.
Èmi ó sì mú wọn padà wá, wọn ó sì máa gbé àárín Jerusalẹmu. Wọn ó sì jẹ́ ènìyàn mi, èmi ó sì jẹ́ Ọlọ́run wọn, ní òtítọ́, àti ní òdodo.”
9 Tak mówi PAN zastępów: Niech się umocnią wasze ręce, wy, którzy słuchaliście w tych dniach słów z ust proroków, którzy byli w dniu, [kiedy] założono fundament domu PANA zastępów, aby świątynia została odbudowana.
Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Jẹ́ kí ọwọ́ yín le ẹ̀yin ti ń gbọ́ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ní ọjọ́ wọ̀nyí ni ẹnu àwọn wòlíì tí ó wà ni ọjọ́ tí a fi ìpìlẹ̀ ilé Olúwa àwọn ọmọ-ogun lélẹ̀, jẹ́ ki ọwọ́ rẹ̀ le kí a bá lè kọ́ tẹmpili.
10 Przed tymi dniami bowiem nie była wynagrodzona praca ludzka i praca bydląt. Dla wychodzących i wchodzących nie było pokoju z powodu wroga, bo ja podburzyłem wszystkich ludzi, jednych przeciwko drugim.
Nítorí pé, ṣáájú ọjọ́ wọ̀nyí, owó ọ̀yà ènìyàn kò tó nǹkan, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀yà ẹran pẹ̀lú, bẹ́ẹ̀ ni kò sí àlàáfíà fún ẹni ń jáde lọ, tàbí ẹni ti ń wọlé bọ, nítorí ìpọ́njú náà: nítorí mo dojú gbogbo ènìyàn, olúkúlùkù kọ aládùúgbò rẹ̀.
11 Lecz teraz nie uczynię z resztką tego ludu tak jak za dawnych dni, mówi PAN zastępów.
Ṣùgbọ́n ní ìsinsin yìí èmi kì yóò ṣè sí ìyókù àwọn ènìyàn yìí gẹ́gẹ́ bí tí ìgbà àtijọ́,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
12 Ale siewy będą [rosły] w pokoju, winorośl wyda swój owoc, ziemia wyda swoje plony i niebiosa także spuszczą swoją rosę, a to wszystko dam resztce tego ludu w posiadanie.
“Nítorí irúgbìn yóò gbilẹ̀, àjàrà yóò ṣo èso rẹ̀, ilẹ̀ yóò sì hu ọ̀pọ̀lọpọ̀ nǹkan rẹ̀ jáde, àwọn ọ̀run yóò sì mu ìrì wọn wá; èmi ó sì mu kí èyí jẹ ogún ìní àwọn ìyókù ènìyàn yìí ni gbogbo nǹkan wọ̀nyí.
13 I stanie się, że jak byliście przekleństwem wśród pogan, domu Judy i domu Izraela, tak was wybawię i będziecie błogosławieństwem. Nie bójcie się i niech się umocnią wasze ręce.
Yóò sì ṣe, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin tí jẹ́ ègún láàrín àwọn kèfèrí, ẹ̀yin ilé Juda, àti ilé Israẹli, bẹ́ẹ̀ ni èmi ó gbà yín sílẹ̀; ẹ̀yin o sì jẹ́ ìbùkún, ẹ má bẹ̀rù, ṣùgbọ́n jẹ́ ki ọwọ́ yín le.”
14 Tak bowiem mówi PAN zastępów: Jak postanowiłem ukarać was, gdy wasi ojcowie pobudzali mnie do gniewu, mówi PAN zastępów – i nie żałowałem tego;
Nítorí báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Gẹ́gẹ́ bí mo ti rò láti ṣe yín níbi nígbà tí àwọn baba yín mú mi bínú,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, tí èmi kò sì ronúpìwàdà.
15 Tak znowu postanowiłem w tych dniach uczynić dobrze Jerozolimie i domowi Judy. Nie bójcie się.
“Bẹ́ẹ̀ ni èmi sì ti ro ọjọ́ wọ̀nyí láti ṣe rere fún Jerusalẹmu, àti fún ilé Juda: ẹ má bẹ̀rù.
16 To [są] rzeczy, które będziecie czynić: Mówcie prawdę, każdy ze swoim bliźnim, wykonujcie sprawiedliwy i spokojny sąd w waszych bramach;
Wọ̀nyí ni nǹkan tí ẹ̀yin ó ṣe: ki olúkúlùkù yín kí ó máa ba ọmọnìkejì rẹ̀ sọ òtítọ́; ṣe ìdájọ́ tòótọ́ àti àlàáfíà ní àwọn ibodè yín.
17 Nie obmyślajcie zła w sercach waszych, jeden przeciwko drugiemu, i nie lubujcie się w krzywoprzysięstwie, gdyż tego wszystkiego nienawidzę, mówi PAN.
Ẹ má ṣe jẹ́ kí ẹnìkan ro ibi ni ọkàn rẹ̀ sí ẹnìkejì rẹ̀; ẹ má fẹ́ ìbúra èké; nítorí gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni mo kórìíra,” ni Olúwa wí.
18 I doszło do mnie słowo PANA zastępów mówiące:
Ọ̀rọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun sì tọ mi wá wí pé.
19 Tak mówi PAN zastępów: Post w czwartym, piątym, siódmym i dziesiątym [miesiącu] zamienią się dla domu Judy w radość i wesele, i w rozkoszne święta. Miłujcie więc prawdę i pokój.
Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé: “Àwẹ̀ oṣù kẹrin, karùn-ún, keje, àti tí ẹ̀kẹwàá, yóò jẹ́ ayọ̀ àti dídùn inú, àti àpéjọ àríyá fún ilé Juda; nítorí náà, ẹ fẹ́ òtítọ́ àti àlàáfíà.”
20 Tak mówi PAN zastępów: Jeszcze będą przychodzić narody i mieszkańcy wielu miast.
Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Àwọn ènìyàn yóò sá à tún wa, àti ẹni tí yóò gbe ìlú ńlá púpọ̀.
21 Mieszkańcy jednego [miasta] pójdą do drugiego, mówiąc: Pójdźmy ochoczo przebłagać oblicze PANA i szukać PANA zastępów. Ja także pójdę.
Àwọn ẹni tí ń gbé ìlú ńlá kan yóò lọ sí òmíràn, wí pé, ‘Ẹ jẹ́ kí a yára lọ gbàdúrà kí a sì wá ojúrere Olúwa, àti láti wá Olúwa àwọn ọmọ-ogun. Èmi pẹ̀lú yóò sì lọ.’
22 A tak liczne ludy i potężne narody przybędą szukać PANA zastępów w Jerozolimie i przebłagać oblicze PANA.
Nítòótọ́, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn àti àwọn alágbára orílẹ̀-èdè yóò wá láti wá Olúwa àwọn ọmọ-ogun ní Jerusalẹmu; àti láti gbàdúrà, àti láti wá ojúrere Olúwa.”
23 Tak mówi PAN zastępów: W tych dniach dziesięciu ludzi ze wszystkich języków narodów uchwyci się poły jednego Żyda, mówiąc: Pójdziemy z wami, bo usłyszeliśmy, [że] Bóg [jest] z wami.
Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Ní àwọn ọjọ́ wọ̀nyí ni ọkùnrin mẹ́wàá láti inú gbogbo èdè àti orílẹ̀-èdè yóò dìímú, àní yóò di etí aṣọ ẹni tí i ṣe Júù mú, wí pé, ‘Àwa yóò ba ọ lọ, nítorí àwa tí gbọ́ pé, Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ.’”

< Zachariasza 8 >