< Psalmów 70 >

1 Przewodnikowi chóru. Psalm Dawida dla przypomnienia. Boże, racz mnie ocalić; PANIE, pospiesz mi na pomoc.
Fún adarí orin. Ti Dafidi. Ẹ̀bẹ̀. Yára, Ọlọ́run, láti gbà mí là, Olúwa, wá kánkán láti ràn mí lọ́wọ́.
2 Niech się zawstydzą i okryją hańbą ci, którzy czyhają na moją duszę; niech się cofną ze wstydem ci, którzy mi źle życzą.
Kí àwọn tí ń wá ọkàn mi kí a dójútì wọ́n, kí wọn sì dààmú; kí àwọn tó ń wá ìparun mi yí ẹ̀yìn padà nínú ìtìjú.
3 Niech się cofną wskutek swej hańby ci, którzy mi mówią: Ha, ha!
Kí a pa wọ́n ní ẹ̀yìn dà fún èrè ìtìjú àwọn tí ń wí pé, “Háà! Háà!”
4 Niech się weselą i radują w tobie wszyscy, którzy cię szukają; niech ci, którzy miłują twoje zbawienie, mówią zawsze: Niech Bóg będzie wywyższony!
Ṣùgbọ́n kí àwọn tí ó ń wá ọ ó máa yọ̀ kí inú wọn kí ó sì máa dùn nípa rẹ, kí àwọn tí ó ń fẹ́ ìgbàlà rẹ máa wí pé, “Jẹ́ kí a gbé Ọlọ́run ga!”
5 Ja zaś jestem nędzny i ubogi, Boże, pospiesz ku mnie, ty jesteś moją pomocą i wybawicielem; PANIE, nie zwlekaj.
Ṣùgbọ́n mo jẹ́ òtòṣì àti aláìní; wa kánkán sí ọ̀dọ̀ mi, Ọlọ́run. Ìwọ ni olùrànlọ́wọ́ àti olùdáǹdè mi; Olúwa, má ṣe dúró pẹ́.

< Psalmów 70 >