< Psalmów 49 >

1 Przewodnikowi chóru. Psalm dla synów Korego. Słuchajcie tego wszystkie narody, nadstawcie ucha wszyscy mieszkańcy świata.
Fún adarí orin. Ti àwọn ọmọ Kora. Saamu. Ẹ gbọ́ èyí, gbogbo ènìyàn! Ẹ fi etí sí i, gbogbo ẹ̀yin aráyé.
2 Zarówno wy, prości, jak i wy, możni; zarówno bogaty, jak i ubogi.
Àti ẹni tí ó ga àti ẹni tí ó kéré tálákà àti ọlọ́lá pẹ̀lú!
3 Moje usta wypowiedzą mądrość, a rozmyślaniem mego serca [będzie] roztropność.
Ẹnu mi yóò sọ̀rọ̀ ọgbọ́n, èrò láti ọkàn mi yóò mú òye wá
4 Nakłonię ucha ku przypowieści, przy harfie rozwiążę moją zagadkę.
èmi yóò dẹ etí mi sílẹ̀ sí òwe, èmi yóò ṣí ọ̀rọ̀ ìkọ̀kọ̀ mi sílẹ̀ lójú okùn dùùrù.
5 Dlaczego mam się bać w dniach niedoli, [gdy] otacza mnie nieprawość tych, którzy mnie depczą?
Èéṣe ti èmi yóò bẹ̀rù nígbà tí ọjọ́ ibi dé? Nígbà tí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ajinnilẹ́sẹ̀ mi yí mi ká,
6 Ci, którzy ufają swym bogactwom i chlubią się swym wielkim dostatkiem;
àwọn tí o gbẹ́kẹ̀lé ọrọ̀ wọn, tí wọn sì ń ṣe ìlérí ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọrọ̀ wọn.
7 Nikt [z nich] w żaden sposób nie odkupi swego brata ani nie może dać Bogu [za niego] okupu;
Kò sí ọkùnrin tí ó lè ra ẹ̀mí ẹnìkejì rẹ̀ padà tàbí san owó ìràpadà fún Ọlọ́run.
8 (Kosztowny bowiem jest okup za ich dusze i nigdy się nie zdarzy);
Nítorí ìràpadà fún ẹni jẹ́ iyebíye kò sì sí iye owó tó tó fún sísan rẹ̀,
9 Aby żył na wieki i nie doznał zniszczenia.
ní ti kí ó máa wà títí ayé láìrí isà òkú.
10 Każdy bowiem widzi, że mądrzy umierają, tak samo jak ginie głupiec i prostak, i zostawiają obcym swoje bogactwa.
Nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn rí ọkùnrin ọlọ́gbọ́n tí ó kú, bẹ́ẹ̀ ni aṣiwèrè àti aláìlọ́gbọ́n pẹ̀lú ṣègbé wọ́n sì fi ọrọ̀ wọn sílẹ̀ fún ẹlòmíràn.
11 Myślą, [że] ich domy [są] wieczne, a ich mieszkania [będą trwać] z pokolenia na pokolenie; nazywają ziemie swymi imionami.
Ibojì wọn ni yóò jẹ́ ilé wọn láéláé, ibùgbé wọn láti ìrandíran, wọn sọ orúkọ ilẹ̀ wọn ní orúkọ ara wọn.
12 Lecz człowiek, choć otoczony czcią, nie przetrwa; podobny jest do bydląt, które giną.
Ṣùgbọ́n ọkùnrin tí o wà nínú ọlá kò dúró pẹ́ ó sì dàbí ẹranko tí ó ṣègbé.
13 Ich droga jest ich głupstwem, mimo to ich potomkowie pochwalają ich mowę. (Sela)
Èyí ni òtítọ́ àwọn ènìyàn tí ó gbàgbọ́ nínú ara wọn, àti àwọn tí ń tẹ̀lé wọn, tí ó gba ọ̀rọ̀ wọn. (Sela)
14 Jak owce będą złożeni w grobie, śmierć ich pożre; prawi będą nad nimi panować o poranku, ich postać zostanie zniszczona w grobie, gdy opuszczą swoje mieszkanie. (Sheol h7585)
Gẹ́gẹ́ bí àgùntàn ni a tẹ́ wọn sínú isà òkú ikú yóò jẹun lórí wọn; ẹni tí ó dúró ṣinṣin ni yóò, jẹ ọba lórí wọn ní òwúrọ̀. Ẹwà wọn yóò díbàjẹ́, isà òkú ni ibùgbé ẹwà wọn. (Sheol h7585)
15 Ale Bóg wykupi moją duszę z mocy grobu, bo mnie przyjmie. (Sela) (Sheol h7585)
Ṣùgbọ́n Ọlọ́run yóò ra ọkàn mi padà kúrò nínú isà òkú, yóò gbé mi lọ sọ́dọ̀ òun fún rara rẹ̀. (Sheol h7585)
16 Nie bój się, gdy się ktoś wzbogaci, gdy się rozmnoży sława jego domu;
Má ṣe bẹ̀rù nígbà tí ẹnìkan bá di ọlọ́rọ̀. Nígbà tí ìyìn ilé rẹ̀ ń pọ̀ sí i.
17 Bo gdy umrze, niczego [ze sobą] nie weźmie i nie pójdzie za nim jego sława.
Nítorí kì yóò mú ohun kan lọ nígbà tí ó bá kú, ògo rẹ̀ kò ní bá a sọ̀kalẹ̀ sí ipò òkú.
18 Chociaż za życia swej duszy pochlebiał i chwalono go, gdy dobrze się urządził;
Nígbà tí ó wà láyé, ó súre fún ọkàn ara rẹ̀. Àwọn ènìyàn yìn ọ́ nígbà tí ìwọ ṣe rere.
19 Pójdzie jednak do grona swych ojców; nigdy nie ujrzą światła.
Òun yóò lọ sí ọ̀dọ̀ ìran àwọn baba rẹ̀ àwọn tí ki yóò ri ìmọ́lẹ̀ ayé.
20 Człowiek, który jest otoczony czcią, a nie rozumie [tego], podobny jest do bydląt, które giną.
Ọkùnrin tí ó ní ọlá tí kò ní òye dàbí ẹranko tí ó ṣègbé.

< Psalmów 49 >