< Psalmów 40 >

1 Przewodnikowi chóru. Psalm Dawida. Z tęsknotą czekałem na PANA, a skłonił się ku mnie i wysłuchał mojego wołania.
Fún adarí orin. Ti Dafidi. Saamu. Mo fi pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ dúró de Olúwa; ó sì dẹtí sí mi, ó sì gbọ́ ẹkún mi.
2 Wyciągnął mnie ze strasznego dołu [i] z błota grząskiego [i] postawił moje stopy na skale, i umocnił moje kroki.
Ó fà mí yọ gòkè láti inú ihò ìparun, láti inú ẹrẹ̀ pọ̀tọ̀pọ́tọ̀, ó sì fi ẹsẹ̀ mi lé orí àpáta, ó sì jẹ́ kí ìgbésẹ̀ mi wà láìfòyà.
3 I włożył w moje usta nową pieśń, chwałę [dla] naszego Boga. Wielu to zobaczy i ulęknie się, i zaufa PANU.
Ó fi orin tuntun sí mi lẹ́nu, àní orin ìyìn sí Ọlọ́run wa. Ọ̀pọ̀ yóò rí i wọn yóò sì bẹ̀rù, wọn yóò sì gbẹ́kẹ̀lé Olúwa.
4 Błogosławiony człowiek, który pokłada w PANU swoją nadzieję, a nie ma względu na pysznych ani na tych, którzy podążają za kłamstwem.
Ayọ̀ ni fún àwọn wọ̀n-ọn-nì tí ó fi Olúwa ṣe ìgbẹ́kẹ̀lé wọn tí wọn kò sì yípadà sí agbéraga, tàbí àwọn tí ó yapa lọ sí ọ̀dọ̀ ọlọ́run mìíràn.
5 Wiele uczyniłeś cudów, PANIE, mój Boże, a twoich zamysłów wobec nas nikt nie potrafi wyliczyć przed tobą; gdybym chciał je opowiedzieć i ogłosić, jest ich więcej, niż zdołałbym wypowiedzieć.
Olúwa Ọlọ́run mi, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn iṣẹ́ ìyanu tí ìwọ ti ṣe. Àwọn ohun tí ìwọ ti ṣètò sílẹ̀ fún wa; ni ẹnikẹ́ni kò le kà wọ́n fún ọ lẹ́sẹẹsẹ, tí èmi yóò sì sọ̀rọ̀ wọn, wọ́n ju ohun tí ènìyàn le è kà lọ.
6 Ofiary i daru nie chciałeś, lecz otworzyłeś mi uszy; nie żądałeś całopalenia i ofiary za grzech.
Ẹbọ àti ẹran ẹbọ ni ìwọ kò fẹ́, ìwọ ti ṣí mi ní etí. Ọrẹ ẹbọ sísun àti ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ ni ìwọ kò béèrè.
7 Wtedy powiedziałem: Oto przychodzę, na początku księgi jest napisane o mnie;
Nígbà náà ni mo wí pé, “Èmi nìyí; nínú ìwé kíká ni a kọ ọ nípa tèmi wí pé.
8 Pragnę czynić twoją wolę, mój Boże, a twoje prawo jest w moim wnętrzu.
Mo ní inú dídùn láti ṣe ìfẹ́ ẹ̀ rẹ, ìwọ Ọlọ́run mi, òfin rẹ̀ ń bẹ ní àyà mi.”
9 Głosiłem [twoją] sprawiedliwość w wielkim zgromadzeniu; oto nie powściągałem moich ust; ty wiesz [o tym], PANIE.
Èmi ti sọ ìròyìn ayọ̀ ti ìgbàlà láàrín àwùjọ ńlá; wò ó, èmi kò pa ètè mi mọ́, gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti mọ̀, ìwọ Olúwa.
10 Twojej sprawiedliwości nie kryłem w głębi serca, opowiadałem twoją wierność i zbawienie; nie taiłem twego miłosierdzia i prawdy w wielkim zgromadzeniu.
Èmi kò fi ìrànlọ́wọ́ ìgbàlà sin ní àyà mi; èmí ti sọ̀rọ̀ nípa òtítọ́ àti ìgbàlà rẹ. Èmi kò sì pa ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti òtítọ́ rẹ̀ mọ́ kúrò láàrín àwọn ìjọ ńlá.
11 Dlatego ty, PANIE, nie odmawiaj mi twej litości; twoje miłosierdzie i prawda niech mnie zawsze strzegą.
Ìwọ má ṣe, fa àánú rẹ tí ó rọ́nú sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ mi Olúwa; jẹ́ kí ìṣeun ìfẹ́ rẹ àti òtítọ́ rẹ kí ó máa pa mi mọ́ títí ayérayé.
12 Otoczyły mnie bowiem nieszczęścia, których nie sposób zliczyć; dosięgły mnie moje nieprawości, tak że nie mogę [ich] przejrzeć; więcej ich niż włosów na mej głowie, więc serce we mnie ustaje.
Nítorí pé àìníye ibi ni ó yí mi káàkiri, ẹ̀ṣẹ̀ mi sì dì mọ́ mi, títí tí èmi kò fi ríran mọ́; wọ́n pọ̀ ju irun orí mi lọ, àti wí pé àyà mí ti kùnà.
13 PANIE, racz mnie ocalić; PANIE, pospiesz mi na pomoc.
Jẹ́ kí ó wù ọ́, ìwọ Olúwa, láti gbà mí là; Olúwa, yára láti ràn mí lọ́wọ́.
14 Niech się zawiodą i zawstydzą wszyscy, którzy czyhają, by zatracić moją duszę; niech się cofną i zawstydzą ci, którzy mi źle życzą.
Gbogbo àwọn wọ̀n-ọn-nì ni kí ojú kí ó tì kí wọn kí ó sì dààmú; àwọn tí ń wá ọkàn mi láti parun jẹ́ kí a lé wọn padà sẹ́yìn kí a sì dójútì wọ́n, àwọn tí ń wá ìpalára mi.
15 Niech będą spustoszeni wskutek swej hańby ci, którzy mi mówią: Ha, ha!
Jẹ́ kí àwọn tí ó wí fún mi pé, “Háà! Háà!” ó di ẹni à fi ọwọ́ rọ́ sẹ́yìn nítorí ìtìjú wọn.
16 Niech się radują i weselą w tobie wszyscy, którzy cię szukają; niech ci, którzy miłują twoje zbawienie, mówią zawsze: Niech PAN będzie wywyższony.
Jẹ́ kí gbogbo àwọn tí ń wá ọ kí ó máa yọ̀ kí inú wọn sì máa dùn sí ọ; kí gbogbo àwọn tí ó sì fẹ́ ìgbàlà rẹ kí o máa wí nígbà gbogbo pé, “Gbígbéga ni Olúwa!”
17 Ja [wprawdzie] jestem ubogi i nędzny, lecz Pan myśli o mnie. Ty jesteś moją pomocą i wybawicielem, mój Boże, nie zwlekaj.
Bí ó ṣe ti èmi ni, tálákà àti aláìní ni èmi, ṣùgbọ́n Olúwa ń ṣe ìrántí mi. Ìwọ ni olùrànlọ́wọ́ mi àti ìgbàlà mi; má ṣe jẹ́ kí ó pẹ́, ìwọ Ọlọ́run mi.

< Psalmów 40 >