< Psalmów 28 >
1 Psalm Dawida. Do ciebie wołam, PANIE, Skało moja; nie bądź głuchy na moje [wołanie], abym jeśli się nie odezwiesz, nie stał się podobny do zstępujących do dołu.
Ti Dafidi. Ìwọ Olúwa, mo ké pe àpáta mi. Má ṣe kọ etí dídi sí mi. Tí ìwọ bá dákẹ́ sí mi, èmí yóò dàbí àwọn tí ó lọ sí ọ̀gbun.
2 Usłysz głos mego błagania, gdy wołam do ciebie, gdy podnoszę ręce ku twojemu miejscu najświętszemu.
Gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ mi fún àánú, bí mo ṣe ń ké pè ọ́ fún ìrànlọ́wọ́, bí mo ṣe gbé àwọn ọwọ́ mi sókè sí Ibi Mímọ́ rẹ Jùlọ.
3 Nie zabieraj mnie z niegodziwymi i z czyniącymi nieprawość, którzy mówią o pokoju z bliźnimi, a zło [jest] w ich sercach.
Má ṣe fà mí lọ pẹ̀lú ènìyàn búburú àti, pẹ̀lú àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀, tí ń sọ̀rọ̀ àlàáfíà sí aládùúgbò wọn ṣùgbọ́n tí ìwà ìkà ń bẹ nínú wọn.
4 Oddaj im według ich uczynków i według zła ich postępków; według czynów ich rąk odpłać im, oddaj im, co im się należy.
San ẹ̀san wọn gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ wọn àti fún iṣẹ́ ibi wọn; gba ẹ̀san wọn gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ wọn; kí o sì san ẹ̀san wọn bí ó ti tọ́.
5 Skoro nie zważają na czyny PANA ani na dzieła jego rąk, on zniszczy ich i nie odbuduje.
Nítorí pé wọn kò ka iṣẹ́ Olúwa sí, tàbí àwọn iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ òun ó rún wọn wọlẹ̀ kì yóò sì gbé wọn ró mọ́.
6 Błogosławiony [niech będzie] PAN, bo wysłuchał głosu mego błagania.
Alábùkún fún ni Olúwa! Nítorí pé ó ti gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ mi.
7 PAN jest moją siłą i tarczą, moje serce jemu zaufało i doznałem pomocy; dlatego moje serce się rozweseliło i moją pieśnią będę go chwalić.
Olúwa ni agbára mi àti asà mi; nínú rẹ̀ ni mo gbẹ́kẹ̀lé; àní, ó sì ràn mí lọ́wọ́. Ọkàn mi sì gbé sókè fún ayọ̀ àní pẹ̀lú orin mi mo fi ọpẹ́ fún un.
8 PAN jest siłą dla swoich i twierdzą zbawienia swego pomazańca.
Olúwa ni agbára àwọn ènìyàn rẹ̀ òun ni odi ìgbàlà àwọn ẹni àmì òróró rẹ̀.
9 Wybaw twój lud, [PANIE], błogosław twemu dziedzictwu, paś ich i nieś na wieki.
Ìwọ gba àwọn ènìyàn rẹ là, kí o sì bùkún àwọn ajogún rẹ; di olùṣọ́-àgùntàn wọn, kí o sì gbé wọn lékè títí ayérayé.