< Psalmów 22 >

1 Przewodnikowi chóru, na Ajjelet haszahar. Psalm Dawida. Boże mój, Boże mój, czemu mnie opuściłeś? [Czemu] jesteś [tak] daleki od wybawienia mnie, od słów mego jęku?
Fún adarí orin. Tí ohùn orin “àgbọ̀nrín òwúrọ̀.” Saamu ti Dafidi. Ọlọ́run mi, Ọlọ́run mi, èéṣe tí ìwọ fi kọ̀ mí sílẹ̀? Èéṣe tí o fi jìnnà láti gbà mí là, àní sí igbe ìkérora mi?
2 Boże mój, wołam we dnie, a nie odzywasz się do mnie; w nocy, a nie mogę się uspokoić.
Ọlọ́run mi, ní ọ̀sán gangan ni mo kígbe, ṣùgbọ́n ìwọ kò dá mi ní ohùn: àti ní òru èmi kò dákẹ́.
3 Ale ty jesteś Święty, mieszkający wśród chwały Izraela.
Ṣùgbọ́n síbẹ̀ ẹni mímọ́ ni Ìwọ; ẹni tí ó tẹ ìyìn Israẹli dó.
4 Tobie ufali nasi ojcowie, ufali i wyzwoliłeś ich.
Àwọn baba ńlá wa ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú rẹ; wọ́n ní ìgbẹ́kẹ̀lé, ìwọ sì gbà wọ́n.
5 Do ciebie wołali i zostali wybawieni, tobie ufali i się nie zawiedli.
Ìwọ ni wọ́n sun ẹkún sí, wọ́n sì ní ìgbàlà; ìwọ ni wọ́n gbẹ́kẹ̀lé, a kò sì dójútì wọ́n.
6 Ja zaś jestem robakiem, a nie człowiekiem, pośmiewiskiem ludzi i wzgardą ludu.
Ṣùgbọ́n kòkòrò ní mo jẹ́, kì í sì í ṣe ènìyàn; mo di ẹlẹ́gàn àwọn ènìyàn, ẹlẹ́yà àwọn ènìyàn.
7 Wszyscy, którzy mnie widzą, szydzą ze mnie, wykrzywiają usta, potrząsają głową, [mówiąc]:
Gbogbo àwọn tí ó rí mí fi mí ṣe ẹlẹ́yà; wọ́n yọ ètè ẹ̀gàn wọn sí mi, wọ́n sì ń mi orí wọn pé.
8 Zaufał PANU, niech go wyzwoli; niech go ocali, skoro go kocha.
“Ó gbẹ́kẹ̀ rẹ̀ lé Olúwa; jẹ́ kí Olúwa gbà á là. Jẹ́ kí ó gbà á là, nítorí pé, ó ní ayọ̀ nínú rẹ̀.”
9 Ale to ty mnie wydobyłeś z łona, napełniłeś mnie ufnością jeszcze u piersi mojej matki.
Síbẹ̀ ìwọ ni ó ti mú mi wá láti inú; ìwọ ni ó mú mi wà láìléwu, nígbà tí mo rọ̀ mọ́ ọmú ìyá mi.
10 Na ciebie byłem zdany od narodzenia, od łona matki ty jesteś moim Bogiem.
Ìwọ ni a fi mí lé lọ́wọ́ láti inú ìyá mi wá, nígbà tí ìyá mí sì ti bí mi, ìwọ ni Ọlọ́run mi.
11 Nie oddalaj się ode mnie, bo utrapienie bliskie, a nie ma nikogo, kto by [mnie] wspomógł.
Má ṣe jìnnà sí mi, nítorí pé ìyọnu súnmọ́ tòsí kò sì ṣí ẹnìkan tí yóò ṣe ìrànlọ́wọ́.
12 Otoczyło mnie mnóstwo cielców, osaczyły mnie byki Baszanu.
Ọ̀pọ̀ akọ màlúù yí mi ká; àwọn màlúù alágbára Baṣani rọ̀gbà yí mi ká.
13 Rozwarły na mnie swe paszcze jak lew drapieżny i ryczący.
Wọ́n ya ẹnu wọn sì mi bí i kìnnìún tí ń dọdẹ kiri, tí ń ké ramúramù.
14 Rozpłynąłem się jak woda i rozłączyły się wszystkie moje kości; moje serce stało się jak wosk, roztopiło się w moim wnętrzu.
A dà mí jáde gẹ́gẹ́ bí omi, gbogbo egungun mi ti yẹ̀ kúrò ní oríkèé rẹ̀. Ọkàn mi sì dàbí i ìda; tí ó yọ́ láàrín inú mi.
15 Moja siła wyschła jak skorupa, a mój język przylgnął do podniebienia; położyłeś mnie w prochu śmierci.
Agbára mí ti gbẹ bí àpáàdì, ahọ́n mí sì tilẹ̀ mọ́ párí ẹ̀rẹ̀kẹ́ ẹ mi; ìwọ ti tẹ́ mi sínú eruku ikú. (questioned)
16 Psy bowiem mnie osaczyły, obległa mnie zgraja złoczyńców; przebili moje ręce i nogi.
Àwọn ajá yí mi ká; ìjọ àwọn ènìyàn ibi ti ká mi mọ́, wọ́n gún mi lọ́wọ́, wọ́n sì gún mi lẹ́sẹ̀.
17 Mogę policzyć wszystkie moje kości; a oni patrzą na mnie, przypatrują się.
Mo lè ka gbogbo àwọn egungun mi; àwọn tìkára wọn ń wò, wọ́n dójú lé mi.
18 Dzielą między siebie moje szaty i o moją tunikę rzucają losy.
Wọ́n pín aṣọ mi láàrín ara wọn àní lórí aṣọ mi ni wọ́n ṣẹ́ gègé.
19 Ale ty, PANIE, nie oddalaj się; mocy moja, spiesz mi na ratunek.
Ṣùgbọ́n ìwọ, Olúwa, má ṣe jìnnà sí mi. Háà! Olùrànlọ́wọ́ ọ̀ mi, yára wá fún àtìlẹ́yìn mi!
20 Ocal od miecza moją duszę, od mocy psów cenną [duszę] moją.
Gba ọkàn mi sílẹ̀ lọ́wọ́ idà, àní ẹ̀mí mi lọ́wọ́ agbára àwọn ajá.
21 Wybaw mnie z lwiej paszczy, [bo] i od rogów jednorożców mnie ocaliłeś.
Gba ọkàn mi sílẹ̀ lọ́wọ́ kìnnìún; kí o sì gbà mí sílẹ̀ lọ́wọ́ ìwo àgbáǹréré.
22 Będę głosił twoje imię moim braciom, będę cię chwalił pośród zgromadzenia.
Èmi yóò kéde orúkọ rẹ láàrín arákùnrin àti arábìnrin mi; nínú ìjọ ni èmi yóò máa yìn ọ́.
23 Chwalcie PANA, wy, którzy się go boicie; wysławiajcie go, całe potomstwo Jakuba; bójcie się go, wszyscy potomkowie Izraela.
Ẹ̀yin tí ẹ bẹ̀rù Olúwa, ẹ yìn ín! Gbogbo ẹ̀yin ìran Jakọbu, ẹ fi ògo fún un! Ẹ dìde fún un tẹ̀rù tẹ̀rù, ẹ̀yin irú-ọmọ Israẹli!
24 Bo nie wzgardził ani się nie brzydził utrapieniem ubogiego, ani nie ukrył przed nim swego oblicza, lecz gdy [ten] do niego wołał, wysłuchał go.
Nítorí pé òun kò ṣátá, bẹ́ẹ̀ ni kò sì kórìíra ìpọ́njú àwọn tí a ni lára; kò sì fi ojú rẹ̀ pamọ́ fún mi ṣùgbọ́n ó gbọ́ nígbà tí mo ké pè é.
25 Od ciebie [pochodzi] moja chwała w wielkim zgromadzeniu; wypełnię swoje śluby wobec tych, którzy się ciebie boją.
Láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ ni ìyìn mi yóò ti wá nínú àjọ ńlá; ẹ̀jẹ́ rẹ̀ ni èmi yóò san níwájú àwọn tí o bẹ̀rù rẹ̀
26 Ubodzy będą jeść i nasycą się, chwalić PANA będą ci, którzy go szukają; wasze serce będzie żyć na wieki.
tálákà yóò jẹ yóò sì yó; àwọn tí n wá Olúwa yóò yin jẹ́ kí ẹ̀mí rẹ̀ wà láààyè títí ayérayé!
27 Przypomną sobie i nawrócą się do PANA wszystkie krańce ziemi i oddadzą pokłon przed twoim obliczem wszystkie rodziny narodów.
Gbogbo òpin ayé ni yóò rántí wọn yóò sì yípadà sí Olúwa, àti gbogbo ìdílé orílẹ̀-èdè ni wọn yóò jọ́sìn níwájú rẹ̀,
28 Do PANA bowiem należy królestwo i on panuje nad narodami.
nítorí ìjọba ni ti Olúwa. Òun ni ó ń pàṣẹ lórí àwọn orílẹ̀-èdè.
29 Wszyscy bogaci ziemi będą jeść i oddawać mu pokłon, upadną przed jego obliczem wszyscy, którzy zstępują w proch, którzy nie mogą swej duszy zachować przy życiu.
Bẹ́ẹ̀ náà ni gbogbo àwọn olówó ayé wọn yóò ṣe àsè, wọn yóò sì sìn; gbogbo àwọn tí ó wọ inú ilẹ̀ lọ yóò kúnlẹ̀ ní iwájú rẹ̀ àti ẹni tí kò lè pa ọkàn ara rẹ̀ mọ́ ni ààyè.
30 Potomstwo będzie mu służyć i będzie poczytane Panu za pokolenie.
Irú-ọmọ rẹ̀ yóò sìn ín; a ó sọ fún àwọn ìran tí ń bọ̀ nípa Olúwa.
31 Przyjdą i ludowi, który się narodzi, opowiedzą jego sprawiedliwość – że on tak uczynił.
Wọn yóò polongo òdodo rẹ̀ sí àwọn ọmọ tí a kò tí ì bí, wí pé, òun ni ó ṣe èyí.

< Psalmów 22 >