< Psalmów 20 >

1 Przewodnikowi chóru. Psalm Dawida. Niech cię wysłucha PAN w dniu utrapienia, niech cię chroni imię Boga Jakuba.
Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi. Kí Olúwa kí ó gbóhùn rẹ ní ọjọ́ ìpọ́njú; kí orúkọ Ọlọ́run Jakọbu kí ó dáàbò bò ọ́.
2 Niech ci ześle pomoc ze świątyni i niech cię wesprze z Syjonu.
Kí ó rán ìrànlọ́wọ́ sí ọ, láti ibi mímọ́ kí ó sì tì ọ́ lẹ́yìn láti Sioni wá.
3 Niech pamięta wszystkie twoje ofiary i niech przyjmie twoje całopalenia. (Sela)
Kí ó sì rántí gbogbo ẹbọ rẹ kí ó sì gba ẹbọ sísun rẹ. (Sela)
4 Niech da ci [wszystko], czego pragnie twoje serce, i każdy twój zamysł niech wypełni.
Kí ó fi fún ọ gẹ́gẹ́ bi ti èrò ọkàn rẹ kí ó sì mú gbogbo ìmọ̀ rẹ ṣẹ.
5 Będziemy się radować z twojego zbawienia i w imię naszego Boga sztandary podniesiemy. Niech PAN spełni wszystkie twoje prośby.
Àwa yóò hó fún ayọ̀ nígbà tí o bá di aṣẹ́gun àwa yóò gbé àsíá wa sókè ní orúkọ Ọlọ́run wa. Kí Olúwa kí ó mú gbogbo ìbéèrè rẹ̀ ṣẹ.
6 Teraz wiem, że PAN wybawia swego pomazańca, wysłucha go ze swego świętego nieba zbawczą mocą swojej prawicy.
Nísinsin yìí, èmi mọ̀ wí pé, Olúwa pa ẹni àmì òróró rẹ̀ mọ́. Yóò gbọ́ láti ọ̀run mímọ́ rẹ̀ wá pẹ̀lú agbára ìgbàlà ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀.
7 Jedni [pokładają ufność] w rydwanach, inni w koniach, lecz my będziemy wspominać imię PANA, naszego Boga.
Àwọn mìíràn gbẹ́kẹ̀ wọn lé kẹ̀kẹ́, àwọn mìíràn gbẹ́kẹ̀ wọn lé ẹṣin, ṣùgbọ́n àwa gbẹ́kẹ̀lé orúkọ Olúwa Ọlọ́run wa.
8 Tamci zachwiali się i upadli, a my powstaliśmy i ostoimy się.
Wọ́n wólẹ̀, ní eékún, wọ́n sì ṣubú, ṣùgbọ́n àwa dìde, a sì dúró ṣinṣin.
9 PANIE, wybaw [nas], a król niech nas wysłucha w dniu naszego wołania.
Olúwa, fi ìṣẹ́gun fún ọba! Dá wa lóhùn nígbà tí a bá ń kígbe pè!

< Psalmów 20 >