< Psalmów 17 >
1 Modlitwa Dawida. Wysłuchaj, PANIE, [mojej] słusznej sprawy, zważ na moje wołanie, nakłoń ucha na modlitwę moich nieobłudnych ust.
Àdúrà ti Dafidi. Gbọ́, Olúwa, ẹ̀bẹ̀ òtítọ́ mi; fi etí sí igbe mi. Tẹ́tí sí àdúrà mi tí kò ti ètè ẹ̀tàn jáde.
2 Niech wyrok o mnie wyjdzie sprzed twego oblicza, niech twoje oczy widzą to, co słuszne.
Kí ìdáláre mi wá láti ọ̀dọ̀ rẹ; kí ojú rẹ kí ó rí ohun tí ó tọ́.
3 Doświadczyłeś moje serce, nawiedziłeś [mnie] nocą, wypróbowałeś mnie ogniem, ale nic nie znalazłeś. Postanowiłem, że moje usta nie zgrzeszą.
Ìwọ ti dán àyà mi wò, ìwọ sì bẹ̀ mí wò ní òru, o sì ti wádìí mi, ìwọ kì yóò rí ohunkóhun èmi ti pinnu pé, ẹnu mi kì yóò ṣẹ̀.
4 Co się tyczy spraw ludzkich, dzięki słowom twoich ust wystrzegałem się dróg okrutnika.
Bí ó ṣe ti iṣẹ́ ènìyàn nípa ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ, èmi ti pa ara mi mọ́ kúrò ní ọ̀nà àwọn ìkà.
5 Zatrzymaj moje kroki na twoich drogach, aby nie zachwiały się moje nogi.
Ìrìn mí ti jẹ mọ́ ọ̀nà rẹ; ẹsẹ̀ mi kì yóò yọ̀.
6 Wzywam cię, Boże, bo mnie wysłuchasz. Nakłoń ku mnie swego ucha, wysłuchaj moich słów.
Èmi ké pè ọ́, Ọlọ́run, nítorí tí ìwọ yóò dá mi lóhùn dẹ etí rẹ sí mi kí o sì gbọ́ àdúrà mi.
7 Okaż swoje miłosierdzie, ty, który wybawiasz ufających tobie od tych, którzy powstają przeciwko twojej prawicy.
Fi ìṣeun ìyanu ìfẹ́ ńlá rẹ hàn ìwọ tí ó fi ọwọ́ ọ̀tún rẹ gba àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé ọ là lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá tí ó dìde sí wọn.
8 Strzeż mnie jak źrenicy oka, ukryj mnie w cieniu swych skrzydeł;
Pa mí mọ́ bí ẹyin ojú rẹ; fi mí pamọ́ sí abẹ́ òjìji ìyẹ́ apá rẹ,
9 Przed niegodziwymi, którzy mnie gnębią, [przed] wrogami mojej duszy, którzy mnie osaczyli.
lọ́wọ́ àwọn ènìyàn búburú tí ń fóròó mi, kúrò ní ọwọ́ àwọn ọ̀tá apani tí ó yí mi ká.
10 Okryli się swoim tłuszczem, zuchwale mówią swymi ustami.
Wọ́n pa ọkàn aláìláàánú wọn mọ́, wọ́n sì fi ẹnu wọn sọ̀rọ̀ ìgbéraga.
11 Gdziekolwiek idziemy, otaczają nas, wytężają swój wzrok, aby nas powalić na ziemię.
Wọ́n sì mú mi mọ́lẹ̀, wọ́n sì yí mi ká, pẹ̀lú ojú ìṣọ́ra láti ṣọ́ mi sílẹ̀.
12 Podobni są do lwa żądnego łupu, do lwiątka siedzącego w ukryciu.
Wọn dàbí i kìnnìún tí ebi ń pa fún ìjẹ, àní bí kìnnìún ńlá tí ó ń ba níbi ìkọ̀kọ̀.
13 Powstań, PANIE, wystąp przeciwko niemu i powal go, swoim mieczem ocal moją duszę od niegodziwego;
Dìde, Olúwa, dojúkọ wọ́n, rẹ̀ wọ́n sílẹ̀; gbà mí sílẹ̀ lọ́wọ́ ẹni búburú nípa idà rẹ.
14 A swoją ręką, PANIE, od ludzi, od ludzi tego świata, których udziałem jest to życie, a których brzuchy napełniasz swymi skarbami, tak że nasyceni są [nawet] ich synowie, a resztę zostawiają ich dzieciom.
Olúwa, nípa ọwọ́ rẹ, gbà mí kúrò lọ́wọ́ irú àwọn ènìyàn bẹ́ẹ̀, kúrò lọ́wọ́ àwọn ènìyàn ayé yìí, tí èrè wọn wà nínú ayé yìí. Ìwọ ń pa ebi àwọn tí ìwọ fẹ́ràn lẹ́nu mọ́; àwọn ọmọ wọn sì ní ọ̀pọ̀lọpọ̀, wọ́n sì kó ọrọ̀ jọ fún àwọn ọmọ wọn.
15 Ja [zaś] w sprawiedliwości ujrzę twe oblicze, a gdy się obudzę, nasycę się twoim podobieństwem.
Ṣùgbọ́n ní tèmi, èmi yóò máa wo ojú rẹ ní òdodo; nígbà tí èmi bá jí, èmi yóò ní ìtẹ́lọ́rùn nígbà tí èmi bá rí àwòrán rẹ.