< Psalmów 140 >
1 Przewodnikowi chóru. Psalm Dawida. Wybaw mnie, PANIE, od złego człowieka; strzeż mnie od okrutnika;
Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi. Olúwa, gbà mi lọ́wọ́ ọkùnrin búburú u nì, yọ mí lọ́wọ́ ọkùnrin ìkà a nì,
2 [Od tych], którzy knują w sercu złe rzeczy, każdego dnia zbierają się na wojnę.
ẹni tí ń ro ìwà búburú ní inú wọn; nígbà gbogbo ni wọ́n ń rú ìjà sókè sí mi.
3 Wyostrzają swe języki jak węże, jad żmii pod ich wargami. (Sela)
Wọ́n ti pọ́n ahọ́n wọn bí ejò, oró paramọ́lẹ̀ ń bẹ ní abẹ́ ètè wọn.
4 Zachowaj mnie, PANIE, od rąk niegodziwego, strzeż mnie od okrutnika; [od tych], którzy postanowili zwalić mnie z nóg.
Olúwa, pa mí mọ́ kúrò lọ́wọ́ àwọn ènìyàn búburú; yọ mí kúrò lọ́wọ́ ọkùnrin ìkà a nì ẹni tí ó ti pinnu rẹ̀ láti bi ìrìn mi ṣubú.
5 Pyszni zastawili na mnie sidła i [przygotowali] powrozy; rozciągnęli sieci przy ścieżce; zastawili na mnie pułapkę. (Sela)
Àwọn agbéraga ti dẹkùn sílẹ̀ fún mi àti okùn: wọ́n ti na àwọ̀n lẹ́bàá ọ̀nà; wọ́n ti kẹ́kùn sílẹ̀ fún mi.
6 Powiedziałem PANU: Ty jesteś moim Bogiem; wysłuchaj, PANIE, głosu moich błagań.
Èmi wí fún Olúwa pé ìwọ ni Ọlọ́run mi; Olúwa, gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ mi.
7 Panie BOŻE, mocy mego zbawienia, który osłaniasz moją głowę w dniu bitwy;
Olúwa Olódùmarè, agbára ìgbàlà mi, ìwọ ni ó bo orí mi mọ́lẹ̀ ní ọjọ́ ìjà.
8 Nie spełniaj, PANIE, pragnień niegodziwego; nie wspomagaj jego złych zamysłów, aby się nie podniósł. (Sela)
Olúwa, máa ṣe fi ìfẹ́ ènìyàn búburú fún un; má ṣe kún ọgbọ́n búburú rẹ̀ lọ́wọ́; kí wọn kí ó máa ba à gbé ara wọn ga. (Sela)
9 Niech nieprawość ich [własnych] warg okryje wodza tych, którzy mnie otoczyli.
Bí ó ṣe ti orí àwọn tí ó yí mi káàkiri ni, jẹ́ kí ète ìka ara wọn kí ó bò wọ́n mọ́lẹ̀.
10 Niech na nich spadną rozżarzone węgle; niech będą wrzuceni do ognia [i] do głębokich dołów, by już nie powstali.
A ó da ẹ̀yin iná sí wọn lára, Òun yóò wọ́ wọn lọ sínú iná, sínú ọ̀gbun omi jíjìn, kí wọn kí ó má ba à le dìde mọ́.
11 Niech oszczerca nie będzie utwierdzony na ziemi, a człowiek okrutny upadnie przygnieciony złem.
Má ṣe jẹ́ kí aláhọ́n búburú fi ẹsẹ̀ múlẹ̀ ní ayé; ibi ni yóò máa dọdẹ ọkùnrin ìkà nì láti bì í ṣubú.
12 Wiem, że PAN ujmie się za strapionym i pomści krzywdę nędzarzy.
Èmi mọ̀ pé, Olúwa yóò mú ọ̀nà olùpọ́njú dúró, yóò sì ṣe ẹ̀tọ́ fún àwọn tálákà.
13 Zaprawdę sprawiedliwi będą wysławiać twoje imię, a prawi będą mieszkać przed twoim obliczem.
Nítòótọ́ àwọn olódodo yóò máa fi ọpẹ́ fún orúkọ rẹ; àwọn ẹni dídúró ṣinṣin yóò máa gbé iwájú rẹ.