< Przysłów 7 >
1 Synu mój, strzeż moich słów i przechowuj u siebie moje przykazania.
Ọmọ mi, pa ọ̀rọ̀ mi mọ́, sì fi àwọn òfin mi pamọ́ sínú ọkàn rẹ.
2 Strzeż moich przykazań, a będziesz żył; [strzeż] mojego prawa jak źrenicy swych oczu.
Pa òfin mi mọ́, ìwọ yóò sì yè tọ́jú ẹ̀kọ́ mi bí ẹyinlójú rẹ.
3 Przywiąż je do swoich palców, wypisz je na tablicy twego serca.
Kọ wọ́n sí ọwọ́ òsì rẹ, má ṣe fi jẹun kọ wọ́n sí inú wàláà àyà rẹ.
4 Mów do mądrości: Jesteś moją siostrą, a roztropność nazywaj przyjaciółką;
Wí fún ọgbọ́n pé, “Ìwọ ni arábìnrin mi,” sì pe òye ní ìbátan rẹ.
5 Aby cię strzegły przed cudzą żoną i przed obcą, [która] mówi gładkie słowa.
Wọn yóò pa ó mọ́ kúrò lọ́wọ́ obìnrin alágbèrè, kúrò lọ́wọ́ àjèjì obìnrin àti ọ̀rọ̀ ìtànjẹ rẹ̀.
6 Bo z okna swego domu wyglądałem przez kratę;
Ní ojú fèrèsé ilé è mi mo wo ìta láti ojú fèrèsé.
7 I zobaczyłem wśród prostych, zauważyłem wśród chłopców nierozumnego młodzieńca;
Mo rí i láàrín àwọn aláìmọ̀kan mo sì kíyèsi láàrín àwọn ọ̀dọ́kùnrin, ọ̀dọ́ kan tí ó ṣe aláìgbọ́n.
8 Który przechodził ulicą blisko jej narożnika, idąc drogą do jej domu.
Ó ń lọ ní pópónà ní tòsí i ilé alágbèrè obìnrin náà, ó ń rìn lọ sí ọ̀nà ilé e rẹ̀.
9 O zmierzchu, pod wieczór, w ciemności nocnej i w mroku.
Ní ìrọ̀lẹ́ bí oòrùn ṣe ń wọ̀, bí òkùnkùn ṣe ń bo ni lára.
10 A oto spotkała go kobieta w stroju nierządnicy, chytrego serca;
Bẹ́ẹ̀ ni obìnrin kan jáde wá láti pàdé rẹ̀, ó múra bí panṣágà pẹ̀lú ètè búburú.
11 Wrzaskliwa i nieopanowana, której nogi nie mogą pozostać w domu:
(Ó jẹ́ aláriwo àti alágídí, ìdí rẹ̀ kì í jókòó nílé;
12 Raz na dworze, raz na ulicach i czyha na każdym rogu.
bí ó ti ń já níhìn-ín ní ó ń já lọ́hùn ún gbogbo orígun ni ó ti ń ba ní ibùba.)
13 Chwyciła go i pocałowała, z bezczelną miną powiedziała do niego:
Ó dìímú, ó sì fẹnukò ó ní ẹnu pẹ̀lú ojú díndín ó wí pé,
14 U mnie są ofiary pojednawcze; spełniłam dzisiaj swoje śluby.
“Mo ní ọrẹ àlàáfíà ní ilé; lónìí ni mo san ẹ̀jẹ́ mi.
15 Dlatego wyszłam ci naprzeciw, szukałam pilnie twojej twarzy i znalazłam cię.
Nítorí náà ni n o ṣe jáde wá pàdé è rẹ; mo wá ọ káàkiri mo sì ti rí ọ!
16 Obiłam kobiercami swoje łoże, [przystrojone] rzeźbieniem i prześcieradłami z Egiptu.
Mo ti tẹ́ ibùsùn mi pẹ̀lú aṣọ aláràbarà láti ilẹ̀ Ejibiti.
17 Skropiłam swoje posłanie mirrą, aloesem i cynamonem.
Mo ti fi nǹkan olóòórùn dídùn sí ibùsùn mi bí i òjìá, aloe àti kinamoni.
18 Chodź, upójmy się miłością aż do rana, nacieszmy się miłością.
Wá, jẹ́ kí a lo ìfẹ́ papọ̀ ní kíkún títí di àárọ̀; jẹ́ kí a gbádùn ara wa pẹ̀lú ìfẹ́!
19 Bo [mojego] męża nie ma w domu; pojechał w daleką drogę.
Ọkọ ọ̀ mi ò sí nílé; ó ti lọ sí ìrìnàjò jíjìn.
20 Wziął ze sobą worek pieniędzy; umówionego dnia wróci do domu.
Ó mú owó púpọ̀ lọ́wọ́ kò sì ní darí dé kí ó tó di ọ̀sán.”
21 Nakłoniła go mnóstwem swoich słów i zniewoliła go pochlebstwem swoich warg.
Pẹ̀lú ọ̀rọ̀ dídùn ó sì í lọ́nà; ó tàn án jẹ pẹ̀lú ẹnu dídùn.
22 Wnet poszedł za nią jak wół prowadzony na rzeź i jak głupi na karę pęt.
Òun sì tọ̀ ọ́ lọ lẹsẹ̀ kan náà, bí i màlúù tí ń lọ sí ibi pípa, tàbí bí àgbọ̀nrín tí ń lọ sí ibi okùn ìso.
23 Aż strzała przebije mu wątrobę; spieszy jak ptak w sidła, nie wiedząc, że [chodzi] o jego życie.
Títí tí ọ̀kọ̀ fi gún un ní ẹ̀dọ̀, bí ẹyẹ ṣe ń fẹ́ wọ inú okùn, láìmọ̀ pé yóò gba ẹ̀mí òun.
24 Więc teraz słuchajcie mnie, synowie, i zważajcie na słowa moich ust.
Nítorí náà báyìí ẹ̀yin ọmọ mi, tẹ́tí sí mi fọkàn sí nǹkan tí mo sọ.
25 Niech twoje serce nie zbacza na jej drogi i nie tułaj się po jej ścieżkach.
Má ṣe jẹ́ kí ọkàn rẹ kí ó yà sí ọ̀nà rẹ̀, tàbí kí ó rìn lọ sí ipa ọ̀nà rẹ̀.
26 Bo wielu zranionych strąciła i wielu mocarzy pozabijała.
Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn tí ó ti fà lulẹ̀. Ogunlọ́gọ̀ àwọn alágbára ni ó ti pa.
27 Jej dom [jest] drogą do piekła, która wiedzie do komnat śmierci. (Sheol )
Ilé e rẹ̀ ni ọ̀nà tààrà sí isà òkú, tí ó lọ tààrà sí àgbàlá ikú. (Sheol )