< Przysłów 21 >
1 Serce króla [jest] w ręku PANA [jak] potoki wód; kieruje je, dokąd chce.
Ọkàn ọba ń bẹ lọ́wọ́ Olúwa; a máa darí rẹ̀ lọ ibi tí ó fẹ́ bí ipa omi.
2 Wszelka droga człowieka jest słuszna w jego oczach, ale PAN waży serca.
Gbogbo ọ̀nà ènìyàn dàbí i pé ó dára lójú rẹ̀, ṣùgbọ́n, Olúwa ló ń díwọ̀n ọkàn.
3 Czynienie sprawiedliwości i sądu bardziej się podobają PANU niż ofiara.
Ṣíṣe ohun tí ó dára tí ó sì tọ̀nà ó ṣe ìtẹ́wọ́gbà sí Olúwa ju ẹbọ lọ.
4 Wyniosłe oczy, pyszne serce [i] praca niegodziwych są grzechem.
Ojú tí ó gbéga àti ọkàn ìgbéraga, ìmọ́lẹ̀ àwọn ènìyàn búburú, ẹ̀ṣẹ̀ ni!
5 Myśli pracowitego [przynoszą] pewny dostatek, a [myśli] każdego spieszącego się – niedostatek.
Ètè àwọn olóye jásí èrè bí ìkánjú ṣe máa ń fa òsì kíákíá.
6 Gromadzenie skarbów kłamliwym językiem jest przemijającą marnością tych, którzy szukają śmierci.
Ìṣúra tí a kójọ nípasẹ̀ ahọ́n tí ń parọ́ jẹ́ ìrì lásán àti ìkẹ́kùn ikú.
7 Grabież niegodziwych zniszczy ich, bo nie chcą czynić tego, co sprawiedliwe.
Ìwà ipá àwọn ènìyàn búburú yóò wọ́ wọn lọ, nítorí wọ́n kọ̀ láti ṣe ohun tí ó tọ́.
8 Droga człowieka jest przewrotna i obca, ale dzieło czystego jest prawe.
Ọ̀nà ẹlẹ́ṣẹ̀ kún fún ìwà ẹ̀ṣẹ̀ ṣùgbọ́n iṣẹ́ onínú funfun jẹ́ títọ́.
9 Lepiej mieszkać w kącie dachu niż z kłótliwą żoną w przestronnym domu.
Ó sàn láti máa gbé ní kọ̀rọ̀ orí òrùlé ju láti ṣe àjọpín ilé pẹ̀lú aya oníjà.
10 Dusza niegodziwego pragnie zła, a jego bliźni nie znajduje łaski w jego oczach.
Ènìyàn búburú ń fẹ́ ibi aládùúgbò rẹ̀ kì í rí àánú kankan gbà lọ́dọ̀ rẹ̀.
11 Gdy się karze szydercę, prosty mądrzeje, a gdy uczą mądrego, przyjmuje wiedzę.
Nígbà tí a bá ń fìyà jẹ ẹlẹ́gàn, òpè a máa kọ́gbọ́n, nígbà tí a bá sì kọ́ ọlọ́gbọ́n yóò ní ìmọ̀.
12 Sprawiedliwy zważa na dom niegodziwego, ale [Bóg] powala niegodziwych za [ich] nieprawość.
Olódodo ṣàkíyèsí ilé ènìyàn búburú ó sì mú ènìyàn búburú wá sí ìparun.
13 Kto zatyka swe ucho na wołanie ubogiego, ten sam będzie wołał, a nie zostanie wysłuchany.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá ti di etí rẹ̀ sí igbe olùpọ́njú, òun tìkára rẹ̀ yóò ké pẹ̀lú; ṣùgbọ́n a kì yóò gbọ́.
14 [Potajemny] dar łagodzi zapalczywość i upominek w zanadrzu uspokaja wielki gniew.
Ọ̀rẹ́ ìkọ̀kọ̀, mú ìbínú kúrò: àti owó àbẹ̀tẹ́lẹ̀ láti ibi ìkọ̀kọ̀ wá, dẹ́kun ìbínú líle.
15 Radością jest dla sprawiedliwego czynić sąd, a na czyniących nieprawość przyjdzie zniszczenie.
Ayọ̀ ni fún olódodo láti ṣe ìdájọ́: ṣùgbọ́n ìparun ni fún àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀.
16 Człowiek, który zbacza z drogi mądrości, odpocznie w zgromadzeniu umarłych.
Ẹni tí ó bá yà kúrò ní ọ̀nà òye, yóò máa gbé inú ìjọ àwọn òkú.
17 Kto kocha zabawę, zubożeje, a kto kocha wino i olejek, nie wzbogaci się.
Ẹni tí ó bá fẹ́ afẹ́, yóò di tálákà: ẹni tí ó fẹ́ ọtí wáìnì pẹ̀lú òróró kò le lọ́rọ̀.
18 Niegodziwy [będzie] okupem za sprawiedliwego, a przewrotny – za prawych.
Ènìyàn búburú ni yóò ṣe owó ìràpadà fún olódodo, àti olùrékọjá fún ẹni dídúró ṣinṣin.
19 Lepiej mieszkać na pustyni niż z kłótliwą i gniewliwą żoną.
Ó sàn láti jókòó ní aginjù ju pẹ̀lú oníjà obìnrin àti òṣónú lọ.
20 Pożądany skarb i olej [są] w mieszkaniu mądrego, ale głupiec je trwoni.
Ìṣúra iyebíye àti òróró wà ní ibùgbé ọlọ́gbọ́n; ṣùgbọ́n òmùgọ̀ ènìyàn n bà á jẹ́.
21 Kto podąża za sprawiedliwością i miłosierdziem, znajduje życie, sprawiedliwość i chwałę.
Ẹni tí ó bá tẹ̀lé òdodo àti àánú yóò rí ìyè, òdodo, àti ọlá.
22 Mądry wdziera się do miasta mocarzy i burzy potęgę ich ufności.
Ọlọ́gbọ́n gòkè odi ìlú àwọn alágbára, ó sì bi ibi gíga agbára ìgbẹ́kẹ̀lé wọn ṣubú.
23 Kto strzeże swoich ust i języka, strzeże swojej duszy przed utrapieniem.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá pa ẹnu àti ahọ́n rẹ̀ mọ́, ó pa ọkàn rẹ̀ mọ́ kúrò nínú ìyọnu.
24 Hardy i pyszny szyderca – oto imię tego, kto działa w pysznym gniewie.
Agbéraga àti alágídí ènìyàn ń gan orúkọ ara rẹ̀ nítorí ó ń hùwà nínú ìwà ìgbéraga rẹ̀, àti nínú ìbínú púpọ̀púpọ̀.
25 Pragnienie leniwego zabija [go], bo jego ręce nie chcą pracować.
Ẹlẹ́rìí èké yóò ṣègbé, àwọn tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀ yóò parun láé; nítorí tí ọwọ́ rẹ̀ kọ iṣẹ́ ṣíṣe.
26 Przez cały dzień pożąda on zachłannie, a sprawiedliwy daje i nie szczędzi.
Ó ń fi ìlara ṣe ojúkòkòrò ní gbogbo ọjọ́: ṣùgbọ́n olódodo a máa fi fún ni kì í sì í dáwọ́ dúró.
27 Ofiara niegodziwych budzi odrazę, a cóż dopiero, gdy ją w niegodziwości ofiarują.
Ẹbọ ènìyàn búburú, ìríra ni: mélòó mélòó ni nígbà tí ó mú un wá pẹ̀lú èrò ìwà ibi?
28 Fałszywy świadek zginie, lecz kto słucha, będzie mówił nieustannie.
Ẹlẹ́rìí èké yóò ṣègbé: ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ ẹni tí ó gbọ́, yóò dúró.
29 Niegodziwy ma upór na twarzy, ale prawy wytycza swoją drogę.
Ènìyàn búburú mú ojú ara rẹ̀ le: ṣùgbọ́n ẹni ìdúró ṣinṣin ni ó ń mú ọ̀nà rẹ̀ tọ́.
30 Nie ma mądrości ani rozumu, ani rady przeciwko PANU.
Kò sí ọgbọ́n, kò sí ìmòye, tàbí ìmọ̀ràn tí ó le mókè níwájú Olúwa.
31 Konia przygotowują na dzień bitwy, ale wybawienie zależy od PANA.
A ń múra ẹṣin sílẹ̀ de ọjọ́ ogun: ṣùgbọ́n ìṣẹ́gun jẹ́ ti Olúwa.