< Liczb 4 >

1 I PAN przemówił do Mojżesza i Aarona tymi słowy:
Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé,
2 Policz synów Kehata spośród synów Lewiego według ich rodzin i według domów ich ojców;
“Ka iye àwọn ọmọ Kohati láàrín àwọn ọmọ Lefi nípa ilé baba wọn àti ìdílé wọn.
3 Od trzydziestego roku życia wzwyż aż do pięćdziesiątego roku życia; wszystkich, którzy są zdolni do służby, aby wykonywali pracę w Namiocie Zgromadzenia.
Ka gbogbo ọkùnrin láti ọmọ ọgbọ̀n ọdún títí dé àádọ́ta ọdún gbogbo àwọn tó ń ṣiṣẹ́ nínú àgọ́ ìpàdé.
4 Służbą synów Kehata w Namiocie Zgromadzenia [będzie troska] o rzeczy najświętsze.
“Wọ̀nyí ni iṣẹ́ ìsìn àwọn ọmọ Kohati nínú àgọ́ àjọ, láti tọ́jú àwọn ohun èlò mímọ́ jùlọ.
5 Gdy obóz będzie ruszał, przyjdzie Aaron ze swymi synami i zdejmą zasłonę okrywającą, którą okryją arkę świadectwa.
Nígbà tí àgọ́ yóò bá tẹ̀síwájú, Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ yóò wọ inú rẹ̀, wọn yóò sí aṣọ ìbòrí rẹ̀, wọn yóò sì fi bo àpótí ẹ̀rí.
6 A położą na niej przykrycie ze skór borsuczych i na tym rozciągną nakrycie z błękitnej [tkaniny], i założą jej drążki.
Wọn yóò sì fi awọ ewúrẹ́ bò ó, lórí awọ ewúrẹ́ yìí ni wọn ó tẹ̀ bọ ààyè rẹ̀.
7 Stół [chlebów] pokładnych również przykryją tkaniną z błękitu i położą na nim misy, czasze, przystawki i kubki do nalewania; a będzie na nim nieustanny chleb.
“Lórí tábìlì àkàrà ìfihàn ni kí wọn ó na aṣọ aláró kan sí, kí wọn kí ó sì fi àwopọ̀kọ́ sórí rẹ̀, àti ṣíbí àti àwokòtò àti ìgò fún ọrẹ ohun mímu; àti àkàrà ìgbà gbogbo ní kí ó wà lórí rẹ̀.
8 I rozciągną na tym tkaninę karmazynową i przykryją to przykryciem ze skór borsuczych, i założą jego drążki.
Lórí gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni wọn yóò da, wọn ó tún fi awọ ewúrẹ́ bò ó, wọn ó sì fi òpó rẹ̀ bọ ààyè rẹ̀.
9 Wezmą też tkaninę z błękitu, którą okryją świecznik do świecenia i jego lampy, szczypce, naczynia na popiół oraz wszystkie jego naczynia na oliwę, których się przy nim używa;
“Kí wọn kí ó sì mú aṣọ aláwọ̀ aláró kan, kí wọn kí ó sì fi bo ọ̀pá fìtílà àti fìtílà rẹ̀, àti alumagaji rẹ̀, àti àwo alumagaji rẹ̀, àti gbogbo ohun èlò òróró rẹ̀, èyí tí wọ́n fi ń ṣe iṣẹ́ rẹ̀.
10 I owiną go wraz ze wszystkimi jego naczyniami przykryciem ze skór borsuczych i umieszczą na drążkach.
Kí wọn ó fi awọ ẹran yí fìtílà àti gbogbo ohun èlò rẹ, kí wọn kí ó sì gbé e lé orí férémù tí wọn yóò fi gbé e.
11 Rozciągną nad złotym ołtarzem tkaninę z błękitu i przykryją go przykryciem ze skór borsuczych, i założą jego drążki.
“Ní orí pẹpẹ wúrà ni kí wọn ó tẹ́ aṣọ aláró kan sí, wọn yóò sì fi awọ seali bò ó, kí wọ́n sì fi òpó rẹ̀ bọ ààyè rẹ̀.
12 Wezmą też wszystkie sprzęty do służby, którymi służą w świątyni, owiną je tkaniną z błękitu, przykryją je okryciem ze skór borsuczych i umieszczą na drążkach.
“Kí wọn kó gbogbo ohun èlò tí wọ́n ń lò fún iṣẹ́ ìsìn ní ibi mímọ́, kí wọn ó fi aṣọ aláwọ̀ búlúù yìí, kí wọn ó sì fi awọ seali bò ó, kí wọn ó sì fi gbé wọn ka orí férémù.
13 Następnie oczyszczą ołtarz z popiołu i rozciągną na nim purpurową tkaninę;
“Kí wọn ó kó eérú kúrò lórí pẹpẹ idẹ, kí wọn ó sì tẹ́ aṣọ aláwọ̀ àlùkò lé e lórí.
14 I położą na nim wszystkie jego sprzęty używane do służby przy nim: kadzielnice, widełki, łopatki i kropielnice, wszystkie naczynia ołtarza, i rozciągną na nim przykrycie ze skór borsuczych, i założą jego drążki.
Nígbà náà ni kí wọn ó kó gbogbo ohun èlò fún iṣẹ́ ìsìn níbi pẹpẹ, títí dórí àwo iná, fọ́ọ̀kì ẹran, ọkọ́ eérú àti àwokòtò. Kí wọn ó fi awọ ewúrẹ́ bo gbogbo rẹ̀, kí wọn ó sì fi òpó rẹ̀ bọ ààyè rẹ̀.
15 Kiedy Aaron i jego synowie skończą przykrywanie świątyni wraz ze wszystkimi jej naczyniami, gdy obóz będzie miał wyruszyć, wtedy przyjdą synowie Kehata, aby [je] nieść. Lecz nie będą dotykać świętych przedmiotów, aby nie umarli. To jest służba synów Kehata przy Namiocie Zgromadzenia.
“Lẹ́yìn tí Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ ti parí bíbo ibi mímọ́ àti gbogbo ohun èlò ibi mímọ́, nígbà tí àgọ́ bá sì ṣetán láti tẹ̀síwájú, kí àwọn ọmọ Kohati bọ́ síwájú láti gbé e, ṣùgbọ́n wọn kò gbọdọ̀ fọwọ́ kan ohun mímọ́ kankan, bí wọ́n bá ṣe bẹ́ẹ̀ wọn ó kú. Àwọn ọmọ Kohati ni yóò gbé gbogbo ohun tó wà nínú àgọ́ ìpàdé.
16 A Eleazar, syn kapłana Aarona, [będzie troszczył się] o oliwę do oświetlenia, wonne kadzidło, stałą ofiarę pokarmową i oliwę do namaszczania oraz będzie doglądał przybytku i wszystkiego, co w nim jest, i w miejscu świętym i przy jego naczyniach.
“Iṣẹ́ Eleasari ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà ni ṣíṣe àbojútó òróró fìtílà, tùràrí dídùn, ẹbọ ohun jíjẹ ìgbà gbogbo àti òróró ìtasórí. Kí ó jẹ́ alábojútó gbogbo ohun tó jẹ mọ́ àgọ́ àti gbogbo ohun tó wà nínú rẹ̀, pẹ̀lú gbogbo ohun èlò ibi mímọ́.”
17 Potem PAN powiedział do Mojżesza i Aarona:
Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé,
18 Nie pozwólcie, by pokolenie rodzin Kehatytów zostało wycięte spośród Lewitów.
“Rí i pé a kò gé ẹ̀yà Kohati kúrò lára àwọn ọmọ Lefi.
19 Ale to im uczynicie, aby żyli i nie pomarli, gdy będą się zbliżać do rzeczy najświętszych: Aaron i jego synowie przyjdą i wyznaczą każdemu z nich, co ma czynić i co ma nieść.
Nítorí kí wọ́n lè yè, kí wọ́n má ba à kú nígbà tí wọ́n bá súnmọ́ tòsí àwọn ohun mímọ́ jùlọ: Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ ni kí ó wọ ibi mímọ́ láti pín iṣẹ́ oníkálùkù àti àwọn ohun tí wọn yóò gbé.
20 Lecz niech nie wchodzą się przyglądać, kiedy rzeczy święte będą przykrywane, by nie pomarli.
Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Kohati kò gbọdọ̀ wọlé láti wo àwọn ohun mímọ́, bó tilẹ̀ jẹ́ ìṣẹ́jú kan, bí wọ́n bá ṣe bẹ́ẹ̀, wọn yóò kú.”
21 PAN dalej mówił do Mojżesza:
Olúwa sọ fún Mose pé,
22 Policz synów Gerszona według domów ich ojców i według ich rodzin;
“Tún ka iye àwọn ọmọ Gerṣoni nípa ilé baba wọn àti ìdílé wọn.
23 Policz tych, którzy są w wieku od trzydziestu lat wzwyż aż do lat pięćdziesięciu; wszystkich, którzy są zdolni do tej pracy, aby mogli pełnić służbę przy Namiocie Zgromadzenia.
Ka gbogbo ọkùnrin láti ọmọ ọgbọ̀n ọdún títí dé àádọ́ta ọdún, gbogbo àwọn tó ń wá ṣiṣẹ́ ní àgọ́ ìpàdé.
24 A to będzie zadanie rodzin Gerszonitów, do służby i do noszenia.
“Èyí ni iṣẹ́ ìsìn ìdílé àwọn ọmọ Gerṣoni, bí wọ́n ti ń ṣiṣẹ́ àti ní ẹrù rírù.
25 Będą nosić zasłony przybytku, Namiot Zgromadzenia, jego przykrycie i przykrycie borsucze, które jest na wierzchu, oraz zasłonę u wejścia do Namiotu Zgromadzenia;
Àwọn ni yóò máa ru àwọn aṣọ títa ti àgọ́, ti àgọ́ ìpàdé àti ìbòrí rẹ̀, àti awọ ewúrẹ́ tí a fi bò ó, aṣọ títa ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé,
26 Zasłony dziedzińca i zasłonę u bramy wejściowej na dziedziniec, który otacza przybytek i ołtarz wokoło, ich sznury i wszystkie przybory do pracy przy nich oraz wszystko, co jest do tego zrobione; tak będą służyć.
aṣọ títa ti àgbàlá tó yí àgọ́ àti pẹpẹ ká, aṣọ títa ti ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé sí àgbàlá, okùn àti àwọn ohun èlò iṣẹ́ ìsìn, àti ohun gbogbo tí à ń lò fún wọn, bẹ́ẹ̀ ni wọn ó máa sìn. Àwọn ọmọ Gerṣoni ni yóò ṣe gbogbo ohun tó bá yẹ pẹ̀lú àwọn nǹkan wọ̀nyí.
27 Wszelka służba synów Gerszonitów związana ze wszystkimi ich ciężarami oraz z całą ich służbą ma odbywać się zgodnie z rozkazem Aarona i jego synów; i powierzycie im troskę o wszystkie ich ciężary.
Gbogbo iṣẹ́ ìsìn àwọn ọmọ Gerṣoni yálà ni iṣẹ́ ṣíṣe tàbí ní ẹrù rírù ni, Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ ni yóò máa darí wọn; ìwọ ni kí o sì yàn ẹrù tí oníkálùkù yóò rù fún un.
28 To będzie zadanie rodzin synów Gerszonitów w Namiocie Zgromadzenia, a nadzór nad nimi będzie miał Itamar, syn kapłana Aarona.
Èyí ni iṣẹ́ ìdílé àwọn Gerṣoni ni àgọ́ ìpàdé Itamari, ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà ni yóò sì jẹ alábojútó iṣẹ́ wọn.
29 A synów Merariego policzysz według ich rodzin i według domów ich ojców;
“Ka iye àwọn ọmọ Merari nípa ilé baba wọn àti ìdílé wọn.
30 Policzysz tych, którzy są w wieku od trzydziestu lat wzwyż aż do lat pięćdziesięciu, wszystkich zdolnych do tej pracy, aby mogli pełnić służbę przy Namiocie Zgromadzenia.
Ka gbogbo ọkùnrin láti ọmọ ọgbọ̀n ọdún títí dé àádọ́ta ọdún, gbogbo àwọn tó ń wá ṣiṣẹ́ ní àgọ́ ìpàdé.
31 A to będzie ich zadanie przy służbie w Namiocie Zgromadzenia: [będą nosić] deski przybytku, jego drążki, słupy i podstawki;
Iṣẹ́ tí wọn yóò sì máa ṣe nínú àgọ́ ìpàdé nìyìí: gbígbẹ́ àwọn férémù àgọ́, pákó ìdábùú rẹ̀, òpó àti ihò òpó rẹ̀,
32 Słupy otaczające dziedziniec, ich podstawki, kołki i sznury wraz ze wszystkimi ich przyborami oraz wszystko, co należy do ich służby. A z przedmiotów, które są im powierzone do noszenia, zrobicie wykaz według nazw.
pẹ̀lú gbogbo òpó tó yí àgbàlá ká àti ohun èlò tó jẹ mọ́ lílò wọn, kí o sì yan ohun tí oníkálùkù yóò rù fún un.
33 To będzie zadanie rodzin synów Merariego według całej ich służby przy Namiocie Zgromadzenia pod nadzorem Itamara, syna kapłana Aarona.
Èyí ni iṣẹ́ ìsìn ìdílé àwọn ọmọ Merari, bí wọn yóò ti máa ṣiṣẹ́ ní àgọ́ ìpàdé lábẹ́ àkóso Itamari ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà.”
34 Mojżesz, Aaron i naczelnicy zgromadzenia policzyli synów Kehata według ich rodzin i według domów ich ojców;
Mose àti Aaroni pẹ̀lú àwọn olórí ìjọ ènìyàn ka àwọn ọmọ Kohati nípa ìdílé àti ilé baba wọn.
35 Tych będących w wieku od trzydziestu lat wzwyż aż do lat pięćdziesięciu, którzy byli zdolni do tej pracy, aby mogli pełnić służbę przy Namiocie Zgromadzenia.
Gbogbo ọmọkùnrin láti ọmọ ọgbọ̀n ọdún títí dé àádọ́ta ọdún gbogbo àwọn tó ń wá ṣiṣẹ́ ní Àgọ́ ìpàdé.
36 A policzonych według ich rodzin było dwa tysiące siedmiuset pięćdziesięciu.
Iye wọn nípa ìdílé jẹ́ ẹgbẹ̀rìnlá ó dín làádọ́ta.
37 Byli to ci policzeni z rodzin Kehatytów, wszyscy, którzy mieli pełnić służbę przy Namiocie Zgromadzenia, których policzyli Mojżesz i Aaron zgodnie z rozkazem PANA przekazanym przez Mojżesza.
Èyí ni àpapọ̀ iye àwọn ọmọ Kohati tó ń ṣiṣẹ́ ní àgọ́ ìpàdé; tí Mose àti Aaroni kà gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún Mose.
38 A policzonych synów Gerszona według ich rodzin i według domów ich ojców;
Wọ́n ka àwọn ọmọ Gerṣoni nípa ìdílé àti ilé baba wọn.
39 Tych, którzy byli w wieku od trzydziestu lat wzwyż aż do lat pięćdziesięciu, zdolnych do pracy, aby mogli pełnić służbę przy Namiocie Zgromadzenia;
Gbogbo ọmọkùnrin láti ọmọ ọgbọ̀n ọdún títí dé àádọ́ta, gbogbo àwọn tó lè ṣiṣẹ́ ní àgọ́ ìpàdé.
40 Policzonych według ich rodzin i domów ich ojców było dwa tysiące sześciuset trzydziestu.
Iye wọn nípa ìdílé àti ilé baba wọn jẹ́ ẹgbẹ̀tàlá ó lé ọgbọ̀n.
41 Byli to ci policzeni z rodzin synów Gerszona, wszyscy, którzy mieli pełnić służbę w Namiocie Zgromadzenia, których policzyli Mojżesz i Aaron zgodnie z rozkazem PANA.
Èyí jẹ́ àpapọ̀ iye àwọn ọmọ Gerṣoni, àwọn tó ṣiṣẹ́ ní àgọ́ ìpàdé. Mose àti Aaroni ṣe bí àṣẹ Olúwa.
42 A policzonych z rodzin synów Merariego według ich rodzin i domów ich ojców;
Wọ́n ka àwọn ọmọ Merari nípa ìdílé àti ilé baba wọn.
43 Tych, którzy byli w wieku trzydziestu lat wzwyż aż do lat pięćdziesięciu, zdolnych do pracy, aby mogli pełnić służbę przy Namiocie Zgromadzenia;
Gbogbo ọkùnrin láti ọmọ ọgbọ̀n ọdún títí dé àádọ́ta ọdún, àwọn tó ṣiṣẹ́ ní àgọ́ ìpàdé.
44 A policzonych według ich rodzin [było] trzy tysiące dwustu.
Iye wọn nípa ìdílé àti ilé baba wọn jẹ́ ẹgbẹ̀rìndínlógún.
45 A to są policzeni z rodzin synów Merariego, których policzyli Mojżesz i Aaron zgodnie z rozkazem PANA przekazanym przez Mojżesza.
Èyí ni àpapọ̀ iye àwọn ọmọ Merari. Mose àti Aaroni kà wọ́n gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Olúwa láti ẹnu Mose.
46 Wszystkich Lewitów policzonych, których policzyli Mojżesz, Aaron i naczelnicy Izraela według ich rodzin i domów ich ojców;
Gbogbo àwọn tí a kà nínú àwọn ọmọ Lefi, ti Mose àti Aaroni àti àwọn olórí Israẹli kà, nípa ìdílé wọn àti gẹ́gẹ́ bí ilé baba wọn.
47 W wieku trzydziestu lat wzwyż aż do lat pięćdziesięciu; wszystkich policzonych, którzy przychodzili pełnić zadanie służby i [noszenia] ciężarów w Namiocie Zgromadzenia;
Gbogbo ọkùnrin láti ọmọ ọgbọ̀n ọdún títí dé àádọ́ta, àwọn tó ń ṣiṣẹ́ ìsìn tó sì ń ru àwọn ẹrù inú Àgọ́ ìpàdé.
48 Było osiem tysięcy pięciuset osiemdziesięciu.
Àpapọ̀ iye wọn jẹ́ ẹgbẹ̀tàlá lé lẹ́gbàarin ó dín ogún.
49 Zgodnie z rozkazem PANA zostali policzeni przez Mojżesza, każdy z osobna według jego służby i według jego ciężaru. Policzono tych, których PAN rozkazał liczyć Mojżeszowi.
Wọ́n yan iṣẹ́ àti àwọn ohun tí ẹni kọ̀ọ̀kan yóò máa gbé fún un gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ láti ẹnu Mose. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe kà wọ́n gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.

< Liczb 4 >