< Liczb 27 >
1 Wtedy przyszły córki Selofchada, syna Chefera, syna Gileada, syna Makira, syna Manassesa, z rodu Manassesa, syna Józefa; a to są imiona jego córek: Machla, Noa, Chogla, Milka i Tirsa.
Ọmọbìnrin Selofehadi ọmọ Heferi, ọmọ Gileadi, ọmọ Makiri ọmọ Manase tó jẹ́ ìdílé Manase, ọmọ Josẹfu wá. Orúkọ àwọn ọmọbìnrin náà ni Mahila, Noa, Hogla, Milka àti Tirsa.
2 I stanęły przed Mojżeszem, przed kapłanem Eleazarem, przed naczelnikami i całym zgromadzeniem u wejścia do Namiotu Zgromadzenia i powiedziały:
Wọ́n súnmọ́ ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé wọ́n sì dúró níwájú Mose, àti Eleasari àlùfáà, àti níwájú àwọn olórí àti ìjọ, wọ́n sì wí pé,
3 Nasz ojciec umarł na pustyni, ale nie należał do zgrai tych, którzy zbuntowali się przeciw PANU w gromadzie Koracha. Umarł za własny grzech, a nie miał synów.
“Baba wa kú sí aginjù. Kò sí lára àwọn ẹgbẹ́ Kora tí wọ́n kó ara wọn pọ̀ lòdì sí Olúwa, ṣùgbọ́n ó kú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ kò sì fi ọmọkùnrin sílẹ̀.
4 Dlaczego imię naszego ojca miałoby zniknąć z jego rodziny przez to, że nie miał syna? Dajcie nam posiadłość pośród braci naszego ojca.
Kín ni ó dé tí orúkọ baba wa yóò parẹ́ nínú ìdílé rẹ̀ nítorí pé kò ní ọmọkùnrin? Fún wa ní ilẹ̀ ìní láàrín àwọn arákùnrin baba wa.”
5 Mojżesz przedstawił więc ich sprawę PANU.
Nígbà náà Mose mú ọ̀rọ̀ wọn wá síwájú Olúwa.
6 I PAN powiedział do Mojżesza:
Olúwa sì wí fún un pé,
7 Córki Selofchada słusznie mówią: Daj im koniecznie dziedziczną posiadłość pośród braci ich ojca, a przenieś na nie dziedzictwo ich ojca.
“Ohun tí àwọn ọmọbìnrin Selofehadi ń sọ tọ̀nà. O gbọdọ̀ fún wọn ní ogún ìní ti baba wọn.
8 I przemów do synów Izraela tak: Jeśli ktoś umrze, a nie miał syna, wtedy przeniesiecie jego dziedzictwo na jego córkę.
“Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, ‘Tí ọkùnrin kan bá kú tí kò sì fi ọmọkùnrin sáyé, ẹ fún àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ ní ogún ìní rẹ̀.
9 A jeśli nie miał córki, to dacie jego dziedzictwo jego braciom.
Tí kò bá ní ọmọbìnrin, fi ohun ìní rẹ́ fún àwọn arákùnrin rẹ̀.
10 A jeśli nie miał braci, to dacie jego dziedzictwo braciom jego ojca.
Tí kò bá ní arákùnrin, fi ogún ìní rẹ̀ fún arákùnrin baba rẹ̀.
11 A jeśli jego ojciec nie miał braci, to dacie jego dziedzictwo najbliższemu krewnemu z jego rodziny, aby je odziedziczył. I będzie to dla synów Izraela ustawą prawną, jak PAN rozkazał Mojżeszowi.
Tí baba rẹ̀ kò bá ní arákùnrin, fún ará ilé rẹ̀ tí ó bá súnmọ́ jù ní ìdílé rẹ̀ ní ogún ìní rẹ̀, kí ó lè jogún rẹ̀. Èyí gbọdọ̀ jẹ́ ìlànà ìdájọ́ fún àwọn ọmọ Israẹli gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.’”
12 Potem PAN powiedział do Mojżesza: Wstąp na tę górę Abarim i spójrz na ziemię, którą dałem synom Izraela.
Nígbà náà Olúwa sọ fún Mose pé, “Lọ sì orí òkè Abarimu yìí, kí o sì lọ wo ilẹ̀ tí mo fún àwọn ọmọ Israẹli.
13 A gdy ją zobaczysz, zostaniesz i ty przyłączony do swego ludu, jak został przyłączony twój brat Aaron.
Lẹ́yìn ìgbà tí o bá sì ti rí i, ìwọ náà yóò darapọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn rẹ gẹ́gẹ́ bí Aaroni arákùnrin rẹ ṣe ṣe,
14 Dlatego że sprzeciwiliście się mojemu rozkazowi na pustyni Syn, podczas buntu zgromadzenia, i nie uświęciliście mnie na ich oczach u tych wód. [To są] wody Meriba w Kadesz, na pustyni Syn.
nítorí nígbà tí ìlú ṣọ̀tẹ̀ níbi omi ní aginjù Sini, tí gbogbo yín ṣe àìgbọ́ràn sí mi láti yà mí sí mímọ́ níwájú wọn.” (Èyí ni omi Meriba ní Kadeṣi ní aginjù Sini.)
15 Wtedy Mojżesz powiedział do PANA:
Mose sọ fún Olúwa wí pé,
16 Niech PAN, Bóg duchów wszelkiego ciała, ustanowi męża nad zgromadzeniem;
“Jẹ́ kí Olúwa, Ọlọ́run ẹ̀mí gbogbo ènìyàn, kí ó yan ọkùnrin kan sí orí ìjọ ènìyàn yìí,
17 Który będzie wychodził przed nim i który będzie wchodził przed nim, który będzie je wyprowadzał i który będzie je przyprowadzał, aby zgromadzenie PANA nie było jak owce, które nie mają pasterza.
láti máa darí wọn, ẹni tí yóò mú wọn jáde, tí yóò sì mú wọn wọlé, gbogbo ènìyàn Olúwa kí yóò dàbí àgùntàn tí kò ní olùṣọ́.”
18 PAN powiedział do Mojżesza: Weź do siebie Jozuego, syna Nuna, męża, w którym jest [mój] Duch, i połóż na nim swoją rękę;
Nígbà náà ní Olúwa sọ fún Mose pé, “Mú Joṣua ọmọ Nuni, ọkùnrin nínú ẹni tí èmi wà, kí o sì gbé ọwọ́ rẹ lé e.
19 I postaw go przed kapłanem Eleazarem i przed całym zgromadzeniem, i na ich oczach daj mu polecenie;
Jẹ́ kí ó dúró níwájú Eleasari àlùfáà àti ojú gbogbo àwọn ìjọ ènìyàn Israẹli kí o sì fi àṣẹ fún un ní ojú wọn.
20 I przenieś na niego część swojej godności, aby [go] słuchało całe zgromadzenie synów Izraela.
Kí ìwọ kí ó sì fi nínú ọláńlá rẹ sí i lára, kí gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli kí ó lè gbọ́rọ̀ sí i lẹ́nu.
21 Będzie on stawał przed kapłanem Eleazarem, aby ten za niego radził się przed PANEM za pośrednictwem sądu Urim. Na jego rozkaz będą wychodzić i na jego rozkaz będą wchodzić – on, a z nim wszyscy synowie Izraela, całe zgromadzenie.
Kí ó dúró níwájú Eleasari àlùfáà, tí yóò gba ìpinnu fún láti béèrè Urimu níwájú Olúwa. Gẹ́gẹ́ bí òfin yìí ni òun pẹ̀lú gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli yóò jáde lọ, pẹ̀lú òfin rẹ̀ sì ni wọn ó wọlé.”
22 I Mojżesz uczynił tak, jak PAN mu rozkazał. Wziął Jozuego i postawił go przed kapłanem Eleazarem i przed całym zgromadzeniem.
Mose sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún un. Ó mú Joṣua ó sì mú kí ó dúró níwájú Eleasari àlùfáà àti níwájú gbogbo ìjọ.
23 Następnie położył na niego swoje ręce i dał mu polecenie, tak jak PAN nakazał przez Mojżesza.
Nígbà náà ni ó gbé ọwọ́ rẹ̀ le e, ó sì fi àṣẹ fún un gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.