< Liczb 16 >

1 Wtedy Korach, syn Ishara, syna Kehata, syna Lewiego, oraz Datan i Abiram, synowie Eliaba, i On, syn Peleta, synowie Rubena, wzięli ludzi;
Kora ọmọ Isari, ọmọ Kohati, ọmọ Lefi àwọn ọmọ Reubeni: Datani àti Abiramu, àwọn ọmọ Eliabu, àti Oni ọmọ Peleti mú ènìyàn mọ́ra.
2 I powstali przeciw Mojżeszowi, a [wraz z nimi] dwustu pięćdziesięciu mężczyzn spośród synów Izraela, naczelników zgromadzenia powołanych do rady, ludzi poważanych.
Wọ́n sì dìde sí Mose, pẹ̀lú àádọ́ta lé nígba ọkùnrin nínú àwọn ọmọ Israẹli, ìjòyè nínú ìjọ, àwọn olórúkọ nínú àjọ, àwọn ọkùnrin olókìkí.
3 Zebrali się oni przeciw Mojżeszowi i Aaronowi i powiedzieli do nich: [Bierzecie] zbyt dużo na siebie! Przecież całe to zgromadzenie, wszyscy oni są święci i wśród nich [jest] PAN. Dlaczego więc wynosicie się ponad zgromadzenie PANA?
Wọ́n kó ara wọn jọ láti tako Mose àti Aaroni, wọ́n sọ fún wọn pé, “Ẹ ti kọjá ààyè yín, ó tó gẹ́ẹ́! Mímọ́ ni gbogbo ènìyàn, kò sí ẹni tí kò mọ́ láàrín wọn, Olúwa sì wà pẹ̀lú wọn, nítorí kí wá ni ẹ̀yin ṣe gbé ara yín ga ju ìjọ ènìyàn Olúwa lọ?”
4 Gdy Mojżesz to usłyszał, upadł na twarz;
Nígbà tí Mose gbọ́ èyí, ó dojúbolẹ̀,
5 I powiedział do Koracha i do całej jego gromady: Jutro rano PAN pokaże, [kto jest] jego, kto jest święty i może zbliżyć się do niego. Kogo bowiem wybrał, temu pozwoli zbliżyć się do siebie.
Ó sì sọ fún Kora àti gbogbo ẹgbẹ́ rẹ̀ pé, “Ní ọ̀la ni Olúwa yóò fi ẹni tí í ṣe tirẹ̀ àti ẹni tó mọ́ hàn, yóò sì mú kí ẹni náà súnmọ́ òun. Ẹni tí ó bá yàn ni yóò mú kí ó súnmọ́ òun.
6 Tak [więc] uczynicie: Weźcie sobie kadzielnice, ty, Korach i cała twoja gromada.
Kí Kora àti gbogbo ẹgbẹ́ rẹ̀ ṣe èyí, ẹ mú àwo tùràrí.
7 I włóżcie w nie ogień, i jutro umieśćcie w nich kadzidło przed PANEM; a ten człowiek, którego PAN wybierze, [będzie] święty. [Bierzecie] zbyt dużo na siebie, synowie Lewiego.
Kí ẹ sì fi iná àti tùràrí sínú rẹ̀ lọ́la níwájú Olúwa, yóò sì ṣe, ọkùnrin tí Olúwa bá yàn òun ni. Ẹ̀yin ọmọ Lefi, ẹ ti kọjá ààyè yín!”
8 I powiedział Mojżesz do Koracha: Słuchajcie, proszę, synowie Lewiego;
Mose sì tún sọ fún Kora pé, “Ẹ gbọ́ báyìí o, ẹ̀yin ọmọ Lefi!
9 Czy wam to mało, że Bóg Izraela oddzielił was od zgromadzenia Izraela, aby zbliżyć was do siebie, abyście pełnili służbę w przybytku PANA i abyście stali przed zgromadzeniem, i mu służyli?
Kò ha tọ́ fún yín pé Ọlọ́run Israẹli ti yà yín sọ́tọ̀ lára ìjọ Israẹli yòókù, tó sì mú yín súnmọ́ ara rẹ̀ láti ṣiṣẹ́ nínú àgọ́ Olúwa àti láti dúró ṣiṣẹ́ ìsìn níwájú àwọn ènìyàn?
10 I ciebie, a wraz z tobą wszystkich twoich braci, synów Lewiego, zbliżył do siebie, a wy jeszcze zabiegacie o kapłaństwo?
Ó ti mú àwọn ènìyàn yín tó jẹ́ ọmọ Lefi súnmọ́ ara rẹ̀, ṣùgbọ́n báyìí ẹ tún ń wá ọnà láti ṣiṣẹ́ àlùfáà.
11 Dlatego ty i cała twoja gromada zbuntowaliście się przeciw PANU, bo kim jest Aaron, że szemracie przeciw niemu?
Olúwa ni ìwọ àti gbogbo ẹlẹgbẹ́ rẹ takò. Ta a ni Aaroni jẹ́ tí ẹ̀yin ó fi kùn sí i?”
12 Wtedy Mojżesz kazał przywołać Datana i Abirama, synów Eliaba, lecz oni odpowiedzieli: Nie przyjdziemy.
Mose sì ránṣẹ́ sí Datani àti Abiramu àwọn ọmọ Eliabu. Ṣùgbọ́n wọ́n wí pé, “Àwa kò ní í wá!
13 Nie dość, że nas wyprowadziłeś z ziemi opływającej mlekiem i miodem, aby nas uśmiercić na tej pustyni, to jeszcze chcesz obwołać się naszym władcą?
Kò ha tó gẹ́ẹ́ pé o ti mú wa jáde láti ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin láti pa wá sínú aginjù yìí? O tún wá fẹ́ sọ ara rẹ di olúwa lé wa lórí bí?
14 Ponadto nie wprowadziłeś nas do ziemi opływającej mlekiem i miodem ani nie dałeś nam w dziedzictwo pól i winnic. Czy chcesz tym mężczyznom wyłupić oczy? Nie przyjdziemy.
Síbẹ̀síbẹ̀ ìwọ kò sì tí ì mú wa dé ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin, bẹ́ẹ̀ ni o kò sì pín ilẹ̀ ìní àti ọgbà àjàrà. Ìwọ ha fẹ́ sọ wá di ẹrú bí? Rárá o, àwa kì yóò gòkè wá!”
15 Wtedy Mojżesz bardzo się rozgniewał i powiedział do PANA: Nie zważaj na ich ofiarę. Nie wziąłem od nich żadnego osła ani też nikogo z nich nie skrzywdziłem.
Nígbà náà ni Mose bínú gidigidi, ó sì sọ fún Olúwa pé, “Má ṣe gba ọrẹ wọn, èmi kò gba kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ lọ́wọ́ wọn, bẹ́ẹ̀ ni n kò sì pa ẹnikẹ́ni nínú wọn lára!”
16 Potem Mojżesz powiedział do Koracha: Ty i cała twoja gromada stawcie się jutro przed PANEM; ty, oni i Aaron:
Mose sọ fún Kora pé, “Ìwọ àti ọmọ lẹ́yìn rẹ gbọdọ̀ fi ara hàn níwájú Olúwa lọ́la—gbogbo yín, ìwọ, àwọn ọmọ lẹ́yìn rẹ àti Aaroni.
17 Każdy z was niech weźmie swoją kadzielnicę i nałoży w nią kadzidła, i niech każdy przyniesie przed PANA swoją kadzielnicę, [razem] dwieście pięćdziesiąt kadzielnic, również ty i Aaron; każdy [przyniesie] swoją kadzielnicę.
Kí ẹnìkọ̀ọ̀kan yín mú àwo tùràrí, kí ó sì fi tùràrí sínú rẹ̀, kí gbogbo rẹ̀ jẹ́ àádọ́ta lé nígba àwo tùràrí kí ẹ sì ko wá síwájú Olúwa. Ìwọ àti Aaroni yóò mú àwo tùràrí wá pẹ̀lú.”
18 Każdy więc wziął swoją kadzielnicę, włożył w nią ogień, nałożył na niego kadzidła i stanęli u wejścia do Namiotu Zgromadzenia [wraz z] Mojżeszem i Aaronem.
Nígbà náà ni oníkálùkù wọn mú àwo tùràrí, wọ́n fi iná àti tùràrí sí i nínú, wọ́n sì dúró sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé, àwọn pẹ̀lú Mose àti Aaroni.
19 A Korach zebrał przeciwko nim całe zgromadzenie u wejścia do Namiotu Zgromadzenia i wtedy chwała PANA ukazała się całemu ludowi.
Nígbà tí Kora kó gbogbo àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ jọ sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé, ògo Olúwa sì farahan gbogbo ìjọ ènìyàn.
20 I PAN powiedział do Mojżesza i Aarona:
Olúwa sì sọ fún Mose àti Aaroni pé,
21 Odłączcie się od tego zgromadzenia, abym [mógł] je w jednej chwili zniszczyć.
“Ẹ ya ara yín sọ́tọ̀ kúrò láàrín ìjọ wọ̀nyí, kí ń ba à le pa wọ́n run lẹ́ẹ̀kan náà.”
22 Lecz oni upadli na twarz i powiedzieli: O Boże, Boże duchów wszelkiego ciała! Czy jeśli zgrzeszy jeden człowiek, będziesz się gniewał na całe zgromadzenie?
Ṣùgbọ́n Mose àti Aaroni dojúbolẹ̀ wọ́n sì kígbe sókè pé, “Ọlọ́run, Ọlọ́run ẹ̀mí gbogbo ènìyàn, Ìwọ ó wa bínú sí gbogbo ìjọ ènìyàn nígbà tó jẹ́ pé ẹnìkan ló ṣẹ̀?”
23 PAN powiedział do Mojżesza:
Olúwa tún sọ fún Mose pé,
24 Przemów do zgromadzenia i powiedz im: Oddalcie się od namiotu Koracha, Datana i Abirama.
“Sọ fún ìjọ ènìyàn pé, ‘Kí wọ́n jìnnà sí àgọ́ Kora, Datani àti Abiramu.’”
25 Mojżesz wstał więc i podszedł do Datana i Abirama, a za nim poszli starsi Izraela.
Mose sì dìde lọ bá Datani àti Abiramu àwọn àgbàgbà Israẹli sì tẹ̀lé.
26 I powiedział do zgromadzenia: Oddalcie się, proszę, od namiotów tych bezbożnych ludzi i nie dotykajcie niczego, co do nich należy, abyście nie zginęli przez wszystkie ich grzechy.
Ó sì kìlọ̀ fún ìjọ ènìyàn pé, “Ẹ kúrò ní àgọ́ àwọn ènìyàn búburú yìí! Ẹ má ṣe fọwọ́ kan ohun kan tí í ṣe tiwọn kí ẹ má ba à parun nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn.”
27 I oddalili się od namiotów Koracha, Datana i Abirama z każdej strony. Datan zaś i Abiram wyszli i stali u wejścia do swoich namiotów razem ze swoimi żonami, synami i małymi dziećmi.
Àwọn ènìyàn sì sún kúrò ní àgọ́ Kora, Datani àti Abiramu. Datani àti Abiramu jáde, àwọn ìyàwó wọn àti àwọn ọmọ wọn sì dúró sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ wọn.
28 Wtedy Mojżesz powiedział: Po tym poznacie, że PAN mnie posłał, abym dokonał wszystkich tych dzieł, i że nic z własnej woli [nie czynię].
Nígbà náà ni Mose wí pé, “Báyìí ni ẹ ó ṣe mọ̀ pé Olúwa ló rán mi láti ṣe gbogbo iṣẹ́ wọ̀nyí àti pé kì í ṣe ìfẹ́ inú mi ni àwọn ohun tí mò ń ṣe.
29 Jeśli ci ludzie umrą taką śmiercią jak wszyscy ludzie albo zostaną ukarani tak jak inni, to nie PAN mnie posłał.
Bí àwọn ènìyàn yìí bá kú bí gbogbo ènìyàn ti ń kú, bí ìrírí wọn kò bá sì yàtọ̀ sí ti àwọn ènìyàn yòókù, a jẹ́ pé kì í ṣe Olúwa ló rán mi.
30 Ale jeśli PAN uczyni coś nowego i ziemia otworzy swoją paszczę, i pochłonie ich oraz wszystko, co do nich należy, i żywcem zstąpią do piekła, wtedy poznacie, że ci mężczyźni rozdrażnili PANA. (Sheol h7585)
Ṣùgbọ́n bí Olúwa bá ṣe ohun tuntun, tí ilẹ̀ sì la ẹnu, tó gbé wọn mì, àwọn pẹ̀lú gbogbo ohun tí wọ́n ní, tí wọ́n sì wọ inú ibojì wọn lọ láààyè, nígbà náà ni ẹ̀yin ó mọ̀ pé àwọn ènìyàn yìí ti kẹ́gàn Olúwa.” (Sheol h7585)
31 Gdy tylko skończył wypowiadać wszystkie te słowa, ziemia rozstąpiła się pod nimi.
Bí ó sì ṣe parí ọ̀rọ̀ wọ̀nyí, ilẹ̀ pín sí méjì nísàlẹ̀ wọn,
32 A ziemia otworzyła swoją paszczę, i pochłonęła ich oraz ich domy i wszystkich ludzi, którzy byli przy Korachu, i cały [ich] dobytek.
ilẹ̀ sì lanu ó sì gbé wọn mì pẹ̀lú gbogbo ará ilé wọn àti àwọn ènìyàn Kora àti gbogbo ohun tí wọ́n ní.
33 I zstąpili oni razem ze wszystkim, co mieli, żywcem do piekła, i ziemia ich okryła; tak zginęli spośród zgromadzenia. (Sheol h7585)
Gbogbo wọn sì sọ̀kalẹ̀ sínú ibojì wọn láààyè pẹ̀lú ohun gbogbo tí wọ́n ní, ilẹ̀ sì padé mọ́ wọn, wọ́n sì ṣègbé kúrò láàrín ìjọ ènìyàn. (Sheol h7585)
34 Wszyscy zaś Izraelici, którzy [stali] wokół nich, uciekli na ich krzyk, bo mówili: By i nas ziemia nie pochłonęła.
Gbogbo ènìyàn Israẹli tí ó yí wọn ká sì sálọ tí àwọn yòókù gbọ́ igbe wọn, wọ́n wí pé, “Ilẹ̀ yóò gbé àwa náà mì pẹ̀lú.”
35 Wyszedł też ogień od PANA i pochłonął tych dwustu pięćdziesięciu mężczyzn, którzy ofiarowali kadzidło.
Iná sì jáde láti ọ̀dọ̀ Olúwa ó sì run àádọ́ta lé nígba ọkùnrin tí wọ́n mú tùràrí wá.
36 I PAN powiedział do Mojżesza:
Olúwa sọ fún Mose pé,
37 Powiedz do Eleazara, syna kapłana Aarona, niech pozbiera kadzielnice z tego pogorzeliska, a ogień niech rozrzuci dalej. Są bowiem poświęcone.
“Sọ fún Eleasari ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà, pé kí ó mú àwọn àwo tùràrí jáde kúrò nínú iná nítorí pé wọ́n jẹ́ mímọ́, kí ó sì tan iná náà káàkiri sí ibi tó jìnnà.
38 A kadzielnice tych, którzy zgrzeszyli przeciwko własnym duszom, rozbijcie na blachy na pokrycie ołtarza. Ofiarowali je bowiem przed PANEM, są więc poświęcone. Dlatego będą znakiem dla synów Izraela.
Èyí ni àwo tùràrí àwọn tí ó kú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn. Kí ẹ gún àwo tùràrí yìí, kí ẹ sì fi ṣe ìbòrí fún pẹpẹ, wọ́n jẹ́ mímọ́ nítorí pé wọ́n ti mú wọn wá síwájú Olúwa. Kí wọ́n jẹ́ àmì fún àwọn ọmọ Israẹli.”
39 Pozbierał więc kapłan Eleazar miedziane kadzielnice, w których ofiarowali ci, którzy spłonęli, i rozbito je na blachy na pokrycie ołtarza;
Eleasari tí í ṣe àlùfáà sì kó gbogbo àwo tùràrí tí àwọn tí ó jóná mú wa, ó gún wọn pọ̀, ó fi ṣe ìbòrí fún pẹpẹ,
40 Na pamiątkę dla synów Izraela, aby żaden obcy, który nie jest z potomstwa Aarona, nie zbliżał się do składania kadzidła przed PANEM i żeby go nie spotkało to, co spotkało Koracha i jego gromady, jak PAN mu powiedział przez Mojżesza.
gẹ́gẹ́ bí Olúwa ṣe sọ láti ẹnu Mose. Èyí yóò jẹ́ ohun ìrántí fún àwọn ọmọ Israẹli pé, àlejò yàtọ̀ sí irú-ọmọ Aaroni kò gbọdọ̀ jó tùràrí níwájú Olúwa, ẹni tí ó bá ṣe bẹ́ẹ̀, yóò dàbí Kora àti àwọn ẹgbẹ́ rẹ̀.
41 A nazajutrz całe zgromadzenie synów Izraela szemrało przeciwko Mojżeszowi i Aaronowi: Wy spowodowaliście śmierć ludu PANA.
Ní ọjọ́ kejì gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli kùn sí Mose àti Aaroni pé, “Ẹ ti pa àwọn ènìyàn Olúwa.”
42 I gdy zgromadzenie zbierało się przeciw Mojżeszowi i Aaronowi, spojrzeli w stronę Namiotu Zgromadzenia, a oto okrył go obłok i ukazała się chwała PANA.
Ṣùgbọ́n nígbà tí gbogbo ìjọ ènìyàn péjọ lòdì sí Mose àti Aaroni, níwájú àgọ́ ìpàdé, lójijì ni ìkùùkuu bolẹ̀, ògo Olúwa sì fi ara hàn.
43 Wtedy Mojżesz z Aaronem przyszli przed Namiot Zgromadzenia.
Nígbà náà ni Mose àti Aaroni lọ síwájú àgọ́ ìpàdé,
44 I PAN powiedział do Mojżesza:
Olúwa sì sọ fún Mose pé,
45 Wyjdźcie spośród tego zgromadzenia, a zniszczę je w mgnieniu oka; i upadli na twarz.
“Yàgò kúrò láàrín ìjọ ènìyàn yìí, kí ń ba le run wọ́n ní ìṣẹ́jú kan.” Wọ́n sì dojúbolẹ̀.
46 Potem Mojżesz powiedział do Aarona: Weź kadzielnicę, włóż w nią ogień z ołtarza, nałóż też kadzidła i pójdź szybko do zgromadzenia, i zrób przebłaganie za nich, bo już wyszedł gniew od PANA i już zaczęła się plaga.
Mose sì sọ fún Aaroni pé, “Mú àwo tùràrí, kí o fi iná sí i lórí pẹpẹ, fi tùràrí sínú rẹ̀, kí o sì tètè mu lọ sí àárín ìjọ ènìyàn láti ṣe ètùtù fún wọn nítorí pé ìbínú Olúwa ti jáde, àjàkálẹ̀-ààrùn sì ti bẹ̀rẹ̀.”
47 Aaron wziął więc [kadzielnicę], jak mu rozkazał Mojżesz, i pobiegł w środek zgromadzenia, a oto [już] zaczęła się plaga wśród ludzi; nałożył kadzidła i dokonał przebłagania za lud.
Aaroni ṣe bí Mose ti wí, ó sáré lọ sí àárín àwọn ènìyàn, ṣùgbọ́n àjàkálẹ̀-ààrùn ti bẹ̀rẹ̀ láàrín wọn, ṣùgbọ́n Aaroni fín tùràrí, ó sì ṣe ètùtù fún wọn.
48 I Aaron stał między umarłymi i żywymi i plaga została powstrzymana.
Ó dúró láàrín àwọn alààyè àti òkú, àjàkálẹ̀-ààrùn náà sì dúró.
49 Tych, co umarli od tej plagi, było czternaście tysięcy siedemset, oprócz tych, którzy umarli w związku ze sprawą Koracha.
Ṣùgbọ́n àjàkálẹ̀-ààrùn ti pa ẹgbàá méje ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ènìyàn ní àfikún sí àwọn tí ó kú níbi ìṣẹ̀lẹ̀ Kora.
50 Potem Aaron wrócił do Mojżesza przed wejście do Namiotu Zgromadzenia, a plaga została zatrzymana.
Aaroni padà tọ Mose lọ ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé nítorí pé àjàkálẹ̀-ààrùn náà ti dúró.

< Liczb 16 >