< Liczb 11 >
1 A lud zaczął się skarżyć, co się PANU nie podobało. Gdy więc PAN to usłyszał, bardzo się rozgniewał. I ogień PANA zapalił się przeciwko niemu i pochłonął krańce obozu.
Àwọn ènìyàn ń ṣe àròyé nípa wàhálà wọn sí etí ìgbọ́ Olúwa. Ìbínú Olúwa sì ru sókè nígbà tí ó gbọ́ àròyé yìí. Nígbà náà ni iná jáde láti ọ̀dọ̀ Olúwa bọ́ sí àárín wọn, ó sì run àwọn tó wà ní òpin ibùdó.
2 Wtedy wołał lud na Mojżesza, a Mojżesz pomodlił się do PANA i ogień zgasł.
Nígbà náà ni àwọn ènìyàn kígbe sí Mose, Mose sì gbàdúrà sí Olúwa iná náà sì kú.
3 I nazwał to miejsce Tabera, bo ogień PANA zapalił się przeciwko nim.
Wọ́n sì ń pe ibẹ̀ ní Tabera nítorí pé, iná láti ọ̀dọ̀ Olúwa jó láàrín wọn.
4 A pospólstwo, które było wśród nich, ogarnęło pragnienie. Synowie Izraela też płakali na nowo i mówili: Któż nas nakarmi mięsem?
Àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn aláìníláárí tó wà láàrín àwọn ọmọ Israẹli pẹ̀lú ọkàn ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ wọn fi ìtara béèrè fún oúnjẹ mìíràn, àwọn ọmọ Israẹli náà bá bẹ̀rẹ̀ sí í sọkún wí pé, “Bí i pé kí á rí ẹran jẹ báyìí!
5 Wspominamy ryby, które jedliśmy w Egipcie za darmo, ogórki, melony, pory, cebulę i czosnek.
Àwa rántí ẹja tí à ń jẹ lọ́fẹ̀ẹ́ ní Ejibiti, apálà, bàrà, ewébẹ̀, àlùbọ́sà àti àwọn ẹ̀fọ́ mìíràn.
6 A teraz nasza dusza wyschła, bo nic innego [przed] oczami [nie mamy] oprócz tej manny.
Ṣùgbọ́n báyìí gbogbo ara wa ti gbẹ, kò sí ohun mìíràn láti jẹ àfi manna nìkan tí a rí yìí!”
7 A manna była jak nasienie kolendry, a jej kolor jak kolor bdellium.
Manna náà dàbí èso korianderi, ìrísí rẹ̀ sì dàbí oje igi.
8 Ludzie wychodzili i zbierali ją, i mełli w żarnach albo tłukli w moździerzach, potem gotowali w kotłach i robili z niej placki. Jej smak był jak smak świeżej oliwy.
Àwọn ènìyàn náà ń lọ káàkiri láti kó o, wọn ó lọ̀ ọ́ lórí ọlọ tàbí kí wọ́n gún un nínú odó. Wọ́n le sè é nínú ìkòkò tàbí kí wọn ó fi ṣe àkàrà, adùn rẹ̀ yóò sì dàbí adùn ohun tí a fi òróró ṣe.
9 Gdy bowiem nocą opadała rosa na obóz, spadała też na niego manna.
Nígbà tí ìrì bá ẹ̀ sí ibùdó lórí ni manna náà máa ń bọ́ pẹ̀lú rẹ̀.
10 Wtedy Mojżesz usłyszał, że lud płacze w swoich rodzinach, każdy przy wejściu do swojego namiotu. Wówczas mocno zapłonął gniew PANA, a i Mojżeszowi to się nie podobało.
Mose sì gbọ́ tí àwọn ènìyàn ń sọkún ní gbogbo ìdílé wọn, oníkálùkù ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ tirẹ̀. Olúwa sì bínú gidigidi. Inú Mose sì bàjẹ́ pẹ̀lú.
11 I Mojżesz powiedział do PANA: Dlaczego tak źle się obchodzisz ze swoim sługą? Dlaczego nie znalazłem łaski w twoich oczach, że włożyłeś na mnie ciężar całego tego ludu?
Mose sì béèrè lọ́wọ́ Olúwa pé, “Kí ló dé tí o fi mú wàhálà yìí bá ìránṣẹ́ rẹ? Kí ni mo ṣe tí n kò fi tẹ ọ lọ́rùn tí ìwọ fi di ẹrù àwọn ènìyàn wọ̀nyí lé mi lórí.
12 Czy ja począłem cały ten lud? Czy ja go zrodziłem, że mówisz do mnie: Nieś go na swoim łonie jak opiekun nosi niemowlę do ziemi, którą przysiągłeś ich ojcom?
Èmi ni mo ha lóyún gbogbo àwọn ènìyàn wọ̀nyí bí? Àbí èmi ló bí wọn? Tí ìwọ fi sọ fún mi pé, máa gbé wọn sí oókan àyà rẹ, gẹ́gẹ́ bí abiyamọ ti máa ń gbe ọmọ ọmú lọ sí ilẹ̀ tí o ti búra láti fún àwọn baba ńlá wọn.
13 Skąd wezmę mięso, aby dać całemu temu ludowi? Płaczą bowiem przede mną i mówią: Daj nam mięsa, abyśmy mogli jeść.
Níbo ni n ó ti rí ẹran fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí? Nítorí wọ́n ń sọkún sí mi pé, ‘Fún wa lẹ́ran jẹ́!’
14 Nie mogę sam znosić całego tego ludu, gdyż jest dla mnie zbyt ciężki.
Èmi nìkan kò lè dágbé wàhálà àwọn ènìyàn wọ̀nyí, ẹrù wọn ti wúwo jù fún mi.
15 A jeśli tak ze mną postępujesz, to raczej zabij mnie, proszę, jeśli znalazłem łaskę w twoich oczach, abym nie patrzył na swoją niedolę.
Bí ó bá sì ṣe pé báyìí ni ìwọ ó ṣe máa ṣe fún mi, kúkú pa mí báyìí, tí mo bá ti bá ojúrere rẹ pàdé—kí ojú mi má ba à rí ìparun mi.”
16 I PAN powiedział do Mojżesza: Zbierz mi siedemdziesięciu mężczyzn spośród starszych Izraela, o których wiesz, że są starszymi ludu oraz jego przełożonymi, przyprowadź ich do Namiotu Zgromadzenia i niech tam staną wraz z tobą.
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Mú àádọ́rin ọkùnrin nínú àwọn àgbàgbà àwọn ọmọ Israẹli, àwọn tí o mọ̀ gẹ́gẹ́ bí olórí àti olóyè láàrín àwọn ènìyàn wá sínú àgọ́ ìpàdé, kí wọ́n lé dúró níwájú mi.
17 A ja zstąpię i będę tam z tobą rozmawiał. Potem wezmę z ducha, który jest na tobie, i złożę na nich. Będą nosić razem z tobą brzemię ludu, abyś nie musiał go nosić ty sam.
Èmi ó sì sọ̀kalẹ̀ wá bá yín sọ̀rọ̀ níbẹ̀. Èmi ó sì mú díẹ̀ nínú agbára Ẹ̀mí tí ń bẹ lára rẹ láti fi sí orí àwọn ènìyàn wọ̀nyí. Wọn ó sì máa ràn ọ́ lọ́wọ́ láti ru àjàgà àwọn ènìyàn kí ó má ṣe pé ìwọ nìkan ni ó o máa ru àjàgà náà.
18 A do ludu powiesz: Poświęćcie się na jutro, a będziecie jeść mięso. Płakaliście bowiem, a to dotarło do uszu PANA: Któż nas nakarmi mięsem? Bo było nam lepiej w Egipcie! PAN da wam więc mięso i będziecie jeść.
“Sọ fún àwọn ènìyàn náà pé, ‘Ẹ ya ara yín sí mímọ́ ní ìmúrasílẹ̀ fún ọ̀la, ẹ ó sì jẹ ẹran. Nítorí pé Olúwa ti gbọ́ igbe ẹkún yín, èyí tí ẹ sun pé, “Ìbá ṣe pé a lè rí ẹran jẹ ni! Ó sàn fún wa ní Ejibiti jù báyìí lọ!” Nítorí náà ni Olúwa yóò fi fún yín ní ẹran, ẹ ó sì jẹ ẹ́.
19 Będziecie je jeść nie przez jeden dzień ani [nie] przez dwa dni, ani przez pięć, ani przez dziesięć dni, ani przez dwadzieścia dni;
Ẹ kò ní i jẹ ẹ́ fún ọjọ́ kan, ọjọ́ méjì, ọjọ́ márùn-ún, ọjọ́ mẹ́wàá tàbí ogúnjọ́ lásán,
20 Lecz przez cały miesiąc, aż wam wyjdzie przez nozdrza i zupełnie [wam] obrzydnie. Wzgardziliście bowiem PANEM, który jest wśród was, i płakaliście przed nim, mówiąc: Po co wyszliśmy z Egiptu?
ṣùgbọ́n fún odidi oṣù kan, títí tí ẹran náà yóò fi máa yọ ní imú yín, tí yóò sì sú yín, nítorí pé ẹ ti kẹ́gàn Olúwa tí ó wà láàrín yín, ẹ sì ti sọkún fún un wí pé, “Kí ló dé tí a fi kúrò ní Ejibiti gan an?”’”
21 Mojżesz powiedział: Sześćset tysięcy pieszych liczy ten lud, pośród którego mieszkam, a ty powiedziałeś: Dam im mięsa i będą jeść przez cały miesiąc.
Ṣùgbọ́n Mose sọ pé, “Mo wà láàrín ọgbọ̀n ọ̀kẹ́ ènìyàn ni ìrìnkiri, ó sì sọ pé, ‘Èmi ó fún wọn ní ẹran láti jẹ fún oṣù kan gbáko!’
22 Czy można zabić [tyle] owiec i wołów, aby im wystarczyło? Czy można dla nich zebrać wszystkie ryby morskie, aby mieli dosyć?
Ǹjẹ́ bí a tilẹ̀ pa àgbò ẹran àti ọmọ ẹran, yóò ha tó wọn bí? Tàbí bí a tilẹ̀ pa gbogbo ẹja inú omi fún wọn, yóò wa tó bí?”
23 PAN powiedział do Mojżesza: Czy ręka PANA jest zbyt krótka? Teraz zobaczysz, czy moje słowo się wypełni, czy też nie.
Olúwa sì dá Mose lóhùn pé, “Ọwọ́ Olúwa ha kúrú bí? Ìwọ yóò ri nísinsin yìí bóyá ọ̀rọ̀ tí mo sọ yóò ṣẹ tàbí kò ni í ṣẹ.”
24 Mojżesz wyszedł więc i opowiedział ludowi słowa PANA. Następnie zebrał siedemdziesięciu mężczyzn spośród starszych ludu i postawił ich wokół namiotu.
Mose sì jáde, ó sọ ohun tí Olúwa wí fún àwọn ènìyàn. Ó mú àwọn àádọ́rin àgbàgbà Israẹli dúró yí àgọ́ ká.
25 Wtedy PAN zstąpił w obłoku i przemówił do niego. Potem wziął z ducha, który był na nim, i dał go siedemdziesięciu starszym. A gdy spoczął na nich duch, prorokowali i nie przestali.
Nígbà náà ni Olúwa sọ̀kalẹ̀ nínú àwọ̀ sánmọ̀ ó sì bá wọn sọ̀rọ̀, ó sì mú lára Ẹ̀mí tó wà lára Mose sí ara àwọn àádọ́rin àgbàgbà náà, Ó sì ṣẹlẹ̀ pé nígbà tí Ẹ̀mí náà bà lé wọn, wọ́n sọtẹ́lẹ̀, ṣùgbọ́n lẹ́yìn èyí wọn kò sọtẹ́lẹ̀ mọ́.
26 Lecz dwaj mężczyźni pozostali w obozie: jeden miał na imię Eldad, a drugi – Medad. Na nich też spoczął duch, bo oni byli wśród spisanych, choć nie przybyli do namiotu. Prorokowali [jednak] w obozie.
Àwọn ọkùnrin méjì, tí orúkọ wọn ń jẹ́ Eldadi àti Medadi kò kúrò nínú àgọ́. Orúkọ wọn wà lára àádọ́rin àgbàgbà yìí ṣùgbọ́n wọn kò jáde nínú àgọ́ síbẹ̀ Ẹ̀mí náà bà lé wọn, wọ́n sì sọtẹ́lẹ̀ nínú àgọ́.
27 Wtedy młodzieniec przybiegł i powiedział do Mojżesza: Eldad i Medad prorokują w obozie.
Ọmọkùnrin kan sì sáré lọ sọ fún Mose pé, “Eldadi àti Medadi ń sọtẹ́lẹ̀ nínú àgọ́.”
28 A Jozue, syn Nuna, sługa Mojżesza i jeden z jego młodzieńców, powiedział: Mojżeszu, panie mój, zabroń im.
Joṣua ọmọ Nuni tí í ṣe ìránṣẹ́ Mose, láti kékeré tó jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ dáhùn pé, “Mose olúwa mi, dá wọn lẹ́kun!”
29 Mojżesz odpowiedział: Czy jesteś zazdrosny o mnie? Oby cały lud PANA zamienił się w proroków, aby PAN złożył na nim swego ducha!
Mose sì wí fún un pé, “Àbí ìwọ ń jowú nítorí mi? Ìbá ti wù mí tó, kí gbogbo àwọn ènìyàn Olúwa jẹ́ wòlíì, kí Olúwa sì fi Ẹ̀mí rẹ̀ sí wọn lára!”
30 Wtedy Mojżesz wrócił do obozu wraz ze starszymi Izraela.
Mose àti àwọn àgbàgbà Israẹli yìí sì padà sínú àgọ́.
31 I zerwał się wiatr od PANA, który porwał od morza przepiórki i zrzucił je na obóz, na jeden dzień drogi z jednej strony i na jeden dzień drogi z drugiej strony, wokół obozu, [wysoko] na dwa łokcie nad ziemią.
Afẹ́fẹ́ sì jáde láti ọ̀dọ̀ Olúwa ó sì kó àparò wá láti inú Òkun. Ó sì dà wọ́n káàkiri gbogbo ibùdó ní ìwọ̀n gíga ẹsẹ̀ bàtà mẹ́ta sórí ilẹ̀, bí ìwọ̀n ìrìn ọjọ́ kan ní gbogbo àyíká.
32 Lud stał przez cały dzień, przez całą noc i przez cały następny dzień i zbierał przepiórki. Ten, kto zebrał najmniej, [miał] dziesięć chomerów. I rozłożyli je sobie wokół obozu.
Ní gbogbo ọjọ́ náà àti òru, títí dé ọjọ́ kejì ni àwọn ènìyàn fi ń kó àparò yìí, ẹni tó kó kéré jùlọ kó ìwọ̀n homeri mẹ́wàá, wọ́n sì ṣà wọ́n sílẹ̀ fún ara wọn yí gbogbo ibùdó.
33 Lecz gdy mięso było między ich zębami, jeszcze nieprzeżute, gniew PANA zapłonął przeciw ludowi i uderzył go wielką plagą.
Ṣùgbọ́n nígbà tí ẹran náà sì wà láàrín eyín wọn, kó tó di pé wọ́n jẹ ẹ́, ìbínú Olúwa sì ru sí àwọn ènìyàn, ó sì pa wọ́n pẹ̀lú àjàkálẹ̀-ààrùn.
34 I nazwano to miejsce Kibrot-Hattaawa, bo tam pochowano lud, który zapragnął [mięsa].
Torí èyí ni wọ́n ṣe pe ibẹ̀ ní Kibirotu-Hattaafa nítorí pé níbẹ̀ ni wọ́n gbé sìnkú àwọn ènìyàn tó ní ọ̀kánjúwà oúnjẹ sí.
35 A z Kibrot-Hattaawy lud wyruszył do Chaserot; i mieszkał w Chaserot.
Àwọn ènìyàn yòókù sì gbéra láti Kibirotu-Hattaafa lọ pa ibùdó sí Haserotu wọ́n sì dúró níbẹ̀.