< Nehemiasza 6 >

1 A gdy Sanballat, Tobiasz, Geszem Arab i pozostali nasi wrogowie usłyszeli, że zbudowałem mur i że nie pozostał w nim żaden wyłom, chociaż jeszcze w tym czasie nie wstawiłem wrót do bram;
Nígbà tí Sanballati, Tobiah Geṣemu ará Arabia àti àwọn ọ̀tá wa tókù gbọ́ pé, mo ti tún odi náà mọ, kò sì sí àlàfo kankan tí ó ṣẹ́kù nínú rẹ̀—bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi kò ì tí ì ri àwọn ìlẹ̀kùn ibodè ní àkókò náà.
2 Wtedy Sanballat i Geszem wysłali do mnie [poselstwo] ze słowami: Przyjdź, spotkajmy się razem w [jednej ze] wsi, na równinie Ono. Lecz oni mieli zamiar uczynić mi coś złego.
Sanballati àti Geṣemu rán iṣẹ́ yìí sí mi pé, “Wá jẹ́ kí a jọ pàdé pọ̀ nínú ọ̀kan lára àwọn ìletò ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Ono.” Ṣùgbọ́n wọ́n ń gbèrò láti ṣe mí ní ibi;
3 Wysłałem więc do nich posłańców z taką odpowiedzią: Wykonuję wielką pracę i nie mogę zejść. Czemu miałaby stanąć ta praca, gdybym jej zaniechał, by zejść do was?
bẹ́ẹ̀ ni mo rán oníṣẹ́ padà pẹ̀lú èsì yìí pé, “Èmi ń ṣe iṣẹ́ ńlá kan, èmi kò le è sọ̀kalẹ̀ wá. Èéṣe tí iṣẹ́ náà yóò fi dúró, nígbà tí mo bá fi í sílẹ̀ tí mo sì sọ̀kalẹ̀ tọ̀ yín wá?”
4 Cztery razy przysłali do mnie [poselstwo] w tej sprawie, a ja odpowiedziałem im tak samo.
Wọ́n rán iṣẹ́ náà sí mi nígbà mẹ́rin ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀, mo sì fún wọn ní èsì bákan náà fún ìgbà kọ̀ọ̀kan.
5 Potem Sanballat po raz piąty przysłał do mnie w ten sam sposób swego sługę z otwartym listem w ręku;
Ní ìgbà karùn-ún, Sanballati rán ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ sí mi pẹ̀lú irú iṣẹ́ kan náà, lẹ́tà kan tí a kò fi sínú àpò ìwé wà ní ọwọ́ rẹ̀
6 A było w nim napisane: Wśród pogan krąży pogłoska – jak powiada Gaszmu – że ty i Żydzi zamierzacie się zbuntować. Dlatego budujesz mur, abyś był ich królem, według tych słów.
tí a kọ sínú un rẹ̀ pé, “A ròyìn rẹ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, Geṣemu sì sọ pé, òtítọ́ ni, pé ìwọ àti àwọn Júù ń gbèrò láti ṣọ̀tẹ̀, nítorí náà ni ẹ ṣe ń mọ odi. Síwájú sí i, gẹ́gẹ́ bí ìròyìn yìí, ìwọ sì ń gbèrò láti di ọba wọn
7 Krąży też pogłoska, że ustanowiłeś proroków, aby opowiadali o tobie w Jerozolimie, mówiąc: Jest król w Judzie. Teraz te słowa dotrą do króla. Przyjdź więc i naradzimy się wspólnie.
àti pé ó ti yan àwọn wòlíì kí wọn lè kéde nípa rẹ̀ ní Jerusalẹmu: ‘Ọba kan wà ní Juda!’ Nísinsin yìí, ìròyìn yìí yóò padà sí ọ̀dọ̀ ọba; nítorí náà wá, jẹ́ kí a bá ara wa sọ̀rọ̀.”
8 Lecz ja wysłałem do niego taką odpowiedź: Nie jest tak, jak powiadasz, ale sam sobie to wymyślasz.
Mo dá èsì yìí padà sí i pé, “Kò sí ohun kan nínú irú ohun tí ìwọ sọ tí ó ṣẹlẹ̀; ìwọ kàn rò wọ́n ní orí ara rẹ ni.”
9 Oni wszyscy bowiem straszyli nas, mówiąc: Ich ręce osłabną od tej pracy i nie zostanie dokonana. Teraz więc, [Boże], wzmocnij moje ręce.
Gbogbo wọn múra láti dẹ́rùbà wá, wọ́n ń rò ó wí pé, “Ọwọ́ wọn kò ní ran iṣẹ́ náà, àti wí pé wọn kò ní parí rẹ̀.” Ṣùgbọ́n mo gbàdúrà pé, “Nísinsin yìí Ọlọ́run fi agbára fún ọwọ́ mi.”
10 A gdy wszedłem do domu Szemajasza, syna Delajasza, syna Mehetabeela, gdzie był zamknięty, powiedział [mi]: Zejdźmy się w domu Bożym, w świątyni, i zamknijmy drzwi. Przyjdą bowiem, aby cię zabić. Tej nocy przyjdą, aby cię zabić.
Ní ọjọ́ kan mo lọ sí ilé Ṣemaiah ọmọ Delaiah, ọmọ Mehetabeeli, ẹni tí a há mọ́ sínú ilé rẹ̀. Ó wí pé, “Jẹ́ kí a pàdé ní ilé Ọlọ́run nínú tẹmpili, kí o sì jẹ́ kí a pa àwọn ìlẹ̀kùn tẹmpili dé, nítorí àwọn ènìyàn ń bọ̀ láti pa ọ́, ní òru ni wọn yóò wá láti pa ọ́.”
11 A ja odpowiedziałem: Czy człowiek taki jak ja miałby uciekać? Czy ktoś taki jak ja wszedłby do świątyni, aby się ratować? Nie wejdę.
Ṣùgbọ́n mo wí pé, “Ǹjẹ́ ó yẹ kí irú ènìyàn bí èmi sálọ? Tàbí kí ènìyàn bí èmi sálọ sínú tẹmpili láti gba ẹ̀mí ara rẹ̀ là? Èmi kò ní lọ!”
12 I poznałem, że to nie Bóg go posłał, ale wypowiedział to proroctwo przeciwko mnie, bo Tobiasz i Sanballat przekupili go.
Èmi wòye pé Ọlọ́run kò rán an, ṣùgbọ́n ó sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí mi nítorí Tobiah àti Sanballati ti bẹ̀ ẹ́ ní ọ̀wẹ̀.
13 Został przekupiony, abym się uląkł i tak uczynił, i zgrzeszył, aby posłużyło [to] do zniesławienia [mnie], by mnie zhańbić.
Wọ́n bẹ̀ ẹ́ ní ọ̀wẹ̀ láti dẹ́rùbà mí nítorí kí èmi lè dẹ́ṣẹ̀ nípa ṣíṣe èyí, kí wọn lè bà mí lórúkọ jẹ́, kí n sì di ẹni ẹ̀gàn.
14 Mój Boże, pamiętaj o Tobiaszu i Sanballacie, według ich uczynków, także o prorokini Noadzie oraz pozostałych prorokach, którzy chcieli mnie straszyć.
A! Ọlọ́run mi, rántí Tobiah àti Sanballati, nítorí ohun tí wọ́n ti ṣe; kí o sì tún rántí Noadiah wòlíì obìnrin àti àwọn wòlíì tókù tí wọ́n ń gbèrò láti dẹ́rùbà mí.
15 A mur został ukończony dwudziestego piątego [dnia miesiąca] Elul, w ciągu pięćdziesięciu dwóch dni.
Bẹ́ẹ̀ ni a parí odi náà ní ọjọ́ kẹẹdọ́gbọ̀n oṣù Eluli, láàrín ọjọ́ méjìléláàádọ́ta.
16 A gdy usłyszeli [o tym] wszyscy nasi wrogowie i gdy widzieli to wszyscy poganie, którzy byli wokół nas, bardzo się zniechęcili. Poznali bowiem, że to dzieło zostało wykonane przez naszego Boga.
Nígbà tí àwọn ọ̀tá wa gbọ́ èyí, gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ó yí wa ká bẹ̀rù jìnnìjìnnì sì mú wọn, nítorí wọ́n wòye pé iṣẹ́ yìí di ṣíṣe pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ Ọlọ́run wa.
17 W te dni dostojnicy z Judy wysyłali wiele listów do Tobiasza, a także listy od Tobiasza przychodziły do nich.
Bákan náà, ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì àwọn ọlọ́lá Juda ń kọ ọ̀pọ̀lọpọ̀ lẹ́tà ránṣẹ́ sí Tobiah, èsì láti ọ̀dọ̀ Tobiah sì ń wá sí ọ̀dọ̀ wọn.
18 Wielu bowiem w Judzie [było] z nim związanych przysięgą, gdyż był on zięciem Szekaniasza, syna Aracha; a jego syn Jochanan pojął za żonę córkę Meszullama, syna Berechiasza.
Nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn Juda ti mulẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀, nítorí tí ó jẹ́ àna Ṣekaniah ọmọ Arah (Sanballati fẹ́ ọmọ Ṣekaniah), ọmọ rẹ̀ Jehohanani sì tún fẹ́ ọmọbìnrin Meṣullamu ọmọ Berekiah.
19 Opowiadali także przede mną jego dobre czyny i moje słowa donosili jemu. Tobiasz zaś wysyłał listy, aby mnie zastraszyć.
Síwájú sí í, wọ́n túbọ̀ ń ròyìn iṣẹ́ rere rẹ̀ fún mi, wọ́n sì ń sọ ohun tí mo sọ fún un. Tobiah sì ń kọ àwọn lẹ́tà ránṣẹ́ sí mi láti dẹ́rùbà mí.

< Nehemiasza 6 >