< Lamentacje 5 >

1 Wspomnij, PANIE, na to, co nas spotkało. Spójrz i zobacz nasze pohańbienie.
Rántí, Olúwa, ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí wa; wò ó, kí o sì rí ìtìjú wa.
2 Nasze dziedzictwo przypadło obcym, a nasze domy – cudzoziemcom.
Àwọn ohun ìní wa ti di ti àlejò, ilé wa ti di ti àjèjì.
3 Staliśmy się sierotami, bez ojca; nasze matki są jak wdowy.
Àwa ti di aláìní òbí àti aláìní baba, àwọn ìyá wa ti di opó.
4 Własną wodę pijemy za pieniądze, nasze drwa za pieniądze kupujemy.
A gbọdọ̀ ra omi tí à ń mu; igi wa di títà fún wa.
5 Prześladowanie ciąży na naszym karku. Pracujemy, [a] nie dają nam odpocząć.
Àwọn tí ó ń lé wa súnmọ́ wa; àárẹ̀ mú wa àwa kò sì rí ìsinmi.
6 Podawaliśmy rękę Egipcjanom i Asyryjczykom, aby nasycić się chlebem.
Àwa jọ̀wọ́ ara wa fún Ejibiti àti Asiria láti rí oúnjẹ tó tó jẹ.
7 Nasi ojcowie zgrzeszyli, nie ma ich, a my nosimy ich nieprawość.
Àwọn baba wa ti ṣẹ̀, wọn kò sì ṣí mọ́, àwa sì ń ru ìjìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
8 Niewolnicy panują nad nami, nie ma nikogo, kto by nas wybawił z ich ręki.
Àwọn ẹrú ń jẹ ọba lórí wa, kò sì ṣí ẹni tí yóò gbà wá lọ́wọ́ wọn.
9 Z narażeniem życia szukamy swego chleba z powodu miecza [na] pustyni.
Àwa ń rí oúnjẹ wa nínú ewu ẹ̀mí wa nítorí idà tí ó wà ní aginjù.
10 Nasza skóra jak piec zaciemniła się od strasznego głodu.
Ẹran-ara wa gbóná bí ààrò, ebi sì yó wa bí àárẹ̀.
11 Kobiety na Syjonie hańbiono, a panny – w miastach Judy.
Wọ́n ti fipá bá àwọn obìnrin wa lòpọ̀ ní Sioni, àti àwọn wúńdíá ti o wa ní ìlú Juda.
12 Książęta byli wieszani ich rękami, oblicza starszych nie uszanowano.
Àwọn ọmọ ọbakùnrin ti di síso sókè ní ọwọ́ wọn; kò sí ìbọ̀wọ̀ fún àgbàgbà mọ́.
13 Młodzieńców wzięli do młócenia, dzieci padały pod [ciężarem] drewna.
Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wa ru òkúta; àwọn ọmọkùnrin sì ń ṣàárẹ̀ lábẹ́ ẹrù igi.
14 Starcy w bramach już nie siadają, młodzieńcy przestali [śpiewać] swoje pieśni.
Àwọn àgbàgbà ti lọ kúrò ní ẹnu-bodè ìlú; àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin sì dákẹ́ orin wọn.
15 Radość zniknęła z naszych serc, nasze pląsanie zamieniło się w żałobę.
Ayọ̀ ti ṣáko ní ọkàn wa; ọ̀fọ̀ sì ti dúró bí ijó fún wa.
16 Spadła korona z naszej głowy. Biada nam, bo zgrzeszyliśmy!
Adé ti ṣí kúrò ní orí wa ègbé ni fún wa, nítorí a ti ṣẹ̀.
17 Dlatego nasze serce omdlewa, dlatego nasze oczy są zaćmione.
Nítorí èyí, àárẹ̀ mú ọkàn wa, nítorí èyí, ojú wa sì ṣú.
18 Z powodu spustoszonej góry Syjonu lisy chodzą po niej.
Fún òkè Sioni tí ó ti di ahoro lórí rẹ̀ àwọn kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ sì ń rìn kiri.
19 Ty, PANIE, trwasz na wieki, twój tron z pokolenia na pokolenie.
Ìwọ, Olúwa, jẹ ọba títí láé; ìjọba rẹ dúró láti ìran kan dé ìran mìíràn.
20 Czemu zapominasz o nas na wieki i opuszczasz nas na tak długi czas?
Kí ló dé tí o ń gbàgbé wa ní gbogbo ìgbà? Kí ló dé tí o fi kọ̀ wá sílẹ̀ fún ọjọ́ pípẹ́?
21 Nawróć nas do siebie, PANIE, a będziemy nawróceni; odnów nasze dni, jak dawniej.
Mú wa padà sí ọ̀dọ̀ rẹ, Olúwa, kí àwa kí ó le padà; mú ọjọ́ wa di tuntun bí ìgbàanì,
22 Czy odrzuciłeś nas całkowicie? Czy bardzo się na nas gniewałeś?
àyàfi tí o bá ti kọ̀ wá sílẹ̀ pátápátá tí ìbínú rẹ sí wa sì kọjá ìwọ̀n.

< Lamentacje 5 >