< Jozuego 11 >

1 A gdy usłyszał o tym Jabin, król Chasoru, posłał wiadomość do Jobaba, króla Madonu, do króla Szimronu, do króla Akszafu;
Nígbà tí Jabini ọba Hasori gbọ́ nǹkan wọ̀nyí, ó ránṣẹ́ sí Jobabu ọba Madoni, sí ọba Ṣimroni àti Akṣafu,
2 I do królów, którzy byli na północy, w górach i na polach, na południe od Kinneret, na równinach i w krainach Dor na zachodzie;
àti sí àwọn ọba ìhà àríwá tí wọ́n wà ní orí òkè ní aginjù, gúúsù ti Kinnereti, ní ẹsẹ̀ òkè ìwọ̀-oòrùn àti ní Nafoti Dori ní ìwọ̀-oòrùn;
3 Do Kananejczyków na wschodzie i na zachodzie, do Amorytów, Chetytów, Peryzzytów, Jebusytów w górach i Chiwwitów pod [górą] Hermon, w ziemi Mispa.
sí àwọn ará Kenaani ní ìlà-oòrùn àti ìwọ̀-oòrùn; sí àwọn Amori, Hiti, Peresi àti Jebusi ní orí òkè; àti sí àwọn Hifi ní ìsàlẹ̀ Hermoni ní agbègbè Mispa.
4 I wyruszyli oni wraz z całym swym wojskiem, lud liczny jak piasek na brzegu morskim, mający bardzo wiele koni i rydwanów.
Wọ́n sì jáde pẹ̀lú gbogbo ogun wọn àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹṣin àti kẹ̀kẹ́ ogun ńlá, wọ́n sì pọ̀, gẹ́gẹ́ bí iyanrìn etí òkun.
5 A gdy wszyscy ci królowie zgromadzili się, przybyli i razem rozbili obóz nad wodami Meromu, aby walczyć przeciwko Izraelowi.
Gbogbo àwọn ọba yìí pa ọmọ-ogun wọn pọ̀, wọ́n sì pa ibùdó sí ibi omi Meromu láti bá Israẹli jà.
6 I PAN powiedział do Jozuego: Nie bój się ich, bo jutro o tej porze wydam ich wszystkich pobitych Izraelowi. Ich koniom podetniesz ścięgna, a ich rydwany spalisz ogniem.
Olúwa sì sọ fún Joṣua pé, “Má ṣe bẹ̀rù wọn, nítorí ní àkókò yìí ní ọ̀la, gbogbo wọn ni èmi yóò fi lé Israẹli lọ́wọ́ ní pípa. Ìwọ yóò já iṣan ẹ̀yìn ẹṣin wọn, ìwọ yóò sì sun kẹ̀kẹ́ ogun wọn.”
7 Wtedy Jozue i cały waleczny lud z nim wyruszyli niespodziewanie przeciwko nim nad wody Meromu i napadli na nich.
Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ yọ sí wọn ní òjijì ní ibi omi Meromu, wọ́n sì kọlù wọ́n,
8 I PAN wydał ich w ręce Izraela, który pobił ich i ścigał aż do Sydonu Wielkiego i aż do Misreft-Maim, i aż do doliny Mispa na wschodzie. Pobili ich tak, że nikogo nie pozostawili przy życiu.
Olúwa sì fi wọ́n lé Israẹli lọ́wọ́. Wọ́n ṣẹ́gun wọn, wọ́n sì lépa wọn ní gbogbo ọ̀nà títí dé Sidoni ńlá, sí Misrefoti-Maimu, àti sí àfonífojì Mispa ní ìlà-oòrùn, títí tí kò fi ku ẹnìkankan sílẹ̀.
9 I Jozue uczynił im tak, jak mu PAN rozkazał: ich koniom podciął ścięgna, a ich rydwany spalił ogniem.
Joṣua sì ṣe sí wọn gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ: Ó sì já iṣan ẹ̀yìn ẹsẹ̀ ẹṣin wọn ó sì sun kẹ̀kẹ́ ogun wọn.
10 W tym czasie Jozue zawrócił i zdobył Chasor, a jego króla zabił mieczem. Chasor bowiem był przedtem głową wszystkich tych królestw.
Ní àkókò náà Joṣua sì padà sẹ́yìn, ó sì ṣẹ́gun Hasori, ó sì fi idà pa ọba rẹ̀. (Hasori tí jẹ́ olú fún gbogbo àwọn ìlú wọ̀nyí kó tó di àkókò yí.)
11 Każdą duszę, która w nim była, pobili ostrzem miecza, wytracając [ją]. Nikt nie pozostał przy życiu, a Chasor spalił ogniem.
Wọ́n sì fi idà pa gbogbo àwọn ènìyàn tí ó wà ní ibẹ̀. Wọ́n sì pa wọ́n run pátápátá, wọn kò sì fi ohun alààyè kan sílẹ̀; ó sì fi iná sun Hasori fúnra rẹ̀.
12 Jozue [zdobył] też wszystkie miasta tych królów i pojmał wszystkich królów, pobił ich ostrzem miecza i wytracił, tak jak nakazał Mojżesz, sługa PANA.
Joṣua sì kó gbogbo àwọn ìlú ọba àti ọba wọn, ó sì fi idà pa wọ́n. Ó sì run gbogbo wọn, gẹ́gẹ́ bí Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti pàṣẹ.
13 Izrael nie spalił jednak żadnego z miast warownych, oprócz samego Chasoru, [który] spalił Jozue.
Síbẹ̀ Israẹli kò sun ọ̀kankan nínú àwọn ìlú tó wà lórí òkè kéékèèké, àyàfi Hasori nìkan tí Joṣua sun.
14 Cały łup tych miast oraz bydło synowie Izraela zabrali dla siebie; tylko wszystkich ludzi pobili ostrzem miecza, aż ich zgładzili, nie zostawiając nikogo przy życiu.
Àwọn ará Israẹli sì kó gbogbo ìkógun àti ohun ọ̀sìn ti ìlú náà fún ara wọn. Wọ́n sì fi idà pa gbogbo ènìyàn títí wọ́n fi run wọ́n pátápátá, kò sí ẹni tí ó wà láààyè.
15 Jak PAN rozkazał Mojżeszowi, swemu słudze, tak Mojżesz nakazał Jozuemu i tak Jozue uczynił; nie zaniedbał niczego z tego wszystkiego, co PAN rozkazał Mojżeszowi.
Bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose ìránṣẹ́ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ní Mose pàṣẹ fún Joṣua, Joṣua sì ṣe bẹ́ẹ̀. Kò fi ọ̀kankan sílẹ̀ láìṣe nínú gbogbo ohun tí Olúwa pàṣẹ fún Mose.
16 Tak Jozue zdobył całą ziemię: góry i całą ziemię na południu, całą ziemię Goszen, równiny, pola i górę Izrael z jej równiną;
Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua gba gbogbo ilẹ̀ náà: ilẹ̀ òkè, gbogbo gúúsù, gbogbo agbègbè Goṣeni, ẹsẹ̀ òkè ti ìwọ̀-oòrùn, aginjù àti àwọn òkè àti pẹ̀tẹ́lẹ̀ Israẹli,
17 Od góry Halak, która wznosi się ku Seirowi, aż do Baal-Gad w dolinie Libanu pod górą Hermon. A wszystkich królów pojmał, pobił i pozabijał.
láti òkè Halaki títí dé òkè Seiri, sí Baali-Gadi ní àfonífojì Lebanoni ní ìsàlẹ̀ òkè Hermoni. Ó sì mú gbogbo ọba wọn, ó sì kọlù wọ́n, ó sì pa wọ́n.
18 Przez długi czas Jozue prowadził wojnę z tymi wszystkimi królami.
Joṣua sì bá gbogbo àwọn ọba wọ̀nyí jagun ní ọjọ́ pípẹ́.
19 Nie było miasta, które by zawarło pokój z synami Izraela, oprócz Chiwwitów, [którzy] mieszkali w Gibeonie; wszystkie [inne] zdobyli podczas wojny.
Kò sí ìlú kan tí ó bá àwọn ará Israẹli ṣe àdéhùn àlàáfíà, àyàfi àwọn ará Hifi tí wọ́n ń gbé ní Gibeoni, gbogbo wọn ló bá a jagun.
20 Od PANA bowiem wyszło, by zatwardzić ich serca, aby wyruszali na bitwę z Izraelem i żeby ich wyniszczył bez miłosierdzia, aż do wytracenia, jak PAN rozkazał Mojżeszowi.
Nítorí Olúwa fúnra rẹ̀ ní ó sé ọkàn wọn le, kí wọn kí ó lè bá Israẹli jagun, kí òun lè pa wọ́n run pátápátá, kí wọn má sì ṣe rí ojúrere, ṣùgbọ́n kí ó lè pa wọ́n, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
21 W tym czasie Jozue wyruszył i wytracił Anakitów z gór, z Hebronu, z Debiru, z Anabu, ze wszystkich gór Judy i ze wszystkich gór Izraela. Jozue zniszczył ich razem z ich miastami.
Ní àkókò náà ni Joṣua lọ tí ó sì run àwọn ará Anaki kúrò ní ilẹ̀ òkè, láti Hebroni, Debiri, àti ní Anabu, àti gbogbo ilẹ̀ Juda, àti kúrò ní gbogbo ilẹ̀ òkè Israẹli. Joṣua sì run gbogbo wọn pátápátá àti ìlú wọn.
22 Nikt z Anakitów nie został w ziemi synów Izraela; zostali tylko w Gazie, w Gat i w Azdodzie.
Kò sí ará Anaki kankan tí ó ṣẹ́kù ní ilẹ̀ Israẹli: bí kò ṣe ní Gasa, Gati àti Aṣdodu.
23 Zdobył więc Jozue całą ziemię, tak jak PAN powiedział do Mojżesza, i oddał ją Jozue jako dziedzictwo Izraelowi [zgodnie z] ich przydziałami według pokoleń. I ziemia zaznała pokoju od wojny.
Bẹ́ẹ̀ ní Joṣua sì gba gbogbo ilẹ̀ náà, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose, ó sì fi fún Israẹli ní ilẹ̀ ìní gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn nípa ẹ̀yà wọn. Ilẹ̀ náà sì sinmi ogun.

< Jozuego 11 >