< Jana 15 >
1 Ja jestem prawdziwą winoroślą, a mój Ojciec jest winogrodnikiem.
“Èmi ni àjàrà tòótọ́, Baba mi sì ni olùṣọ́gbà.
2 Każdą latorośl, która we mnie nie wydaje owocu, odcina, a każdą, która wydaje owoc, oczyszcza, aby wydawała obfitszy owoc.
Gbogbo ẹ̀ka nínú mi tí kò bá so èso, òun a mú kúrò, gbogbo ẹ̀ka tí ó bá sì so èso, òun a wẹ̀ ẹ́ mọ́, kí ó lè so èso sí i.
3 Wy już jesteście czyści z powodu słów, które do was mówiłem.
Ẹ̀yin mọ́ nísinsin yìí nítorí ọ̀rọ̀ tí mo ti sọ fún yín.
4 Trwajcie we mnie, a ja w was. Jak latorośl nie może wydawać owocu sama z siebie, jeśli nie będzie trwała w winorośli, tak i wy, jeśli nie będziecie trwać we mnie.
Ẹ máa gbé inú mi, èmi ó sì máa gbé inú yín. Gẹ́gẹ́ bí ẹ̀ka kò ti lè so èso fún ara rẹ̀ bí kò ṣe pé ó ba ń gbé inú àjàrà, bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin, bí kò ṣe pé ẹ bá ń gbé inú mi.
5 Ja jestem winoroślą, a wy jesteście latoroślami. Kto trwa we mnie, a ja w nim, ten wydaje obfity owoc, bo beze mnie nic nie możecie zrobić.
“Èmi ni àjàrà, ẹ̀yin ni ẹ̀ka. Ẹni tí ó ń gbé inú mi, àti èmi nínú rẹ̀, òun ni yóò so èso lọ́pọ̀lọ́pọ̀, nítorí ní yíya ara yín kúrò lọ́dọ̀ mi, ẹ kò lè ṣe ohun kan.
6 Jeśli ktoś nie trwa we mnie, zostanie wyrzucony precz jak latorośl i uschnie. Takie się zbiera i wrzuca do ognia, i płoną.
Bí ẹnìkan kò bá gbé inú mi, a gbé e sọnù gẹ́gẹ́ bí ẹ̀ka, a sì gbẹ; wọn a sì kó wọn jọ, wọn a sì sọ wọ́n sínú iná, wọn a sì jóná.
7 Jeśli będziecie trwać we mnie i moje słowa będą trwać w was, proście, o cokolwiek chcecie, a spełni się wam.
Bí ẹ̀yin bá ń gbé inú mi, tí ọ̀rọ̀ mi bá sì gbé inú yín, ẹ ó béèrè ohunkóhun tí ẹ bá fẹ́, a ó sì ṣe é fún yín.
8 W tym będzie uwielbiony mój Ojciec, że wydacie obfity owoc; i będziecie moimi uczniami.
Nínú èyí ní a yìn Baba mi lógo pé, kí ẹ̀yin kí ó máa so èso púpọ̀; ẹ̀yin ó sì jẹ́ ọmọ-ẹ̀yìn mi.
9 Jak mnie umiłował Ojciec, [tak] i ja was umiłowałem. Trwajcie w mojej miłości.
“Gẹ́gẹ́ bí Baba ti fẹ́ mi, bẹ́ẹ̀ ni èmi sì fẹ́ yín, ẹ dúró nínú ìfẹ́ rẹ̀.
10 Jeśli zachowacie moje przykazania, będziecie trwać w mojej miłości, jak i ja zachowałem przykazania mego Ojca i trwam w jego miłości.
Bí ẹ̀yin bá pa òfin mi mọ́, ẹ ó dúró nínú ìfẹ́ mi; gẹ́gẹ́ bí èmi ti pa òfin Baba mi mọ́, tí mo sì dúró nínú ìfẹ́ rẹ̀.
11 To wam powiedziałem, aby moja radość trwała w was i aby wasza radość była pełna.
Nǹkan wọ̀nyí ni mo ti sọ fún yín, kí ayọ̀ mi kí ó lè wà nínú yín, àti kí ayọ̀ yín kí ó lè kún.
12 To jest moje przykazanie, abyście się wzajemnie miłowali, jak i ja was umiłowałem.
Èyí ni òfin mi, pé kí ẹ̀yin kí ó fẹ́ràn ara yín, gẹ́gẹ́ bí mo ti fẹ́ràn yín.
13 Nikt nie ma większej miłości od tej, gdy ktoś oddaje swoje życie za swoich przyjaciół.
Kò sí ẹnìkan tí ó ní ìfẹ́ tí ó tóbi ju èyí lọ, pé ẹnìkan fi ẹ̀mí rẹ̀ lélẹ̀ nítorí àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀.
14 Wy jesteście moimi przyjaciółmi, jeśli robicie to, co wam przykazuję.
Ọ̀rẹ́ mi ni ẹ̀yin ń ṣe, bí ẹ bá ṣe ohun tí èmi pàṣẹ fún yín.
15 Już więcej nie będę nazywał was sługami, bo sługa nie wie, co robi jego pan. Lecz nazwałem was przyjaciółmi, bo oznajmiłem wam wszystko, co słyszałem od mego Ojca.
Èmi kò pè yín ní ọmọ ọ̀dọ̀ mọ́; nítorí ọmọ ọ̀dọ̀ kò mọ ohun tí olúwa rẹ̀ ń ṣe, ṣùgbọ́n èmi pè yín ní ọ̀rẹ́ nítorí ohun gbogbo tí mo ti gbọ́ láti ọ̀dọ̀ Baba mi wá, mo ti fihàn fún yín.
16 Nie wy mnie wybraliście, ale ja was wybrałem i przeznaczyłem, abyście wyszli i wydali owoc, i aby wasz owoc trwał, i aby Ojciec dał wam to, o cokolwiek poprosicie go w moje imię.
Kì í ṣe ẹ̀yin ni ó yàn mí, ṣùgbọ́n èmi ni ó yàn yín, mo sì fi yín sípò, kí ẹ̀yin kí ó lè lọ, kí ẹ sì so èso, àti kí èso yín lè dúró; kí ohunkóhun tí ẹ bá béèrè lọ́wọ́ Baba ní orúkọ mi, kí ó lè fi í fún yín.
17 To wam przykazuję, abyście się wzajemnie miłowali.
Nǹkan wọ̀nyí ni mo pàṣẹ fún yín pé, kí ẹ̀yin kí ó fẹ́ràn ara yín.
18 Jeśli świat was nienawidzi, wiedzcie, że znienawidził mnie wcześniej niż was.
“Bí ayé bá kórìíra yín, ẹ mọ̀ pé, ó ti kórìíra mi ṣáájú yín.
19 Gdybyście byli ze świata, świat miłowałby to, co jest jego. Ponieważ jednak nie jesteście ze świata, ale ja was wybrałem ze świata, dlatego świat was nienawidzi.
Ìbá ṣe pé ẹ̀yin ń ṣe ti ayé, ayé ìbá fẹ́ yin bi àwọn tirẹ̀; gẹ́gẹ́ bi o ṣe ri tí ẹ̀yin kì ń ṣe ti ayé, ṣùgbọ́n èmi ti yàn yín kúrò nínú ayé, nítorí èyí ni ayé ṣe kórìíra yín.
20 Przypomnijcie sobie słowo, które wam powiedziałem: Sługa nie jest większy od swego pana. Jeśli mnie prześladowali, to i was będą prześladować. Jeśli moje słowa zachowywali, to i wasze będą zachowywać.
Ẹ rántí ọ̀rọ̀ tí mo ti sọ fún yín pé, ‘Ọmọ ọ̀dọ̀ kò tóbi ju olúwa rẹ̀ lọ.’ Bí wọ́n bá ti ṣe inúnibíni sí mi, wọ́n ó ṣe inúnibíni sí yín pẹ̀lú: bí wọ́n bá ti pa ọ̀rọ̀ mi mọ́, wọ́n ó sì pa tiyín mọ́ pẹ̀lú.
21 Ale będą wam to wszystko czynić z powodu mego imienia, bo nie znają tego, który mnie posłał.
Ṣùgbọ́n gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni wọ́n yóò ṣe sí yín, nítorí orúkọ mi, nítorí tí wọn kò mọ ẹni tí ó rán mi.
22 Gdybym nie przyszedł i nie mówił im, nie mieliby grzechu. Teraz jednak nie mają wytłumaczenia dla swego grzechu.
Ìbá ṣe pé èmi kò ti wá kí n sì ti bá wọn sọ̀rọ̀, wọn kì bá tí ní ẹ̀ṣẹ̀, ṣùgbọ́n nísinsin yìí wọ́n di aláìríwí fún ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
23 Kto mnie nienawidzi, nienawidzi też mego Ojca.
Ẹni tí ó bá kórìíra mi, ó kórìíra Baba mi pẹ̀lú.
24 Gdybym nie spełniał wśród nich tych uczynków, których nikt inny nie spełniał, nie mieliby grzechu. Teraz jednak widzieli i nienawidzili i mnie, i mego Ojca.
Ìbá ṣe pé èmi kò ti ṣe iṣẹ́ wọ̀n-ọn-nì láàrín wọn tí ẹlòmíràn kò ṣe rí, wọn kì bá tí ní ẹ̀ṣẹ̀, ṣùgbọ́n nísinsin yìí wọ́n sì rí, wọ́n sì kórìíra èmi àti Baba mi.
25 Ale [to się stało], żeby się wypełniło słowo, które jest napisane w ich Prawie: Nienawidzili mnie bez powodu.
Ṣùgbọ́n èyí rí bẹ́ẹ̀ kí ọ̀rọ̀ tí a kọ nínú òfin wọn kí ó lè ṣẹ pé, ‘Wọ́n kórìíra mi ní àìnídìí.’
26 Gdy jednak przyjdzie Pocieszyciel, którego ja wam poślę od Ojca, Duch prawdy, który wychodzi od Ojca, on będzie świadczył o mnie.
“Ṣùgbọ́n nígbà tí Olùtùnú náà bá dé, ẹni tí èmi ó rán sí yín láti ọ̀dọ̀ Baba wá, àní Ẹ̀mí òtítọ́ nì, tí ń ti ọ̀dọ̀ Baba wá, òun náà ni yóò jẹ́rìí mi.
27 Ale i wy będziecie świadczyć, bo jesteście ze mną od początku.
Ẹ̀yin pẹ̀lú yóò sì jẹ́rìí mi, nítorí tí ẹ̀yin ti wà pẹ̀lú mi láti ìpilẹ̀ṣẹ̀ wá.