< Hioba 39 >
1 Czy znasz porę, kiedy rodzą górskie kozice? Czy wiesz, kiedy rodzą łanie?
“Ìwọ mọ àkókò ìgbà tí àwọn ewúrẹ́ orí àpáta ń bímọ? Ìwọ sì lè kíyèsi ìgbà tí abo àgbọ̀nrín ń bímọ?
2 Czy możesz zliczyć miesiące, w których noszą [młode]? Czy znasz czas ich porodu?
Ìwọ lè ka iye òṣùpá tí wọn ń pé, ìwọ sì mọ àkókò ìgbà tí wọn ń bímọ.
3 Przykucają, rodzą swoje młode, pozbywają się ich z bólem;
Wọ́n tẹ ara wọn ba, wọ́n bímọ, wọ́n sì mú ìkáàánú wọn jáde.
4 Ich młode wzmacniają się, rosną wśród zboża, odchodzą i już do nich nie wracają.
Àwọn ọmọ wọn rí dáradára, wọ́n dàgbà nínú ọ̀dàn; wọ́n jáde lọ, wọn kò sì tún padà wá sọ́dọ̀ wọn.
5 Kto wypuścił dzikiego osła na wolność i kto rozwiązał jego pęta?
“Ta ni ó jọ̀wọ́ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ oko lọ́wọ́? Tàbí ta ní ó tú ìdè kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó,
6 [Za] dom dałem mu pustynię, a [za] jego mieszkanie słone miejsca.
èyí tí mo fi aginjù ṣe ilé fún, àti ilẹ̀ iyọ̀ ní ibùgbé rẹ̀.
7 On naśmiewa się ze zgiełku miejskiego i nie słucha głosu poganiacza.
Ó rẹ́rìn-ín sí ariwo ìlú, bẹ́ẹ̀ ni òun kò sì gbọ́ igbe darandaran.
8 Wypatruje w górach paszy i szuka wszelkiej zielonej trawy.
Orí àtòlé òkè ńlá ni ibùjẹ oko rẹ̀, òun a sì máa wá ewé tútù gbogbo rí.
9 Czy jednorożec zechce ci służyć albo nocować przy twoim żłobie?
“Àgbáǹréré ha jẹ́ sìn ọ́ bí? Tàbí ó jẹ́ dúró ní ibùjẹ ẹran rẹ ní òru?
10 Czy możesz powrozem zaprzęgać jednorożca do bruzdy? Czy będzie bronował doliny za tobą?
Ìwọ le fi òkun tata de àgbáǹréré nínú aporo? Tàbí ó jẹ́ máa fa ìtulẹ̀ nínú aporo oko tọ̀ ọ́ lẹ́yìn?
11 Czy zaufasz mu, ponieważ jego siła jest wielka? Czy powierzysz mu swoją pracę?
Ìwọ ó gbẹ́kẹ̀lé e nítorí agbára rẹ̀ pọ̀? Ìwọ ó sì fi iṣẹ́ rẹ lé e lọ́wọ́?
12 Czy zawierzysz mu, że zwiezie twoje ziarno i zgromadzi je w twoim spichlerzu?
Ìwọ le gbẹ́kẹ̀lé pé, yóò mú èso oko rẹ̀ wá sílé, àti pé yóò sì kó ọ jọ sínú àká rẹ?
13 Czy [dałeś] pawiowi piękne skrzydła, a skrzydła i pióra strusiowi?
“Ìwọ ni yóò ha fi ìyẹ́ dáradára fún ọ̀kín bí, tàbí ìyẹ́ àti ìhùhù bo ògòǹgò?
14 Składa swoje jaja na ziemię i ogrzewa je w prochu;
Ó yé ẹ̀yìn rẹ̀ sílẹ̀ lórí ilẹ̀, a sì mú wọn gbóná nínú ekuru;
15 I zapomina, że noga może je rozgnieść lub dzikie zwierzę może zdeptać.
tí ó sì gbàgbé pé, ẹsẹ̀ lè tẹ̀ wọ́n fọ́, tàbí pé ẹranko igbó lè tẹ̀ wọ́n fọ́.
16 Jest twardy [dla] swoich młodych, [jakby] nie [były] jego. Nie boi się, że jego trud jest próżny;
Kò ní àánú sí àwọn ọmọ rẹ̀ bí ẹni pé wọn kì í ṣe tirẹ̀; asán ni iṣẹ́ rẹ̀ láìní ìbẹ̀rù;
17 Bo Bóg pozbawił go mądrości i nie udzielił mu rozumu.
nítorí pé Ọlọ́run kò fún un ní ọgbọ́n, bẹ́ẹ̀ ni kò sì fi ìpín òye fún un.
18 Kiedy jednak podnosi się wysoko, naśmiewa się z konia i z jego jeźdźca.
Nígbà tí ó gbé ara sókè, ó gan ẹṣin àti ẹlẹ́ṣin.
19 Czy możesz dać koniowi moc? Czy rżeniem ozdobiłeś jego szyję?
“Ìwọ ni ó fi agbára fún ẹṣin bí, tàbí ṣé ìwọ ni ó fi gọ̀gọ̀ wọ ọrùn rẹ̀ ní aṣọ?
20 Czy przestraszysz go jak szarańczę? Parskanie jego nozdrzy [jest] straszne.
Ìwọ le mú fò sókè bí ẹlẹ́ǹgà? Ògo èémí imú rẹ ní ẹ̀rù ńlá.
21 Grzebie [kopytem] w ziemi i cieszy się [swą] siłą, biegnie przeciwko uzbrojonym.
Ó fi ẹsẹ̀ halẹ̀ nínú àfonífojì, ó sì yọ̀ nínú agbára rẹ̀; ó lọ jáde láti pàdé àwọn ìhámọ́ra ogun.
22 Drwi sobie z lęku i nie boi się, i nie ustępuje przed ostrzem miecza.
Ó fi ojú kékeré wo ẹ̀rù, àyà kò sì fò ó; bẹ́ẹ̀ ni kì í sì í padà sẹ́yìn kúrò lọ́wọ́ idà.
23 Kołczan na nim chrzęści, błyszczy oszczep i dzida.
Lọ́dọ̀ rẹ ni apó-ọfà ń mì pẹkẹpẹkẹ, àti ọ̀kọ̀ dídán àti àpáta.
24 Z grzmotem i z gniewem pochłania ziemię i nie staje spokojnie na głos trąby.
Ó fi kíkorò ojú àti ìbínú ńlá gbé ilé mi, bẹ́ẹ̀ ni òun kò sì gbà á gbọ́ pé, ìró ìpè ni.
25 Na głos trąby mówi: Ha, ha; z daleka czuje bitwę, grom dowódców i okrzyk.
Ó wí nígbà ìpè pé, Háà! Háà! Ó sì gbóhùn ogun lókèèrè réré, igbe àwọn balógun àti ìhó ayọ̀ ogun wọn.
26 Czy dzięki twojemu rozumowi lata jastrząb [i] rozciąga swe skrzydła ku południu?
“Àwòdì ha máa ti ipa ọgbọ́n rẹ̀ fò sókè, tí ó sì na ìyẹ́ apá rẹ̀ sí ìhà gúúsù?
27 Czy na twój rozkaz orzeł wzbija się i zakłada swoje gniazdo wysoko?
Idì ha máa fi àṣẹ rẹ̀ fò sókè, kí ó sì lọ tẹ́ ìtẹ́ rẹ̀ sí òkè gíga?
28 Mieszka na skale, przebywa na iglicach jak na zamku.
Ó ń gbé, ó sì ń wò ní orí àpáta, lórí pàlàpálá òkúta àti ibi orí òkè.
29 Stamtąd wypatruje [sobie] pokarmu, jego oczy widzą daleko.
Láti ibẹ̀ lọ ni ó ti ń wá oúnjẹ kiri, ojú rẹ̀ sì ríran rí òkè réré.
30 Jego młode też piją krew, a gdzie są zabici, tam jest on.
Àwọn ọmọ rẹ̀ pẹ̀lú a máa mu ẹ̀jẹ̀, níbi tí òkú bá gbé wà, níbẹ̀ ni òun wà pẹ̀lú.”