< Hioba 20 >

1 Wtedy Sofar z Naama odpowiedział:
Ìgbà náà ní Sofari, ará Naama dáhùn, ó sì wí pé,
2 Dlatego moje myśli skłaniają mnie do odpowiedzi i z tego powodu [mówię] pośpiesznie.
“Nítorí náà ní ìrò inú mi dá mi lóhùn, àti nítorí èyí náà ní mo sì yára si gidigidi.
3 Słuchałem obraźliwego upomnienia i duch mojego zrozumienia podsuwa mi odpowiedź:
Mo ti gbọ́ ẹ̀san ẹ̀gàn mi, ẹ̀mí òye mi sì dá mi lóhùn.
4 Czy nie wiesz, że od wieków, odkąd człowieka postawiono na ziemi;
“Ìwọ kò mọ̀ èyí rí ní ìgbà àtijọ́, láti ìgbà tí a sọ ènìyàn lọ́jọ̀ sílé ayé,
5 Radość niegodziwych [jest] krótka, a wesołość obłudnika [trwa] okamgnienie?
pé, orin ayọ̀ ènìyàn búburú, ìgbà kúkúrú ni, àti pé, ní ìṣẹ́jú kan ní ayọ̀ àgàbàgebè?
6 Choćby jego wyniosłość sięgała aż do niebios, a jego głowa – do obłoków;
Bí ọláńlá rẹ̀ tilẹ̀ gòkè dé ọ̀run, ti orí rẹ̀ sì kan àwọsánmọ̀;
7 [To jednak] zginie on na wieki jak jego własny gnój, [a] ci, którzy go widzieli, powiedzą: Gdzie [on] się podział?
ṣùgbọ́n yóò ṣègbé láéláé bí ìgbẹ́ ara rẹ̀; àwọn tí ó ti rí i rí yóò wí pé, ‘Òun ha dà?’
8 Uleci jak sen i nie znajdą go; ucieknie jak nocne widzenie.
Yóò fò lọ bí àlá, a kì yóò sì rí i, àní a ó lé e lọ bi ìran òru.
9 Oko, które go widziało, nie zobaczy go więcej, i już nie ujrzy go jego miejsce.
Ojú tí ó ti rí i rí kì yóò sì rí i mọ́, bẹ́ẹ̀ ni ibùjókòó rẹ̀ kì yóò sì ri i mọ́.
10 Jego synowie będą się korzyć przed ubogim, jego ręce zwrócą swe bogactwo.
Àwọn ọmọ rẹ̀ yóò máa wá àti rí ojúrere lọ́dọ̀ tálákà, ọwọ́ rẹ̀ yóò sì kó ọrọ̀ wọn padà.
11 Jego kości są pełne [grzechów] jego młodości, razem z nim spoczną w prochu.
Egungun rẹ̀ kún fún agbára ìgbà èwe rẹ̀, tí yóò bá a dùbúlẹ̀ nínú erùpẹ̀.
12 A choć zło jest słodkie w jego ustach i zataja je pod swoim językiem;
“Bí ìwà búburú tilẹ̀ dún ní ẹnu rẹ̀, bí ó tilẹ̀ pa á mọ́ nísàlẹ̀ ahọ́n rẹ̀,
13 Chociaż rozkoszuje się nim i nie opuszcza go, zatrzymując je na swoim podniebieniu;
bí ó tilẹ̀ dá a sì, tí kò si kọ̀ ọ́ sílẹ̀, tí ó pa á mọ́ síbẹ̀ ní ẹnu rẹ̀,
14 [To jednak] jego pokarm we wnętrznościach przemienia się, [staje się] żółcią żmii w jego wnętrzu.
ṣùgbọ́n oúnjẹ rẹ̀ nínú ikùn rẹ̀ ti yípadà, ó jásí òróró paramọ́lẹ̀ nínú rẹ̀;
15 Połknął bogactwa i zwróci je; Bóg je wyrzuci z jego brzucha.
Ó ti gbé ọrọ̀ mì, yóò sì tún bí i jáde; Ọlọ́run yóò pọ̀ ọ́ yọ jáde láti inú rẹ̀ wá.
16 Będzie ssał jad żmii, zabije go język węża.
Ó ti fà oró paramọ́lẹ̀ mú; ahọ́n ejò olóró ní yóò pa á.
17 Nie zobaczy rzek, potoków, strumieni miodu ani masła.
Kì yóò rí odò wọ̀n-ọn-nì, ìṣàn omi, odò tí ń ṣàn fún oyin àti ti òrí-àmọ́.
18 Zwróci swój zysk i nie połknie go; i choć znowu zdobędzie wielki majątek, nie ucieszy się [z niego].
Ohun tí ó ṣiṣẹ́ fún ni yóò mú un padà, kí yóò sì gbé e mì; gẹ́gẹ́ bí ọrọ̀ tí ó ní, kì yóò sì ìgbádùn nínú rẹ̀.
19 Bo uciskał [i] opuszczał ubogich, przemocą zabrał dom, którego nie zbudował.
Nítorí tí ó fi owó rẹ̀ ni tálákà lára, ó sì ti pẹ̀yìndà si wọ́n; nítorí ti ó fi agbára gbé ilé tí òun kò kọ́.
20 Dlatego nie zazna pokoju w swoim wnętrzu, nie zatrzyma tego, czego pragnął.
“Nítorí òun kò mọ̀ ìwà pẹ̀lẹ́ nínú ara rẹ̀, kì yóò sì gbà nínú èyí tí ọkàn rẹ̀ fẹ́ sílẹ̀.
21 Z jego pokarmów nic nie zostanie, nie rozmnożą się jego dobra.
Ohun kan kò kù fún jíjẹ́ rẹ̀; nítorí náà ọ̀rọ̀ rẹ̀ kì yóò dúró pẹ́.
22 Mimo obfitości jego dostatku dosięgnie go bieda. Wszelka ręka nikczemnych uderzy na niego.
Nínú ànító rẹ̀, ìdààmú yóò dé bá a; àwọn ènìyàn búburú yóò dáwọ́jọ lé e lórí.
23 Gdy będzie miał czym napełnić swój brzuch, [Bóg] ześle na niego zapalczywość swego gniewu, wyleje na niego [i] na jego pokarmy.
Yóò sì ṣe, nígbà tí ó bá fẹ́ jẹun, Ọlọ́run yóò fà ríru ìbínú rẹ̀ sí í lórí, nígbà tó bá ń jẹun lọ́wọ́, yóò sì rọ òjò ìbínú rẹ̀ lé e lórí.
24 [Gdy] będzie uciekał przed żelazną bronią, przebije go łuk spiżowy.
Bi o tilẹ̀ sá kúrò lọ́wọ́ ohun ìjà ìrìn; ọrun akọ irin ní yóò ta a po yọ.
25 Wyjęta będzie [strzała] z grzbietu, a grot przeszyje jego wątrobę; ogarnie go strach.
O fà á yọ, ó sì jáde kúrò lára; idà dídán ní ń jáde láti inú òróòro wá. Ẹ̀rù ńlá ń bẹ ní ara rẹ̀;
26 Wszelka ciemność zaczai się w jego kryjówkach. Pożre go ogień niewzniecony, a ten, kto pozostał w jego przybytku, będzie udręczony.
òkùnkùn biribiri ní a ti pamọ́ fún ìṣúra rẹ̀. Iná ti a kò fẹ́ ní yóò jó o run yóò sì jẹ èyí tí ó kù nínú àgọ́ rẹ̀ run.
27 Niebo odkryje jego nieprawość, a ziemia powstanie przeciwko niemu.
Ọ̀run yóò fi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ hàn, ayé yóò sì dìde dúró sí i.
28 Dobytek jego domu przepadnie, [jego dobra] rozpłyną się w dniu [Bożego] gniewu.
Ìbísí ilé rẹ̀ yóò kọjá lọ, àti ohun ìní rẹ̀ yóò sàn dànù lọ ni ọjọ́ ìbínú Ọlọ́run.
29 Taki [jest] dział Boga dla niegodziwego i dziedzictwo przeznaczone mu przez Boga.
Èyí ni ìpín ènìyàn búburú láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá, àti ogún tí a yàn sílẹ̀ fún un láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.”

< Hioba 20 >