< Jeremiasza 9 >
1 Oby moja głowa była wodą, a moje oczy źródłem łez, abym dniem i nocą opłakiwał pomordowanych córki mego ludu!
Háà! Orí ìbá jẹ́ orísun omi kí ojú mi sì jẹ́ orísun omijé! Èmi yóò sì sọkún tọ̀sán tòru nítorí ìparun àwọn ènìyàn mi.
2 Obym miał na pustyni schronisko dla podróżnych, abym mógł opuścić swój lud i oddalić się od nich! Wszyscy bowiem są cudzołożnikami, zgrają zdrajców;
Háà, èmi ìbá ní ni aginjù ilé àgbàwọ̀ fún àwọn arìnrìn-àjò, kí n ba à lè fi àwọn ènìyàn mi sílẹ̀ kí n sì lọ kúrò lọ́dọ̀ wọn: nítorí gbogbo wọn jẹ́ panṣágà àjọ aláìṣòótọ́ ènìyàn.
3 I [jak] łuk napinają swój język do kłamstwa. Nie wzmocnili się prawdą na ziemi, bo od zła do zła przechodzą, a mnie nie znają, mówi PAN.
Wọ́n ti pèsè ahọ́n wọn sílẹ̀ bí ọfà láti fi pa irọ́; kì í ṣe nípa òtítọ́ ni wọ́n fi borí ní ilẹ̀ náà. Wọ́n ń lọ láti inú ẹ̀ṣẹ̀ kan sí òmíràn; wọn kò sì náání mi, ní Olúwa wí.
4 Niech się każdy strzeże swego bliźniego, a bratu nie ufa, bo każdy brat oszukuje podstępnie i każdy bliźni postępuje jak oszczerca.
“Ṣọ́ra fún àwọn ọ̀rẹ́ rẹ; má ṣe gbẹ́kẹ̀lé àwọn arákùnrin rẹ. Nítorí pé oníkálùkù arákùnrin jẹ́ atannijẹ, oníkálùkù ọ̀rẹ́ sì jẹ́ abanijẹ́.
5 Każdy też oszukuje swego bliźniego i nie mówi prawdy. Przyuczyli swój język do mówienia kłamstwa, męczą się, aby popełnić nieprawość.
Ọ̀rẹ́ ń dalẹ̀ ọ̀rẹ́. Kò sì ṣí ẹni tó sọ òtítọ́, wọ́n ti kọ́ ahọ́n wọn láti máa purọ́. Wọ́n sọ ara wọn di onírẹ̀wẹ̀sì pẹ̀lú ẹ̀ṣẹ̀
6 Twoje mieszkanie jest pośród ludu podstępnego; z powodu podstępu nie chcą mnie poznać, mówi PAN.
Ó ń gbé ní àárín ẹ̀tàn; wọ́n kọ̀ láti mọ̀ mí nínú ẹ̀tàn wọn,” ni Olúwa wí.
7 Dlatego tak mówi PAN zastępów: Oto przetopię ich i wypróbuję; jak bowiem mam postąpić z córką mego ludu?
Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Àwọn ọmọ-ogun wí: “Wò ó, èmi dán wọn wo; nítorí pé kí ni èmi tún le è ṣe? Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn mi?
8 Ich język [jest] śmiercionośną strzałą, wypowiada oszustwa. [Jeden] mówi ustami o pokoju ze swym przyjacielem, ale w sercu zastawia [na niego] sidła.
Ahọ́n wọn dàbí ọfà olóró; ó ń sọ ẹ̀tàn. Oníkálùkù sì ń fi ẹnu rẹ̀ sọ̀rọ̀ àlàáfíà sí aládùúgbò rẹ̀, ní inú ọkàn rẹ̀, ó dẹ tàkúté sílẹ̀.
9 Czyż za to nie [powinienem] ich nawiedzić? – mówi PAN. Czyż nad takim narodem moja dusza nie powinna się zemścić?
Èmi kì yóò ha fi ìyà jẹ wọ́n nítorí èyí?” ni Olúwa wí. “Èmi kì yóò ha gbẹ̀san ara mi lórí irú orílẹ̀-èdè yìí bí?”
10 Z powodu tych gór podniosę płacz i lament, z powodu pastwisk na pustkowiu – pieśń żałobną. Są bowiem spalone tak, że nikt tamtędy nie przechodzi ani odgłosu bydła nie słychać; ptactwo niebieskie i zwierzęta rozbiegły się i odeszły.
Èmi yóò sì sọkún, pohùnréré ẹkún fún àwọn òkè àti ẹkún ìrora lórí pápá oko aginjù wọ̀n-ọn-nì. Nítorí wọ́n di ahoro, wọn kò sì kọjá ní ibẹ̀. A kò sì gbọ́ igbe ẹran ọ̀sìn. Àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run sì ti sálọ, bẹ́ẹ̀ náà ni àwọn ẹranko sì ti lọ.
11 I zamienię Jerozolimę w gruzy, w legowisko smoków, a miasta Judy – w pustkowie, [zostaną] bez mieszkańca.
“Èmi yóò sì sọ Jerusalẹmu di òkìtì àlàpà àti ihò àwọn ìkookò. Èmi ó sì sọ ìlú Juda di ahoro tí ẹnikẹ́ni kò sì ní le è gbé.”
12 Któż jest tak mądry, aby [mógł] to zrozumieć? A do kogo mówiły usta PANA, aby [mógł] ogłosić, dlaczego ziemia ginie [i] jest spalona jak pustynia, tak że przez nią nikt nie przechodzi?
Ta ni ẹni náà tí ó ní ọgbọ́n láti mòye nǹkan wọ̀nyí? Ta ni Olúwa ti sọ èyí fún, tí ó sì lè ṣàlàyé rẹ̀? Èéṣe tí ilẹ̀ náà fi ṣègbé bí aginjù, tí ẹnìkankan kò sì le là á kọjá?
13 PAN bowiem mówi: Dlatego że porzucili moje prawo, które im przedłożyłem, a nie słuchali mojego głosu ani nie szli za nim;
Olúwa sì wí pé, nítorí pé wọ́n ti kọ òfin mi sílẹ̀, èyí tí mo gbé kalẹ̀ níwájú wọn, wọn ṣe àìgbọ́ràn sí wọn, wọn kò sì rìn nínú òfin mi.
14 Ale postępowali według uporu swego serca i [szli] za Baalami, jak ich nauczyli ich ojcowie;
Dípò èyí, wọ́n ti tẹ̀lé agídí ọkàn wọn, wọ́n ti tẹ̀lé Baali gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wọn ṣe kọ́ wọn.
15 Dlatego tak mówi PAN zastępów, Bóg Izraela: Oto nakarmię ich, ten lud, piołunem i napoję ich wodą żółci.
Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí, “Wò ó, Èmi yóò mú kí àwọn ènìyàn wọ̀nyí jẹ oúnjẹ kíkorò àti láti mu omi májèlé.
16 Rozproszę ich między narodami, których nie znali oni ani ich ojcowie, i poślę za nimi miecz, aż ich doszczętnie wytracę.
Èmi yóò sì tú wọn ká láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, nínú èyí tí àwọn tàbí àwọn baba wọn kò mọ̀. Èmi yóò sì lépa wọn pẹ̀lú idà títí èmi yóò fi pa wọ́n run.”
17 Tak mówi PAN zastępów: Zastanówcie się i wezwijcie płaczki, i niech przyjdą; poślijcie po te, które są wyćwiczone w tym, i niech przyjdą.
Èyí sì ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun wí: “Sá à wò ó nísinsin yìí! Ké sí obìnrin ti ń ṣọ̀fọ̀ nì kí ó wá; sì ránṣẹ́ pe àwọn tí ó mòye nínú wọn.
18 Niech się pospieszą, niech podniosą nad nami lament, aby łzami spływały nam oczy i powieki ociekały wodą.
Jẹ́ kí wọn wá kíákíá, kí wọn wá pohùnréré ẹkún lé wa lórí títí ojú wa yóò fi sàn fún omijé tí omi yóò sì máa sàn àwọn ìpéǹpéjú wa.
19 Głos lamentu bowiem słychać z Syjonu: Jakże jesteśmy spustoszeni! Jesteśmy bardzo zawstydzeni, bo opuściliśmy ziemię, zburzono nasze mieszkania.
A gbọ́ igbe ìpohùnréré ẹkún ní Sioni: ‘Àwa ti ṣègbé tó! A gbọdọ̀ fi ilẹ̀ wa sílẹ̀, nítorí pé àwọn ilé wa ti parun.’”
20 Słuchajcie więc, kobiety, słowa PANA, niech wasze ucho przyjmie wyrok jego ust, abyście uczyły wasze córki lamentu, a jedna drugą – pieśni żałobnej.
Nísinsin yìí, ẹ̀yin obìnrin ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa; ṣí etí yín sí ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ. Kọ́ àwọn ọmọbìnrin yín ní ìpohùnréré ẹkún, kí ẹ sì kọ́ ara yín ní arò.
21 Śmierć bowiem wtargnęła przez nasze okna, weszła do naszych pałaców, aby wytracić dzieci na rynku i młodzieńców na ulicach.
Ikú ti gba ojú fèrèsé wa wọlé ó sì ti wọ odi alágbára wa ó ti ké àwọn ọmọ kúrò ní àdúgbò àti àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin kúrò ní gbọ̀ngàn ìta gbangba.
22 Mów: Tak mówi PAN: Nawet trupy ludzkie padną jak gnój na polu i jak snopy za żniwiarzem, a nikt ich nie zbierze.
Sọ pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Òkú àwọn ènìyàn yóò ṣubú bí ààtàn ní oko gbangba àti bí ìbùkúnwọ́ lẹ́yìn olùkórè láìsí ẹnìkankan láti kó wọn jọ.’”
23 Tak mówi PAN: Niech się nie chlubi mądry swoją mądrością, niech się nie chlubi mocarz swoją siłą i niech się nie chlubi bogaty swoim bogactwem;
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Má ṣe jẹ́ kí ọlọ́gbọ́n yangàn nítorí agbára ọgbọ́n rẹ̀, tàbí alágbára nítorí agbára rẹ̀, tàbí ọlọ́rọ̀ nítorí ọrọ̀ rẹ̀.
24 Ale kto chce się chlubić, niech się chlubi tym, że rozumie i zna mnie, [wie], że ja [jestem] PAN, który okazuje miłosierdzie, sąd i sprawiedliwość na ziemi. To bowiem [mi] się podoba, mówi PAN.
Ẹ jẹ́ kí ẹni tí ń ṣògo nípa èyí nì wí pé: òun ní òye, òun sì mọ̀ mí wí pé, Èmi ni Olúwa tí ń ṣe òtítọ́, ìdájọ́ àti òdodo ní ayé, nínú èyí ni mo ní inú dídùn sí,” Olúwa wí.
25 Oto nadchodzą dni, mówi PAN, w których nawiedzę każdego obrzezanego i nieobrzezanego;
“Ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí Èmi yóò fi ìyà jẹ gbogbo àwọn tí a kọ ilà fún nínú ara nìkan.
26 Egipt, Judę, Edom, Ammonitów, Moabitów i wszystkich, którzy są w najdalszych zakątkach i mieszkają na pustyni. Wszystkie te narody bowiem [są] nieobrzezane, a cały dom Izraela ma nieobrzezane serce.
Ejibiti, Juda, Edomu, Ammoni, Moabu àti gbogbo àwọn tí ń gbé ní ọ̀nà jíjìn réré ní aginjù. Nítorí pé gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí jẹ́ aláìkọlà gbogbo àwọn ará ilé Israẹli sì jẹ́ aláìkọlà ọkàn.”