< Jeremiasza 25 >

1 Słowo, które doszło do Jeremiasza o całym ludzie Judy w czwartym roku Joakima, syna Jozjasza, króla Judy, a był to pierwszy rok Nabuchodonozora, króla Babilonu;
Ọ̀rọ̀ sì tọ Jeremiah wá nípa àwọn ènìyàn Juda ní ọdún kẹrin Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda, èyí tí ó jẹ́ ọdún kìn-ín-ní Nebukadnessari ọba Babeli.
2 Które wypowiedział prorok Jeremiasz do całego ludu Judy i do wszystkich mieszkańców Jerozolimy, mówiąc:
Nítorí náà, Jeremiah wòlíì sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn Juda àti sí àwọn olùgbé Jerusalẹmu.
3 Od trzynastego roku Jozjasza, syna Amona, króla Judy, aż do dziś, to [znaczy] już [przez] dwadzieścia trzy lata, dochodziło do mnie słowo PANA i przemawiałem do was z wczesnym wstawaniem i mówieniem, ale nie słuchaliście.
Fún odidi ọdún mẹ́tàlélógún, bẹ̀rẹ̀ láti ọdún kẹtàlá Josiah, ọmọ Amoni ọba Juda, títí di ọjọ́ yìí, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá, mo sì ti sọ ọ́ fún un yín láti ìgbà dé ìgbà, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fetísílẹ̀.
4 PAN też posyłał do was wszystkie swoje sługi, proroków, z wczesnym wstawaniem i przesłaniem, ale nie usłuchaliście ani nie nakłoniliście swego ucha, aby usłyszeć.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Olúwa ti rán gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn wòlíì sí i yín láti ìgbà dé ìgbà, ẹ̀yin kò fetísílẹ̀.
5 Oni mówili: Niech teraz każdy z was się odwróci od swojej złej drogi i od zła swoich uczynków, a będziecie mieszkać w tej ziemi, którą PAN dał wam i waszym ojcom na wieki wieków.
Wọ́n sì wí pé, “Ẹ yípadà olúkúlùkù yín kúrò ní inú ibi rẹ̀ àti ní ọ̀nà ibi rẹ̀, ẹ̀yin yóò sì lè dúró ní ilẹ̀ tí Olúwa fún un yín àti àwọn baba yín títí láéláé.
6 Nie chodźcie za innymi bogami, aby im służyć i oddawać im pokłon, i nie pobudzajcie mnie do gniewu uczynkami waszych rąk, a [ja] nie uczynię wam nic złego.
Má ṣe tọ àwọn ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn láti sìn wọ́n tàbí bọ wọ́n; ẹ má ṣe mú inú bí mi pẹ̀lú ohun tí ẹ ti fi ọwọ́ yín ṣe. Nígbà náà ni Èmi kò ní ṣe yín ní ibi.”
7 Ale nie usłuchaliście mnie, mówi PAN, pobudzając mnie do gniewu uczynkami swoich rąk na własne nieszczęście.
“Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fetí sí mi,” ni Olúwa wí; “bẹ́ẹ̀ ni ẹ sì ti mú inú bí mi pẹ̀lú ohun tí ẹ fi ọwọ́ yín ṣe, ẹ sì ti mú ibi wá sórí ara yín.”
8 Dlatego tak mówi PAN zastępów: Ponieważ nie usłuchaliście moich słów;
Nítorí náà, Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ èyí: “Nítorí wí pé ẹ̀yin kò fetí sí ọ̀rọ̀ mi,
9 Oto poślę po wszystkie rody północne i zbiorę [je], mówi PAN, i Nabuchodonozora, króla Babilonu, swego sługę, i sprowadzę ich na tę ziemię, na jej mieszkańców i na te wszystkie okoliczne narody, a doszczętnie zniszczę ich i uczynię ich [przedmiotem] zdumienia i świstania, i wiecznym spustoszeniem.
Èmi yóò pe gbogbo àwọn ènìyàn àríwá, àti ìránṣẹ́ mi Nebukadnessari ọba Babeli,” ni Olúwa wí. “Èmi yóò sì mú wọn dìde lòdì sí ilẹ̀ náà àti àwọn olùgbé rẹ̀ àti sí gbogbo orílẹ̀-èdè àyíká rẹ̀. Èmi yóò pa wọ́n run pátápátá, Èmi yóò sọ wọ́n di nǹkan ẹ̀rù àti yẹ̀yẹ́ àti ìparun ayérayé.
10 I sprawię, że zaniknie głos wesela i głos radości, głos oblubieńca i głos oblubienicy, odgłos żaren i światło pochodni.
Èmi yóò sì mú ìró ayọ̀ àti inú dídùn kúrò lọ́dọ̀ wọn; ohùn ìyàwó àti ọkọ ìyàwó, ìró ọlọ òkúta àti ìmọ́lẹ̀ fìtílà.
11 I cała ta ziemia stanie się spustoszeniem i zdumieniem, a te narody będą służyć królowi Babilonu przez siedemdziesiąt lat.
Gbogbo orílẹ̀-èdè yìí yóò sì di ahoro, orílẹ̀-èdè yìí yóò sì sìn ọba Babeli ní àádọ́rin ọdún.
12 A gdy się dopełni siedemdziesiąt lat, ukarzę króla Babilonu i ten naród, mówi PAN, za ich nieprawość, oraz ziemię Chaldejczyków, i zamienię ją w wieczne spustoszenie.
“Ṣùgbọ́n, nígbà tí àádọ́rin ọdún náà bá pé, Èmi yóò fi ìyà jẹ ọba Babeli àti orílẹ̀-èdè rẹ, ilẹ̀ àwọn ará Babeli nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn,” ni Olúwa wí; “bẹ́ẹ̀ ni Èmi yóò sọ ọ́ di ahoro títí láé.
13 I sprowadzę na tę ziemię wszystkie moje słowa, które wypowiedziałem przeciw niej, [mianowicie] to wszystko, co jest napisane w tej księdze, co prorokował Jeremiasz przeciw wszystkim narodom.
Èmi yóò sì mú gbogbo ohun tí mo ti sọ wọ̀nyí wá sórí ilẹ̀ náà, gbogbo ohun tí a ti sọ àní gbogbo èyí tí a ti kọ sínú ìwé yìí, èyí tí Jeremiah ti sọtẹ́lẹ̀ sí gbogbo orílẹ̀-èdè.
14 Gdyż i one będą podbite i wzięte do niewoli przez liczne narody i wielkich królów. Odpłacę im według ich czynów i według uczynków ich rąk.
Àwọn fúnra wọn yóò sì sin orílẹ̀-èdè púpọ̀ àti àwọn ọba ńlá. Èmi yóò sì sán fún oníkálùkù gẹ́gẹ́ bí ìṣe àti iṣẹ́ ọwọ́ wọn.”
15 Tak bowiem powiedział do mnie PAN, Bóg Izraela: Weź z mojej ręki kubek wina tej zapalczywości i daj z niego pić wszystkim narodom, do których cię posyłam.
Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí fún mi: “Gba ago yìí ní ọwọ́ mí tí ó kún fún ọtí wáìnì ìbínú mi, kí o sì mú gbogbo orílẹ̀-èdè ti mo rán ọ sí mu ún.
16 Będą pić i zataczać się, a nawet szaleć przed ostrzem miecza, który posyłam między nie.
Nígbà tí wọ́n bá mu ún, wọn yóò ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n: bẹ́ẹ̀ ni kí wọ́n di aṣiwèrè nítorí idà tí yóò ránṣẹ́ sí àárín wọn.”
17 Wziąłem więc kubek z ręki PANA i napoiłem wszystkie narody, do których PAN mnie posłał:
Mo sì gba ago náà lọ́wọ́ Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni mo sì mú gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó rán mi sí mu ún.
18 Jerozolimę i miasta ziemi Judy, jej królów i książąt, aby uczynić ich [przedmiotem] spustoszenia, zdumienia, świstania i przekleństwa, jak [to jest] dzisiaj;
Jerusalẹmu àti àwọn ìlú Juda, àwọn ọba wọn pẹ̀lú àwọn aláṣẹ wọn, láti sọ wọ́n di ohun ìparun, ohun ẹ̀rù, ẹ̀sìn àti ègún, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti rí lónìí yìí.
19 Faraona, króla Egiptu, jego sługi i książąt, oraz cały jego lud;
Farao ọba Ejibiti, àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn aláṣẹ rẹ̀ àti àwọn ènìyàn rẹ̀.
20 Całą różnorodną ludność, wszystkich królów ziemi Uz, wszystkich królów ziemi Filistynów oraz Aszkelon, Gazę, Ekron i resztkę Aszdodu;
Àti gbogbo àwọn ènìyàn àjèjì tí ó wà níbẹ̀; gbogbo àwọn ọba Usi, gbogbo àwọn ọba Filistini, gbogbo àwọn ti Aṣkeloni, Gasa, Ekroni àti gbogbo àwọn ènìyàn tí ó kù sí Aṣdodu.
21 Edom, Moab i synów Ammona;
Edomu, Moabu àti Ammoni;
22 Wszystkich królów Tyru, wszystkich królów Sydonu oraz królów zamorskich wysp;
gbogbo àwọn ọba Tire àti Sidoni; gbogbo àwọn ọba erékùṣù wọ̀n-ọn-nì tí ń bẹ ní ìkọjá Òkun.
23 Dedan, Temę, Buzę i wszystkich [mieszkańców] w najdalszych zakątkach:
Dedani, Tema, Busi àti gbogbo àwọn tí ń gbé lọ́nà jíjìn réré.
24 Wszystkich królów Arabii i wszystkich królów różnorodnej ludności mieszkającej na pustyni;
Gbogbo àwọn ọba Arabia àti àwọn ọba àwọn àjèjì ènìyàn tí ń gbé inú aginjù.
25 Wszystkich królów Zimri, wszystkich królów Elamu i wszystkich królów Medii;
Gbogbo àwọn ọba Simri, Elamu àti Media.
26 I wszystkich królów Północy, bliskich i dalekich, jednego po drugim; wszystkie królestwa ziemi, jakie są na powierzchni ziemi. A król Szeszak będzie po nich pił.
Àti gbogbo àwọn ọba àríwá ní tòsí àti lọ́nà jíjìn, ẹnìkínní lẹ́yìn ẹnìkejì; gbogbo àwọn ìjọba lórí orílẹ̀ ayé. Àti gbogbo wọn, ọba Ṣeṣaki náà yóò sì mu.
27 I powiesz im: Tak mówi PAN zastępów, Bóg Izraela: Pijcie i upijacie się, wymiotujcie i padajcie, aby już nie powstać z powodu miecza, który ja poślę między was.
“Nígbà náà, sọ fún wọn, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Alágbára Israẹli wí. Mu, kí o sì mú àmuyó kí o sì bì, bẹ́ẹ̀ ni kí o sì ṣubú láì dìde mọ́ nítorí idà tí n ó rán sí àárín yín.
28 A jeśli nie zechcą wziąć kubka z twojej ręki, aby pić, wtedy im powiesz: Tak mówi PAN zastępów: Koniecznie będziecie pić.
Ṣùgbọ́n bí wọ́n ba kọ̀ láti gba ago náà ní ọwọ́ rẹ kí wọ́n sì mu ún, sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ: Ẹyin gbọdọ̀ mu ún!
29 Oto bowiem na to miasto, nad którym jest wzywane moje imię, zaczynam sprowadzać nieszczęście, a wy mielibyście pozostać nieukarani? Nie ujdziecie karze, bo ja przyzywam miecz na wszystkich mieszkańców tej ziemi, mówi PAN zastępów.
Wò ó, èmi ń mú ibi bọ̀ sí orí orílẹ̀-èdè tí ó ń jẹ́ orúkọ mi; ǹjẹ́ yóò ha a lè lọ láìjìyà? Ẹ̀yin ń pe idà sọ̀kalẹ̀ sórí gbogbo àwọn olùgbé ayé, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ.’
30 Dlatego ty prorokuj przeciwko nim wszystkie te słowa i powiedz im: PAN zagrzmi z wysoka i ze swego Świętego Przybytku wyda swój głos; zagrzmi nad swoim miejscem zamieszkania; wzniesie okrzyk jak tłoczący winogrona przeciwko wszystkim mieszkańcom tej ziemi.
“Nísinsin yìí, sọ àsọtẹ́lẹ̀ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí nípa wọn: “‘Kí o sì sọ pé, Olúwa yóò bú láti òkè wá, yóò sì bú kíkankíkan sí ilẹ̀ náà. Yóò parí gbogbo olùgbé ayé, bí àwọn tí ń tẹ ìfúntí.
31 I dojdzie wrzawa aż do krańców ziemi, bo PAN prowadzi spór z tymi narodami, sprawuje sąd nad wszelkim ciałem, bezbożnych wyda pod miecz, mówi PAN.
Ìrọ́kẹ̀kẹ̀ yóò wà títí dé òpin ilẹ̀ ayé, nítorí pé Olúwa yóò mú ìdààmú wá sí orí àwọn orílẹ̀-èdè náà, yóò mú ìdájọ́ wá sórí gbogbo ènìyàn, yóò sì fi àwọn olùṣe búburú fún idà,’” ni Olúwa wí.
32 Tak mówi PAN zastępów: Oto nieszczęście przejdzie z narodu na naród, a wielki wicher zerwie się od krańców ziemi.
Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Wò ó! Ibi ń tànkálẹ̀ láti orílẹ̀-èdè kan sí òmíràn; ìjì ńlá yóò sì ru sókè láti òpin ayé.”
33 I pobici przez PANA w tym dniu leżeć będą od krańca ziemi aż po kraniec ziemi; nie będą ich opłakiwać ani zbierać, ani grzebać, będą jak nawóz na polu.
Nígbà náà, àwọn tí Olúwa ti pa yóò wà ní ibi gbogbo, láti ìpẹ̀kun kan sí òmíràn. A kì yóò ṣọ̀fọ̀ wọn, a kì yóò kó wọn jọ tàbí sin wọ́n; ṣùgbọ́n wọn yóò dàbí ààtàn lórí ilẹ̀.
34 Zawódźcie, pasterze, i wołajcie, tarzajcie się w popiele, wy, przewodnicy tej trzody! Dopełniły się bowiem dni waszej rzezi i rozproszenia i padniecie jak drogie naczynie.
Ké, kí ẹ sì pohùnréré ẹkún ẹ̀yin olùṣọ́-àgùntàn, ẹ yí nínú eruku, ẹ̀yin olùdarí agbo ẹran. Nítorí pé ọjọ́ àti pa yín ti dé, ẹ̀yin ó sì ṣubú bí ohun èlò iyebíye.
35 Nie będzie ucieczki dla pasterzy ani ocalenia dla przewodników tej trzody.
Àwọn olùṣọ́-àgùntàn kì yóò rí ibi sálọ kì yóò sì ṣí àsálà fún olórí agbo ẹran.
36 [Będzie słychać] głos wołania pasterzy i zawodzenie przewodników tej trzody, bo PAN spustoszy ich pastwiska.
Gbọ́ igbe àwọn olùṣọ́-àgùntàn, àti ìpohùnréré ẹkún àwọn olórí agbo ẹran; nítorí pé Olúwa ń pa pápá oko tútù wọn run.
37 I będą zniszczone spokojne łąki z powodu zapalczywości gniewu PANA.
Ibùgbé àlàáfíà yóò di ahoro, nítorí ìbínú ńlá Olúwa.
38 Opuścił jak lew swoją jaskinię, bo ich ziemia jest spustoszona z powodu zapalczywości niszczyciela i zapalczywości jego gniewu.
Gẹ́gẹ́ bí kìnnìún yóò fi ibùba rẹ̀ sílẹ̀, ilẹ̀ wọn yóò sì di ahoro, nítorí idà àwọn aninilára, àti nítorí ìbínú ńlá Olúwa.

< Jeremiasza 25 >