< Jeremiasza 21 >

1 Słowo, które doszło do Jeremiasza od PANA, gdy król Sedekiasz posłał do niego Paszchura, syna Malkiasza, i Sofoniasza, syna Maasejasza, kapłana, aby powiedzieli:
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jeremiah wá nígbà tí ọba Sedekiah rán Paṣuri ọmọ Malkiah àti àlùfáà Sefaniah ọmọ Maaseiah sí i; wọ́n wí pé:
2 Poradź się, proszę, PANA w naszej sprawie, bo Nabuchodonozor, król Babilonu, walczy przeciwko nam. Może PAN postąpi z nami zgodnie ze wszystkimi swoimi cudownymi dziełami, aby ten odstąpił od nas.
“Wádìí lọ́wọ́ Olúwa fún wa nítorí Nebukadnessari ọba Babeli ń kọlù wá. Bóyá Olúwa yóò ṣe ìyanu fún wa gẹ́gẹ́ bí ti àtẹ̀yìnwá, kí ó sì yípadà kúrò lọ́dọ̀ wa.”
3 Jeremiasz odpowiedział im: Tak powiedzcie Sedekiaszowi:
Ṣùgbọ́n Jeremiah dáhùn wí pé, “Sọ fún Sedekiah,
4 Tak mówi PAN, Bóg Izraela: Oto odwrócę sprzęt wojenny, który jest w waszych rękach, [i] którym walczycie przeciw królowi Babilonu i przeciwko Chaldejczykom, którzy was oblegli dokoła muru, i zgromadzę ich w środku tego miasta.
‘Èyí ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli wí, Èmi fẹ́ kọjú idà tí ó wà lọ́wọ́ yín sí yín, èyí tí ẹ̀ ń lò láti bá ọba àti àwọn ará Babeli tí wọ́n wà lẹ́yìn odi jà, Èmi yóò sì kó wọn jọ sínú ìlú yìí.
5 A ja [sam] będę walczył przeciwko wam wyciągniętą ręką i mocnym ramieniem, z gniewem, zawziętością i wielką zapalczywością.
Èmi gan an yóò sì bá yín jà pẹ̀lú ohun ìjà olóró nínú ìbínú àti ìrunú líle.
6 I pobiję mieszkańców tego miasta, zarówno ludzi, jak i zwierzęta. Umrą od wielkiej zarazy.
Èmi yóò sì lu gbogbo ìlú yìí, ènìyàn àti ẹranko, gbogbo wọn ni àjàkálẹ̀-ààrùn yóò kọlù tí wọn yóò sì kú.
7 A potem, mówi PAN, wydam Sedekiasza, króla Judy, jego sługi i lud oraz ocalałych w tym mieście od zarazy, od miecza i od głodu w ręce Nabuchodonozora, króla Babilonu, w ręce ich wrogów i w ręce czyhających na ich życie. A on pobije ich ostrzem miecza, nie pożałuje ich ani nie oszczędzi, ani się nie zlituje.
Olúwa sọ pé lẹ́yìn èyí, èmi yóò fi Sedekiah ọba Juda, àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àti àwọn ènìyàn, àti àwọn tí ó kù ní ìlú yìí lọ́wọ́ àjàkálẹ̀-ààrùn àti lọ́wọ́ idà, àti lọ́wọ́ ìyàn; èmi yóò fi wọ́n lé Nebukadnessari ọba Babeli lọ́wọ́, àti lé ọwọ́ àwọn ọ̀tá wọn, àti lé ọwọ́ àwọn tí ń lépa ẹ̀mí wọn, òun yóò sì fi ojú idà pa wọ́n, kì yóò sì dá wọn sí, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò ní ìyọ́nú tàbí ṣàánú wọn.’
8 A ludowi temu powiedz: Tak mówi PAN: Oto kładę przed wami drogę życia i drogę śmierci.
“Síwájú sí i, sọ fún àwọn ènìyàn, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó sọ: Wò ó, Èmi ń fi ọ̀nà ìyè àti ikú hàn yín.
9 Ktokolwiek zostanie w tym mieście, zginie od miecza, z głodu i od zarazy. Kto zaś wyjdzie i podda się Chaldejczykom, którzy was oblegli, pozostanie żywy i jego życie będzie dla niego jak zdobycz.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá dúró sí ìlú yìí yóò ti ipa idà, ìyàn tàbí àjàkálẹ̀-ààrùn kú. Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá jáde tí ó sì jọ̀wọ́ ara rẹ̀ fún àwọn Babeli tí ó ń lépa yín yóò sì yè. Òun yóò sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ̀.
10 Zwróciłem bowiem swoje oblicze przeciwko temu miastu na zło, a nie na dobro, mówi PAN. Będzie wydane w ręce króla Babilonu, a on spali je ogniem.
Mo ti pinnu láti jẹ ìlú yìí ní yà, ni Olúwa wí. A ó sì gbé e fún ọba Babeli, yóò sì run ún pẹ̀lú iná.’
11 Ale do domu króla Judy [powiedz]: Słuchajcie słowa PANA.
“Ẹ̀wẹ̀, wí fún ìdílé ọba Juda pé, ‘Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa.
12 Domu Dawida, tak mówi PAN: Sprawujcie sąd każdego poranka i wybawiajcie uciśnionego z ręki ciemięzcy, aby moja zapalczywość nie wybuchła jak ogień i nie płonął on tak, że nikt nie zdoła go zgasić z powodu zła waszych uczynków.
Ilé Dafidi èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa sọ: “‘Ṣe ìdájọ́ tí ó tọ́ ní àràárọ̀; yọ ọ́ kúrò lọ́wọ́ ẹni tí ó ń ni í lára ẹni tí a ti jà lólè bí bẹ́ẹ̀ kọ́ ìbínú mi yóò jáde síta, yóò sì jó bí iná. Nítorí ibi tí a ti ṣe yóò sì jó láìsí ẹni tí yóò pa á.
13 Oto ja jestem przeciwko tobie, mieszkanko doliny, skało równiny, mówi PAN – [przeciwko] wam, którzy mówicie: Któż nadciągnie na nas? Któż wejdzie do naszych mieszkań?
Mo kẹ̀yìn sí ọ, Jerusalẹmu, ìwọ tí o gbé lórí àfonífojì lórí òkúta tí ó tẹ́jú, ni Olúwa wí. Ìwọ tí o ti wí pé, “Ta ni ó le dojúkọ wá? Ta ni yóò wọ inú ibùgbé wa?”
14 Lecz ja was nawiedzę według owocu waszych uczynków, mówi PAN. Rozniecę ogień w jej lesie, który pochłonie wszystko dokoła niego.
Èmi yóò jẹ ọ ní ìyà gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ ni Olúwa wí. Èmi yóò mú kí iná jó ilé rẹ̀; yóò si jó gbogbo ohun tí ó wà ní àyíká rẹ.’”

< Jeremiasza 21 >