< Jeremiasza 14 >

1 Słowo PANA, które doszło do Jeremiasza w związku z suszą:
Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa sí Jeremiah nípa ti àjàkálẹ̀-ààrùn:
2 Ziemia Judy płacze, a jej bramy osłabły, w szacie żałobnej siedzą na ziemi, a krzyk Jerozolimy się podnosi.
“Juda káàánú, àwọn ìlú rẹ̀ kérora wọ́n pohùnréré ẹkún fún ilẹ̀ wọn, igbe wọn sì gòkè lọ láti Jerusalẹmu.
3 Ich szlachetni posyłają swoje sługi po wodę. A gdy przyszli do cystern, nie znaleźli wody i powrócili z pustymi naczyniami. Zapłonęli i zawstydzili się, i zakryli swoje głowy.
Àwọn ọlọ́lá ènìyàn rán àwọn ìránṣẹ́ wọn lọ bu omi, wọ́n lọ sí ìdí àmù ṣùgbọ́n wọn kò rí omi. Wọ́n padà pẹ̀lú ìkòkò òfìfo; ìrẹ̀wẹ̀sì àti àìnírètí bá wọn, wọ́n sì bo orí wọn.
4 Z powodu spękanej ziemi – bo nie było deszczu na ziemi – oracze ze wstydu zakryli swoje głowy.
Ilẹ̀ náà sán nítorí pé kò sí òjò ní ilẹ̀ náà; ìrètí àwọn àgbẹ̀ di òfo, wọ́n sì bo orí wọn.
5 Nawet łania rodząca na polu porzuciła [młode], bo nie było trawy.
Kódà, abo àgbọ̀nrín tí ó wà lórí pápá fi ọmọ rẹ̀ tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ bí sílẹ̀, torí pé kò sí koríko.
6 A dzikie osły, stojąc na wysokich miejscach, chwyciły wiatr jak smoki; ich oczy osłabły, bo nie było trawy.
Àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó dúró lórí òkè òfìfo wọ́n sì ń mí ẹ̀fúùfù bí ìkookò ojú wọn kò ríran nítorí pé kò sí koríko jíjẹ.”
7 PANIE, chociaż nasze nieprawości świadczą przeciwko nam, działaj przez wzgląd na twoje imię. Liczne są bowiem nasze odstępstwa, zgrzeszyliśmy przeciwko tobie.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ̀ṣẹ̀ wa jẹ́rìí lòdì sí wa, wá nǹkan kan ṣe sí i Olúwa, nítorí orúkọ rẹ. Nítorí ìpadàsẹ́yìn wa ti pọ̀jù, a ti ṣẹ̀ sí ọ.
8 Nadziejo Izraela, jego Zbawicielu w czasie utrapienia, czemu jesteś jak przybysz w tej ziemi, jak podróżny, który zatrzymuje się na nocleg?
Ìrètí Israẹli; ìgbàlà rẹ lásìkò ìpọ́njú, èéṣe tí ìwọ dàbí àlejò ní ilẹ̀ náà bí arìnrìn-àjò tí ó dúró fún bí òru ọjọ́ kan péré?
9 Czemu jesteś jak człowiek osłupiały [albo] jak mocarz, który nie może wybawić? Ty jednak jesteś pośród nas, PANIE, i twoje imię jest wzywane nad nami. Nie opuszczaj nas.
Èéṣe tí ìwọ dàbí ẹni tí a dààmú, bí jagunjagun tí kò le ran ni lọ́wọ́? Ìwọ wà láàrín wa, Olúwa, orúkọ rẹ ni a sì ń pè mọ́ wa; má ṣe fi wá sílẹ̀.
10 Tak mówi PAN o tym ludzie: Tak kochają błądzić, swoich nóg nie powstrzymają; dlatego PAN nie ma w nich upodobania, teraz wspomina ich nieprawość i nawiedza ich [za ich] grzechy.
Báyìí ni Olúwa sọ nípa àwọn ènìyàn wọ̀nyí: “Wọ́n fẹ́ràn láti máa rìn kiri; wọn kò kó ọkàn wọn ní ìjánu. Nítorí náà Olúwa kò gbà wọ́n; yóò wá rántí ìwà búburú wọn báyìí, yóò sì fi ìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn jẹ wọ́n.”
11 Potem PAN powiedział do mnie: Nie módl się o dobro tego ludu.
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún mi pé, “Má ṣe gbàdúrà fún àlàáfíà àwọn ènìyàn wọ̀nyí.
12 Gdy będą pościć, nie wysłucham ich wołania, a gdy będą składać całopalenia i ofiarę z pokarmów, nie przyjmę tego, ale wytracę ich mieczem, głodem i zarazą.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n gbààwẹ̀, èmi kò ní tẹ́tí sí igbe wọn. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n rú ẹbọ sísun àti ẹbọ ìyẹ̀fun, èmi ò nígbà wọ́n. Dípò bẹ́ẹ̀, èmi ó fi idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn pa wọ́n run.”
13 Wtedy powiedziałem: Ach, Panie BOŻE! Oto prorocy mówią im: Nie zobaczycie miecza ani nie dotknie was głód, ale dam wam trwały pokój na tym miejscu.
Ṣùgbọ́n mo sọ pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè. Àwọn wòlíì ń sọ fún wọn pé, ‘Ẹ kò ni rí idà tàbí ìyàn. Dájúdájú èmi ó fún yín ní àlàáfíà tí yóò tọ́jọ́ níbí yìí?’”
14 I PAN powiedział do mnie: Ci prorocy fałszywie prorokują w moje imię. Nie posłałem ich ani im [niczego] nie nakazywałem, ani nie mówiłem do nich. Prorokują wam kłamliwe widzenie i wróżbę, marność i urojenie swego serca.
Nígbà náà Olúwa sọ fún mi pé, “Àwọn wòlíì ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké ní orúkọ mi. Èmi kò rán wọn, tàbí yàn wọ́n tàbí bá wọn sọ̀rọ̀. Ìran èké ni wọ́n ń rí sí i yín. Àsọtẹ́lẹ̀ èké ni wọ́n ń sọ fún un yín nípa ìran ìrírí, àfọ̀ṣẹ, ìbọ̀rìṣà àti ìtànjẹ ọkàn wọn.
15 Dlatego tak mówi PAN o prorokach, którzy prorokują w moje imię, chociaż ich nie posłałem, i którzy mówią: Miecza i głodu nie będzie w tej ziemi. Ci sami prorocy od miecza i głodu zginą.
Nítorí náà, èyí ni Olúwa sọ nípa àwọn wòlíì tí wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ lórúkọ mi. Èmi kò rán wọn, síbẹ̀ wọ́n sì ń sọ pé, ‘Idà kan tàbí ìyàn, kì yóò dé ilẹ̀ yìí.’ Àwọn wòlíì kan náà yóò parẹ́ nípa idà àti ìyàn.
16 A ten lud, któremu oni prorokują, będzie wyrzucony na ulice Jerozolimy z powodu głodu i miecza i nie będzie nikogo, kto by pogrzebał ich samych ani ich żon, ani ich synów i córek. Tak wyleję na nich ich niegodziwość.
Bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn ènìyàn tí wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ fún ni a ó lé sí òpópónà Jerusalẹmu torí idà àti ìyàn. Wọn kò ní i rí ẹni tí yóò sìn wọ́n tàbí ìyàwó wọn, àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn. Èmi yóò mú ìdààmú tí ó yẹ bá ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn.
17 Dlatego powiesz im to słowo: Moje oczy wylewają łzy w nocy i we dnie, bez przerwy, bo dziewicza córka mego ludu została dotknięta wielką klęską, ciosem bardzo bolesnym.
“Kí ìwọ kí ó sì sọ ọ̀rọ̀ yìí fún wọn pé: “‘Jẹ́ kí ojú mi kí ó sun omijé ní ọ̀sán àti ní òru láìdá; nítorí tí a ti ṣá wúńdíá, ọmọ ènìyàn mi ní ọgbẹ́ ńlá pẹ̀lú lílù bolẹ̀.
18 Jeśli wychodzę na pole – oto pobici mieczem, jeśli wchodzę do miasta – oto ginący od głodu. Tak, zarówno prorok, jak i kapłan kupczą ziemią, a [ludzie] tego nie zauważają.
Bí mo bá lọ sí orílẹ̀-èdè náà, Èmi yóò rí àwọn tí wọ́n fi idà pa. Bí mo bá lọ sí ìlú ńlá, èmi rí àwọn tí ìyàn ti sọ di aláàrùn. Wòlíì àti Àlùfáà ti lọ sí ilẹ̀ tí wọn kò mọ̀.’”
19 Czy całkowicie odrzucasz Judę? Czy twoja dusza obrzydziła sobie Syjon? Czemu nas bijesz, tak że już nie ma dla nas uzdrowienia? Oczekiwaliśmy pokoju, ale nie [ma] nic dobrego; [oczekiwaliśmy] czasu uleczenia, a oto trwoga.
Ṣé o ti kọ Juda sílẹ̀ pátápátá ni? Ṣé o ti ṣá Sioni tì? Èéṣe tí o fi pọ́n wa lójú tí a kò fi le wò wá sàn? A ń retí àlàáfíà ṣùgbọ́n ohun rere kan kò tí ì wá, ní àsìkò ìwòsàn ìpayà là ń rí.
20 Uznajemy, PANIE, swoją niegodziwość i nieprawość naszych ojców, bo zgrzeszyliśmy przeciw tobie.
Olúwa, a jẹ́wọ́ ìwà ibi wa àti àìṣedéédéé àwọn baba wa; lóòótọ́ ni a ti ṣẹ̀ sí ọ.
21 Nie odrzucaj [nas] przez wzgląd na twoje imię, nie dopuść do znieważenia tronu swojej chwały. Pamiętaj o swoim przymierzu i nie zrywaj go z nami.
Nítorí orúkọ rẹ má ṣe kórìíra wa; má ṣe sọ ìtẹ́ ògo rẹ di àìlọ́wọ̀. Rántí májẹ̀mú tí o bá wa dá kí o má ṣe dà á.
22 Czy wśród marności pogan są takie, co spuszczają deszcz? Czy niebiosa mogą [same] dawać deszcze? Czy to nie ty, PANIE, nasz Boże? Dlatego oczekujemy ciebie, bo ty czynisz to wszystko.
Ǹjẹ́ èyíkéyìí àwọn òrìṣà yẹ̀yẹ́ tí àwọn orílẹ̀-èdè le ṣe kí òjò rọ̀? Ǹjẹ́ àwọsánmọ̀ fúnra rẹ̀ rọ òjò bí? Rárá, ìwọ ni, Olúwa Ọlọ́run wa. Torí náà, ìrètí wa wà lọ́dọ̀ rẹ, nítorí pé ìwọ lo ń ṣe gbogbo nǹkan wọ̀nyí.

< Jeremiasza 14 >