< Ozeasza 4 >

1 Słuchajcie słowa PANA, synowie Izraela, bo PAN wnosi skargę przeciwko mieszkańcom tej ziemi, gdyż nie ma prawdy ani żadnego miłosierdzia, ani poznania Boga [w] ziemi.
Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin ọmọ Israẹli, nítorí pé Olúwa fi ẹ̀sùn kan ẹ̀yin tí ń gbé ní ilẹ̀ náà. “Kò sí ìwà òtítọ́, kò sí ìfẹ́, Kò sí ìmọ̀ Ọlọ́run ní ilẹ̀ náà,
2 Krzywoprzysięstwo, kłamstwo, zabójstwo, kradzież i cudzołóstwo mnożą się, a morderstwo goni morderstwo.
àfi èpè, irọ́ pípa àti ìpànìyàn olè jíjà àti panṣágà. Wọ́n rú gbogbo òfin, ìtàjẹ̀ sílẹ̀ sì ń gorí ìtàjẹ̀ sílẹ̀.
3 Dlatego ziemia będzie lamentować i marnieje wszystko, co w niej mieszka, wraz z polnymi zwierzętami i ptactwem nieba, nawet ryby morskie wyginą.
Nítorí èyí, ilẹ̀ náà ń ṣọ̀fọ̀, gbogbo olùgbé ibẹ̀ sì ń ṣòfò dànù. Ẹranko igbó àti ẹyẹ ojú ọ̀run àti ẹja inú omi ló ń kú.
4 Ale niech nikt z nimi się nie spiera ani ich nie strofuje, bo twój lud [jest] jak ci, którzy spierają się z kapłanem.
“Ṣùgbọ́n kí ẹnikẹ́ni má ṣe mú ẹ̀sùn wá, kí ẹnìkan má sì ṣe fi ẹ̀sùn kan ẹnìkejì nítorí àwọn ènìyàn rẹ̀ dàbí àwọn ti ń fi ẹ̀sùn kan àlùfáà.
5 Dlatego upadniesz we dnie, upadnie też wraz z tobą prorok w nocy; wyniszczę twoją matkę.
Ẹ ń ṣubú lọ́sàn án àti lóru àwọn wòlíì yín sì ń ṣubú pẹ̀lú yín. Èmi ó pa ìyá rẹ run,
6 Mój lud ginie z braku poznania; a ponieważ ty odrzuciłeś poznanie, ja też ciebie odrzucę, abyś [już] nie był dla mnie kapłanem. Skoro zapomniałeś o prawie twego Boga, ja też zapomnę o twoich synach.
àwọn ènìyàn mi ń ṣègbé nítorí pé wọn kò ní ìmọ̀. “Nítorí pé ẹ ti kọ ìmọ̀ sílẹ̀. Èmi náà kọ̀ yín ní àlùfáà mi; nítorí pé ẹ ti kọ òfin Ọlọ́run yín sílẹ̀, Èmi náà yóò gbàgbé àwọn ọmọ yín.
7 Im bardziej się rozmnożyli, tym więcej grzeszyli przeciwko mnie. [Dlatego] ich chwałę zamienię w hańbę.
Bí àwọn àlùfáà ṣe ń pọ̀ sí i bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe ń dẹ́ṣẹ̀ sí mi. Wọ́n yí ògo mi padà sí ohun ìtìjú
8 Pożerają ofiary za grzech mego ludu i swoją duszą pragną jego nieprawości.
wọ́n ń jẹun nípa ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn mi, wọ́n sì ń gbádùn nínú ìwà búburú wọn.
9 I tak samo stanie się z ludem jak z kapłanem, bo ukarzę ich za ich drogi i oddam im za ich uczynki.
Yóò sì ṣe gẹ́gẹ́ bí ènìyàn ṣe rí náà ni àwọn àlùfáà rí. Èmi ó jẹ gbogbo wọn ní yà nítorí ọ̀nà wọn. Èmi ó sì san án fún wọn gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ wọn.
10 Będą jeść, ale się nie nasycą, będą uprawiać nierząd, ale się nie pomnożą, bo nie chcą zważać na PANA.
“Wọn ó máa jẹun ṣùgbọ́n wọn kò ní yó; wọn ó ṣe àgbèrè ṣùgbọ́n, wọn kò ni pọ̀ sí i, nítorí pé wọ́n ti kọ Olúwa sílẹ̀, wọ́n sì ti fi ara wọn
11 Nierząd, wino i moszcz odbierają serce.
fún àgbèrè; wọ́n fi ara wọn fún wáìnì àtijọ́, àti tuntun èyí tó gba òye àwọn ènìyàn mi sọnù.
12 Mój lud radzi się u swego drewna, a jego kij mu odpowiada, bo duch nierządu wprowadza ich w błąd i uprawiali nierząd, odstępując od swego Boga.
Wọ́n ń gba ìmọ̀ràn lọ́wọ́ ère igi ọ̀pá igi sì ń dá wọn lóhùn. Ẹ̀mí àgbèrè ti mú wọn ṣìnà wọ́n sì jẹ́ aláìṣòótọ́ sí Ọlọ́run wọn.
13 Na szczytach gór składają ofiary i na pagórkach palą kadzidło pod dębem, topolą i wiązem, bo ich cień jest dobry. Dlatego wasze córki uprawiają nierząd i wasze kobiety cudzołożą.
Wọ́n ń rú ẹbọ lórí àwọn òkè ńlá, wọ́n sì ń sun ọrẹ tùràrí lórí àwọn òkè kékeré, lábẹ́ igi óákù, àti igi Poplari àti igi ẹlimuati onírúurú igi tí ìbòjú rẹ̀ dára. Nítorí náà àwọn ọmọbìnrin yín yóò ṣe àgbèrè àti àwọn àfẹ́sọ́nà yín yóò ṣe àgbèrè.
14 Nie będę karał waszych córek, gdy uprawiają nierząd, ani waszych kobiet, gdy cudzołożą. Oni [sami] bowiem odłączają się z nierządnicami i składają ofiary wraz z nierządnicami. A lud, który [tego] nie rozumie, upadnie.
“Èmi kò ní jẹ àwọn ọmọbìnrin yín ní yà nígbà tí wọ́n bá ṣe àgbèrè tàbí àwọn àfẹ́sọ́nà ọmọ yín, nígbà tí wọ́n bá ṣe àgbèrè nítorí pé àwọn ọkùnrin pàápàá ń bá alágbèrè kẹ́gbẹ́. Wọ́n sì ń rú ẹbọ pẹ̀lú àwọn alágbèrè ojúbọ òrìṣà. Nítorí náà, ènìyàn tí kò bá ní òye yóò parun!
15 Jeśli ty, Izraelu, uprawiasz nierząd, niech [chociaż] Juda nie obciąży się winą. Nie idźcie do Gilgal ani nie wstępujcie do Bet-Awen, ani nie przysięgajcie: Jak żyje PAN!
“Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé o ṣe àgbèrè ìwọ Israẹli, ìdájọ́ yìí wà fún un yín. Ẹ má ṣe jẹ́ kí Juda di ẹlẹ́bi. “Ẹ má ṣe lọ sí Gilgali. Ẹ má sì ṣe gòkè lọ sí Beti-Afeni ẹ má sì búra pé, ‘Bí Olúwa ti wà láààyè nítòótọ́!’
16 Izrael bowiem jest nieujarzmiony jak narowista jałówka. Zaprawdę, PAN będzie ich paść jak jagnię na rozległym miejscu.
Àwọn ọmọ Israẹli ṣe agídí bí alágídí ọmọ màlúù. Báwo wá ni Olúwa ṣe fẹ́ bọ́ wọn bí àgùntàn ní pápá oko tútù?
17 Efraim związał się z bożkami. Zostaw go.
Efraimu ti darapọ̀ mọ́ òrìṣà, ẹ fi sílẹ̀!
18 Ich napój czyni ich upartymi; nieustannie uprawiają nierząd; jego obrońcy wstydliwie kochają dary.
Bí ohun mímu wọn bá tilẹ̀ tán, wọ́n tún tẹ̀síwájú nínú àgbèrè. Àwọn olórí wọn fẹ́ràn ohun ìtìjú ju ohun ìyìn lọ.
19 Pochwyci ich wiatr swoimi skrzydłami i będą zawstydzeni z powodu swoich ofiar.
Ìjì ni yóò gbá wọn lọ. Gbogbo ìrúbọ wọn yóò sì kó ìtìjú bá wọn.

< Ozeasza 4 >