< Ozeasza 11 >

1 Gdy Izrael był dzieckiem, umiłowałem go, a z Egiptu wezwałem mego syna.
“Nígbà tí Israẹli wà ní ọmọdé mo fẹ́ràn rẹ̀, mo sì pe ọmọ mi jáde láti Ejibiti wá.
2 [Prorocy] wzywali ich, ale oni tym bardziej odchodzili sprzed ich oblicza. Składali ofiary Baalom i palili kadzidło rzeźbionym bożkom.
Bí a ti ń pe wọn, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe ń sá kúrò lọ́dọ̀ mi, wọn rú ẹbọ sí Baali, wọn sì fi tùràrí jóná sí ère fínfín.
3 Postawiłem Efraima na nogi, biorąc ich na ramiona, ale nie chcieli poznać, że ja ich wyleczyłem.
Lóòtítọ́ mo kọ́ Efraimu pẹ̀lú ní ìrìn mo di wọ́n mú ní apá, ṣùgbọ́n wọn kò mọ̀ pé mo ti mú wọn láradá.
4 Ciągnąłem ich powrozami ludzkimi, więzami miłości, a byłem dla nich jak [ci], którzy zdejmują jarzmo z ich szczęk, i podawałem im pokarm.
Mo fi okùn ènìyàn fà wọ́n àti ìdè ìfẹ́. Mo mú àjàgà kúrò ni ọrùn wọn, Mo sì fi ara balẹ̀ fún wọn ni oúnjẹ.
5 Nie wróci on do ziemi Egiptu, ale Asyryjczyk [będzie] jego królem, gdyż nie chcieli się nawrócić.
“Ṣé wọn ò wá ní padà sí Ejibiti bí. Ṣé Asiria kò sì ní jẹ ọba lé wọn lórí bí nítorí pé wọ́n kọ̀ jálẹ̀ láti ronúpìwàdà?
6 Ponadto miecz będzie trwać w jego miastach, zniszczy jego gałęzie i pożre [je] z powodu ich rad.
Idà yóò kọ mọ̀nà ní gbogbo ìlú wọn yóò si bá gbogbo irin ẹnu odi ìlú wọn jẹ́ yóò sì fi òpin sí gbogbo èrò wọn.
7 Mój lud jest skłonny do odstępowania ode mnie, a chociaż wezwano go do Najwyższego, nikt [go] nie wywyższa.
Àwọn ènìyàn mi ti pinnu láti pẹ̀yìndà kúrò lọ́dọ̀ mi bí wọ́n tilẹ̀ pè wọ́n sọ́dọ̀ Ọ̀gá-ògo jùlọ, kò ní gbé wọn ga rárá.
8 Jakże mógłbym cię porzucić, Efraimie? [Jakże] mógłbym cię wydać, Izraelu? Jakże mógłbym cię równać z Admą [i] postąpić z tobą jak z Seboim? Moje serce odmieniło się we mnie, moja litość poruszyła się.
“Báwo ni èmi ó ṣe fi ọ́ sílẹ̀, Efraimu? Báwo ni èmi ó ṣe yọ̀ǹda rẹ̀, Israẹli? Báwo ni mo ṣe lè ṣe ọ bi i Adma? Báwo ni mo ṣe lè ṣe ọ bi i Seboimu? Ọkàn mi yípadà nínú mi àánú mi sì ru sókè.
9 Nie wykonam zapalczywości swojego gniewu i nie zniszczę Efraima ponownie, bo jestem Bogiem, a nie człowiekiem; Święty pośród ciebie. I nie nadciągnę przeciwko miastu.
Èmi kò ni mú ìbínú gbígbóná mi ṣẹ, tàbí kí èmi wá sọ Efraimu di ahoro. Nítorí pé èmi ni Ọlọ́run, àní, èmi kì í ṣe ènìyàn. Ẹni mímọ́ láàrín yín, Èmi kò ní í wá nínú ìbínú.
10 Pójdą za PANEM, który jak lew będzie ryczał. Gdy zaryczy, synowie z drżeniem przybiegną z zachodu.
Wọn yóò máa tẹ̀lé Olúwa; òun yóò bú ramúramù bí i kìnnìún. Nígbà tó bá bú, àwọn ọmọ rẹ yóò wá ní ìwárìrì láti ìwọ̀-oòrùn.
11 Przybiegną z drżeniem jak ptaki z Egiptu i jak gołębica z ziemi Asyrii i posadzę ich w ich domach, mówi PAN.
Wọn ó wá pẹ̀lú ẹ̀rù bí i ẹyẹ láti Ejibiti, bí i àdàbà láti Asiria, Èmi ó mú wọn padà sí ilé wọn,” ni Olúwa wí.
12 Efraim otoczył mnie kłamstwem, a dom Izraela – zdradą, gdy Juda jeszcze panuje z Bogiem i jest wierny ze świętymi.
Efraimu tí fi irọ́ yí mi ká ilé Israẹli pẹ̀lú ẹ̀tàn. Ṣùgbọ́n Juda sì dúró ṣinṣin pẹ̀lú Ọlọ́run. Ó sì ṣe olóòtítọ́ sí Ẹni mímọ́ Israẹli.

< Ozeasza 11 >