< Rodzaju 30 >

1 Gdy Rachela widziała, że nie rodzi dzieci Jakubowi, zazdrościła swej siostrze i powiedziała do Jakuba: Daj mi dzieci, bo inaczej umrę.
Nígbà tí Rakeli rí i pe òun kò bímọ, ó bẹ̀rẹ̀ sí ṣe ìlara sí Lea, arábìnrin rẹ̀, ó sì wí fún Jakọbu pé, “Fún mi lọ́mọ, bí kò ṣe bẹ́ẹ̀, èmi ó kú!”
2 Jakub rozgniewał się na Rachelę i powiedział: Czy ja jestem Bogiem, który odmówił ci owocu twego łona?
Inú sì bí Jakọbu sí i, ó sì wí pé, “Èmi ha wà ní ipò Ọlọ́run, ẹni tí ó mú ọ yàgàn bí?”
3 A [ona] odpowiedziała: Oto moja służąca Bilha. Obcuj z nią i urodzi na moich kolanach, i będę miała z niej dzieci.
Nígbà náà ni Rakeli wí pé, “Biliha ìránṣẹ́bìnrin mi nìyìí, bá a lòpọ̀, kí ó ba à le bí ọmọ fún mi, kí èmi si le è tipasẹ̀ rẹ̀ ní ọmọ.”
4 Dała mu więc swoją służącą Bilhę za żonę, a Jakub z nią obcował.
Báyìí ni Rakeli fi Biliha fún Jakọbu ní aya, ó sì bá a lòpọ̀.
5 Bilha poczęła i urodziła Jakubowi syna.
Biliha sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan fún Jakọbu.
6 I Rachela powiedziała: Bóg mnie osądził i usłyszał mój głos, i dał mi syna. Dlatego nadała mu imię Dan.
Rakeli sì wí pé, “Ọlọ́run ti ṣe ìdájọ́ mi; ó sì ti gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ mi, ó sì fún mi ni ọmọkùnrin kan.” Nítorí ìdí èyí ni ó ṣe pe orúkọ rẹ̀ ní Dani.
7 Potem Bilha, służąca Racheli, znowu poczęła i urodziła Jakubowi drugiego syna.
Biliha, ọmọ ọ̀dọ̀ Rakeli sì tún lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kejì fún Jakọbu.
8 Wtedy Rachela powiedziała: Dzielnie walczyłam z moją siostrą i zwyciężyłam. I nadała mu imię Neftali.
Nígbà náà ni Rakeli wí pé, “Mo ti bá ẹ̀gbọ́n mi ja ìjàkadì ńlá, èmi sì ti borí.” Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Naftali.
9 A gdy Lea widziała, że przestała rodzić, wzięła swoją służącą Zilpę i dała ją Jakubowi za żonę.
Nígbà tí Lea sì ri pé òun ko tún lóyún mọ́, ó sì fi ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ obìnrin, Silipa fún Jakọbu bí aya.
10 I Zilpa, służąca Lei, urodziła Jakubowi syna.
Silipa ọmọ ọ̀dọ̀ Lea sì bí ọmọkùnrin kan fún Jakọbu.
11 Wtedy Lea powiedziała: Przyszedł oddział. I nadała mu imię Gad.
Nígbà náà ni Lea wí pé, “Orí rere ni èyí!” Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Gadi.
12 Potem Zilpa, służąca Lei, urodziła Jakubowi drugiego syna.
Silipa ọmọ ọ̀dọ̀ Lea sì tún bí ọmọkùnrin kejì fún Jakọbu.
13 I Lea powiedziała: To na moje szczęście, bo kobiety będą mnie nazywać szczęśliwą. I nadała mu imię Aszer.
Nígbà náà ni Lea wí pé, “Mo ní ayọ̀ gidigidi! Àwọn ọmọbìnrin yóò sì máa pe mí ní Alábùkún fún.” Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Aṣeri.
14 A w czasie żniwa pszenicznego Ruben wyszedł i znalazł na polu mandragory, i przyniósł je do swojej matki Lei. Wtedy Rachela powiedziała do Lei: Daj mi, proszę, z mandragor twego syna.
Ní ọjọ́ kan, ní àkókò ìkórè ọkà jéró, Reubeni jáde lọ sí oko, ó sì rí èso mándrákì, ó sì mú un tọ Lea ìyá rẹ̀ wá. Rakeli sì wí fún Lea pé, “Jọ̀wọ́ fún mi ní ara èso mándrákì tí ọmọ rẹ mú wá.”
15 A ona jej odpowiedziała: Mało ci, że zabrałaś mi mojego męża, to teraz chcesz też zabrać mandragory mego syna? Wtedy Rachela powiedziała: Niech śpi z tobą tej nocy za mandragory twego syna.
Ṣùgbọ́n Lea dalóhùn pé, “Ọkọ mi tí o gbà kò tó kọ́? Ṣe ìwọ yóò tún gba èso mándrákì ọmọ mi pẹ̀lú?” Rakeli sì dáhùn pé, “Ó dára, yóò sùn tì ọ́ lálẹ́ yìí nítorí èso mándrákì ọmọ rẹ.”
16 A gdy Jakub wracał wieczorem z pola, Lea wyszła mu naprzeciw i powiedziała: Masz do mnie przyjść, bo nabyłam cię za mandragory mego syna. I spał z nią tej nocy.
Nítorí náà, nígbà tí Jakọbu ti oko dé ní ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ náà, Lea jáde lọ pàdé rẹ̀, ó sì wí pé, “O ní láti sun ọ̀dọ̀ mi ní alẹ́ yìí nítorí mo ti fi èso mándrákì tí ọmọ mi wá bẹ̀ ọ́ lọ́wẹ̀.” Nítorí náà ni Jakọbu sùn tì í ní alẹ́ ọjọ́ náà.
17 A Bóg wysłuchał Leę i poczęła, i urodziła Jakubowi piątego syna.
Ọlọ́run sì gbọ́ ti Lea, ó sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin karùn-ún fún Jakọbu.
18 I Lea powiedziała: Bóg [mi] oddał moją zapłatę za to, że dałam moją służącą swemu mężowi. I nadała mu imię Issachar.
Nígbà náà ni Lea wí pé, “Ọlọ́run ti sẹ̀san ọmọ ọ̀dọ̀ mi ti mo fi fún ọkọ mi fún mi,” ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Isakari.
19 Potem Lea znowu poczęła i urodziła Jakubowi szóstego syna.
Lea sì tún lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kẹfà fún Jakọbu.
20 I Lea mówiła: Bóg obdarzył mnie wspaniałym darem. Teraz mój mąż będzie ze mną mieszkał, bo urodziłam mu sześciu synów. I nadała mu imię Zebulon.
Nígbà náà ni Lea tún wí pé “Ọlọ́run ti fún mi ní ẹ̀bùn iyebíye, nígbà yìí ni ọkọ mi yóò máa bu ọlá fún mi.” Nítorí náà ni ó ṣe pe orúkọ rẹ̀ ni Sebuluni.
21 Potem urodziła córkę i nadała jej imię Dina.
Lẹ́yìn èyí, ó sì bí ọmọbìnrin kan, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Dina.
22 Bóg wspomniał też na Rachelę i wysłuchał ją Bóg, i otworzył jej łono.
Nígbà náà ni Ọlọ́run rántí Rakeli, Ọlọ́run sì gbọ́ tirẹ̀, ó sì ṣí i ní inú.
23 Poczęła więc i urodziła syna, i powiedziała: Bóg zabrał moją hańbę.
Ó lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan ó sì wí pé, “Ọlọ́run ti mú ẹ̀gàn mi kúrò.”
24 Nadała mu imię Józef i powiedziała: Niech PAN da mi drugiego syna.
Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ni Josẹfu, ó sì wí pé, “Ǹjẹ́ kí Olúwa kí ó fi ọmọkùnrin mìíràn kún un fún mi.”
25 Gdy Rachela urodziła Józefa, Jakub powiedział do Labana: Puść mnie, abym wrócił do mego miejsca i do mojej ziemi.
Lẹ́yìn tí Rakeli ti bí Josẹfu, Jakọbu wí fún Labani pé, “Jẹ́ kí èmi máa lọ sí ilẹ̀ mi tí mo ti wá.
26 Daj mi moje żony i moje dzieci, za które ci służyłem, abym mógł iść. Wiesz przecież, jak ci służyłem.
Kó àwọn ọmọ àti ìyàwó mi fún mi, àwọn ẹni tí mo ti torí wọn sìn ọ́. Ki èmi lè máa bá ọ̀nà mi lọ. O sá à mọ bí mo ti ṣiṣẹ́ sìn ọ́ tó.”
27 I Laban powiedział do niego: Proszę, jeśli znalazłem łaskę w twoich oczach, [zostań ze mną]. Doznałem [bowiem] tego, że PAN mi błogosławił ze względu na ciebie.
Ṣùgbọ́n Labani wí fún un pé, “Bí o bá ṣe pé mo rí ojúrere rẹ, jọ̀wọ́ dúró, nítorí, mo ti ṣe àyẹ̀wò rẹ, mo sì rí i pé Olúwa bùkún mi nítorí rẹ.
28 Mówił dalej: Wyznacz swoją zapłatę, a dam ci ją.
Sọ ohun tí o fẹ́ gẹ́gẹ́ bí owó iṣẹ́ ẹ̀ rẹ, èmi yóò sì san án.”
29 Wtedy [Jakub] mu odpowiedział: Ty wiesz, jak ci służyłem i jaki stał się przy mnie twój dobytek.
Jakọbu sì wí fún un pé, “Ìwọ sá à mọ bí mo ti ṣiṣẹ́ sìn ọ́ àti bí ẹran ọ̀sìn rẹ ti pọ̀ si lábẹ́ ìtọ́jú mi.
30 Miałeś bowiem niewiele przed moim przyjściem, a bardzo się to pomnożyło i PAN błogosławił ci, odkąd tu jestem. Kiedy jednak mam się starać o swój dom?
Ìwọ̀nba díẹ̀ sá à ni o ní kí èmi tó dé, ó sì ti pọ̀ sí i gidigidi, Olúwa sì ti bùkún ọ nínú gbogbo èyí tí mo ṣe. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, nígbà wo ní èmi yóò pèsè fún ìdílé tèmi.”
31 I [Laban] zapytał: Cóż mam ci dać? Jakub odpowiedział: Nic mi nie dasz. Ale jeśli zrobisz to, [co ci powiem], wtedy wrócę i będę pasł twoje stado, i strzegł go.
Ó sì tún béèrè wí pé, “Kín ni kí èmi ó fi fún ọ?” Jakọbu dáhùn pé, “Má fun mi ni ohunkóhun, ṣùgbọ́n bí ìwọ yóò bá ṣe ohun tí mo fẹ́ sọ yìí, èmi yóò sì máa bá ọ tọ́jú àwọn agbo ẹran rẹ, èmi yóò sì máa bọ́ wọn.
32 Obejdę dziś wszystkie twoje stada i odłączę z nich każde bydło pstre i nakrapiane i każde bydło ciemne wśród owiec, a nakrapiane i pstre wśród kóz. To będzie moja zapłata.
Jẹ́ kí èmi kí ó la agbo ẹran kọjá ní òní, èmi yóò sì mú gbogbo àgùntàn onílà àti èyí tí ó ní àmì, àti gbogbo àgbò dúdú pẹ̀lú ewúrẹ́ onílà tàbí tí ó ní àmì. Àwọn wọ̀nyí ni yóò dúró fún owó iṣẹ́ mi.
33 Potem moja sprawiedliwość da świadectwo o mnie, gdy przyjdzie czas, abyś mi zapłacił. Wszystko, co nie będzie pstre i nakrapiane wśród kóz, a ciemne wśród owiec, niech będzie mi [poczytane] za kradzież.
Òtítọ́ inú mi yóò sì jẹ́rìí fún mi ní ọjọ́ iwájú nígbà tí ìwọ bá wo owó iṣẹ́ mi tí ìwọ san fún mi, yóò sì ṣe pé gbogbo èyí tí kì í bá ṣe onílà tàbí alámì nínú ewúrẹ́ tàbí tí kì í ṣe dúdú nínú àgùntàn, tí o bá rí ni ọ̀dọ̀ mi ni kí o kà sí mi lọ́rùn pé jíjí ni mo jí gbé.”
34 Laban powiedział: Niech się stanie według twego słowa.
Labani sì dáhùn pé, “Mo fi ara mọ́ ọn, ṣe bí ìwọ ti wí.”
35 W tym dniu odłączył kozły prążkowane i nakrapiane i wszystkie kozy pstre i nakrapiane, i wszystkie, które miały jakąś białą plamkę, także i czarne wśród owiec, i oddał [je] w ręce swych synów.
Ní ọjọ́ náà gan an ni Labani kó gbogbo ewúrẹ́ tí ó ní àmì tàbí ilà (àti òbúkọ àti abo, tí ó ní funfun díẹ̀ lára), pẹ̀lú gbogbo àgùntàn dúdú, ó sì fi wọ́n sí ìtọ́jú àwọn ọmọ rẹ̀.
36 I [Laban] odłączył się od Jakuba na odległość trzech dni drogi. A Jakub pasł resztę stada Labana.
Ibi tí Labani àti Jakọbu sì wà sí ara wọn, sì tó ìrìn ọjọ́ mẹ́ta. Jakọbu sì ń tọ́jú agbo ẹran Labani tí ó kù.
37 Wtedy Jakub nabrał zielonych prętów topolowych, laskowych i kasztanowych i [miejscami] poobdzierał je z kory do białego, obnażając białość, która [była] na prętach.
Nígbà náà ni Jakọbu gé ọ̀pá tẹ́ẹ́rẹ́ tútù kan lára igi Poplari, àti igi almondi àti igi Pileeni. Ó sì bó èèpo kúrò ní ibi kọ̀ọ̀kan lára igi náà láti fún igi náà ní àwọ̀ ju ẹyọ kan lọ.
38 Gdy stada przychodziły pić, przed stadami nakładł do rynien i koryt z wodą tych prętów, które poobdzierał z kory, aby parzyły się stada, przychodząc pić.
Ó sì mú àwọn ọ̀pá wọ̀nyí tì sí ọ̀ọ́kán agbada omi níbi tí àwọn ẹran ti lè rí i nígbà tí wọ́n bá wá mu omi.
39 I stada parzyły się przy tych prętach i rodziły jagnięta prążkowane, pstre i nakrapiane.
Tí àwọn ẹran bá sì ń gùn, níwájú àwọn ọ̀pá náà, wọn sì bí àwọn ẹran onílà àti alámì, àwọn tí ó ní tótòtó lára.
40 I Jakub odłączył jagnięta, a owce stawiał przodem do [jagniąt] prążkowanych i do wszystkich ciemnych w stadzie Labana, a swoje stada stawiał osobno i nie łączył ich ze stadem Labana.
Nígbà náà ni ó ya àwọn abo ẹran kúrò nínú agbo ẹran Labani, ó sì yà wọ́n sọ́tọ̀ kúrò lára àgbò, ó sì mú kí wọn máa gùn pẹ̀lú àwọn àgbò Jakọbu dúdú nìkan, bẹ́ẹ̀ ni ó kó agbo ẹran jọ fún ara rẹ̀ láti ara agbo ẹran Labani.
41 A gdy silniejsze zwierzęta się parzyły, Jakub kładł pręty w koryta, przed oczy zwierząt, aby parzyły się przed prętami.
Nígbàkígbà tí àwọn ẹran tí ó lera bá ń gùn, Jakọbu yóò fi àwọn ọ̀pá wọ̀nyí lélẹ̀ níwájú wọn, ní ibi tí wọn ti ń mu omi.
42 Lecz gdy przychodziły słabsze zwierzęta, nie kładł [ich]. I słabsze były Labana, a silniejsze Jakuba.
Ṣùgbọ́n tí ó bá jẹ́ wí pé wọn kò lera, kò ní fi àwọn ọ̀pá náà lélẹ̀. Nítorí náà, àwọn tí kò lera ń jẹ́ ti Labani, nígbà tí àwọn tí ó lera ń jẹ́ ti Jakọbu.
43 I tak wzbogacił się bardzo ten człowiek, i miał wiele stad, a także służące i służących oraz wielbłądy i osły.
Nítorí ìdí èyí, Jakọbu di ọlọ́rọ̀ gidigidi, agbo ẹran rẹ̀ pọ̀ àti àwọn ìránṣẹ́kùnrin, ìránṣẹ́bìnrin pẹ̀lú ìbákasẹ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.

< Rodzaju 30 >