< Ezdrasza 4 >
1 A gdy wrogowie Judy i Beniamina usłyszeli, że lud, [który powrócił] z niewoli, budował świątynię PANU, Bogu Izraela;
Nígbà tí àwọn ọ̀tá Juda àti Benjamini gbọ́ wí pé àwọn ìgbèkùn tí ó padà dé ń kọ́ tẹmpili fún Olúwa, Ọlọ́run Israẹli,
2 Wówczas przybyli do Zorobabela i naczelników rodów i powiedzieli im: Będziemy budować z wami, gdyż szukamy waszego Boga tak jak wy i składamy mu ofiary od czasów Asarchaddona, króla Asyrii, który nas tu przyprowadził.
wọ́n wá sí ọ̀dọ̀ Serubbabeli àti sí ọ̀dọ̀ àwọn olórí àwọn ìdílé, wọ́n sì wí pé, “Jẹ́ kí a bá a yín kọ́ nítorí pé, bí i tiyín, a ń wá Ọlọ́run yín, a sì ti ń rú ẹbọ sí i láti ìgbà Esarhadoni ọba Asiria, tí ó mú wa wá sí ibi yìí.”
3 Ale Zorobabel, Jeszua i pozostali naczelnicy rodów z Izraela odpowiedzieli im: Nie wolno wam razem z nami budować domu naszemu Bogu, ale my sami będziemy budować PANU, Bogu Izraela, jak nam rozkazał Cyrus, król Persji.
Ṣùgbọ́n Serubbabeli, Jeṣua àti ìyókù àwọn olórí àwọn ìdílé Israẹli dáhùn pé, “Ẹ kò ní ohunkóhun pẹ̀lú wa ní kíkọ́ ilé fún Ọlọ́run wa. Àwa nìkan yóò kọ́ ọ fún Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, bí Kirusi, ọba Persia, ti pàṣẹ fún wa.”
4 Wtedy lud tej ziemi zaczął zniechęcać lud Judy i przeszkadzał im w budowie.
Nígbà náà ni àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà mú ọwọ́ àwọn ènìyàn Juda rọ, wọ́n sì dẹ́rùbà wọ́n ní ti kíkọ́ ilé náà.
5 Ponadto przekupywał przeciwko nim radców, aby udaremnić ich zamiar po wszystkie dni Cyrusa, króla Persji, aż do panowania Dariusza, króla Persji.
Wọ́n gba àwọn olùdámọ̀ràn láti ṣiṣẹ́ lòdì sí wọn àti láti sọ ète wọn di asán ní gbogbo àsìkò ìjọba Kirusi ọba Persia àti títí dé ìgbà ìjọba Dariusi ọba Persia.
6 Za panowania Aswerusa, na początku jego panowania, napisali skargę przeciwko obywatelom Judy i Jerozolimy;
Ní ìbẹ̀rẹ̀ ìjọba Ahaswerusi wọ́n fi ẹ̀sùn kan àwọn ènìyàn Juda àti Jerusalẹmu.
7 A za czasów Artakserksesa Biszlam, Mitredat, Tabeel wraz z pozostałymi towarzyszami napisali do Artakserksesa, króla Persji. List [był] sporządzony pismem syryjskim i przetłumaczony na język syryjski.
Àti ní àkókò ìjọba Artasasta ọba Persia, Biṣilami, Mitredati, Tabeli àti àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ yòókù kọ̀wé sí Artasasta. A kọ ìwé náà ní ìlànà ìkọ̀wé Aramaiki èdè Aramaiki sì ní a fi kọ ọ́.
8 Kanclerz Rechum i pisarz Szimszaj napisali do króla Artakserksesa list przeciwko Jerozolimie następującej treści:
Rehumu balógun àti Ṣimṣai akọ̀wé jùmọ̀ kọ́ ìwé láti dojúkọ Jerusalẹmu sí Artasasta ọba báyìí:
9 Kanclerz Rechum, pisarz Szimszaj i pozostali ich towarzysze: Dynajczycy, Afarsadchajczycy, Tarpelajczycy, Afarsajczycy, Arkewijczycy, Babilończycy, Susanchici, Dehawici [i] Elamici;
Rehumu balógun àti Ṣimṣai akọ̀wé, pẹ̀lú àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn tókù—àwọn ará Dina, ti Afarsatki, ti Tarpeli, ti Afarsi, Ereki àti Babeli, àwọn ará Elamu ti Susa,
10 I reszta narodów, które wielki i sławny Asnappar przyprowadził i osiedlił w miastach Samarii, oraz pozostali, którzy są za rzeką – otóż;
pẹ̀lú àwọn ènìyàn mìíràn tí ẹni ọlá àti ẹni ọ̀wọ̀ Asnappari kó jáde, tí ó sì tẹ̀ wọ́n dó sí ìlú Samaria àti níbòmíràn ní agbègbè e Eufurate.
11 To [jest] odpis listu, który posłali do króla Artakserksesa – Twoi słudzy, ludzie mieszkający za rzeką – otóż:
(Èyí ni ẹ̀dà ìwé tí wọ́n fi ránṣẹ́ sí i.) Sí ọba Artasasta, láti ọ̀dọ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn ọkùnrin agbègbè Eufurate.
12 Niech królowi będzie wiadomo, że Żydzi, którzy wyszli od ciebie, przybyli do nas, do Jerozolimy, i odbudowują to buntownicze i niegodziwe miasto, już wznosili mury i położyli fundamenty.
Ọba gbọdọ̀ mọ̀ pé àwọn ará Júù tí ó gòkè wá sọ́dọ̀ wa láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ ti lọ sí Jerusalẹmu wọ́n sì ń tún ìlú búburú àti ìlú ọlọ̀tẹ̀ ẹ nì kọ́. Wọ́n ń tún àwọn ògiri náà kọ́, wọ́n sì ń tún àwọn ìpìlẹ̀ náà ṣe.
13 Niech więc będzie królowi wiadomo, że jeśli to miasto zostanie odbudowane i [jego] mury będą wzniesione, wtedy podatku, danin ani cła oni nie będą płacić, a to przyniesie szkodę dochodom króla.
Síwájú sí i, ọba gbọdọ̀ mọ̀ pé tí a bá kọ́ ìlú yìí àti tí a sì tún àwọn ògiri rẹ̀ mọ, kò sí owó orí, owó òde tàbí owó ibodè tí a ó san, owó tí ó sì ń wọlé fún ọba yóò sì dínkù.
14 Teraz więc, ponieważ jesteśmy na utrzymaniu [twego] pałacu i nie przystoi nam patrzeć na zniewagę króla, posyłamy królowi tę wiadomość;
Nísinsin yìí níwọ̀n ìgbà tí a ní ojúṣe sí ààfin ọba, kò sì bójúmu fún wa láti rí ìtàbùkù ọba, àwa ń rán iṣẹ́ yìí láti sọ fún ọba,
15 Aby poszukano w księdze kronik twoich ojców, a znajdziesz w niej i dowiesz się, że to miasto jest miastem buntowniczym i przynosi szkodę królom i prowincjom i że od dawien dawna wzniecano w nim bunty. Z tego powodu to miasto zostało zburzone.
kí a bá a lè ṣe ìwádìí ní inú ìwé ìrántí àwọn aṣíwájú rẹ̀. Nínú ìwé ìrántí wọn yìí, ìwọ yóò rí i wí pé, ìlú yìí jẹ́ ìlú aṣọ̀tẹ̀, oníwàhálà sí àwọn ọba àti àwọn ìgbèríko, ibi ìṣọ̀tẹ̀ láti ìgbà àtijọ́. Ìdí ni èyí tí a ṣe pa ìlú yìí run.
16 Zawiadamiamy króla, że jeśli to miasto zostanie odbudowane i jego mury będą wzniesione, wtedy już nie będziesz miał udziału za rzeką.
A fi dá ọba lójú wí pé tí a bá tún ìlú kọ́ àti ti àwọn ògiri rẹ̀ si di mímọ padà, kì yóò sì ohun ti yóò kù ọ́ kù ní agbègbè Eufurate.
17 [Wtedy] król wysłał taką odpowiedź: Kanclerzowi Rechumowi, pisarzowi Szimszajowi i pozostałym ich towarzyszom, którzy mieszkają w Samarii, a także i pozostałym za rzeką: Pokój! Otóż:
Ọba fi èsì yìí ránṣẹ́ padà. Sí Rehumu balógun, Ṣimṣai akọ̀wé àti àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn yòókù tí ń gbé ní Samaria àti ní òpópónà Eufurate. Ìkíni.
18 List, który do nas przysłaliście, został przede mną dokładnie odczytany.
A ti ka ìwé tí ẹ fi ránṣẹ́ sí wa, a sì ti túmọ̀ rẹ̀ níwájú mi.
19 Dlatego rozkazałem, aby poszukano. I znaleziono, że to miasto od dawna powstawało przeciwko królom, a bunt i rozruchy były w nim wzniecane;
Mo pa àṣẹ, a sì ṣe ìwádìí, nínú ìtàn ọjọ́ pípẹ́ àti ti ìsinsin yìí ti ìṣọ̀tẹ̀ sí àwọn ọba pẹ̀lú, ó sì jẹ́ ibi ìṣọ̀tẹ̀ àti ìrúkèrúdò.
20 Ponadto potężni królowie panowali nad Jerozolimą i rządzili nad wszystkimi za rzeką, i płacono im podatek, daninę i cło.
Jerusalẹmu ti ní àwọn ọba alágbára tí ń jẹ ọba lórí gbogbo àwọn agbègbè Eufurate, àti àwọn owó orí, owó òde àti owó ibodè sì ni wọ́n ń san fún wọn.
21 Wydajcie więc wyrok, aby powstrzymać tych mężczyzn, żeby to miasto nie zostało odbudowane, dopóki [inny] rozkaz nie będzie przeze mnie wydany.
Nísinsin yìí pa àṣẹ fún àwọn ọkùnrin yìí láti dá iṣẹ́ dúró, kí a má ṣe tún ìlú náà kọ títí èmi yóò fi pàṣẹ.
22 Pilnujcie, abyście nie zaniedbali tego. Dlaczego miałoby to wzrastać na szkodę królów?
Ẹ ṣọ́ra kí ẹ má ṣe àìkọbi-ara sí ọ̀rọ̀ yìí. Èéṣe tí ìbàjẹ́ yóò fi pọ̀ sí i, sí ìpalára àwọn ọba?
23 Gdy więc odpis listu króla Artakserksesa został odczytany przed Rechumem, pisarzem Szimszajem i ich towarzyszami, udali się spiesznie do Żydów w Jerozolimie i siłą i mocą wstrzymali budowę.
Ní kété tí a ka ẹ̀dà ìwé ọba Artasasta sí Rehumu àti Ṣimṣai akọ̀wé àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn, wọ́n yára lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn Júù ní Jerusalẹmu pẹ̀lú, wọ́n fi agbára mú wọn láti dáwọ́ dúró.
24 W ten sposób ustała praca przy domu Bożym, który był w Jerozolimie. I została wstrzymana aż do drugiego roku panowania Dariusza, króla Persji.
Báyìí, iṣẹ́ lórí ilé Ọlọ́run ní Jerusalẹmu wá sí ìdúró jẹ́ẹ́ títí di ọdún kejì ìjọba Dariusi ọba Persia.