< Ezechiela 33 >
1 I doszło do mnie słowo PANA mówiące:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
2 Synu człowieczy, przemów do synów twego ludu i powiedz im: Gdy sprowadzam miecz na jakąś ziemię, a lud tej ziemi weźmie jakiegoś mężczyznę spośród siebie i ustanowi go sobie stróżem;
“Ọmọ ènìyàn sọ̀rọ̀ sí àwọn ènìyàn ilẹ̀ rẹ kí ó sì sọ fún wọn: ‘Nígbà tí mo bá fi idà kọlu ilẹ̀ kan, tí àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà yan ọ̀kan lára àwọn ọkùnrin wọn láti jẹ́ alóre wọn,
3 A [on], gdy zobaczy nadciągający miecz na tę ziemię, zadmie w trąbę i ostrzeże lud;
tí ó sì rí i pé idà ń bọ̀ lórí ilẹ̀ náà, tí ó sì fọn ìpè láti kìlọ̀ fún àwọn ènìyàn,
4 A ktoś usłyszy dźwięk trąby i nie przyjmie przestrogi, a miecz przyjdzie i zabierze go, to jego krew spadnie na jego [własną] głowę.
nígbà náà tí ẹnikẹ́ni bá gbọ́ ìpè ṣùgbọ́n tí kò gbọ́ ìkìlọ̀, tí idà náà wá tí ó sì gba ẹ̀mí rẹ̀, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ yóò wà lórí ara rẹ̀.
5 Dźwięk trąby usłyszał, ale nie przyjął przestrogi, jego krew spadnie na niego. Ten jednak, który przyjmie przestrogę, ocali swoją duszę.
Nítorí tí ó gbọ́ ohùn ìpè ṣùgbọ́n tí kò sì gbọ́ ìkìlọ̀, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ yóò wà ní orí ara rẹ̀. Tí ó bá gbọ́ ìkìlọ̀, òun ìbá ti gba ara rẹ̀ là.
6 Ale jeśli stróż zobaczy nadciągający miecz, a nie zadmie w trąbę i ludu nie ostrzeże, a przyjdzie miecz i zabierze kogoś z nich, to ten [jest] porwany w swojej nieprawości, ale jego krwi zażądam z ręki tego stróża.
Ṣùgbọ́n bí alóre bá rí idà tí o ń bọ̀, tí kò sì fọn ìpè láti ki àwọn ènìyàn nílọ̀, tí idà náà wá, tí ó sì gba ẹ̀mí ọ̀kan nínú wọn, a yóò mú ọkùnrin náà lọ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, ṣùgbọ́n èmi yóò béèrè ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ lọ́wọ́ rẹ̀.’
7 Ciebie, synu człowieczy, ciebie ustanowiłem stróżem dla domu Izraela. Gdy usłyszysz słowo z moich ust, ostrzeżesz go ode mnie.
“Ọmọ ènìyàn, èmi fi ọ ṣe alóre fún ilé Israẹli; nítorí náà gbọ́ ọ̀rọ̀ tí mo sọ, kí o sì fún wọn ni ìkìlọ̀ láti ọ̀dọ̀ mi.
8 Gdy mówię do bezbożnego: Bezbożniku, na pewno umrzesz – a ty mu [tego] nie powiesz, aby przestrzec bezbożnika przed jego drogą, to ten bezbożnik umrze z powodu swojej nieprawości; ale jego krwi zażądam z twojej ręki.
Nígbà ti mo bá sọ fún ẹni búburú pé, ‘A! Ẹni búburú, ìwọ yóò kú dandan,’ ti ìwọ kò sì sọ̀rọ̀ síta láti yí i lọ́kàn padà kúrò ni ọ̀nà rẹ̀ gbogbo, ẹni búburú náà yóò kú nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, èmi yóò sì béèrè ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ lọ́wọ́ rẹ.
9 Jeśli jednak ostrzeżesz bezbożnego przed jego drogą, aby odwrócił się od niej, a on się nie odwróci od swojej drogi, to umrze on z powodu swojej nieprawości; ale ty ocalisz swoją duszę.
Ṣùgbọ́n bí ìwọ bá kìlọ̀ fún ẹni búburú láti yí padà kúrò ni ọ̀nà rẹ̀ gbogbo, tí òun kò sì ṣe bẹ́ẹ̀, òun yóò kú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, ṣùgbọ́n ìwọ ti gba ọkàn rẹ̀ là.
10 Ty więc, synu człowieczy, mów do domu Izraela: Tak mówicie: Skoro ciążą na nas nasze występki i nasze grzechy, tak że w nich marniejemy, to jakże możemy żyć?
“Ọmọ ènìyàn; sọ fún ilé Israẹli, ‘Èyí yìí ní ìwọ sọ: “Àwọn ìrékọjá àti ẹ̀ṣẹ̀ wa tẹ orí wa ba, àwa sì ń ṣòfò dànù nítorí wọn. Bá wó wa ni a ṣe lè yè?”’
11 Powiedz im: Jak żyję, mówi Pan BÓG: Nie pragnę śmierci bezbożnego, ale aby bezbożny odwrócił się od swojej drogi i żył. Odwróćcie się, odwróćcie się od swoich złych dróg. Dlaczego macie umrzeć, domu Izraela?
Sọ fún wọn pé, ‘Níwọ́n ìgbà tí mo wà láààyè ni Olúwa Olódùmarè wí, èmi kò ní inú dídùn sí ikú ènìyàn búburú, ṣùgbọ́n dípò bẹ́ẹ̀, kí wọ̀nyí padà kúrò ní ọ̀nà wọn gbogbo kì wọn kì ó sì yè. Yí! Yípadà kúrò ni ọ̀nà búburú gbogbo! Kí ló dé tí ìwọ yóò kú ẹ̀yin ènìyàn Israẹli?’
12 Ty więc, synu człowieczy, mów do synów swego ludu: Sprawiedliwość sprawiedliwego nie wybawi go w dniu jego przestępstwa, a bezbożność bezbożnego nie zgubi go w dniu, kiedy się odwróci od swojej bezbożności. Sprawiedliwy nie będzie mógł żyć dzięki swojej [sprawiedliwości] w dniu, kiedy zgrzeszy.
“Nítorí náà, ọmọ ènìyàn, sọ fún àwọn ènìyàn ilẹ̀ rẹ, ‘Ìṣòdodo ti olódodo ènìyàn kì yóò gbà á nígbà tí òun bá ṣe àìgbọ́ràn, ìwà búburú ènìyàn búburú kì yóò mú kí o ṣubú nígbà tí ó bá yí padà kúrò nínú rẹ̀. Bí olódodo ènìyàn bá ṣẹ̀, a kò ni jẹ́ kí ó yè nítorí òdodo rẹ̀ ti tẹ́lẹ̀.’
13 Jeśli powiem sprawiedliwemu: Na pewno będziesz żyć, a on, polegając na swojej sprawiedliwości, uczyni nieprawość, to żadna jego sprawiedliwość nie będzie wspomniana, ale umrze z powodu swojej nieprawości, którą uczynił.
Bí mo bá sọ fún olódodo ènìyàn pé òun yóò yè, ṣùgbọ́n nígbà náà tí ó gbẹ́kẹ̀lé òdodo rẹ̀ tí ó sì ṣe búburú, a kò ní rántí nǹkan kan nínú iṣẹ́ òdodo tí o ti ṣe sẹ́yìn; òun yóò kú nítorí búburú tí ó ṣe.
14 A jeśli powiem bezbożnemu: Na pewno umrzesz, a on odwróci się od swego grzechu i uczyni to, co prawe i sprawiedliwe;
Bí mo bá sọ fún ènìyàn búburú pé, ‘Ìwọ yóò kú dandan,’ ṣùgbọ́n tí ó bá yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, ti o sì ṣe èyí tí ó tọ́ àti èyí tí o yẹ.
15 Jeśli bezbożny zwróci zastaw, odda to, co wydarł, i będzie chodził według praw życia, nie czyniąc nieprawości, na pewno będzie żył i nie umrze.
Tí ó bá mu ògo padà, tí o sì da ohun tí o ti jí gbé padà, tí ó sì tẹ̀lé òfin tí ó ń fún ni ní ìyè, tí kò sì ṣe búburú, òun yóò yè dandan; òun kì yóò kú.
16 Żadne jego grzechy, które popełnił, nie będą mu wspominane. Czynił to, co prawe i sprawiedliwe; na pewno będzie żył.
A kò ní rántí ọ̀kan nínú ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ti dá. Ó ti ṣe èyí tí ó tọ àti èyí tí o yẹ; òun yóò sì yè dájúdájú.
17 Lecz synowie twego ludu mówią: Droga Pana nie jest słuszna, choć to ich droga nie jest słuszna.
“Síbẹ̀ àwọn ènìyàn ilẹ̀ rẹ sọ pé, ‘Ọ̀nà Olúwa kò tọ́.’ Ṣùgbọ́n ọ̀nà tí àwọn ní ó tọ́.
18 Jeśli sprawiedliwy odwróci się od swojej sprawiedliwości i będzie czynił nieprawość, to umrze z jej powodu.
Bí olódodo ènìyàn ba yípadà kúrò nínú òdodo rẹ̀, tí o sì ṣe búburú, òun yóò kú nítorí rẹ̀.
19 Ale jeśli bezbożny odwróci się od swojej bezbożności i będzie czynił to, co prawe i sprawiedliwe, to dzięki temu będzie żył.
Bí ènìyàn búburú bá yípadà kúrò nínú búburú rẹ̀, tí ó sì ṣe èyí tí ó tọ́ àti èyí tí ó yẹ, òun yóò yè nípa ṣíṣe bẹ́ẹ̀.
20 Wy jednak mówicie: Droga Pana nie jest słuszna. Domu Izraela, będę sądził każdego z was według jego drogi.
Síbẹ̀, ilé Israẹli ìwọ wí pé, ‘Ọ̀nà Olúwa ki i ṣe òtítọ́.’ Ṣùgbọ́n èmi yóò ṣe ìdájọ́ ẹnìkọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ̀ ṣe rí.”
21 I stało się w dwunastym roku naszego uprowadzenia, w dziesiątym [miesiącu], piątego [dnia] tego miesiąca, że przyszedł do mnie jeden zbieg z Jerozolimy, mówiąc: Zdobyto miasto.
Ní ọjọ́ karùn-ún oṣù kẹwàá, ọdún kejìlá ìkólọ wa, ọkùnrin kan tí ó sá kúrò ni Jerusalẹmu wá sọ́dọ̀ mi, ó sì wí pé, “Ìlú ńlá náà ti ṣubú!”
22 A ręka PANA była nade mną wieczorem, zanim przyszedł ten zbieg, i otworzyła moje usta, aż ten przyszedł do mnie rano. Otworzyła moje usta i nie byłem już niemy.
Ní ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ tí ó ku ọ̀la tí ẹni tí ó sálọ náà yóò dé, ọwọ́ Olúwa sì níbẹ̀ lára mi, o sì ya ẹnu mi ki ọkùnrin náà tó wá sọ́dọ̀ mi ní òwúrọ̀. Ẹnu mí sì ṣí, èmi kò sì yadi mọ́.
23 I doszło do mnie słowo PANA mówiące:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
24 Synu człowieczy, mieszkańcy tych spustoszonych miejsc w ziemi Izraela mówią: Abraham był jeden i wziął ziemię w posiadanie. Ale nas jest wielu, nam więc dana jest ta ziemia w posiadanie.
“Ọmọ ènìyàn, àwọn ènìyàn tí ó ń gbé nínú ìparun ní ilẹ̀ Israẹli ń wí pé, ‘Abrahamu jẹ́ ọkùnrin kan, síbẹ̀ o gba ilẹ̀ ìní náà. Ṣùgbọ́n àwa pọ̀, lóòótọ́ a ti fi ilẹ̀ náà fún wa gẹ́gẹ́ bí ìní wa.’
25 Dlatego mów do nich: Tak mówi Pan BÓG: Jadacie z krwią, podnosicie swe oczy ku swoim bożkom i przelewacie krew, a ziemię chcielibyście wziąć w posiadanie?
Nítorí náà, sọ fún wọn pé, ‘Èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Níwọ́n ìgbà tí ẹ̀yin jẹ ẹran pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀ ni inú rẹ̀, tí ẹ̀yin sì wó àwọn ère yín, tí ẹ sì ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀, ẹ̀yin yóò ha gba ilẹ̀ náà?
26 Opieracie się na swoim mieczu, popełniacie obrzydliwość i każdy plugawi żonę swego bliźniego, a ziemię chcielibyście wziąć w posiadanie?
Ẹ̀yin gbẹ́kẹ̀lé idà yín, ẹ̀yin ṣe nǹkan ìríra, ẹnìkọ̀ọ̀kan nínú yín ba á obìnrin aládùúgbò rẹ̀ jẹ́. Ẹ̀yin yóò ha gba ilẹ̀ náà?’
27 Tak im powiedz: Tak mówi Pan BÓG: Jak żyję, ci, którzy są w spustoszonych miejscach, polegną od miecza, a [kto jest na] otwartym polu, tego wydam zwierzętom na pożarcie, a ci, którzy są w warowniach lub w jaskiniach, umrą od zarazy.
“Sọ èyí fún wọn: ‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Bí mo ti wà láààyè, àwọn tí ó kúrò nínú ìparun yóò ti ipa idà ṣubú, àwọn tí ẹranko búburú yóò pajẹ, àwọn tí ó sì wà ní ilé ìṣọ́ àti inú ihò òkúta ni àjàkálẹ̀-ààrùn yóò pa.
28 I wydam ziemię na wielkie spustoszenie, i ustanie pycha jej mocy; spustoszeją góry Izraela i nikt przez nie nie będzie przechodził.
Èmi yóò mú kí ilẹ̀ náà di ahoro, ọ̀ṣọ́ ńlá agbára rẹ̀ kì yóò sí mọ́, àwọn òkè Israẹli yóò sì di ahoro, tí ẹnikẹ́ni kò ní le là á kọjá.
29 I poznają, że ja jestem PANEM, gdy wydam [ich] ziemię na wielkie spustoszenie z powodu wszystkich ich obrzydliwości, które czynili.
Nígbà náà, wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa, nígbà tí mo bá mú ilẹ̀ náà di ahoro nítorí gbogbo ohun ìríra tí wọ́n ti ṣe.’
30 Ale co do ciebie, synu człowieczy, synowie twego ludu często rozmawiają o tobie przy murach i w drzwiach domów, i mówi jeden do drugiego, każdy do swego bliźniego: Chodźcie i posłuchajcie, co za słowo wyszło od PANA.
“Ní tìrẹ, ọmọ ènìyàn, àwọn ènìyàn ìlú n sọ̀rọ̀ nípa rẹ ní ẹ̀gbẹ́ ògiri àti ní ẹnu-ọ̀nà ilé wọn, wọ́n ń sọ sí ara wọn wí pé, ‘Ẹ wá gbọ́ iṣẹ́ ti a ran láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá.’
31 I przychodzą do ciebie, tak zwykł przychodzić lud, zasiadają przed tobą [jak] mój lud i słuchają twoich słów, ale ich nie wypełniają. Mają bowiem miłość na ustach, lecz ich serce podąża za niegodziwym zyskiem.
Àwọn ènìyàn mi wá sọ́dọ̀ rẹ, gẹ́gẹ́ bí wọn ṣe ń ṣe, wọn sì jókòó níwájú rẹ láti fetísí ọ̀rọ̀ rẹ, ṣùgbọ́n wọn kò mú wá sí ìṣe. Ẹnu wọn ni wọ́n fi n sọ̀rọ̀ ìfọkànsìn, ṣùgbọ́n ọkàn wọn ní ìwọra èrè tí kò tọ́.
32 A oto jesteś dla nich jak urokliwa pieśń [tego, który] ma piękny głos i cudownie gra. Słuchają bowiem twoich słów, ale ich nie wykonują.
Nítòótọ́ lójú wọn, ìwọ jẹ́ ẹni kan tí ó ń kọrin ìfẹ́ pẹ̀lú ohun dídára àti ohun èlò orin kíkọ, nítorí wọ́n gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ ṣùgbọ́n wọn kò mu wá sí ìṣe.
33 Lecz gdy to nadejdzie – oto nadejdzie – wtedy poznają, że prorok był pośród nich.
“Nígbà tí gbogbo ìwọ̀nyí bá ṣẹ tí yóò sì ṣẹ dandan, nígbà náà wọn yóò mọ̀ pé wòlíì kan ti wa láàrín wọn rí.”