< Ezechiela 32 >

1 W dwunastym roku, w dwunastym miesiącu, pierwszego [dnia] tego miesiąca, doszło do mnie słowo PANA mówiące:
Ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù kejìlá, ọdún kejìlá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
2 Synu człowieczy, podnieś lament nad faraonem, królem Egiptu, i powiedz mu: Jesteś podobny do młodego lwa pośród narodów, jesteś jak wieloryb w morzu, gdyż bujając po swoich rzekach, mącisz wody swoimi nogami i mieszasz jego rzeki.
“Ọmọ ènìyàn, ṣe ìpohùnréré ẹkún nítorí Farao ọba Ejibiti kí o sì wí fún un: “‘Ìwọ dàbí kìnnìún láàrín àwọn orílẹ̀-èdè náà; ìwọ dàbí ohun ẹ̀mí búburú inú àwọn omi okun to ń lọ káàkiri inú àwọn odò rẹ, ìwọ fi ẹsẹ̀ rẹ tẹ omi láti mú kí àwọn odò ní ẹrẹ̀.
3 Tak mówi Pan BÓG: Rozciągnę nad tobą swoją sieć w zgromadzeniu wielu narodów, a wyciągną cię w swoim niewodzie.
“‘Èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Pẹ̀lú ọ̀pọ̀ ìpéjọ ènìyàn èmi yóò da àwọ̀n mi bò ọ́ wọn yóò sì fà ọ́ sókè nínú àwọ̀n mi.
4 I zostawię cię na ziemi, porzucę cię na otwartym polu i sprawię, że obsiądzie cię wszelkie ptactwo niebieskie, i nasycę tobą zwierzęta całej ziemi.
Èmi yóò jù ọ́ sí orí ilẹ̀ èmi yóò sì fà ọ́ sókè sí orí pápá gbangba. Èmi yóò jẹ́ kí gbogbo ẹyẹ ojú ọ̀run ṣe àtìpó ní orí rẹ. Gbogbo àwọn ẹranko ayé yóò fi ìwọra gbé ara wọn lórí rẹ.
5 Rozrzucę twoje ciało po górach i napełnię doliny twoją wysokością.
Èmi yóò tan ẹran-ara rẹ ká sórí àwọn òkè gíga ìyókù ara rẹ ní wọn yóò fi kún àwọn àárín àwọn òkè gíga.
6 Twoją ziemię, w której pływasz, napoję twoją krwią aż do gór, i rzeki będą napełnione tobą.
Ẹ̀jẹ̀ rẹ ti ń sàn ní èmi yóò sì fi rin ilẹ̀ náà gbogbo ọ̀nà sí orí àwọn òkè gíga, àwọn àlàfo jíjìn ní wọn yóò kún fún ẹran-ara rẹ.
7 A gdy cię zgaszę, zakryję niebo i zaciemnię jego gwiazdy, słońce zakryję chmurą, a księżyc nie da swego światła.
Nígbà tí mo bá fọ́n ọ jáde, èmi yóò pa ọ̀run dé àwọn ìràwọ̀ wọn yóò sì ṣókùnkùn; èmi yóò sì fi ìkùùkuu bo oòrùn òṣùpá kì yóò sì tan ìmọ́lẹ̀ rẹ̀.
8 Wszystkie świecące światła na niebie zaciemnię z twojego powodu i sprowadzę ciemność na twoją ziemię, mówi Pan BÓG.
Gbogbo ìmọ́lẹ̀ títàn ní ojú ọ̀run ni èmi yóò mú ṣókùnkùn lórí rẹ; èmi yóò mú òkùnkùn wá sórí ilẹ̀ rẹ, ni Olúwa Olódùmarè wí.
9 Nadto zasmucę serce wielu narodów, gdy za moją sprawą nadejdzie [wieść] o twoim zniszczeniu do narodów, do ziem, których nie znałeś.
Èmi yóò da ọkàn ọ̀pọ̀ àwọn ènìyàn rú nígbà tí mo bá mú ìparun rẹ wá ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè tí ìwọ kò í tí ì mọ̀.
10 Tak, sprawię, że zdumieje się nad tobą wiele narodów, a ich królowie bardzo się zatrwożą z twojego powodu, gdy zacznę wywijać swoim mieczem przed nimi; i będą drżeć nieustannie – każdy o swoją duszę – w dniu twego upadku.
Èmi yóò mú kí ọ̀pọ̀ àwọn ènìyàn dẹ́rùbà ọ́, àwọn ọba wọn yóò sì wárìrì fún ìbẹ̀rù pẹ̀lú ìpayà nítorí rẹ, nígbà tí mo bá ju idà mi ní iwájú wọn. Ní ọjọ́ ìṣubú rẹ ọ̀kọ̀ọ̀kan nínú wọn yóò wárìrì ní gbogbo ìgbà fún ẹ̀mí rẹ.
11 Tak bowiem mówi Pan BÓG: Miecz króla Babilonu spadnie na ciebie.
“‘Nítorí èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Idà ọba Babeli yóò wá sí orí rẹ,
12 Mieczami mocarzy powalę twoją rzeszę. Najokrutniejsi ze wszystkich narodów zniszczą pychę Egiptu i będzie zgładzone całe jego mnóstwo.
Èmi yóò mú kí ìjọ ènìyàn rẹ kí ó tí ipa idà àwọn alágbára ènìyàn ṣubú àwọn orílẹ̀-èdè aláìláàánú jùlọ. Wọn yóò tú ìgbéraga Ejibiti ká, gbogbo ìjọ rẹ ní a yóò dá ojú wọn bolẹ̀.
13 Wytępię całe jego bydło znad wielkich wód, tak że nie zamąci ich stopa ludzka ani nie zamąci ich kopyto bydlęcia.
Gbogbo ẹran ọ̀sìn rẹ ni èmi yóò parun ní ẹ̀gbẹ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi kì i ṣe ẹsẹ̀ ènìyàn ní yóò tẹ ibẹ̀ ẹsẹ̀ ẹran ọ̀sìn kì yóò sì mú kí ibẹ̀ ni ẹrọ̀fọ̀.
14 Wtedy sprawię, że ich wody uspokoją się, a ich rzeki popłyną jak oliwa – mówi Pan BÓG.
Lẹ́yìn náà èmi yóò mú kí omi rẹ̀ tòrò kí àwọn odò rẹ̀ kí o sàn bí epo, ni Olúwa Olódùmarè wí.
15 Gdy zamienię ziemię Egiptu w spustoszenie, a ziemia zostanie pozbawiona tego, co ją napełnia, gdy pobiję wszystkich jej mieszkańców, wtedy poznają, że ja jestem PANEM.
Nígbà tí mo bá sọ Ejibiti di ahoro, tí mo sì kó gbogbo ohun tí ó wà ní orí ilẹ̀ náà kúrò. Nígbà tí mo bá gé àwọn olùgbé ibẹ̀ lulẹ̀, nígbà náà wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’
16 To jest lament, który podniosą nad nią. Córki narodów będą ją opłakiwać. Nad Egiptem i nad całą jego rzeszą będą lamentować, mówi Pan BÓG.
“Èyí yìí ni ẹkún tí a yóò sun fún un. Àwọn ọmọbìnrin orílẹ̀-èdè yóò sun ún; nítorí Ejibiti àti gbogbo ìjọ rẹ, wọn yóò sun ún, ní Olúwa Olódùmarè wí.”
17 Potem, w dwunastym roku, piętnastego [dnia] miesiąca, doszło do mnie słowo PANA mówiące;
Ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù, ọdún kejìlá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ mí wá:
18 Synu człowieczy, zawódź nad rzeszą Egiptu, zepchnij ją i córki tych sławnych narodów aż do najniższych stron ziemi, do tych, którzy zstępują do dołu.
“Ọmọ ènìyàn, pohùnréré ẹkún lórí Ejibiti kí o sì ránṣẹ́ sí ìsàlẹ̀ ilẹ̀ àti òun àti àwọn ọmọbìnrin orílẹ̀-èdè alágbára, pẹ̀lú àwọn tí o lọ sí ìsàlẹ̀, kòtò.
19 I [mów]: Kogo przewyższasz pięknem? Zstąp i połóż się z nieobrzezanymi.
Sọ fún wọn, ‘Ǹjẹ́ ìwọ ní ojúrere jù àwọn tí o kù lọ? Lọ sí ìsàlẹ̀ kí a sì tẹ́ ọ sí àárín àwọn aláìkọlà náà.’
20 Padną pośród pobitych mieczem; został wydany pod miecz, wywleczcie go z całą jego rzeszą.
Wọn yóò ṣubú láàrín àwọn tí a fi idà pa. A fa idà yọ; jẹ́ kí a wọ́ Ejibiti kúrò pẹ̀lú gbogbo ìjọ rẹ̀.
21 Najmocniejsi z mocarzy będą do niego mówić spośród piekła wraz z jego pomocnikami. Zstąpili [tam], leżą z nieobrzezanymi pobitymi mieczem. (Sheol h7585)
Láti inú isà òkú alágbára tí í ṣe aṣáájú yóò sọ nípa Ejibiti àti àwọn àlejò rẹ̀, ‘Wọn ti wá sí ìsàlẹ̀, wọn sì sùn pẹ̀lú aláìkọlà, pẹ̀lú àwọn tí a fi idà pa.’ (Sheol h7585)
22 Tam [jest] Assur i cała jego rzesza, wokół niego [są] jego groby; wszyscy ci pobici upadli od miecza.
“Asiria wà níbẹ̀ pẹ̀lú gbogbo jagunjagun rẹ̀; àwọn isà òkú àwọn tí a ti pa sì yí i ká, gbogbo àwọn tí ó ti ipa idà ṣubú.
23 Ich groby są położone po stronach dołu, jego rzesza jest dokoła jego grobu. Ci wszyscy pobici polegli od miecza, ci, którzy szerzyli postrach w ziemi żyjących.
Isà òkú wọn wà ní ibi tí ó jinlẹ̀ gan an nínú kòtò. Gbogbo àwọn tí ó ti tan ẹ̀rù ká ilẹ̀ alààyè ní a pa, tí ó ti ipa idà ṣubú.
24 Tam [jest] Elam i cała jego rzesza dokoła jego grobu, ci wszyscy pobici upadli od miecza i zstąpili nieobrzezani do najgłębszych stron ziemi; szerzyli swój postrach w ziemi żyjących. Już znoszą swoją hańbę z tymi, którzy zstępują do dołu.
“Elamu wà níbẹ̀, o yí isà òkú rẹ̀ ká pẹ̀lú gbogbo ogun rẹ̀. Gbogbo wọn ni a pa, àwọn tí ó ti ipa idà ṣubú. Gbogbo àwọn tí ó ti tan ẹ̀rù ká ilẹ̀ alààyè lọ sí ìsàlẹ̀ láìkọlà sí abẹ́ ilẹ̀. Wọ́n gba ìtìjú wọn pẹ̀lú àwọn tí ó lọ sí ìsàlẹ̀ kòtò.
25 Postawili mu łoże pośród pobitych z całą jego rzeszą, wokół niego są jego groby. Wszyscy ci nieobrzezani są pobici mieczem. Ich postrach szerzył się w ziemi żyjących, ale już ponoszą swoją hańbę z tymi, którzy zstąpili do dołu, a wśród pobitych zostali położeni.
A ṣe ibùsùn fún un láàrín àwọn tí a pa, pẹ̀lú gbogbo ìjọ rẹ̀ tí ó yí isà òkú ká. Gbogbo wọn jẹ́ aláìkọlà, tí a fi idà pa. Nítorí pé a tan ẹ̀rù wọn ká ilẹ̀ alààyè, wọn ru ìtìjú wọn pẹ̀lú àwọn tí ó lọ sí ìsàlẹ̀ kòtò; a tẹ́ wọn pẹ̀lú àwọn tí a pa.
26 Tam [jest] Meszek, Tubal i cała jego rzesza, i wokoło niego jego groby. Ci wszyscy nieobrzezani [zostali] pobici mieczem, choć szerzyli swój postrach w ziemi żyjących.
“Meṣeki àti Tubali wà níbẹ̀, pẹ̀lú gbogbo ogun wọn yí isà òkú wọn ká. Gbogbo wọn jẹ́ aláìkọlà, wọ́n fi idà pa wọ́n nítorí ẹ̀rù tiwọn tàn ká ilẹ̀ alààyè.
27 Oni jednak nie będą leżeć z mocarzami, którzy spośród nieobrzezanych upadli i zstąpili do grobu ze swym orężem wojennym i położono im miecze pod głowy. Ich nieprawości zaś zostaną na ich kościach, chociaż byli postrachem dla mocarzy w ziemi żyjących. (Sheol h7585)
Wọn kì yóò sì dùbúlẹ̀ ti àwọn tí ó ṣubú nínú àwọn aláìkọlà, tí wọn sọ̀kalẹ̀ lọ sí ipò òkú pẹ̀lú ìhámọ́ra ogun wọn, wọ́n tí fi idà wọn rọ orí wọn. Ṣùgbọ́n àìṣedéédéé wọn yóò wà ní orí egungun wọn—bí wọ́n tilẹ̀ jẹ́ ẹ̀rù àwọn alágbára ní ilẹ̀ alààyè. (Sheol h7585)
28 I ty będziesz skruszony wśród nieobrzezanych, i będziesz leżał pośród pobitych mieczem.
“Ìwọ náà, Farao, ní yóò ṣẹ, ti yóò dùbúlẹ̀ láàrín aláìkọlà, pẹ̀lú àwọn tí a fi idà pa.
29 Tam [jest] Edom, jego królowie i wszyscy jego książęta, którzy zostali położeni ze swoją mocą i wraz z pobitymi mieczem. Ci będą leżeć z nieobrzezanymi i z tymi, którzy zstępują do dołu.
“Edomu wà níbẹ̀, àwọn ọba rẹ̀ àti gbogbo ọmọbìnrin ọba; bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ní agbára, a tẹ́ wọn pẹ̀lú àwọn tí a fi idà pa. Wọn dùbúlẹ̀ pẹ̀lú aláìkọlà, pẹ̀lú àwọn ti o lọ sínú kòtò.
30 Tam [są] wszyscy książęta północy i wszyscy Sydończycy, którzy zstępują do pobitych; wstydzą się swego postrachu, jaki szerzyli swoją mocą, i leżą nieobrzezani z pobitymi mieczem. Znoszą swoją hańbę z tymi, którzy zstępują do dołu.
“Gbogbo àwọn ọmọ-aládé ilẹ̀ àríwá àti gbogbo àwọn ará Sidoni wà níbẹ̀; wọn lọ sí ìsàlẹ̀ pẹ̀lú àwọn tí a pa ní ìtìjú, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọn ṣe okùnfà ẹ̀rù pẹ̀lú agbára wọn. Wọn sùn ní àìkọlà pẹ̀lú àwọn tí a fi idà pa, wọn sì ru ìtìjú wọn pẹ̀lú àwọn tí ó lọ sí ìsàlẹ̀ kòtò.
31 Zobaczy ich faraon i ucieszy się z całej swojej rzeszy, którą pobito mieczem, faraon i całe jego wojsko – mówi Pan BÓG.
“Farao, òun àti gbogbo jagunjagun rẹ̀ yóò rí wọn, a yóò sì tù ú nínú nítorí gbogbo ogun rẹ̀ tí a fi idà pa, ní Olúwa Olódùmarè wí.
32 Szerzyłem bowiem swój postrach w ziemi żyjących i zostanie położony wśród nieobrzezanych z pobitymi mieczem – faraon i cała jego rzesza – mówi Pan BÓG.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo ti tan ẹ̀rù ká ilẹ̀ alààyè, Farao àti gbogbo ogun rẹ̀ ni a yóò tẹ́ sí àárín aláìkọlà, pẹ̀lú àwọn tí a fi idà pa ní Olúwa Olódùmarè wí.”

< Ezechiela 32 >