< Ezechiela 3 >

1 I powiedział do mnie: Synu człowieczy, zjedz to, co jest przed tobą; zjedz ten zwój i idź, przemawiaj do domu Izraela.
Síwájú sí i, ó sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, jẹ ohun tí ó wà níwájú rẹ, jẹ ìwé kíká yìí; kí o sì lọ fi bá ilé Israẹli sọ̀rọ̀.”
2 Otworzyłem więc swe usta i dał mi zjeść ten zwój.
Mo sì ya ẹnu mi, ó sì mú mi jẹ ìwé kíká náà.
3 I powiedział mi: Synu człowieczy, nakarm swój brzuch i napełnij swoje wnętrzności tym zwojem, który ci daję. Zjadłem [go], a był w moich ustach słodki jak miód.
Ó tún sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, jẹ ìwé kíká tí mo fún ọ yìí, fi bọ́ inú àti ikùn rẹ.” Nígbà náà ni mo jẹ ẹ́, dídùn rẹ̀ dàbí oyin ní ẹnu mi.
4 Potem powiedział do mnie: Synu człowieczy, idź, udaj się do domu Izraela i mów do niego moimi słowami.
Ó sì tún sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, lọ ni ìsinsin yìí bá mi sọ ọ̀rọ̀ mi fún ilé Israẹli.
5 Bo nie posyłam cię do ludu o niezrozumiałej mowie lub trudnym języku, [ale] do domu Izraela;
A kò rán ọ sí àwọn tó ń sọ èdè àjèjì tàbí tí èdè wọn ṣòro láti gbọ́, ṣùgbọ́n orílẹ̀-èdè Israẹli ni mo rán ọ sí
6 Nie do wielu narodów o niezrozumiałej mowie i trudnym języku, których słów byś nie zrozumiał, chociaż gdybym cię do nich posłał, usłuchałyby cię.
kì í ṣe sí ọ̀pọ̀ ènìyàn tó ń sọ àjèjì èdè tàbí tí èdè wọn ṣòro láti gbọ́, àwọn tí ọ̀rọ̀ wọn le fún ọ láti gbọ́ yé. Dájúdájú bí mo bá rán ọ sí wọn, wọn ìbá sì fetísílẹ̀ sí ọ.
7 Lecz dom Izraela nie będzie chciał cię słuchać, ponieważ mnie [samego] nie chce usłuchać. Cały dom Izraela ma bowiem twarde czoło i zatwardziałe serce.
Ṣùgbọ́n ilé Israẹli kò fẹ́ gbọ́ tìrẹ nítorí pé wọn kò fẹ́ láti gbọ́ tèmi, torí pé aláìgbọ́ràn àti ọlọ́kàn líle ni gbogbo ilé Israẹli.
8 Oto uczyniłem twoją twarz twardą przeciwko ich twarzom, a twoje czoło twarde przeciwko ich czołom.
Ṣùgbọ́n bí i tiwọn lèmi náà yóò ṣe jẹ́ kí ojú àti ọkàn rẹ le.
9 Uczyniłem twe czoło jak diament, twardszym od krzemienia. Nie bój się ich ani nie lękaj się ich twarzy, gdyż są domem buntowniczym.
Èmi yóò ṣe iwájú orí rẹ bí òkúta tó le jùlọ, ànító le ju òkúta-ìbọn lọ. Má ṣe bẹ̀rù wọn tàbí jẹ́ kí wọn ó dáyà já ọ. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìdílé ọlọ̀tẹ̀ ni wọ́n.”
10 I powiedział do mnie: Synu człowieczy, weź sobie do serca wszystkie moje słowa, które będę do ciebie mówić, i słuchaj ich uszami.
Ó sì sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ tí mo ń sọ, kí o sì gba gbogbo ọ̀rọ̀ yìí sí ọkàn rẹ.
11 Idź, udaj się do pojmanych, do synów twego ludu, i powiedz im: Tak mówi Pan BÓG – czy będą słuchać, czy nie.
Lọ nísinsin yìí sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ tó wà ní ìgbèkùn. Sọ fún wọn pé báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí yálà wọ́n gbọ́ tàbí wọn kò gbọ́.”
12 Wtedy duch uniósł mnie i usłyszałem za sobą huk wielkiego grzmotu: [Niech będzie] błogosławiona chwała PANA ze swego miejsca.
Nígbà náà ni ẹ̀mí gbé mi sókè, mo sì gbọ́ ohùn ìró ńlá lẹ́yìn mi tó sọ pé, kí a gbé ògo Olúwa ga láti ibùgbé rẹ̀ wá!
13 [Usłyszałem też] szum skrzydeł tych istot żywych, które się dotykały nawzajem, głos kół naprzeciwko nich i głos wielkiego grzmotu.
Bẹ́ẹ̀ ni mo tún gbọ́ ariwo ìyẹ́ apá àti kẹ̀kẹ́ àwọn ẹ̀dá alààyè náà pẹ̀lú ariwo tó dàbí àrá ńlá.
14 A duch uniósł mnie i zabrał. I poszedłem w goryczy i w gniewie swego ducha, lecz ręka PANA mocno ciążyła nade mną.
Ẹ̀mí náà sì gbé mi sókè, ó sì mú mi lọ, mo lọ pẹ̀lú ọkàn kíkorò àti ìbínú nínú ẹ̀mí mi, pẹ̀lú ọwọ́ líle Olúwa ni ara mi.
15 I przyszedłem do pojmanych w Tel-Abib, którzy mieszkali nad rzeką Kebar, i usiadłem [tam], gdzie oni mieszkali, pozostałem tam osłupiały wśród nich przez siedem dni.
Nígbà náà ni mo lọ sí etí odò Kebari níbi tí àwọn ìgbèkùn ń gbé ni Teli-Abibu. Níbẹ̀ níbi tí wọ́n ń gbé, mo jókòó láàrín wọn pẹ̀lú ìyanu, fún ọjọ́ méje.
16 A gdy minęło siedem dni, doszło do mnie słowo PANA mówiące:
Lẹ́yìn ọjọ́ méje, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé,
17 Synu człowieczy, ustanowiłem cię stróżem domu Izraela. Usłysz więc słowo z moich ust i upominaj go ode mnie.
“Ọmọ ènìyàn, mo ti fi ọ́ ṣe olùṣọ́ fún ilé Israẹli; nítorí náà gbọ́ ọ̀rọ̀ tí mo ń sọ, fún wọn ní ìkìlọ̀ láti ọ̀dọ̀ mi.
18 Gdy powiem bezbożnemu: Z pewnością umrzesz, a nie upomnisz go ani nie ostrzeżesz, aby go odwieść od jego bezbożnej drogi, aby uratować jego życie, to ten bezbożny umrze w swojej nieprawości, ale jego krwi zażądam z twojej ręki.
Bí mo bá sọ fún ènìyàn búburú pé, dájúdájú, ‘Ìwọ yóò kú,’ tí ìwọ kò sì kìlọ̀ fún ènìyàn búburú yìí láti dáwọ́ ìwà ibi rẹ̀ dúró, kí o sì gba ẹ̀mí rẹ̀ là, ènìyàn búburú náà yóò kú nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, ṣùgbọ́n ní ọwọ́ rẹ ni èmi yóò ti béèrè ẹ̀jẹ̀ rẹ̀.
19 Lecz jeśli ostrzeżesz bezbożnego, a on nie odwróci się od swej bezbożności i od swej bezbożnej drogi, to on umrze w swojej nieprawości, ale ty wybawisz swoją duszę.
Ṣùgbọ́n bí o bá kìlọ̀ fún ènìyàn búburú, tí ó kọ̀ tí kò fi ìwà búburú rẹ̀ sílẹ̀, yóò kú sínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀; ṣùgbọ́n ọrùn tìrẹ ti mọ́.
20 Gdy zaś sprawiedliwy odwróci się od swojej sprawiedliwości i popełni nieprawość, a ja ześlę na niego przeszkodę, to on umrze. Ponieważ nie ostrzegłeś go, umrze w swym grzechu i nie będzie się pamiętać o jego sprawiedliwości, którą czynił, lecz jego krwi zażądam z twojej ręki.
“Bákan náà, bí olódodo kan bá yípadà, tó sì bẹ̀rẹ̀ sí í ṣe àìṣòdodo, tí mo sì fi ohun ìkọ̀sẹ̀ sí ọ̀nà rẹ̀, yóò kú sínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀. Nítorí pé ìwọ kọ̀ láti kìlọ̀ fún un, yóò kú sínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, a ó gbàgbé gbogbo ìwà rere tó ti hù tẹ́lẹ̀, ṣùgbọ́n ní ọwọ́ rẹ̀ ni èmi yóò ti béèrè ẹ̀jẹ̀ rẹ̀.
21 Ale jeśli ostrzeżesz sprawiedliwego, aby sprawiedliwy nie zgrzeszył, i on nie zgrzeszy, na pewno będzie żył, bo przyjął ostrzeżenie, a ty ocalisz swoją duszę.
Ṣùgbọ́n bí o bá kìlọ̀ fún olódodo tó sì dáwọ́ ìwà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ dúró, dájúdájú òun yóò yè nítorí pé ó ti gba ìkìlọ̀, ọrùn tìrẹ sì mọ́.”
22 I spoczęła tam nade mną ręka PANA, i powiedział do mnie: Wstań i pójdź na równinę, tam będę z tobą mówił.
Ọwọ́ Olúwa wà lára mi níbẹ̀, ó sì wí fún mi pé, “Dìde, lọ sí ibi tí ó tẹ́jú, èmi yóò sì bá ọ sọ̀rọ̀ níbẹ̀.”
23 Wstałem więc i wyszedłem na równinę, a oto chwała PANA stała tam, taka jak chwała, którą widziałem nad rzeką Kebar, i upadłem na twarz.
Mo sì dìde, mo lọ sí ibi tí ó tẹ́jú. Ògo Olúwa dúró níbẹ̀, ó dàbí irú ògo tí mo rí létí odò Kebari, mo sì dojúbolẹ̀.
24 Wtedy duch wstąpił we mnie, postawił mnie na nogi i przemówił do mnie: Idź i zamknij się w swym domu.
Nígbà náà ni Ẹ̀mí wọ inú mi, tí ó sì tún gbé mi dúró. Ó sì wí fún mi pé, “Lọ, ti ara rẹ mọ́ inú ilé rẹ
25 Bo oto, synu człowieczy, włożą na ciebie powrozy i zwiążą cię nimi, a nie będziesz mógł wyjść między nich.
ṣùgbọ́n ìwọ, ọmọ ènìyàn, wọn yóò fi okùn dè ọ́ mọ́lẹ̀; dé ibi pé ìwọ kò ní í le rìn káàkiri láàrín àwọn ènìyàn.
26 A ja sprawię, że twój język przylgnie do twego podniebienia i będziesz niemy, i nie będziesz dla nich człowiekiem, który strofuje, gdyż są domem buntowniczym.
Èmi yóò mú kí ahọ́n rẹ lẹ̀ mọ́ àjà ẹnu rẹ, tó bẹ́ẹ̀ ti ìwọ yóò wà ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́. Ìwọ kò sì ní lè bá wọn wí, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ọlọ̀tẹ̀ ilé ní wọn.
27 Ale gdy będę z tobą mówić, otworzę ci usta i powiesz do nich: Tak mówi Pan BÓG: Kto [chce] słuchać, niech słucha, a kto nie chce, niech nie słucha – gdyż są domem buntowniczym.
Ṣùgbọ́n nígbà tí èmi bá bá ọ sọ̀rọ̀, Èmi yóò ṣí ọ lẹ́nu, ìwọ yóò sì sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí.’ Ẹni tó bá fẹ́ kí ó gbọ́, ẹni tó bá fẹ́ kọ̀, kó kọ̀ nítorí ọlọ̀tẹ̀ ilé ni wọ́n.

< Ezechiela 3 >