< Ezechiela 24 >
1 W dziewiątym roku, w dziesiątym miesiącu, dziesiątego [dnia] tego miesiąca, znowu doszło do mnie słowo PANA mówiące:
Ní ọdún kẹsànán, oṣù kẹwàá, ọjọ́ kẹwàá, ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
2 Synu człowieczy, napisz sobie datę tego dnia, tego właśnie dnia. W tym dniu [bowiem] król Babilonu obległ Jerozolimę.
“Ọmọ ènìyàn, kọ ọjọ́ náà sílẹ̀, ọjọ́ náà gan an, nítorí ọba Babeli náà ti da ojú ti Jerusalẹmu ní ọjọ́ yìí gan an.
3 I opowiedz przypowieść temu domowi buntowniczemu. Powiedz do niego: Tak mówi Pan BÓG: Postaw kocioł, postaw i nalej do niego wody.
Sì pa òwe yìí fún ilé ọlọ́tẹ̀ náà, sọ fún wọn pé: ‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “‘Gbé ìkòkò ìdáná náà ka iná, gbé e ka iná kí o sì da omi sí i nínú.
4 Włóż do niego kawałki [mięsa], każdy dobry kawałek, udziec i łopatkę, napełnij [go] najlepszymi kośćmi.
Kó àwọn ègé ẹran tí a gé náà sínú rẹ̀, gbogbo àwọn ègé ẹran tí ó tóbi, itan àti apá. Kó àwọn egungun tí ó dára jù sínú rẹ̀,
5 Weź [to], co najlepsze ze stada, rozpal pod nim ogień z kości, aby wrzało i kipiało, i niech się ugotują w nim kości.
mú àwọn tí ó jọjú nínú agbo ẹran. Kó àwọn egungun sí abẹ́ ẹ rẹ̀; sì jẹ́ kí ó hó dáradára sì jẹ́ kí àwọn egungun náà bọ̀ nínú rẹ̀.
6 Dlatego tak mówi Pan BÓG: Biada miastu krwawemu, kotłowi, w którym jest jego szumowina i z którego szumowina nie wychodzi. Wyciągaj z niego kawałek po kawałku, niech nie padnie na niego los.
Nítorí báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Ègbé ni fún ìlú ẹlẹ́jẹ̀ náà, fún ìkòkò náà tí èérí rẹ̀ wà nínú rẹ̀, tí èérí kò dà kúrò lójú rẹ̀! Mú ẹran náà jáde ní ekìrí ekìrí má ṣe ṣà wọ́n mú.
7 W nim bowiem jest krew przelana przez niego; wystawiono ją na wierzchu skały, nie wylano jej na ziemię, aby była przykryta prochem;
“‘Nítorí ẹ̀jẹ̀ tí ó ta sílẹ̀ wà ní àárín rẹ̀; à á sí orí àpáta kan lásán kò dà á sí orí ilẹ̀, níbi ti erùpẹ̀ yóò ti bò ó.
8 Aby rozniecić zapalczywość dla dokonania zemsty. Wystawiłem [więc] jego krew na wierzchu skały, aby nie była przykryta.
Láti bá à le jẹ́ kí ìbínú kí ó dé láti gbẹ̀san mo da ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ sí orí àpáta kan lásán, kí o ma bà á wà ni bíbò.
9 Dlatego tak mówi Pan BÓG: Biada miastu krwawemu! Ja ułożę wielki stos [drew].
Nítorí náà báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “‘Ègbé ni fún ìlú ẹlẹ́jẹ̀ náà! Èmi pàápàá yóò jẹ́ kí òkìtì iná náà tóbi.
10 Nakładaj drwa, rozniecaj ogień, ugotuj mięso i przypraw korzeniem, niech kości się spalą.
Nítorí náà kó igi náà jọ sí i, kí o sì fi iná sí i. Ṣe ẹran náà dáradára, fi tùràrí dùn ún; kí o sì jẹ́ kí egungun náà jóná.
11 Potem postaw pusty kocioł na węglach, aby się rozgrzał i rozpaliła jego miedź, by się roztopiła w nim jego nieczystość i jego szumowina była zniszczona.
Lẹ́yìn náà gbé òfìfo ìkòkò náà lórí ẹyin iná kí idẹ rẹ̀ lè gbóná, kí ó lè pọ́n àti ki ìfófó rẹ̀ le di yíyọ́ nínú rẹ̀ kí èérí rẹ̀ le jó dànù.
12 Zmęczyła się [swymi] kłamstwami, a ogrom jej szumowiny nie wychodzi z niej, jej szumowina [będzie strawiona] w ogniu.
Ó ti ba gbogbo akitiyan jẹ: èérí rẹ̀ kò sì jáde kúrò lára rẹ̀, èérí náà gan an yóò wà nínú iná.
13 W twojej nieczystości [jest] rozwiązłość. Ponieważ [chciałem] cię oczyścić, a nie dałaś się oczyścić, to już nie będziesz oczyszczona ze swojej nieczystości, aż uśmierzę na tobie swoją zapalczywość.
“‘Nísinsin yìí èérí rẹ̀ ni ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ wà. Nítorí mo gbìyànjú láti wẹ̀ ọ́ mọ́, ṣùgbọ́n ìwọ kò sì mọ́ kúrò nínú ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ, a kì yóò sì tún wẹ̀ ọ mọ́ kúrò nínú èérí rẹ, títí èmi yóò fi jẹ́ kí ìbínú mi balẹ̀ sórí rẹ̀.
14 Ja, PAN, powiedziałem. Przyjdzie [to] i dokonam [tego], nie cofnę się i nie zlituję się ani nie będę żałował; według twoich dróg i według twoich czynów będę cię sądzić, mówi Pan BÓG.
“‘Èmi Olúwa ni ó sọ ọ́, yóò sì ṣe, èmi yóò sì ṣe é. Èmi kì yóò padà sẹ́yìn; bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò dá sí i, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò yí ọkàn mi padà; gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ, àti gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ, ni wọn yóò dá ọ lẹ́jọ́, ni Olúwa Olódùmarè wí.’”
15 I doszło do mnie słowo PANA mówiące:
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá pé:
16 Synu człowieczy, oto zabiorę ci nagle rozkosz twoich oczu, ale ty nie lamentuj ani nie płacz, niech twoje łzy się nie wylewają.
“Ọmọ ènìyàn, kíyèsi i, mo mú ìfẹ́ ojú rẹ kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ, nípa lílù kan. Ṣùgbọ́n ìwọ kò gbọdọ̀ gbààwẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ sọkún, bẹ́ẹ̀ ni omijé ojú rẹ kò gbọdọ̀ kán sílẹ̀.
17 Zaniechaj zawodzenia, nie urządzaj żałoby [po] zmarłej; zawiąż sobie zawój, nałóż obuwie na nogi, nie zasłaniaj warg i nie jedz niczyjego chleba.
Má ṣe sọkún, má ṣe gbààwẹ̀ fún òkú. Wé ọ̀já sí orí rẹ, sì bọ bàtà sí ẹsẹ̀ rẹ, má ṣe bo ètè ìsàlẹ̀ rẹ, ma ṣe jẹ oúnjẹ tí àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ ń jẹ gẹ́gẹ́ bí àṣà.”
18 Rano przemówiłem więc do ludu, a wieczorem umarła moja żona; i uczyniłem rano, jak mi rozkazano.
Báyìí ni mo sọ̀rọ̀ fún àwọn ènìyàn ní òwúrọ̀, ní àṣálẹ́ ìyàwó mi sì kú. Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, mo ṣe bí a ti pàṣẹ fún mi.
19 I lud zapytał mnie: Czy nie powiesz nam, co [znaczą] dla nas te rzeczy, które czynisz?
Lẹ́yìn náà àwọn ènìyàn bi mí léèrè pé, “Ṣe o kò ni sọ fún wa ohun ti nǹkan wọ̀nyí ní láti ṣe pẹ̀lú wa?”
20 Wtedy odpowiedziałem im: Słowo PANA doszło do mnie mówiące:
Mo sọ báyìí fún wọn pé, “Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
21 Powiedz domowi Izraela: Tak mówi Pan BÓG: Oto zbezczeszczę swoją świątynię, chlubę waszej potęgi, rozkosz waszych oczu i miłość waszej duszy, a wasi synowie i wasze córki, które pozostawiliście, polegną od miecza.
Sọ fún ilé Israẹli, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Kíyèsi i, èmi yóò sọ ibi mímọ́ mi di ibi àìmọ́ tayọ agbára yín, ìfẹ́ ojú yín, ìkáàánú yín, àti ọmọ yín ọkùnrin àti àwọn ọmọ yín obìnrin tí ẹ̀yin fi sílẹ̀ sẹ́yìn yóò ṣubú nípa idà.
22 I uczynicie tak, jak ja uczyniłem: nie zasłonicie warg i nie będziecie jeść niczyjego chleba;
Ẹyin yóò sì ṣe bí mo ti ṣe. Ẹ̀yin kì yóò bo ìsàlẹ̀ ojú yín tàbí jẹ oúnjẹ ti àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ ń jẹ gẹ́gẹ́ bí àṣà.
23 Wasze zawoje [będą] na waszych głowach i wasze obuwie na nogach; nie będziecie zawodzić ani płakać, lecz będziecie schnąć z powodu waszych nieprawości i będziecie wzdychać jeden do drugiego.
Ẹ̀yin yóò fi àwọn ọ̀já wé àwọn orí yín àti àwọn bàtà ni ẹsẹ̀ yín, ẹ̀yin kì yóò ṣọ̀fọ̀ tàbí sọkún, ṣùgbọ́n ẹ̀yin yóò ṣòfò dànù nítorí àwọn àìṣedéédéé yín, ẹ̀yin yóò sì máa kérora láàrín ara yín.
24 I Ezechiel będzie dla was znakiem: wszystko, co on uczynił, wy będziecie czynić. [A] gdy to nastąpi, poznacie, że ja jestem Panem BOGIEM.
Esekiẹli yóò jẹ àmì fún un yín; ẹ̀yin yóò sì ṣe gẹ́gẹ́ bí òun ti ṣe. Nígbà tí èyí bá ṣẹlẹ̀, ẹ̀yin yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Olódùmarè.’
25 A ty, synu człowieczy, czy w tym dniu, w którym zabiorę im ich moc, radość ich chluby, rozkosz ich oczu i tęsknotę duszy, ich synów i córki;
“Pẹ̀lúpẹ̀lú ìwọ, Ọmọ ènìyàn, kì yóò ha jẹ́ pé, ní ọjọ́ náà, nígbà ti mo bá gba agbára wọn, ayọ̀ wọn àti ògo wọn, ìfẹ́ ojú wọn, ohun tí wọn gbé ọkàn wọn lé, àti àwọn ọmọ ọkùnrin wọn pẹ̀lú àwọn ọmọ obìnrin wọn kúrò lọ́dọ̀ wọn,
26 [Czy] w tym dniu nie przyjdzie do ciebie ten, co ucieknie, aby przynieść wieść dla twoich uszu?
ní ọjọ́ náà ẹni tí ó bá sálà yóò tọ̀ ọ́ wá láti sọ ìròyìn náà fún ọ.
27 W tym dniu otworzą się twoje usta przed tym, który uszedł, i będziesz mówił, a nie będziesz już niemy. Będziesz dla nich znakiem i poznają, że ja jestem PANEM.
Ní ọjọ́ náà ẹnu rẹ yóò sì ṣí; ìwọ yóò sọ̀rọ̀, ìwọ kì yóò sì yadi mọ́. Báyìí ìwọ yóò jẹ́ àmì fún wọn; wọn yóò sì mọ̀ pé èmi ní Olúwa.”